< Josoa 15 >
1 Ty anjara’ i fifokoan’ ana’ Iehoda ty amo hasavereña’eo an-tsapake le pak’ an-tane’ i Edome naho ty fatrambei’ i Tsine mb’ amy Negeve mb’eo ho efe’e atimo.
Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
2 Ty efe-tane’ iareo atimo, le boak’ añ’ olo’ i Riake Siray hirik’ amy fitolian-dakañe mitolike mañatimoy;
Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
3 le mb’e Negeve mb’eo pak’amy fitroara’ i Akrabime sikal’ amy Tsine naho mionjomb’ ami’ty ila atimo’ i Kadese-barnea an-kalo’ i Ketsrone naho mionjoñe mb’e Adare vaho mitolike mb’e Karkà mb’eo,
ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
4 ie boak’ ao le miary mb’e Atsmone vaho miakatse mb’ amy oñe’ i Mitsraimey, le mitakatse i riak’ ahandrefañey i efe’ey. Izay ty efe’o atimo.
Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
5 I Riake Siray ty efe’e atiñanañe pak’ am’ Iardeney. Le ty efe’e avaratse boak’ am-pitolian-daka’ i riakey, am-binàñe’ Iardeney,
Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
6 le mitohy mb’e Betehoglà naho miary avara’ i Bete’ arabà; ie boak’ ao mionjomb’ am-bato’ i Bohane, ana’ i Reobene mb’eo i efetsey.
ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
7 Mibalike mb’e Debire boak’ am-bavatane’ i Akore i efetsey le mañavaratse, mitolike mb’e Gilgale, aolo’ ty fitroara’ i Adomime, atimo i sakay; miary amo rano’ i Ensemeseo i efetsey vaho miakatse amy rano migoangoa’ i Rogeley,
Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
8 le mionjomb’ amy vavatanen’ ana’ i Hinome añ’ ila’ i nte-Iebosiý mañatimo; izay t’Ierosalaime, naho manganike mb’ an-dengom-bohitse aolo’ i vavatane’ i Hinomey mañandrefa ami’ty figadoña’ i vavatanen-dRafày, mañavaratse;
Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
9 miary ambone’ i vohitsey i efetsey pak’ amy rano migoangoa’ i Neftoà naho miakatse mb’ amo rova’ am-bohi’ i Efroneo mb’eo; le miary Efrone i efetsey pake Baalà; ie i Kiriat-iearime.
Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
10 Ie amy zay miolake boake Baalà mañandrefa pak’ am-bohi-Seire naho miary mb’ añila’ avara’ i vohi’ Iearimey mb’eo—i Kesalone zay, le mizotso mb’e Bete-Semese mb’eo vaho miary mb’e Timnà mb’eo.
Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
11 Le miary añ’ ila’ i Ekrone mañavaratse i efetsey; le miary mb’e Sikrone mb’eo ty efe’e naho mb’ amy Baalà naho miakatse mb’e Iabnile; vaho miakatse mb’ an-driak’ añe i efe’ey.
Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
12 Ty efe’e ahandrefa, le i olon-driake jabajabay. Ie ty efe-tane’ o ana’ Iehodao mb’eo mb’eo ty amo hasavereña’eo.
Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
13 Natolo’e amy Kalebe’ ana’ Iefonè ty ila’ o anjara’ o ana’ Iehodaoo, ty amy nandilia’ Iehovà Iehosoay, rekets’ i Kiriate-Arbà, toe rae’ i Anàke t’i Arbà; ty rova atao Kebrone.
Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
14 Natao i Kalebe soike i ana-dahi’ telo’ i Anàke rey: i Sesay naho i Ahimane naho i Talmay, i ana’ i Anàke rey.
Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
15 Ie boak’ ao le nionjomb’ amo mpimone’ i Debireo mb’eo; natao Kiriate-sefere ty añara’ i Debire taolo.
Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
16 Le hoe t’i Kalebe, Hatoloko amy ze manjevoñe i Kiriate-sefere vaho mahatavañe aze t’i Aksàe anak’ ampelako ho vali’e.
Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
17 Aa le tinava’ i Otniele ana’i Kenaze rahalahi’ i Kalebe vaho natolo’e aze t’i Aksae anak’ ampela’e ho tañanjomba’e.
Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
18 Ie amy zao, naho nasese ama’e i ampelay, le nosihe’e ty hihalaly tetek’ aman-drae’e; aa ie nizotso amy borìke’ey, le hoe ty asa’ i Kalebe ama’e: Ino o paia’oo?
Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
19 Hoe re: Tatao iraho, kanao tinolo’o tane atimo ao, ehe itoloro rano manganahana. Aa le natolo’e aze i Rano Manganahana Amboney naho i Rano Manganahana Ambaney.
Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
20 Zao ty lova ty fifokoa’ Iehoda ty amo hasavereña’eo.
Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
21 O rovam-pifokoa’ o ana’ Iehodao mañatimo mb’ añ’efe-tane’ Edome mb’eoo le i Kab-tseel naho i Eder naho Iagore
Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
22 naho i Kinà naho i Dimonà naho i Adadà
Kina, Dimona, Adada,
23 naho i Kedese naho i Katsore naho Iitnàne;
Kedeṣi, Hasori, Itina,
24 i Zife naho i Teleme naho i Bealote
Sifi, Telemu, Bealoti,
25 naho i Katsore-kadatà naho i Keriote naho i Ketsrone ze toe Katsore,
Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
26 i Amame naho i Semà naho i Moladà,
Amamu, Ṣema, Molada,
27 naho i Katsar-gadà naho i Kesmone naho i Betepalete
Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
28 naho i Katsar-soale naho i Beersevà naho i Beziotià,
Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
29 i Baalà naho Iime naho i Etseme
Baalahi, Limu, Esemu,
30 naho i Eltolade naho i Kesile naho i Kormà
Eltoladi, Kesili, Horma,
31 naho i Tsiklage naho i Madmanà naho i Sansanà
Siklagi, Madmana, Sansanna,
32 naho i Lebaote naho i Silehime naho i Aine vaho i Rimone; rova roapolo-sive’ amby rekets’ o tanà’eo.
Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
33 Aa naho an-tane pisake, i Estaole naho i Tsoreà naho i Asnà,
Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
34 naho i Tsanoà naho i Enganime, i Tapoà naho i Ename,
Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
35 Iarmote naho i Adolame, i Sokò naho i Azekà,
Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
36 naho i Saraime naho i Aitaime naho i Gederà vaho i Gederotaime: rova folo-efats’ amby rekets’ o tanà’eo.
Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
37 I Tsenane naho i Kadasà naho i Migdal-gade
Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
38 naho i Dileane naho i Mitspe naho Ioktile,
Dileani, Mispa, Jokteeli,
39 i Lakise naho i Bots-kate naho i Eglone
Lakiṣi, Boskati, Egloni,
40 naho i Kabone naho i Lamame naho i Kitlise
Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
41 naho i Gederote, i Bete-dagone, naho i Naamà vaho i Màkedà; rova folo-eneñ’ amby rekets’ o tanà’eo.
Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
42 I Libnà, naho i Etere naho i Asane
Libina, Eteri, Aṣani,
43 naho Iptà, naho i Asnà naho i Netsibe,
Hifita, Aṣna, Nesibu,
44 naho i Keilà naho i Akzeebe vaho i Maresà: rova sive rekets’ o tanà’eo.
Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
45 I Ekrone, rekets’ o rova’eo naho o tanà’eo.
Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
46 Le boak’ Ekrone pak’ an-driakey mañohoke i Asdode naho o tanà’e iabio.
ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
47 I Asdode rekets’ o rova’eo naho o tanà’eo naho i Aza rekets’ o rova’eo naho o tanà’eo pak’ an-tsaka’ i Mitsraime añe, i riake jabajabay ro efe-tane’e.
Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
48 Le amo vohitseo: i Samire, Iatire naho i Sokò, naho
Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
49 i Danà, naho i Kiriate-sanà (i Debire izay),
Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
50 i Anabe naho i Estemò naho i Enime,
Anabu, Eṣitemo, Animu,
51 naho i Gosene naho i Kolone vaho i Gilò; rova folo-raik’ amby rekets’ o tanà’eo.
Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
52 I Arabe naho i Doma naho i Eseane,
Arabu, Duma, Eṣani,
53 naho Ianome naho i Bete-tapoà naho i Afekà,
Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
54 naho i Kamotà naho i Kiriate-arbà (i Kebrone izay) vaho i Tsiore: rova sive naho o tanà’eo;
Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
55 i Maone, i Karmele naho i Zife naho Iotà
Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
56 naho Iezreele naho Iokdeame naho i Zanoàke,
Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
57 i Kaine, i Gibà vaho i Timnà: rova folo rekets’ o tanà’eo.
Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
58 I Kalkole, i Bete-tsore naho i Gedore
Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
59 naho i Maarate naho i Betanote vaho i Eltekone: rova eneñe rekets’ o tanà’eo.
Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
60 I Kiriabat-baale, toe Kiriate-Iearime naho i Rabà: rova roe rekets’ o tanà’eo;
Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
61 aa naho am-patrambey añe: i Bete-arabà, i Midine, naho i Sekakà,
Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
62 i Nisbane, naho i rovan-tSiray, vaho i Engedý: rova eneñe rekets’ o tanà’eo.
Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
63 Aa naho o nte-Iebosý mpimoneñe e Ierosalaime ao, tsy naharoake iareo o nte’ Iehodao, fa mbe tambatse e Ierosalaime ao miharo amo ana’ Iehodao pak’ androany o nte-Iebosio.
Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.