< Lioka 10 >

1 Ie modo izay, le nijoboñe ondaty fitompolo ila’e ka t’i Talè, vaho nirahe’e kiroe-kiroe hiaolo mb’amy ze hene rova naho tane homba’e.
Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Olúwa sì yan méjìléláàádọ́rin ọmọ-ẹ̀yìn mìíràn pẹ̀lú, ó sì rán wọn ní méjì méjì lọ ṣáájú rẹ̀, sí gbogbo ìlú àti ibi tí òun tìkára rẹ̀ yóò sì dé.
2 Le hoe re tam’ iereo: Tombo ty vokatse fe tsy ampe ty mpandrofotse; aa le halalio i Talèm-bokatsey ty hañeke ho amy fanatahañey;
Ó sì wí fún wọn pé, “Ìkórè pọ̀, ṣùgbọ́n àwọn alágbàṣe kò tó nǹkan, nítorí náà ẹ bẹ Olúwa ìkórè, kí ó lè rán àwọn alágbàṣe sínú ìkórè rẹ̀.
3 Akia, iraheko hoe vik’añondry mitoam-parasy.
Ẹ mú ọ̀nà yín pọ̀n: sá wò ó, èmi rán yín lọ bí ọ̀dọ́-àgùntàn sáàrín ìkookò.
4 Ko mitintin-koro ndra kontrañe ndra hana vaho ko mifañinoñe an-dalañe eo.
Ẹ má ṣe mú àpò, ẹ má ṣe mú àpamọ́wọ́, tàbí bàtà: ẹ má sì ṣe kí ẹnikẹ́ni lọ́nà.
5 Ze traño iziliha’ areo, anò hey ty hoe: Hanitsiñe ty anjomba toy.
“Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá wọ̀, kí ẹ kọ́ wí pé, ‘Àlàáfíà fún ilé yìí!’
6 Aa naho ao ty anan-kanintsiñe, le hitoetse ao i fañanintsi’ areoy; fe naho tsy izay le himpolia’e.
Bí ọmọ àlàáfíà bá sì wà níbẹ̀, àlàáfíà yín yóò bà lé e: ṣùgbọ́n bí kò bá sí, yóò tún padà sọ́dọ̀ yín.
7 Mañialoa amy trañoy; mikama naho minoma amy ze azotso amy te mañeva ty rima’e ty mpanatake. Ko mitsatsàk’ anjomba.
Ẹ dúró sínú ilé náà, kí ẹ máa jẹ, kí ẹ sì máa mu ohunkóhun tí wọ́n bá fi fún yín, nítorí ọ̀yà alágbàṣe tọ́ sí i. Ẹ má ṣe lọ láti ilé dé ilé.
8 Ze tanañe omba’ areo, naho ampiho­vae’e: ikamao ze azotso’e.
“Ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá wọ̀, tí wọ́n bá sì gbà yín, ẹ jẹ ohunkóhun tí a bá gbé ka iwájú yín.
9 Jangaño ze marare, le anò ty hoe: Fa totok’ anahareo i Fifehean’ Añaharey.
Ẹ sì mú àwọn aláìsàn tí ń bẹ nínú rẹ̀ láradá, kí ẹ sì wí fún wọn pé, ‘Ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀ sí yín!’
10 Ze rova anjoà’ areo tsy mampihova, le miheovà mb’an-dàmoke mb’ eo vaho anò ty hoe:
Ṣùgbọ́n ní ìlúkílùú tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, tí wọn kò bá sì gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá sì jáde ní ìgboro ìlú náà, kí ẹ̀yin sì wí pé,
11 Ndra ty lembo’ ty rova’ areo manditek’ ama’ay ho piohe’ay hanjehazeha anahareo. Fe mahafohina te nitotoha’ i Fifehean’ Añaharey.
‘Eruku ìlú yín tí ó kù sí wa lẹ́sẹ̀, a gbọ̀n ọ́n sílẹ̀ fún yín! Ṣùgbọ́n ẹ mọ èyí pé, ìjọba Ọlọ́run kù sí dẹ̀dẹ̀.’
12 Itaroñako te haivañe ty hifetsak’ amy Sodoma amy andro zay ta ty hizò i rovay.
Ṣùgbọ́n mo wí fún yín, yóò sàn fún Sodomu ní ọjọ́ náà, ju fún ìlú náà lọ.
13 Hankàñe ama’o, Korazina! Hankàñe ama’o Betsaida! Fa naho nanoeñe e Tirò naho e Sidona añe o raha jabajaba nitoloñeñe ama’areoo le ho nisoloho haehae vaho ho nitobok’ an-gony naho lavenoke.
“Ègbé ni fún ìwọ, Korasini! Ègbé ni fún ìwọ Betisaida! Nítorí ìbá ṣe pé a ti ṣe iṣẹ́ agbára tí a ṣe nínú yín, ní Tire àti Sidoni, wọn ìbá ti ronúpìwàdà lọ́jọ́ pípẹ́ sẹ́yìn, wọn ìbá sì jókòó nínú aṣọ ọ̀fọ̀ àti nínú eérú.
14 Haivañe ho amy Tirò naho i Sidona amy zakay ta ty ama’ areo.
Ṣùgbọ́n yóò sàn fún Tire àti Sidoni nígbà ìdájọ́ jù fún yín lọ.
15 Ihe ka, ry Kapernaomy, haonjomb’ andindìñe añe v’ iheo? Te mone hatotse an-tsikeokeok’ao! (Hadēs g86)
Àti ìwọ, Kapernaumu, a ó ha gbé ọ ga dé òkè ọ̀run? A ó rẹ̀ ọ́ sílẹ̀ dé isà òkú. (Hadēs g86)
16 Ze mijanjiñe anahareo mijanjiñe ahy, naho ze malaiñ’ anahareo malaiñ’ ahy, vaho ze malaiñ’ ahy, malaiñe i Nañirak’ ahiy.
“Ẹni tí ó bá gbọ́ tiyín, ó gbọ́ tèmi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ yín, ó kọ̀ mi. Ẹni tí ó bá sì kọ̀ mi, ó kọ ẹni tí ó rán mi.”
17 Nimpoly an-kaehake i fitom-polo rey, le hoe ty asa’iareo: O Rañandria, ndra o kokolampao miambane ama’ay ty amy tahina’oy.
Àwọn àádọ́rin náà sì fi ayọ̀ padà, wí pé, “Olúwa, àwọn ẹ̀mí èṣù tilẹ̀ foríbalẹ̀ fún wa ní orúkọ rẹ.”
18 Le hoe t’Iesoà tam’ iereo: Nitreako nidoindoiñe boak’ andin­dìñey hoe helatse i mpañìnjey.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èmí rí Satani ṣubú bí mọ̀nàmọ́ná láti ọ̀run wá.
19 Inao! fa tinoloko lily ambone’ ty haozara’ i rafelahiy nahareo handialia mereñe naho kalengo fa ndra inoñ’ inoñe tsy hijoy.
Kíyèsi i, èmí fún yín ní àṣẹ láti tẹ ejò àti àkéekèe mọ́lẹ̀, àti lórí gbogbo agbára ọ̀tá, kò sì ṣí ohun kan bí ó ti wù tí ó ṣe, tí yóò pa yín lára.
20 Aa ko irebeha’ areo te itsolofìña’ o koko­lampao, fe mandià-taroba te pinatetse andindìñe ao o tahina’ areoo.
Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe yọ̀ nítorí èyí pé, àwọn ẹ̀mí ń foríbalẹ̀ fún yín; ṣùgbọ́n ẹ kúkú yọ̀, pé; a kọ̀wé orúkọ yín ní ọ̀run!”
21 Ie amy ora izay, nilifon-kaehak’ añ’ arofo t’Iesoà nanao ty hoe: Mandrenge Azo iraho ry Aba, Talèn-dikerañe naho ty tane toy, te naeta’o amo mahihitseo naho amo mahilalao o raha zao vaho nampalangese’o amo anak-ajajao; Eka, Aba, zay ty ninò’o am-pivazohoa’o.
Ní wákàtí kan náà Jesu yọ̀ nínú Ẹ̀mí mímọ́ ó sì wí pé, “Mo dúpẹ́ lọ́wọ́ rẹ, Baba, Olúwa ọ̀run àti ayé, pé, ìwọ pa nǹkan wọ̀nyí mọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n àti amòye, ìwọ sì fi wọ́n hàn fún àwọn ọmọ ọwọ́. Bẹ́ẹ̀ ni, Baba, bẹ́ẹ̀ ni ó sá à yẹ ní ojú rẹ.
22 Kila natolon-dRaeko ahy, le tsy eo ty mahafohiñe te ia i Anakey naho tsy t’i Rae, naho te ia t’i Rae lehe tsy i Anakey vaho ze ampahafohiñe’ i Anakey.
“Ohun gbogbo ni a ti fi fún mi láti ọ̀dọ̀ Baba mi; kò sì ṣí ẹni tí ó mọ ẹni tí ọmọ jẹ́, bí kò ṣe Baba, àti ẹnikẹ́ni tí ó bá sì wu ọmọ láti fi í hàn fún.”
23 Nitolik’amo mpiama’eo avao le nanao ty hoe: Haha ty fihaino mahaisake o raha isa’ areoo;
Ó sì yípadà sí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ní apá kan. Ó ní, “Ìbùkún ni fún ojú tí ń rí ohun tí ẹ̀yin ń rí.
24 Itaroñako te maro ty mpitoky naho ty mpanjaka nisalala hahaoniñe o oni’ areoo fe tsy nahaoniñe, vaho hahajanjiñe o janji’ areoo fe tsy nahajanjiñe.
Nítorí mo wí fún yín, ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì àti àwọn ọba ni ó ń fẹ́ láti rí ohun tí ẹ̀yin ń rí, wọn kò sì rí wọn, àti láti gbọ́ ohun tí ẹ̀yin ń gbọ́, wọn kò sì gbọ́ wọn.”
25 Teo te niongake ty mpahay lily ni­tsoke Iesoà ami’ty hoe: O Talè, ino ty hanoeko handovàko haveloñe nainai’e? (aiōnios g166)
Sì kíyèsi i amòfin kan dìde, ó ń dán an wò, ó ní, “Olùkọ́, kín ni èmi ó ṣe kí èmi lè jogún ìyè àìnípẹ̀kun?” (aiōnios g166)
26 Le hoe re tama’e, Ino ty pinatetse amy Hake ao? Akore ty vaki’o aze?
Ó sì bi í pé, “Kí ni a kọ sínú ìwé òfin? Báwo ni ìwọ sì ti kà á?”
27 Hoe ty natoi’e: Kokò t’Iehovà Andrianañahare’o an-kaampon’arofo’o, naho an-kaliforam-pañova’o naho amy ze hene haozara’o naho am-pitsa­korea’o iaby, vaho ondatio mira ami’ty vata’o.
Ó sì dáhùn wí pé, “‘Kí ìwọ fi gbogbo àyà rẹ, àti gbogbo ọkàn rẹ, àti gbogbo agbára rẹ, àti gbogbo inú rẹ fẹ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ’; àti, ‘Ẹnìkejì rẹ bí ara rẹ.’”
28 Le hoe re tama’e: To i natoi’oy, anò, vaho ho veloñe.
Ó sì wí fún un pé, “Ìwọ́ dáhùn rere. Ṣe èyí, ìwọ ó sì yè.”
29 Aa ie te haniom-batañe, nanao ty hoe am’ Iesoà: Ia v’indaty zay?
Ṣùgbọ́n ó ń fẹ́ láti da ara rẹ̀ láre, ó wí fún Jesu wí pé, “Ta ha sì ni ẹnìkejì mi?”
30 Hoe ty natoi’ Iesoà: Teo t’indaty nizotso boake Ierosaleme homb’e Hie­rikò mb’eo nizò malaso nañolits’ o siki’eo, nitrabotrabok’ aze vaho nampidoñ’ aze fiai-drifi’e;
Jesu sì dáhùn ó wí pé, “Ọkùnrin kan ń ti Jerusalẹmu sọ̀kalẹ̀ lọ sí Jeriko, ó sì bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà; wọ́n gbà á ní aṣọ, wọ́n sá a lọ́gbẹ́, wọ́n sì fi sílẹ̀ lọ ní àìpatán.
31 tojo te nizotso mb’eo amy zao ty mpisoroñe; nizoe’e fe niriràña’e.
Ní kòńgẹ́ àkókò yìí ni àlùfáà kan sì ń sọ̀kalẹ̀ lọ lọ́nà náà. Nígbà tí ó sì rí i ó kọjá lọ níhà kejì.
32 Nanao izay ka t’i nte-Levy, ie pok’eo, nahaisake fe nanoe’e riom-paoke.
Bẹ́ẹ̀ náà sì ni ọmọ Lefi kan pẹ̀lú, nígbà tí ó dé ibẹ̀, tí ó sì rí i, ó kọjá lọ níhà kejì.
33 Nivotrak’ eo ka ty nte Samaria amy lia’ey, ie niisa’e le niferenaiña’e,
Ṣùgbọ́n ará Samaria kan, bí ó ti ń re àjò, ó dé ibi tí ó gbé wà; nígbà tí ó sì rí i, àánú ṣe é.
34 nitotok’ aze naho namoloñosa” e o fere’eo naho nañiliña’e solike vaho divay; le nampiningire’e amy borìke’ey, naho ninday aze mb’ami’ty anjom­ba fanjoàn’ambahiny mb’eo vaho natrahe’e.
Ó sì tọ̀ ọ́ lọ, ó sì di ọgbẹ́ rẹ̀, ó da òróró àti ọtí wáìnì sí i, ó sì gbé e lé orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti òun tìkára rẹ̀, ó sì mú un wá sí ilé èrò, a sì ń ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
35 Ie maraindray, nañakatse bogady roe, le natolo’e amy tompon’ anjombay ami’ty hoe: Itahao; ndra firefire ty lany mandikoatse zao le havahako ami’ty fimpoliko.
Nígbà tí ó sì lọ ní ọjọ́ kejì, ó fi owó idẹ méjì fún olórí ilé èrò ó sì wí fún un pé, ‘Máa tọ́jú rẹ̀; ohunkóhun tí ìwọ bá sì ná kún un, nígbà tí mo bá padà dé, èmi ó san án fún ọ.’
36 Aa vaho ia amy telo rey ty atao’o nifampilongo amy nizo mpitavañey?
“Nínú àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí, ta ni ìwọ rò pé ó jẹ́ ẹnìkejì ẹni tí ó bọ́ sí ọwọ́ àwọn ọlọ́ṣà?”
37 Hoe ty natoi’e: I nilem-po ama’ey. Le hoe t’Iesoà tama’e: Akia, itsikombeo.
Ó sì dáhùn wí pé, “Ẹni tí ó ṣàánú fún un ni.” Jesu sì wí fún un pé, “Lọ, kí o ṣe bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́!”
38 Nañavelo iereo, le nizilik’ an-tanañe ao t’Iesoà naho nampihova aze añ’anjomba ty rakemba atao Martae,
Ó sì ṣe, bí wọ́n ti ń lọ, o wọ ìletò kan, obìnrin kan tí a ń pè ní Marta sì gbà á sí ilé rẹ̀.
39 niambesatse am-pandia’ i Talè nitsendreñe o tsara’eo ty rahavave’e Marie.
Ó sì ní arábìnrin kan tí a ń pè ní Maria tí ó sì jókòó lẹ́bàá ẹsẹ̀ Olúwa, tí ó ń gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀.
40 Fe niembetse’amy fitoroña’ey t’i Martae le niheo mb’amy Talè mb’eo nanao ty hoe: O Rañandria, tsy ahoa’o hao te nieng’ ahy hikotepe irery ty rahavaveko? Ampañoloro ahy.
Ṣùgbọ́n Marta ń ṣe ìyọnu ohun púpọ̀, ó sì tọ̀ ọ́ wá, ó wí pé, “Olúwa, ìwọ kò sì bìkítà sí ti arábìnrin mi pé ó fi mí sílẹ̀ láti máa nìkan ṣe ìránṣẹ́? Wí fún un kí ó ràn mí lọ́wọ́.”
41 Hoe ty natoi’ Iesoà: O Martae, Martae, ihe tsotseke naho tsimboetse ami’ty raha maro,
Ṣùgbọ́n Olúwa sì dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Marta, Marta, ìwọ ń ṣe àníyàn àti làálàá nítorí ohun púpọ̀.
42 raha raike ty paiaeñe; nijoboñe ty soa t’i Marie, le tsy hasintak’ ama’e izay.
Ṣùgbọ́n ohun kan ni a kò lè ṣe aláìní, Maria sì ti yan ipa rere náà tí a kò lè gbà lọ́wọ́ rẹ̀.”

< Lioka 10 >