< Nomery 28 >

1 Hoe ty nitsara’ Iehovà amy Mosè:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Lilio o Ana’ Israeleo naho ano ty hoe: Ambeno’ areo amy andro famantañañ’ azey ty hañengàñe amako i hanekoy, i soroñañe amako ho hàñin-kanintsiñe amakoy.
“Fún àwọn ọmọ Israẹli ní òfin yìí kí o sì wí fún wọn pé: ‘Ẹ rí i wí pé ẹ gbé e wá sí iwájú mi ní àkókò tí a ti yàn, oúnjẹ ọrẹ ẹbọ mi tí a fi iná ṣe sí mi, gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn sí mi.’
3 Le ano ty hoe iereo: Zao ty hisoroñañe am’ Iehovà andro am-pohatse ho lilim-pisoroñañe: vik’ añondrilahy roe tsy aman-kandra.
Sọ fún wọn, ‘Èyí ní ọrẹ ẹbọ tí a fi iná sun tí ẹ gbọdọ̀ mú wá fún Olúwa: akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kan aláìlábàwọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹbọ sísun ní ojoojúmọ́.
4 Hengae’o maraindray ty vik’ añondry vaho hengae’o folakandro ty faharoe,
Pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn kan ní òwúrọ̀ àti òmíràn ní àfẹ̀mọ́júmọ́.
5 reketse mona fahafolo’ ty efà linaro mena-piniritse fahèfa’ ty hine ho enga-mahakama.
Pẹ̀lú ẹbọ ohun jíjẹ tí ó jẹ́ ìdámẹ́wàá efa ìyẹ̀fun dáradára tí a pò mọ́ ìdámẹ́rin hínì òróró tí a yọ lára Olifi.
6 Ie lilim-pisoroñañe norizañe ambohi-Sinay añe ho hàñin-kanintsiñe, fisoroñañe am’ Iehovà.
Èyí ni ẹbọ sísun gbogbo ìgbà tí a fi lélẹ̀ ní òkè Sinai gẹ́gẹ́ bí olóòórùn dídùn ẹbọ tí a fi iná sun fún Olúwa pẹ̀lú iná.
7 Le songa añengañe enga-rano fahèfa’ ty hine i añondry roe rey; ailiñe am’ Iehovà amy toe-miavakey i divay soay ho enga-rano.
Àfikún ọrẹ ohun mímu rẹ gbọdọ̀ jẹ́ ìdámẹ́rin ti hínì dídé omi mímu tí ó kan pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn. Da ẹbọ mímu náà síta sí Olúwa ní ibi mímọ́.
8 Engae’o ami’ ty folakandro i vik’ añondry ila’ey rekets’ i enga-maha­kama’ey naho i enga-rano’ey, hambañe amy nañengañe amy maraiñeiy ty hañenga’o aze: soroñe ho hàñin-kanintsiñe am’ Iehovà.
Pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn kejì ní àfẹ̀mọ́júmọ́, pẹ̀lú oríṣìí ẹbọ ohun jíjẹ àti ẹbọ ohun mímu èyí tí ó pèsè ní òwúrọ̀, èyí ni ẹbọ tí a fi iná ṣe, olóòórùn dídùn sí Olúwa.
9 Ie ami’ty andro Sabotse, le vik’ añondrilahy roe tsy aman-kandra, naho mona fahafolo’ ty efa roe ho enga-mahakama, linaro menake naho i enga-rano’ey:
“‘Ní ọjọ́ ìsinmi, pèsè akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méjì ọlọ́dún kan tí kò lábùkù, pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu àti ẹbọ ohun jíjẹ tí i ṣe ìdá méjì nínú ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí a fi òróró pò.
10 zay ty hisoroñañe boa-tSabata ambone’ i enga hisoroñañe boak’ àndroy rekets’ i enga-rano’ey.
Èyí ni ẹbọ sísun fún gbogbo ọjọ́ ìsinmi kọ̀ọ̀kan, ní àfikún pẹ̀lú ẹbọ sísun àti ẹbọ ohun mímu.
11 Mañengà soroñe am’ Iehovà amo jiri-bola’ areoo: bania roe, añon­drilahy raike, vik’ añondrilahy fito tsy aman-kandra;
“‘Àti ní ọjọ́ tí o bẹ̀rẹ̀ oṣù kọ̀ọ̀kan, kí ẹ̀yin kí ó gbé ẹbọ sísun fún Olúwa pẹ̀lú ọ̀dọ́ akọ màlúù méjì, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan, kí gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ aláìlábùkù.
12 naho songa mona fahafolo’ ty efà telo linaro menake ty bania; naho fahafolo’ ty efà roe linaro menake ho enga-mahakama, i añondri­lahiy;
Pẹ̀lú akọ màlúù kọ̀ọ̀kan ni kí wọn ó rú ẹbọ ohun jíjẹ ẹbọ ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá ìyẹ̀fun tí a pòpọ̀ pẹ̀lú òróró; pẹ̀lú àgbò, ni kí wọn ó rú ẹbọ ohun jíjẹ tí í ṣe ìdá méjì nínú mẹ́wàá òsùwọ̀n ìyẹ̀fun tí a pòpọ̀ mọ́ òróró;
13 le sindre mona fahafolo’ ty efà linaro menake ho enga-mahakama ty vik’ añondry, enga olorañe, hàñin-kanintsiñe, soroñañe am’ Iehovà.
pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn, ni kí ẹ rú ẹbọ ìyẹ̀fun ìyẹ̀fun kíkúnná tí a pò mọ́ òróró. Èyí ni ẹbọ sísun, òórùn dídùn, àti ẹbọ tí a ṣe fún Olúwa pẹ̀lú iná.
14 songa ho divay vaki’ ty hine ty bania, sindre fahatelo’ ty hine i añondrilahiy vaho fonga fah’efa’ ty hine ty vik’ añondry. Izay ty hisoroñañe an-jiri-bola’ ze hene volañe amo taoñeo.
Kí ẹbọ ohun mímu wọn jẹ́ ààbọ̀ òsùwọ̀n hínì ti ọtí wáìnì, fún akọ màlúù kan, àti ìdámẹ́wàá òsùwọ̀n hínì fún àgbò kan àti ìdámẹ́rin òsùwọ̀n hínì fún ọ̀dọ́-àgùntàn kan. Èyí ni ẹbọ sísun tí wọn ó máa rú ní oṣù kọ̀ọ̀kan nínú ọdún.
15 Le forototò ho engan-kakeo am’ Iehovà ty oselahy; ho tovo’ i soroñe boak’ andro rekets’ i enga-rano’eiy.
Yàtọ̀ sí ẹbọ sísun pẹ̀lú ẹbọ ohun mímu, ẹ gbọdọ̀ fi akọ ewúrẹ́ kọ̀ọ̀kan fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀.
16 Ami’ty andro faha-folo-efats’ambi’ i volam-baloha’ey ty Pèsa’ Iehovà.
“‘Ní ọjọ́ kẹrìnlá oṣù kìn-ín-ní ni ìrékọjá Olúwa gbọdọ̀ wáyé.
17 Le hanoeñe sabadidake amy andro faha folo-lime-ambi’ i volañeiy; ho kamaeñe fito andro ty mofo po-dalivay.
Ní ọjọ́ kẹ́ẹ̀dógún oṣù yìí ẹ gbọdọ̀ ṣiṣẹ́ àjọ̀dún fún ọjọ́ méje kí ó jẹ àkàrà tí kò ní ìwúkàrà.
18 Hanao fañohara-miavake nahareo amy andro valoha’ey; tsy itolonan-draha.
Ní ọjọ́ kìn-ín-ní kí àpéjọ mímọ́ kí ó wà; ẹ́yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ agbára kankan.
19 Le mibanabanà enga hisoroñañe am’ Iehovà: bania roe, ty añondrilahy, naho ty vik’ añondrilahy fito, asoao te tsy aman-kandra.
Ẹ rú ẹbọ sísun sí Olúwa, ẹ rú u pẹ̀lú ọ̀dọ́ màlúù méjì akọ, ẹbọ sísun pẹ̀lú iná àgbò kan àti ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kọ̀ọ̀kan kí wọn kí ó jẹ́ aláìlábùkù.
20 Mona linaro menake ty enga-maha­kama’ iareo, songa fahafolo’ ty efà telo ty bania, naho fahafolo’ ty efà roe i añondrilahiy;
Pẹ̀lú akọ màlúù kọ̀ọ̀kan ni kí ẹ pèsè ẹbọ ohun mímu pẹ̀lú ìdámẹ́ta nínú mẹ́wàá ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi òróró pò; pẹ̀lú àgbò, ìdá méjì nínú mẹ́wàá;
21 le sindre fahafolo’ ty efà ty vik’ añondry, ho a i vi’e fito rey;
pẹ̀lú ọ̀dọ́-àgùntàn kọ̀ọ̀kan ìdákan nínú mẹ́wàá.
22 vaho oselahy ty ho engan-kakeo hijebañañe anahareo.
Pẹ̀lú òbúkọ kan fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ láti ṣètùtù fún un yín.
23 Halankañe’ areo ho tovo’ i enga marain­draiñey, i enga boak’ androy.
Ṣe eléyìí ní àfikún sí ẹbọ sísun àràárọ̀.
24 Izay ty fañengañe boak’ andro, fito andro, ty mahakama’ i enga fisoroñañey, hàñin-kanintsiñe am’Iehovà, engaeñe ho tovo’ i enga boak’ àndroy naho i enga-rano’ey.
Báyìí ní kí ẹ̀yin rúbọ ní ọjọọjọ́, jálẹ̀ ní ọjọ́ méjèèje, oúnjẹ ẹbọ tí a fi iná ṣe, tí olóòórùn dídùn sí Olúwa; ó rú u pẹ̀lú ẹbọ sísun ìgbà gbogbo, àti ẹbọ ohun mímu.
25 le hanao fañohara-miavake nahareo ami’ty andro fahafito. Tsy itoloñan-draha.
Ní ọjọ́ keje kí ẹ̀yin kí ó ní àpéjọ mímọ́, ẹ kò sì gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.
26 Ie amy andron-dengom-boay, le mibanabanà enga-mahakama vao am’ Iehovà amy sabadida-kereñandro’ areoy, le ano fañohara-miavake vaho ko mitolon-draha.
“‘Ní ọjọ́ àkọ́so pẹ̀lú, nígbà tí ẹ̀yin bá mú ẹbọ ohun jíjẹ tuntun wá fún Olúwa lẹ́yìn àsìkò àjọ̀dún, kí ẹ̀yin kí ó ní àpéjọ mímọ́, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ṣe iṣẹ́ kankan.
27 Mibanabanà enga hisoroñañe ho hàñin-kanintsiñe am’ Iehovà: bania roe, ty añondri­lahy raike vaho ty vik’añondrilahy fito,
Kí ẹ mú ẹbọ sísun ẹgbọrọ màlúù méjì, àgbò kan àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn méje ọlọ́dún kan gẹ́gẹ́ bí òórùn dídùn fún Olúwa.
28 mitraok’ ami’ty mona linaro menake ho enga-mahakama’e: songa fahafolo’ ty efà telo ty bania, naho fahafolo’ ty efà roe i añondrilahiy
Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan akọ màlúù ní kí ẹ rú ẹbọ ohun mímu ìdámẹ́ta pẹ̀lú òsùwọ̀n ìyẹ̀fun kíkúnná tí a fi òróró pò pẹ̀lú àgbò kan.
29 sindre fahafolo’ ty efà ty vik’ añondry ho amy vi’e fito rey;
Àti pẹ̀lú ọ̀kọ̀ọ̀kan ọ̀dọ́-àgùntàn méje, kí ó jẹ́ ìdákan nínú mẹ́wàá.
30 vaho ty vik’ oselahy hijebañañe anahareo.
Ẹ fi òbúkọ kan ṣe ètùtù fún ara yín.
31 Hengae’ areo ho tovo’ i soroñañe nainai’ey rezay, naho o enga mahakama’e naho enga-rano’e. Asoao t’ie tsy ho aman-kandra.
Kí ẹ̀yin kí ó rú wọn pẹ̀lú ẹbọ sísun ìgbà gbogbo, àti ẹbọ ohun mímu yín àti ẹbọ ohun jíjẹ yín. Kí ẹ sì ri dájú pé àwọn ẹranko náà jẹ́ aláìlábùkù.

< Nomery 28 >