< Nomery 24 >

1 Aa kanao nioni’ i Balame te ninò’ Iehovà ty hitata Israele le tsy nisikilie’e nanahake i lili’ey fe nampitolihe’e mb’ am-patrambey eñe ty lahara’e.
Nísinsin yìí nígbà tí Balaamu rí i wí pé ó tẹ́ Olúwa lọ́rùn láti bùkún àwọn Israẹli, kò lo ọ̀nà ìṣoṣó gẹ́gẹ́ bí ti ìgbà ìṣáájú, ṣùgbọ́n ó yí ojú rẹ̀ sí apá aginjù.
2 Aa naho niandra t’i Balame le nioni’e t’Israele nimoneñe an-kiboho’e ey nilahatse amo fifokoa’eo; le nivotrak’ ama’e ty arofon’ Andrianañahare;
Nígbà tí Balaamu wo ìta ó sì rí Israẹli tí wọ́n pàgọ́ gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì bà sórí rẹ̀
3 vaho nonjone’e ami’ty hoe ty razan-drehake, Hoe ty fetse’ i Balame ana’ i Beore, naho ty lañona’ ondaty am-pihaino misokake.
ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀, “Àsọtẹ́lẹ̀ tí Balaamu ọmọ Beori, àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
4 Ty enta’ ondaty mahajanjiñe ty tsaran’Añahare, naho mahaisake ty aroñaro’ i El-Sadai, mibaboke fe am-pihaino mibolanake:
àsọtẹ́lẹ̀ ẹni tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, ẹni tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dojúbolẹ̀, tí ojú rẹ̀ là kedere.
5 Fanjaka o kiboho’oo ry Iakòbe naho o kivoho’oo ry Israele.
“Àgọ́ rẹ ti dára tó, ìwọ Jakọbu, àti ibùgbé rẹ, ìwọ Israẹli!
6 Mivelatse hoe vavatane, hoe kodobo añ’olon-tsaka, hoe vahoñe nambole’ Iehovà hoe mendoraveñe añ’olon-drano.
“Gẹ́gẹ́ bí àfonífojì tí ó tàn jáde, gẹ́gẹ́ bí ọgbà tí ó wà ní ẹ̀bá odò ńlá, gẹ́gẹ́ bí igi aloe tí Olúwa gbìn, gẹ́gẹ́ bí igi kedari tí ó wà lẹ́bàá odò.
7 Hidoandoan-drano o sihoa’eo naho ho an-drano maro o tabiri’eo. Mitoabotse ambone’ i Agage ty mpanjaka’e vaho onjoneñe i fifehea’ey.
Omi yóò sàn láti inú garawa: èso wọn yóò ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi. “Ọba wọn yóò ga ju Agagi lọ; ìjọba wọn yóò di gbígbéga.
8 Manahake ty tsifan-drimo mitiotiotse t’i Andrianañahare nampiavotse aze amy Mitsraime. Hampibotseke ze tane malaiñe aze hampipozapozake o taola’eo, hampitrofahe’e amo ana-pale’eo.
“Ọlọ́run mú wọn jáde láti Ejibiti wá; wọ́n ní agbára gẹ́gẹ́ bí i ti àgbáǹréré. Wọ́n jẹ orílẹ̀-èdè tí ń ṣe ọ̀tá rẹ̀ run, wọ́n sì fọ́ egungun wọn sí túútúú; wọ́n ó sì fi ọfà wọn ta wọ́n ní àtapòyọ.
9 Nitsakononòke re, nanao fandrean-diona naho hoe liona rene’e, ia ty hampitsekak’ aze? Hene soa tata ze mitat’azo Fonga ozoñeñe o mañozoñ’azoo.
Ó tẹríba ó sì dùbúlẹ̀ bí kìnnìún, bí abo kìnnìún: ta ni ó gbọdọ̀ jí wọn? “Ìbùkún ni fún ẹni tí ó bùkún fún ọ, kí ìfibú jẹ́ ti ẹni tí ó fi ọ́ bú!”
10 Nisolebotse amy Balame amy zao ty habose’ i Balake, le nifampitrabohe’e o fità’eo, naho hoe t’i Balak’ amy Bala­me, Nikanjiako haño­zoñe o rafelahikoo, vaho hehe te nitsitsihe’o tata in-telo.
Nígbà náà ni ìbínú Balaki sì dé sí Balaamu. Ó sì fi ọwọ́ lu ọwọ́ ó wí pé, “Mo pè ọ́ láti bú àwọn ọ̀tá mi ṣùgbọ́n o tún bùkún fún wọn nígbà mẹ́ta yìí.
11 Mibioña arè mb’ an-toe’o añe, ie ho nonjoneko andi­kerañe eñe ty asi’o; te mone kinala’ Iehovà i ho ni-enge’oy.
Nísinsin yìí sálọ sí ibùjókòó rẹ! Èmi ti rò láti sọ ọ́ di ẹni ńlá, ṣùgbọ́n Olúwa tí fà ọ́ sẹ́yìn láti gba èrè yìí.”
12 Le hoe t’i Balame amy Balake, Tsy vinolako hao o ìra’o nampihitrife’o amakoo ty hoe,
Balaamu dá Balaki lóhùn, “Ǹjẹ́ èmi kò sọ fún àwọn ìránṣẹ́ tí o rán sí mi wí pé,
13 Ndra te hatolo’ i Balak’ ahiko ty volafoty naho volamena mahaatseke i anjomba’ey, tsy ho likoareko ty falie’ Iehovà, hanoako ty soa ndra ty raty boak’ an-troko, fa ze nitsarae’ Iehovà ty ho taroñeko?
‘Kódà bí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò le ṣe ohunkóhun lọ́wọ́ ara mi, yálà búburú tàbí rere, láti kọjá òfin Olúwa: ohun tí Olúwa bá wí ni èmi ó sọ’?
14 Aa le himpoliako ondatikoo henaneo, fe adono hey hitoroako ty hanoe’ ondaty reroañe am’ondati’oo amo andro ampara’e añeo.
Nísinsin yìí mò ń padà lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí èmi kí ó kìlọ̀ fún ọ nítorí nǹkan tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí yóò ṣe sí àwọn ènìyàn rẹ ní ọjọ́ iwájú.”
15 Aa le nonjone’e ami’ty hoe i fandrazaña’ey: Ty lañona’ i Balame ana’ i Beore, ty taro’ ondaty am-pihaino nabeake.
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe: “Òwe Balaamu ọmọ Beori, òwe ẹni tí ojú rẹ̀ ríran kedere,
16 Ty kora’ i mpijanjiñe o tsaran’ Añahareoy, vaho ama’e ty fahafohinañe i Andindimoneñey, Oni’e ty aroñaro’ i El-Sadai mibaboke fe am-pihaino mibeake:
ẹni tó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ń wí, tí ó sì mọ ìmọ̀ Ọ̀gá-ògo, tí ó ríran láti ọ̀dọ̀ Olódùmarè, ẹni tí ó dọ̀bálẹ̀, tí ojú rẹ̀ sì ṣí:
17 Treako fa tsy henaneo; misamb’ aze iraho fe tsy mitotoke; hiboak’ am’ Iakòbe ty vasiañe; hionjoñe hirik’am’ Israele ty kobaiñe, ho demohe’e o olon-tane’ i Moabeo le fonga ho rotsahe’e o anam-pifandrakarakañeo.
“Mo rí i, ṣùgbọ́n kì í ṣe ìsinsin yìí. Mo kíyèsi, ṣùgbọ́n kò súnmọ́. Ìràwọ̀ kan yóò jáde láti ọ̀dọ̀ Jakọbu; yóò yọ jáde láti Israẹli. Yóò tẹ̀ fọ́ orí Moabu, yóò sì fọ́ agbárí gbogbo ọmọ Seti.
18 Ho fanañañe t’i Edome, ho hanaña’ o rafelahi’eo t’i Seire, le hitoloñ’ an-kafatrarañe t’Israele.
Wọn yóò borí Edomu; yóò ṣẹ́gun Seiri ọ̀tá rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli yóò dàgbà nínú agbára.
19 Hiboak’ am’ Iakòbe ty hifehe, handrotsake ty sehanga’ i Are.
Olórí yóò jáde láti Jakọbu yóò sì pa àwọn tó ṣẹ́kù nínú ìlú náà run.”
20 Ie nitalakese’e t’i Amaleke le nonjone’e ty fetse’e ami’ty hoe: Nilohà’ o kilakila taneo t’i Amaleke, Fe hamongorañe ty ho figadoña’e.
Nígbà náà ni Balaamu rí Amaleki ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Amaleki ni àkọ́kọ́ nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ṣùgbọ́n yóò dahoro níkẹyìn.”
21 Nisambae’e amy zao o nte-Keineo, vaho nañonjona’e fetse ami’ ty hoe: Fatratse o fimoneña’oo naho mioreñe an-damilamy eo ty akiba’o;
Nígbà náà ní ó rí ará Keni ó sì bẹ̀rẹ̀ òwe: “Ibùgbé rẹ ní ààbò, ìtẹ́ rẹ ni a tò sínú àpáta;
22 fe ho forototoeñe t’i Kàine; ampara’ mbia te ho tana’ i Asore an-drohy?
síbẹ̀ ẹ̀yin ará Keni ni yóò di píparun nígbà tí Asiria bá mú yín ní ìgbèkùn.”
23 Le nonjone’e ty fetse’e nanao ty hoe: Hedey! Ia ty ho veloñe naho akipen’ Añahare?
Nígbà náà ni ó bẹ̀rẹ̀ òwe rẹ̀: “Háà, ta ni ó lè yè nígbà tí Ọlọ́run bá ṣe èyí?
24 Hitotsak’ eo o lakambey hirik’ añ’olo’ i Ketio, ho silofe’ iareo t’i Asore naho hampiambane’e t’i Aibere, ampara’ t’ie mongotse nainai’e.
Ọkọ̀ yóò wá láti ibùdókọ̀ Kittimu; wọn yóò ṣẹ́gun Asiria àti Eberi, ṣùgbọ́n àwọn náà yóò di píparun.”
25 Aa le niongake t’i Balame, nienga, naho nimpoly mb’an-toe’e añe; vaho nimb’ amy lia’e mb’eo ka t’i Balake.
Nígbà náà ni Balaamu dìde ó sì padà sí ilé rẹ̀, Balaki sì lọ ní ọ̀nà tirẹ̀.

< Nomery 24 >