< Salamo 78 >
1 Tsendreño o fañòhakoo ry ondatiko, atokilaño mb’am-pivolañam-bavako o ravembia’ areoo.
Maskili ti Asafu. Ẹ̀yin ènìyàn mi, ẹ gbọ́ ẹ̀kọ́ mi; tẹ́tí rẹ sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
2 Ho sokafeko ty vavako handrazaña’e: ho lañoneko razan-tsaontsy miheotse boak’an-kaehae’e;
Èmi ó la ẹnu mi ní òwe, èmi o sọ ohun ìkọ̀kọ̀, ohun ti ọjọ́ pípẹ́;
3 o jinanjin-tika naho fohin-tikañe vaho natalilin-droae aman-tikañeo.
ohun tí a ti gbọ́ tí a sì ti mọ̀, ohun tí àwọn baba wa ti sọ fún wa.
4 Aa le tsy haetantika amo ana’ iareoo, fa hatalilin-tika amo tariratse ho avio ty fandrengeañe Iehovà, naho ty haozara’e vaho o fitoloña’e ra’elahy nifonire’eo.
Àwa kì yóò pa wọ́n mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọmọ, ní fífi ìyìn Olúwa, àti ipa rẹ̀ àti iṣẹ́ ìyanu tó ti ṣe hàn fún ìran tí ń bọ̀.
5 Fa noriza’e e Iakobe ao ty taroñe naho najado’e e Israele ao t’i Hake linili’e aman-droaen-tikañey, hañanara’ iareo o ana’ iareo,
Ó gbé ẹ̀rí kalẹ̀ ní Jakọbu o sì fìdí àṣẹ múlẹ̀ ní Israẹli, èyí tí ó pàṣẹ fún àwọn baba ńlá wa láti kọ́ àwọn ọmọ wọn,
6 hampahafohina’ iareo ty tariratse ho avy, naho o ajaja mbe hasamakeo, hitroara’ iareo hañoke o ana’eo,
nítorí náà, àwọn ìran tí ń bọ̀ yóò mọ̀ wọ́n bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí tí yóò dìde tí wọn yóò sọ fún àwọn ọmọ wọn.
7 soa te ho aman’Añahare ty fatokisa’e, vaho tsy handikofa’ iareo o fitoloñan’ Añahareo, fe hambena’ iereo o lili’eo;
Nígbà náà ni wọ́n ò fi ìgbẹ́kẹ̀lé wọn sínú Ọlọ́run wọn kò sì ní gbàgbé iṣẹ́ Ọlọ́run ṣùgbọ́n wọn ó pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
8 naho tsy hitsikombe o roae’ iareoo; tariratse mitangingìñe naho miola, tariratse tsy nampifahatse troke, tsy nigahiñe aman’ Añahare ty arofo’e.
Kí wọn kí ó má ṣe dàbí àwọn baba ńlá wọn, ìran alágídí àti ọlọ́tẹ̀, ìran tí ọkàn wọn kò ṣọ òtítọ́ si olóore, àti ẹ̀mí ẹni tí kò bá Ọlọ́run dúró ṣinṣin.
9 Nimpitam-pale ninday fale o ana’ i Efraimeo f’ie niamboho tañ’ andro’ i hotakotakey.
Àwọn ọkùnrin Efraimu, tí ó há mọ́ ọ tí wọ́n mú ọrun, wọ́n yípadà ní ọjọ́ ogun
10 Tsy nambena’ iareo i fañinan’ Añaharey, vaho nifoneñe tsy hañavelo amy Tsara’ey.
Wọn kò pa májẹ̀mú Ọlọ́run mọ́ wọn sì kọ̀ láti máa gbé nínú òfin rẹ̀.
11 Nihaliño’ iareo o fitoloña’eo— o halatsàñe naboa’e am’ iareoo,
Wọ́n gbàgbé ohun tí ó ti ṣe, àwọn ìyanu tí ó ti fihàn wọ́n.
12 o raha tsitantane nanoe’e añatrefan- droae’ iareo e Mitsraimeo, an-tete’ i Tsòañe ao.
Ó ṣe ìyanu níwájú àwọn baba wọn ní ilẹ̀ Ejibiti, ní agbègbè Ṣoani.
13 Finatsi’e i riakey naho nampisorohe’e mb’eo iereo! najoha’e hoe votry i ranoy.
Ó pín òkun ní yà, ó sì mú wọn kọjá Ó mù kí omi náà dúró bi odi gíga.
14 Le niaoloa’e an-drahoñe iereo te antoandro, naho an-kazavàñ’afo te haleñe am-para’ te niporea.
Ní ọ̀sán, ó fi ìkùùkuu àwọsánmọ̀ ṣe amọ̀nà wọn àti ní gbogbo òru pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ iná.
15 Finoi’e o vato am-patrañeo, finaha’e rano bey manahake i an-dalekey;
Ó sán àpáta ní aginjù ó sì fún wọn ní omi mímu lọ́pọ̀lọ́pọ̀ bí ẹni pé láti inú ibú wá.
16 Nampitotsaha’e torahañe ty lamilamy vaho nampikararaha’e rano hoe oñe.
Ó mú ìṣàn omi jáde láti inú àpáta omi ṣíṣàn sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí odò.
17 Fe mbe nandilara’ iareo, niola amy Abo Tiañey am-babangoañ’ añe.
Wọ́n sì tún tẹ̀síwájú láti dẹ́ṣẹ̀ sí i ní ìṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo ní aginjù.
18 Nitsohe’ iereo an-troke t’i Andrianañahare, nihalaly mahakama ty amy hadrao’iareo.
Wọ́n mọ̀ ọ́n mọ̀ dán Ọlọ́run wò nípa bíbéèrè fún oúnjẹ tí wọn bẹ̀bẹ̀ fún.
19 Toe, nandrabio’ iareo t’i Andrianañahare, ami’ty hoe: Mahafañalankañe fandambañañe an-dratraratra ao hao t’i Andrianañahare,
Wọ́n sọ̀rọ̀-òdì sí Ọlọ́run, wí pé “Ọlọ́run ha lè tẹ́ tábìlì ní aginjù?
20 Eka, finofo’e i vato nampidoandoan-dranoy, vaho nampanganahanae’e o torahañeo. Aa vaho hahafanjotsoa’e mofo ka? he ho fahana’e hena hao ondati’eo?
Nígbà tí ó lu àpáta, omi tú jáde, odò sì sàn lọ́pọ̀lọ́pọ̀ ṣùgbọ́n òun ha lè fún wa lóúnjẹ ó ha le pèsè ẹran fún àwọn ènìyàn rẹ̀?”
21 Aa ie jinaji’ Iehovà, le niforoforo ty fifombo’e, naho namiañañe afo t’Iakobe, vaho nionjoñe am’ Israele ty haviñerañe,
Nígbà tí Olúwa gbọ́ wọn, ó bínú gidigidi; iná rẹ̀ sọ̀kalẹ̀ sí Jakọbu, ìbínú rẹ̀ sì rú sí Israẹli,
22 Amy t’ie tsy natoky an’Andrianañahare, vaho tsy niatoa’ iareo ty fandrombaha’e;
nítorí wọn kò gba Ọlọ́run gbọ́, wọn kò sì gbẹ́kẹ̀lé ìgbàlà rẹ̀.
23 Fe linili’e o rahoñe amboneo, naho sinoka’e o lalambein-dindìñeo,
Síbẹ̀ ó pàṣẹ fún ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì ṣí ìlẹ̀kùn ọ̀run sílẹ̀;
24 nampikojojoaha’e mane ho kamae’iereo; nanjotsoa’e ampemban-dikerañe.
Ó rọ manna fún àwọn ènìyàn láti jẹ, ó fún wọn ní ọkà láti ọ̀run.
25 Nikama ty mofom-panalolahy ondatio! nampidobaña’e mahakama nahaeneñe!
Àwọn ènìyàn jẹ oúnjẹ àwọn angẹli; Ó fún wọn ní oúnjẹ ní àjẹyó,
26 Nampikofaohe’e an-dikerañe ey ty tiok’ atiñanañe vaho nitehafe’e an-kaozarañe i tiok’ atimoy.
Ó mú afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀run wá ó mú afẹ́fẹ́ gúúsù wá nípa agbára rẹ̀.
27 Nampidoañe’e am’ iareo ty hena hoe lemboke, voroñe amañ’elatse mira amo fasen-driakeo!
Ó rọ òjò ẹran sílẹ̀ sórí wọn bí erùpẹ̀ ilẹ̀, àti ẹyẹ abìyẹ́ gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun
28 nampivotrahe’e aivo’ ty tobe’e ao, niarikoboñe i Toem-pimoneña’ey.
Ó jẹ́ kí wọn jáde ní ibùdó wọn, yíká àgọ́ wọn.
29 Aa le nikama iareo vaho nianjañe amy te nanjotsoa’e ty hasiji’ iareo.
Wọ́n jẹ, wọ́n sì yó jọjọ nítorí ó ti fún wọn ní ohun tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún.
30 Ie mboe nibòro ty drao’ iareo, mbe tam-palie’ iareo ao i henay,
Ṣùgbọ́n wọn kò kúrò nínú oúnjẹ tí wọn fìtara bẹ̀bẹ̀ fún, nígbà tí oúnjẹ wọn sì wà ní ẹnu wọn,
31 le nihelofe’ ty haviñeran’ Añahare navetra’e o nanjofak’ am’iereoo, vaho nampihotrahe’e o jinoboñ’ Israeleo.
ìbínú Ọlọ́run dìde sí wọn ó pa àwọn tí ó jùlọ nínú wọn, ó sì lu àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli bolẹ̀.
32 Ie amy zay iaby, mbe nitolon-kakeo iereo, tsy niantoke o fitoloña’e fanjakao.
Nínú gbogbo ìwọ̀nyí, wọ́n ń dẹ́ṣẹ̀ síwájú; nínú gbogbo iṣẹ́ ìyanu rẹ̀, wọ́n kò gbàgbọ́.
33 Aa le nampigadoña’e an-kamodoañe ty andro’ iareo, naho an-kebahebake ty tao’ iareo.
O fi òpin sí ayé wọn nínú asán àti ọdún wọn nínú ìpayà.
34 Ie zinevo’e iereo, naho nipay aze, nisoloho vaho nitsoeke an’Andrianañahare,
Nígbàkígbà tí Ọlọ́run bá pa wọ́n, wọn yóò wá a kiri; wọn yóò fi ìtara yípadà sí i.
35 le nahatiahy te lamilami’ iareo t’i Andrianamboatse, naho t’ie Mpijeba’ iareo i Andrianañaharen-dindimoneñey.
Wọ́n rántí pé Ọlọ́run ní àpáta wọn; wí pé Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo jùlọ ni olùràpadà àpáta wọn.
36 Fe kinabea’ iareo am-palie; vaho nandañitse am-pameleke.
Ṣùgbọ́n nígbà náà ni wọ́n yóò pọ́n ọn pẹ̀lú ẹnu wọ́n wọ́n fi ahọ́n wọ́n purọ́ fún un;
37 Toe tsy nifahatse ama’e o arofo’ iareoo, naho tsy nigahiñe amy fañìna’ey.
ọkàn wọn kò sòtítọ́ sí i, wọn kò jẹ́ olódodo sí májẹ̀mú rẹ̀.
38 Fe amy fitretreza’ey, le hinaha’e o hakeo’ iareoo, naho tsy rinotsa’e; beteke natoli’e ty haviñera’e, vaho tsy fonga nitroboa’e o fifombo’eo!
Síbẹ̀ ó ṣàánú; ó dárí àìṣedéédéé wọn jì òun kò sì pa wọ́n run nígbà púpọ̀ ló ń yí ìbínú rẹ̀ padà kò sì ru ìbínú rẹ̀ sókè
39 Nitiahi’e te nofotse avao iareo, tioke mihelañe naho tsy mibalike.
Ó rántí pé ẹlẹ́ran ara ni wọ́n, afẹ́fẹ́ tó ń kọjá tí kò lè padà.
40 Impire hao ty niodia’ iareo am-patrambey añe, vaho nampioje’Aze an-dratraratra añe?
Nígbà gbogbo ní wọn ń ṣọ̀tẹ̀ sí i ní aginjù wọn mú un bínú nínú ilẹ̀ tí ó di ahoro!
41 Eka, niamboho naho nitsok’ an’Andrianañahare iereo, vaho nanigike i Masi’ Israeley
Síwájú àti síwájú wọ́n dán Ọlọ́run wò; wọ́n mú ẹni mímọ́ Israẹli bínú.
42 Tsy nitiahi’ iereo ty fità’e, i andro nijebaña’e iareo amy rafelahiy,
Wọ́n kò rántí agbára rẹ̀: ní ọjọ́ tí ó rà wọ́n padà lọ́wọ́ àwọn aninilára,
43 Ie nampipoha’e e Mitsraime añe o vilo’eo naho an-tete’ i Tsòañe ao o halatsà’eo.
ní ọjọ́ tí ó fi iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ hàn ní Ejibiti, àti iṣẹ́ àmì rẹ̀ ni ẹkùn Ṣoani
44 Nafote’e ho lio o saka’ iareoo, vaho tsy nimete kamaeñe o toraha’ iareoo.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀; wọn kò lè mu láti odò wọn.
45 Nañiraha’e laletse nifamorohotse, namotseke, naho sahoñe nandrotsake.
Ó rán ọ̀wọ́ eṣinṣin láti pa wọ́n run, àti ọ̀pọ̀lọ́ tí ó bá wọn jẹun.
46 Natolo’e amo oletseo ty havokara’ iareo, amo valalao ty tolim-pitoloña’ iareo.
Ó fi ọkà wọn fún láńtata, àwọn ìre oko wọn fún eṣú.
47 Rinotsa’e ami’ty havandra ty vahe’ iareo, naho an-drano-panala o sakoa’ iareoo.
Ó fi yìnyín ba àjàrà wọn jẹ́ ó bá èso sikamore wọn jẹ́.
48 Nengae’e amy havandray o añombe’ iareoo, vaho an-kelatse nibelabela o mpirai-tro’ iareoo.
Ó fi ohun ọ̀sìn wọn fún yìnyín, agbo ẹran wọn fún mọ̀nàmọ́ná.
49 Nahitri’e am’iereo ty fiforoforoa’e; fifomboañe naho haviñerañe vaho hankàñe; firimboñan’ anjely mpandrotsake.
Ó mú kíkorò ìbínú rẹ̀ wá sí wọn lára, ìrunú àti ìkáàánú, àti ìpọ́njú, nípa rírán angẹli apanirun sí wọn.
50 Nampimirae’e lalañe i haviñera’ey; tsy navotso’e am-pihomahañe ty fiai’iareo, fa napo’e ho zamanen-kiria ty havelo’ iareo
Ó pèsè ipa fún ìbínú rẹ̀, òun kò gbà wọ́n lọ́wọ́ ikú, ṣùgbọ́n ó fi ẹ̀mí wọ́n fún àjàkálẹ̀-ààrùn.
51 Binaibai’e ze hene tañoloñoloña’ i Mitsraime, ty lohan-kaozara’iareo an-kiboho’ i Kame ao.
Ó kọlu àwọn àkọ́bí ọmọ ọkùnrin Ejibiti, olórí agbára wọn nínú àgọ́ Hamu.
52 Nonjone’e hoe añondry ondati’eo; vaho niaoloa’e mb’am-babangoañe añe hoe lia-raike.
Ṣùgbọ́n ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde bí ọ̀wọ́ ẹran; ó ṣọ́ wọn gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú aginjù.
53 Nindese’e tsy nolañeñe, le tsy nihembañe iereo, vaho nampiopoe’ i riakey o rafelahio.
Ó dáàbò bò wọ́n dáradára, nítorí náà ni ẹ̀rù kò ṣe bà wọ́n ṣùgbọ́n òkun padé mọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
54 Nindese’e mb’an-tane’e miavake mb’eo, sikala’ami’ty vohitse vinilim-pità’e havana toy.
Bákan náà ni ó mú wọn wá sí etí ilẹ̀ mímọ́ rẹ̀ òkè tí ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ti gbà
55 Rinoa’e aolo’ iareo ka o kilakila’ndatio; le zinara’e an-taly ty lova’ iareo, vaho nampitobea’e amo akiba’ iareoo o fifokoa’ Israeleo.
Ó lé kèfèrí jáde níwájú wọn ó sì fi títa okùn pín ilẹ̀ náà fún wọn gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní; ó mú àwọn ẹ̀yà Israẹli jókòó ní ilẹ̀ wọn.
56 F’ie nangala-pañahy naho niola aman’Añahare Andindimoneñe, vaho tsy nambena’ iereo o taro’eo;
Ṣùgbọ́n wọn dán Ọlọ́run wò wọn sì ṣọ̀tẹ̀ sí Ọ̀gá-ògo; wọn kò pa àṣẹ rẹ̀ mọ́.
57 Te mone nibalintoa naho nañorike ty tsy fatokisan-droae’ iareo; niolake hoe fale mibatriotse.
Ṣùgbọ́n wọ́n yípadà, wọn jẹ́ aláìṣòdodo gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn wọ́n sì pẹ̀yìndà sí apákan bí ọrun ẹ̀tàn.
58 Ie nikai-jaka ama’e amo tamboho’ iareo; vaho nampamarahy aze amo raham-pahasive’iareoo.
Wọ́n bí i nínú pẹ̀lú ibi gíga wọn; wọn rú owú rẹ̀ sókè nípa òrìṣà wọn.
59 Nahajanjiñe t’i Andrianañahare le nifombo vaho niheje’e vintañe t’Israele.
Nígbà tí Ọlọ́run gbọ́ wọn, inú bí i gidigidi; ó kọ Israẹli pátápátá.
60 Le naforintse’e ty kivoho’e e Silo ao, i akiba nanoe’e himoneña’e añivo’ondatioy.
Ó kọ àgọ́ Ṣilo sílẹ̀, àgọ́ tí ó ti gbé kalẹ̀ láàrín àwọn ènìyàn.
61 Nasese’e mb’ am-pandrohizañe añe ty haozara’e, le am-pità’ o rafelahio ty enge’e.
Ó rán àpótí ẹ̀rí, agbára rẹ̀ lọ sí ìgbèkùn, dídán ògo rẹ̀ lọ sí ọwọ́ àwọn ọ̀tá.
62 Natolo’e ami’ty fibara ka ondati’eo, naha-fiforoforo Aze i lova’ey.
Ó fi àwọn ènìyàn rẹ̀ lé idà lọ́wọ́, ó sì bínú sí àwọn ohun ìní rẹ̀.
63 Nabotse’ ty afo o ajalahi’eo; naho tsy nanan-tsabo haonjoñe o somondrara’eo.
Iná run àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wọn, àwọn ọmọbìnrin wọn kò sì ní orin ìgbéyàwó:
64 Nampikorovohem-pibara o mpisoro’ iareoo, naho tsy nahafandala o remavoi’ iareoo.
àfi àlùfáà wọn fún idà, àwọn opó wọn kò sì le è sọkún.
65 Nivañoñe amy zao t’i Talè hoe nirotse, manahake ty fanalolahy niopoen-divay.
Olúwa sì jí gẹ́gẹ́ bí ẹni ojú oorun, gẹ́gẹ́ bí ọkùnrin ti i jí kúrò nínú ìraníyè ọtí.
66 Nampipolie’e an-dafa o rafelahi’eo, le nametsaha’e hasalarañe tsy modo kitro katroke.
Ó kọlu àwọn ọ̀tá rẹ̀ padà; ó fi wọn sínú ìtìjú ayérayé.
67 Mbore nifarie’e ty kivoho’ Iosefe; le tsy jinobo’e ty tarira’ i Efraime.
Nígbà náà ni ó kọ́ àgọ́ Josẹfu, kò sì yan ẹ̀yà Efraimu,
68 Fe ginene’e ty fifokoa’ Iehodà, i vohy Tsiône nikokoa’ey.
ṣùgbọ́n ó yan ẹ̀yà Juda, òkè Sioni, èyí tí ó fẹ́ràn.
69 Rinanji’e hoe o haboañeo i toe’e miavakey, manahake ty tane naore’e ho nainai’e tsy ho modo toy.
Ó kọ́ ibi mímọ́ rẹ̀, ibi gíga, gẹ́gẹ́ bí ayé tí ó fi ìdí rẹ̀ múlẹ̀ títí láé.
70 Jinobo’e ka t’i Davide mpitoro’e, rinambe’e amo golobon’añondrio.
Ó yan Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀ ó mú láti inú àwọn agbo ẹran;
71 Boak’ am-piarahañe o añondry mampinonoo ty nendesa’e aze hiaraha’e o tiri’ Iakobe ondati’eo, naho Israele lova’ey
Ó mú un jáde nínú ìtọ́jú àgùntàn láti jẹ́ olùṣọ́-àgùntàn àwọn ènìyàn rẹ̀ Jakọbu àti Israẹli ogún un rẹ̀.
72 Nifahana’e añ’ arofo-vañonañe le niaoloa’e am-pitàñe mahimbañe.
Dafidi sì ṣọ́ wọn pẹ̀lú òtítọ́ inú ọkàn; pẹ̀lú ọwọ́ òye ni ó fi darí wọn.