< Levitikosy 8 >
1 Hoe ty nitsara’ Iehovà amy Mosè:
Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Rambeso t’i Aharone naho o ana’e ama’eo, o saro’eo, i mena-pañorizañey, i banian-engan-kakeoy, i añondrilahy roe rey vaho i hàroñe ama’ mofo po-dalivaiy,
“Mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀, aṣọ wọn, òróró ìtasórí, akọ màlúù fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀, àgbò méjì àti apẹ̀rẹ̀ tí a kó àkàrà aláìwú sínú rẹ̀.
3 le atontoño an-dalam-bein-kibohom-pamantañañe eo i fivoribeiy.
Kí o sì kó gbogbo ìjọ ènìyàn jọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé.”
4 Aa le nanoe’ i Mosè i nandilia’ Iehovày, naho nifanontoñe an-dalan-kibohom-pamantañañe eo i fivori-beiy;
Mose sì ṣe bí Olúwa ti pa á láṣẹ fún un, gbogbo ènìyàn sì péjọ sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ.
5 le hoe t’i Mosè amy fivori-beiy, Inao ty nandilia’ Iehovà hanoeñe.
Mose sì sọ fún ìjọ ènìyàn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa ti pàṣẹ pé kí á ṣe.”
6 Nendese’ i Mosè mb’eo t’i Aharone naho o ana’eo vaho nampandroa’e an-drano.
Nígbà náà ni Mose mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá síwájú, ó sì fi omi wẹ̀ wọ́n.
7 Naombe’e ama’e i sikiñey, naho nidiaña’e i sadiay, nanikina’e i saroñey, naombe’e i kitambey, le nadia’e i fièn-kitambe soa-vahotsey vaho nifeheza’e.
Ó sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ Aaroni, ó fi àmùrè dì í, ó wọ̀ ọ́ ní efodu; aṣọ ìgúnwà, ó sì tún wọ̀ ọ́ ni aṣọ ìlekè oyè àlùfáà tí ó ní ìgbànú tí a ṣe ọnà dáradára sí.
8 Le napeta’e ama’e i takon’ arañañey vaho nazili’e amy takon’ arañañey ty Orimae naho i Tomimae;
Ó fi ìgbàyà sí àyà rẹ̀, ó sì fi Urimu àti Tumimu sí ibi ìgbàyà náà.
9 naho nasabaka’e añ’ ambone’e i sabakay vaho napeta’e amy sabakay, aolo’e eo, i bogady volamenay; i ravan-daharañe miavake linili’ Iehovà i Mosèy.
Ó dé e ní fìlà, ó sì fi àwo wúrà tí í ṣe adé mímọ́ síwájú rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
10 Rinambe’ i Mosè amy zao i mena-pañorizañey le noriza’e i kivohoy naho ze he’e ama’e ao vaho nefera’e.
Mose sì fi òróró ìtasórí ya àgọ́ àti ohun gbogbo tó wà nínú rẹ̀ sí mímọ́.
11 Nafitse’e amy kitreliy im-pito ty ila’e, le noriza’e i kitreliy naho ze hene harao’e vaho i fanasàñey rekets’ i foto’ey, hañefera’e.
Ó wọ́n díẹ̀ nínú òróró yìí sórí pẹpẹ lẹ́ẹ̀méje, ó ta òróró sórí pẹpẹ àti gbogbo ohun èlò àti agbada pẹ̀lú ohun tó gbé agbada yìí dúró láti lè yà á sí mímọ́,
12 Nañiliña’e menake ty añambone’ i Aharone le noriza’e hampiavahañ’ aze.
ó da díẹ̀ lára òróró ìtasórí yìí sórí Aaroni, ó sì yà á sí mímọ́.
13 Nendese’ i Mosè mb’eo ka o ana’ i Aharoneo vaho naombe’e o sikiñeo le nadia’e sadia, le nifehe’e o sabaka’ iareoo amy nandilia’ Iehovà i Mosèy.
Lẹ́yìn èyí ló mú àwọn ọmọ Aaroni wá síwájú, ó sì fi ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n, ó fi àmùrè dìwọ́n lára, ó fi fìlà dé wọn lórí gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
14 Nitantalie’e mb’eo i banian-engan-kakeoy, le nanampeza’ i Aharone naho o ana’eo fitàñe ty loha’ i banian-engan-kakeoy,
Ó sì mú akọ màlúù wá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbọ́wọ́ lé orí ẹran náà.
15 ie linenta, le nandrambesa’ i Mosè i lioy naho natente’e amy tsifa’ i kitreliy rey añ’ariary aze an-drambom-pità’e vaho nefera’e i kitreliy; nadoa’e am-poto’ i kitreliy i lioy, le nefera’e, hanoe’e fijebańañe.
Mose pa akọ màlúù náà, ó sì ti ìka bọ inú ẹ̀jẹ̀ náà, ó fi sí orí gbogbo ìwo pẹpẹ láti wẹ pẹpẹ náà mọ́. Ó da ìyókù ẹ̀jẹ̀ náà sí ìsàlẹ̀ pẹpẹ. Bẹ́ẹ̀ ní ó ṣe yà á sí mímọ́ láti ṣe ètùtù fún un.
16 Le fonga rinambe’e ty safotsena amo ova’eo, i kambinatey, ty voa roe reke-tsafo’e naho nengae’ i Mosè an-katoeñe amy kitreliy,
Mose tún mú gbogbo ọ̀rá tí ó bo nǹkan inú, èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀, kíndìnrín méjèèjì àti ọ̀rá wọn, ó sì sun gbogbo rẹ̀ lórí pẹpẹ.
17 naho noroa’e alafe’ i tobey i baniay, ty holi’e, ty nofo’e, vaho ty tai’e; ami’ty nandilia’ Iehovà i Mosè.
Ṣùgbọ́n akọ màlúù yìí pẹ̀lú awọ àti ara ẹran àti ìgbẹ́ rẹ̀ ní ó sun lẹ́yìn ibùdó gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti paláṣẹ fún Mose.
18 Nampitotoheñe amy zao i añondrilahy hisoroñañey vaho nanampeza’ i Aharone naho o ana’eo fitàñe ty loha’ i añondrilahiy,
Lẹ́yìn náà ló mú àgbò wá fún ẹbọ sísun Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbọ́wọ́ lé orí àgbò náà.
19 le linenta, naho nafetsa’ i Mosè amy kitreliy añ’ariariy aze i lioy;
Mose sì pa àgbò náà, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.
20 le nifatepatere’e i añondrilahiy, naho nengae’ i Mosè an-katoeñe ty loha’e, naho o fatets’enao, vaho o safo’eo.
Ó gé àgbò náà sí wẹ́wẹ́, Mose sì sun orí àti àwọn ègé àti ọ̀rá rẹ̀.
21 Le nisasae’e aman-drano o ova’eo naho o tombo’eo, vaho nengae’ i Mosè an-katoeñe ambone’ i kitreliy i añondrilahy iabiy, fa soroñe, hàñim-pañanintsiñe, nisoroñañe am’ Iehovà, amy nandilia’ Iehovà i Mosèy.
Ó fi omi fọ gbogbo nǹkan inú àti ẹsẹ̀ rẹ̀, ó sì sun odidi àgbò náà lórí pẹpẹ bí ẹbọ sísun òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná ṣe sí Olúwa gẹ́gẹ́ bí Olúwa tí pàṣẹ fún Mose.
22 Nasese’e ka i añondrilahy faharoey, i añondrilahim-panokanañey, le nampitongoà’ i Aharone naho o ana’eo fitàñe ty loha’ i añondrilahiy.
Ó sì mú àgbò kejì wa, èyí ni àgbò ìfinijoyè àlùfáà, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì gbọ́wọ́ lé e lórí.
23 Le linenta naho nandrambesa’ i Mosè ty lio’e naho natente’e an-dengon-dravembia’ havana’ i Aharone naho an-tondrobeim-pità’e havana vaho an-tondrobeim-pandia’e havana.
Mose sì pa àgbò náà, ó sì mú díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀, ó tọ́ ọ sí etí ọ̀tún Aaroni, sórí àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún àti ti ẹsẹ̀ ọ̀tún rẹ̀.
24 Nampomba’e mb’eo o ana’ i Aharoneo le natente’ i Mosè an-dengon-dravembia-havana’ iareo ty ila’ i lioy, naho ami’ty tondrobeim-pitàn-kavana’ iareo, naho an-tondrobeim-pandia havana’ iareo; vaho nafetsa’ i Mosè añariariy i kitreliy i lioy.
Mose sì tún mú àwọn ọmọ Aaroni wá síwájú, ó sì mú ẹ̀jẹ̀ díẹ̀ ó fi sí etí ọ̀tún wọn, àtàǹpàkò ọwọ́ ọ̀tún wọn, ó sì wọ́n ẹ̀jẹ̀ yí pẹpẹ náà ká.
25 Le rinambe’e i safotsenay naho i hofake vondrakey, naho ze safotsena amo ovao naho i kambinatey naho i voa roe rey reke-tsafo’e vaho ty tso’e havana.
Ó mú ọ̀rá ẹran náà, ìrù rẹ̀ tí ó lọ́ràá, gbogbo ọ̀rá tó wà lára nǹkan inú àti èyí tí ó bo ẹ̀dọ̀, kíndìnrín méjèèjì àti ọ̀rá wọn pẹ̀lú itan ọ̀tún.
26 Le nandrambe mofo po-dalivay raik’ amy haroñe po-dalivay aolo’ Iehovày, rinambe’e ty mofo nañiliñañe menake naho ty mofo pisake, vaho napo’e amy safo’ey naho amy tso’e havanay.
Lẹ́yìn náà ló mú àkàrà aláìwú sí, èyí tó wà níwájú Olúwa àti àkàrà tí a fi òróró ṣe, àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́, ó sì kó gbogbo rẹ̀ sórí ọ̀rá àti itan ọ̀tún ẹran náà.
27 Napo’e am-pità’ i Aharone naho am-pità’ o ana’eo i he’e rezay, vaho nahelahela ho engan-kelahela am’ Iehovà.
Ó kó gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí lé Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́, wọ́n sì fì wọ́n gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì níwájú Olúwa.
28 Le rinambe’ i Mosè am-pità’ iareo irezay vaho nengae’e an-katoeñe amy kitreliy mitraok’ amy soroñey, ho sorom-panokanañe mañonjoñe hàñim-pañanintsiñe, nengaeñe añ’afo am’ Iehovà.
Lẹ́yìn náà, Mose gba gbogbo rẹ̀ lọ́wọ́ wọn, ó sì sun wọn lórí ẹbọ sísun tó wà lórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ìfinijoyè àlùfáà òórùn dídùn, ẹbọ tí a fi iná sun sí Olúwa.
29 Le rinambe’ i Mosè i tratra’ey vaho nahelahela’e ho engan-kelahela am’ Iehovà. Anjara’ i Mosè amy añondrilahi-panokanañey izay ami’ty nandilia’ Iehovà i Mosè.
Mose sì mú igẹ̀ ẹran náà, èyí tó jẹ́ ìpín rẹ̀ nínú àgbò fún ìfinijoyè, ó sì fì í níwájú Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ fífì, bi Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
30 Nandrambesa’ i Mosè i mena-pañorizañey naho ty lio amy kitreliy le nafitse’e amy Aharone naho amo saro’eo naho amo ana’eo naho amo saro’ iareoo. Le noriza’e t’i Aharone rekets’ o saro’eo naho o ana’eo rekets’ o saro’ iareoo.
Mose sì mú díẹ̀ lára òróró ìtasórí àti díẹ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ láti orí pẹpẹ, ó wọ́n sára àwọn ọmọ Aaroni àti aṣọ rẹ̀, ó sì tún wọ́n sára àwọn ọmọ Aaroni àti aṣọ wọn. Bẹ́ẹ̀ ní Mose ya Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú aṣọ wọn sí mímọ́.
31 Le hoe t’i Mosè amy Aharone naho amo ana’eo, Ahandrò an-dalan-kibohom-pamantañañe eo i henay vaho ikamao ey naho ty mofo amy harom-pañengam-panokanañey, ami’ty nandiliako ty hoe, Ho kamae’ i Aharone naho o ana’eo;
Mose sì sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ se ẹran náà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé kí ẹ sì jẹ ẹ́ níbẹ̀ pẹ̀lú àkàrà tí a mú láti inú apẹ̀rẹ̀ ọrẹ ìfinijoyè àlùfáà gẹ́gẹ́ bí mo ti pa á láṣẹ pé, ‘Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ni kí ó jẹ ẹ́.’
32 le ho forototoe’ areo an’ afo ao ze tsi-ri’ i henay naho i mofoy.
Kí ẹ fi iná sun ìyókù àkàrà àti ẹran náà.
33 Le tsy hiakatse i lalan-kibohom-pamantañañey nahareo naho tsy modo ty fito andro, am-para’ te heneke o androm-pañorizañe anahareoo. Fito andro ty añoriza’e anahareo.
Ẹ má ṣe kúrò ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé fún ọjọ́ méje, títí tí ọjọ́ ìfinijoyè àlùfáà yín yóò fi pé, nítorí pé ìfinijoyè àlùfáà yín yóò gba ọjọ́ méje gbáko.
34 I nanoeñe anindroaniy, ty nandilia’ Iehovà hanoeñe; hijebañañe anahareo.
Ohun tí a ṣe lónìí jẹ́ ohun tí Olúwa ti pàṣẹ láti ṣe ètùtù fún yín.
35 Aa le hidoñe an-dalan-kitrelin-kibohom-pamantañañe eo handro an-kaleñe fito andro nahareo, hitañe ty namantoha’ Iehovà, tsy hivetrake; fa izay ty nandiliañe ahy.
Ẹ gbọdọ̀ wà ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé lọ́sàn án àti lóru fún ọjọ́ méje kí ẹ sì ṣe ohun tí Olúwa fẹ́, kí ẹ má ba à kú, nítorí ohun tí Olúwa pàṣẹ fún mi ni èyí.”
36 Le nanoe’ i Aharone naho o ana’eo ze hene nandilia’ Iehovà am-pità’ i Mosèo.
Báyìí ni Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ ṣe ohun gbogbo tí Olúwa pàṣẹ láti ẹnu Mose.