< Josoa 10 >

1 Aa ie jinanji’ i Adoni-tsedeke mpanjaka’ Ierosa­laime te rinambe’ i Iehosoa ty Ay naho nandrotsak’ aze; le manahake ty nanoe’e Ieriko rekets’ i mpanjaka’ey, ty nanoe’e i Ay rekets’ i mpan­jaka’ey; naho nifampilongo amy Israele o mpimone’ i Giboneo vaho fa aivo’ iereo ao.
Ní báyìí tí Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu gbọ́ pé Joṣua ti gba Ai, tí ó sì ti pa wọ́n pátápátá; tí ó sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, àti bí àwọn ènìyàn Gibeoni ti ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú Israẹli, tí wọ́n sì ń gbé nítòsí wọn.
2 Le nangebahebake iereo kanao posetse jabajaba ty Gibone, rovam-panjaka mandikoats’ i Ay, vaho fanalolahy iaby o lahilahi’eo.
Ìbẹ̀rù sì mú òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ torí pé Gibeoni jẹ́ ìlú tí ó ṣe pàtàkì, bí ọ̀kan nínú àwọn ìlú ọba; ó tóbi ju Ai lọ, gbogbo ọkùnrin rẹ̀ ní ó jẹ́ jagunjagun.
3 Aa le nahitri’ i Adoni-tsedeke mpanjaka’ Ierosalaime amy Hohame, mpanjaka’ i Kebrone naho amy Pirame, mpanjaka’ Iarmote naho am’ Iafia, mpanjaka’ i Lakise vaho amy Debire, mpanjaka’ i Eglone, ty hoe:
Nítorí náà Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu bẹ Hohamu ọba Hebroni, Piramu ọba Jarmatu, Jafia ọba Lakiṣi àti Debiri ọba Egloni. Wí pe,
4 Mionjona mb’ amako mb’etoa; antao tika handafa i Gibone amy t’ie nifampilongo amy Iehosoa naho amo ana’ Israeleo.
“Ẹ gòkè wá, kí ẹ sì ràn mi lọ́wọ́ láti kọlu Gibeoni, nítorí tí ó ti wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Joṣua àti àwọn ará Israẹli.”
5 Aa le nifañosoñe i mpanjaka lime’ o nte-Amoreo rey, ty mpanjaka’ Ierosalaime, ty mpanjaka’ i Kebrone, ty mpanjaka’ Iarmote, ty mpanjaka’ i Lakise vaho ty mpanjaka’ i Eglone rekets’ o valobohò’ iareo iabio, nitobe tandrife i Gibone ey vaho nialia’e.
Àwọn ọba Amori márààrún, ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni, kó ara wọn jọ, wọ́n sì gòkè, àwọn àti gbogbo ogun wọn, wọ́n sì dojúkọ Gibeoni, wọ́n sì kọlù ú.
6 Aa le nañitrik’ am’ Iehosoa e Gilgale añe ondati’ i Giboneo nanao ty hoe: Ko ageba’o amo mpitoro’oo o fità’oo; malisà! mionjona mb’ ama’ay mb’etoy, rombaho vaho oloro; amy te nifanontoñe haname anay ze hene mpanjaka nte-Amore mpimoneñe am-bohibohitse ao.
Àwọn ará Gibeoni sì ránṣẹ́ sí Joṣua ní ibùdó ní Gilgali pé, “Ẹ má ṣe fi ìránṣẹ́ yín sílẹ̀. Ẹ gòkè tọ̀ wà wá ní kánkán kí ẹ sì gbà wá là. Ẹ ràn wá lọ́wọ́, nítorí gbogbo àwọn ọba Amori tí ń gbé ní orílẹ̀-èdè òkè dojú ìjà kọ wá.”
7 Aa le niavotse i Gilgale t’Iehosoa reketse ze hene lahindefo’e, toe o fanalo­lahi’e iabio.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gòkè lọ láti Gilgali pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, àti akọni nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
8 Le hoe t’Iehovà amy Iehosoa, Ko hembañe, ie fa natoloko am-pità’o; leo raik’ am’ondati’eo tsy hahafijohañe ama’o.
Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, Mo ti fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́. Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wọn ti yóò lè dojúkọ ọ́.”
9 Aa le nivovo am’ iereo t’Iehosoa fa nikatsakatsake haleñe boake Gilgale añe,
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wọ́de ogun ní gbogbo òru náà láti Gilgali, Joṣua sì yọ sí wọn lójijì.
10 vaho navalitsi­kota’ Iehovà añatrefa’ Israele eo, le binaibai’e e Gibone am-pizamanam-bey; naho hinorida’e mb’ amy fitroara’ i Bete-koroney mb’ eo, vaho finofo’e pak’ Azekà naho Makedà añe.
Olúwa mú kí wọn dààmú níwájú àwọn Israẹli, wọ́n sì pa wọ́n ní ìpakúpa ní Gibeoni. Israẹli sì lépa wọn ní ọ̀nà tí ó lọ sí Beti-Horoni, ó sì pa wọ́n dé Aseka, àti Makkeda.
11 Aa ie nandripàke ty lay am’ Israele, amy fizotsoa’ i Bete-koroney le nahirirì’ Iehovà ama’ iereo ty vato gada­boñe boak’ an-dikerañey pak’ Azekà, vaho nikoromake; maro ty nampivetrahe’ i havandra gada­boñey te amo vinono’ o ana’ Israeleo am-pibarao.
Bí wọ́n sì tí ń sá ní iwájú Israẹli ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ ní ọ̀nà láti Beti-Horoni títí dé Aseka, Olúwa rọ yìnyín ńlá sí wọn láti ọ̀run wá, àwọn tí ó ti ipa yìnyín kú sì pọ̀ ju àwọn tí àwọn ará Israẹli fi idà pa lọ.
12 Le hoe t’Iehosoa am’ Iehovà amy andro nanolora’ Iehovà o nte-Amo­reo añatrefa’ o ana’ Israeleoy; hoe re ampahaisaha’ Israele, Ry andro, mijihera amy Gibone ey, naho ry volañe, am-bavatane’ i Aialone ey.
Ní ọjọ́ tí Olúwa fi àwọn ọmọ Amori lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sọ fún Olúwa níwájú àwọn ará Israẹli, “Ìwọ oòrùn, dúró jẹ́ẹ́ ní orí Gibeoni, Ìwọ òṣùpá, dúró jẹ́ẹ́ lórí àfonífojì Aijaloni.”
13 Aa le nijihetse i àndroy vaho ni­tsan­gañe i volañey, ampara’ te niheneke ty fañondroha’ iareo amo rafelahi’ iareoo. Tsy fa sinokitse amy boke Iasarey hao? Nijohañe an-teñateñan-dikerañe ey i àndroy, va’e andro raike t’ie tsy nalisa niroñe.
Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn náà sì dúró jẹ́ẹ́, òṣùpá náà sì dúró, títí tí ìlú náà fi gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé Jaṣari. Oòrùn sì dúró ní agbede-méjì ọ̀run, kò sì wọ̀ ní ìwọ̀n odindi ọjọ́ kan.
14 Mboe lia’e tsy teo ty andro taolo ndra nanonjohy ty nanahake aze, te nihaoñe’ Iehovà ty feo’ ondaty raike; amy te nialy ho a Israele t’Iehovà.
Kò sí ọjọ́ tí o dàbí rẹ̀ ṣáájú tàbí ní ẹ̀yìn rẹ̀, ọjọ́ tí Olúwa gbọ́ ohùn ènìyàn. Dájúdájú Olúwa jà fún Israẹli!
15 Nimpoly amy zao t’Iehosoa, naho Israele iaby nindre ama’e mb’an-tobe e Gilgale añe.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli padà sí ibùdó ní Gilgali.
16 Fe nipoliotse i mpanjaka lime rey nietak’ an-dakato’ i Makedà ao.
Ní báyìí àwọn ọba Amori márùn-ún ti sálọ, wọ́n sì fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta kan ní Makkeda,
17 Aa le nitaro­ñeñe am’ Iehosoa ty hoe: Nioniñe mietak’ an-dakato’ i Makedà ao i mpan­jaka lime rey.
nígbà tí wọ́n sọ fún Joṣua pé, a ti rí àwọn ọba márààrún, ti ó fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta ní Makkeda,
18 Le hoe t’Iehosoa: Amariño vato jabajaba am-bava’ i lakatoy le ajadoño eo t’indaty hañambeñe iareo
ó sì wí pé, “Ẹ yí òkúta ńlá dí ẹnu ihò àpáta náà, kí ẹ sì yan àwọn ọkùnrin sí ibẹ̀ láti ṣọ́ ọ.
19 le ko tambatse eo, fa horidaño o rafelahi’ areoo vaho lafao o amboli’eoo; ko engañe hizilik’ amo rova’eo; amy t’ie natolo’ Iehovà Andrianañahare’ areo am-pità’ areo.
Ṣùgbọ́n, ẹ má ṣe dúró! Ẹ lépa àwọn ọ̀tá yín, ẹ kọlù wọ́n láti ẹ̀yìn, kí ẹ má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó dé ìlú wọn, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
20 Naho nihenefe’ Iehosoa naho o ana’ Israeleo ty fanjamanañe iareo am-pañohofan-doza ra’elahy, ampara’ t’ie fonga nimongotse vaho fa nimoak’ amo rova fatratseo o sehanga’eo,
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli pa wọ́n ní ìpakúpa wọ́n sì pa gbogbo ọmọ-ogun àwọn ọba márààrún run, àyàfi àwọn díẹ̀ tí wọ́n tiraka láti dé ìlú olódi wọn.
21 le nimpoly mb’an-tobe mb’eo am-panintsiñañe ondaty iabio mb’ amy Iehosoa e Makedà mb’eo; tsy teo ka ty naniom-pameleke hitreatre ndra iaia amo ana’ Israeleo.
Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní ibùdó ogun ní Makkeda ní àlàáfíà, kò sí àwọn tí ó dábàá láti tún kọlu Israẹli.
22 Le hoe t’Iehosoa, Sokafo ty vava’ i lakatoy vaho aseseo amako boak’ an-dakato ao i mpanjaka lime rey.
Joṣua sì wí pe, “Ẹ ṣí ẹnu ihò náà, kí ẹ sì mú àwọn ọba márààrún jáde wá fún mi.”
23 Aa le nanoe’ iereo; nakare’ iareo boak’ an-dakato ao i mpanjaka lime rey: ty mpanjaka’ Ierosalaime, ty mpanjaka’ i Kebrone, ty mpanjaka’ Iarmote, ty mpanjaka’ i Lakise, ty mpanjaka’ i Eglone.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú àwọn ọba márààrún náà kúrò nínú ihò àpáta, àwọn ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni.
24 Le nakare’ iareo mb’ am’ Iehosoa i mpanjaka rey, naho kinanji’ Iehosoa o lahindefo’ Israele iabio, le nanao ty hoe amo mpifelen-dahin-defo mpindre ama’eo: Mañarinea; apetaho am-pititia’ o mpanjakao o fandia’ areoo. Nañarine amy zao iereo vaho nanoe’ iereo am-pititia’ i mpanjaka rey o fandia’ iereoo.
Nígbà tí wọ́n mú àwọn ọba náà tọ Joṣua wá, ó pe gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli, ó sì sọ fún àwọn olórí ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ bí, kí ẹ sì fi ẹsẹ̀ yín lé ọrùn àwọn ọba wọ̀nyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wá sí iwájú, wọ́n sì gbé ẹsẹ̀ lé ọrùn wọn.
25 Le hoe t’Iehosoa am’ iereo: Ko hembañe, ko mihakahaka, mihaozara naho mahavania; fa zao ty hanoa’ Iehovà ze rafelahy iaby hialia’ areo.
Joṣua sì sọ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ ṣe gírí, kí ẹ sì mú àyà le. Báyìí ni Olúwa yóò ṣe sí gbogbo àwọn ọ̀tá yín, tí ẹ̀yin yóò bá jà.”
26 Linafa’ Iehosoa amy zao iereo, vinono’e vaho nampandradoradoe’e an-katae lime; niradorado amy hatae rey am-para’ te haleñe.
Nígbà náà ni Joṣua kọlù wọ́n, ó sì pa àwọn ọba márààrún náà, ó sì so wọ́n rọ̀ ní orí igi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ márùn-ún, wọ́n sì fi wọ́n sí orí igi títí di ìrọ̀lẹ́.
27 Ie nitsofots’ andro, le nandily t’Iehosoa, naho nazotso amo hataeo, naho navokovoko amy lakato nietaha’ iareoy, vaho nampipohañe vato jabajaba maro am-bava’ i lakatoy—pak’ami’ty andro toy.
Nígbà tí oòrùn wọ̀, Joṣua pàṣẹ, wọ́n sì sọ̀ wọ́n kalẹ̀ kúrò ní orí igi, wọ́n sì gbé wọn jù sí inú ihò àpáta ní ibi tí wọ́n sá pamọ́ sí. Wọ́n sì fi òkúta ńlá dí ẹnu ihò náà, tí ó sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
28 Ie amy àndroy, rinambe’ Iehosoa ka t’i Makedà naho linafa’e an-dela-pibara naho nimongore’e i mpanjaka’ey, naho ze fonga ondaty ao; leo raike tsy nisisa; vaho nanoe’e amy mpanjaka’ i Makedày hambañe amy nanoa’e i mpanjaka’ Ierikoy.
Ní ọjọ́ náà Joṣua gba Makkeda. Ó sì fi ojú idà kọlu ìlú náà àti ọba rẹ̀, ó sì run gbogbo wọn pátápátá, kò fi ẹnìkan sílẹ̀. Ó sì ṣe sí ọba Makkeda gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe sí ọba Jeriko.
29 Nienga’ i Makedà t’Iehosoa rekets’ Israele iaby naho nimb’e Libnà mb’eo vaho nialy amy Libnà;
Nígbà náà ní Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Makkeda lọ sí Libina wọ́n sì kọlù ú.
30 natolo’ Iehovà am-pità’ Israele ka izay naho i mpanjaka’ey le linafa’e an-dela-pibara naho ze fonga ondaty ao; tsy nampipoke sengaha’e, le nanoe’e amy mpanjaka’ey hambañe amy nanoe’e amy mpanjaka’ Ierikoy.
Olúwa sì fi ìlú náà àti ọba rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́. Ìlú náà àti gbogbo àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Joṣua fi idà pa. Kò fi ẹnìkan sílẹ̀ ní ibẹ̀: Ó sì ṣe sí ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí ọba Jeriko.
31 Nienga i Libnà t’Iehosoa naho Israele iaby, nomb’e Lakise mb’eo naho nitobe marine aze vaho nialia’e;
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo ará Israẹli, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Libina lọ sí Lakiṣi; ó sì dó tì í, ó sì kọlù ú.
32 le natolo’ Iehovà am-pità’ Israele t’i Lakise; rinambe’e amy andro faha roey vaho linafa’e an-dela-pibara naho ze fonga ondaty ao, hambañe amy nanoe’e i Libnày.
Olúwa sì fi Lakiṣi lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sì gbà á ní ọjọ́ kejì. Ìlú náà àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀ ní ó fi idà pa gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Libina.
33 Aa le nionjoñe mb’e Lakise mb’eo t’i Korame mpanjaka’ i Gezere hañolots’ aze, le linafa’ Iehosoa ka naho ondati’eo am-para te tsy aman-tsehanga’e.
Ní àkókò yìí, Horamu ọba Geseri gòkè láti ran Lakiṣi lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Joṣua ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.
34 Nienga i Lakise t’Iehosoa rekets’ Israele iaby le nimb’e Eglone mb’eo naho nitobe eo vaho nialia’e.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lakiṣi lọ sí Egloni; wọ́n sì dó tì í, wọ́n sì kọlù ú.
35 Rinambe’ iereo amy àndroy avao, vaho linafa’e an-dela-pibara; ie naho o fonga ondati’eo ro zina­ma’e amy àndroy, hambañe amy nanoe’e i Lakisey.
Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lakiṣi.
36 Nienga i Eglone t’Iehosoa naho nindre ama’e t’Israele iaby, nimb’e Kebrone mb’ eo le nialia’e.
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli ṣí láti Egloni lọ sí Hebroni, wọ́n sì kọlù ú.
37 Rinambe izay naho linafa’e an-dela-pibara rekets’ i mpanjaka’ey naho ze hene rova’e naho ondati’e iabio; leo sehanga’e tsy napo’e, hambañe amy nanoe’e i Egloney, ie vata’e narotsa’e reketse ze fonga ondaty ama’e ao.
Wọ́n gba ìlú náà, wọ́n sì ti idà bọ̀ ọ́, pẹ̀lú ọba rẹ̀, gbogbo ìletò wọn àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀. Wọn kò dá ẹnìkan sí. Gẹ́gẹ́ bí ti Egloni, wọ́n run un pátápátá àti gbogbo ènìyàn inú rẹ̀.
38 Nibalike mb’e Debire mb’eo t’Iehosoa naho nindre ama’e t’Israele iaby vaho nialia’e;
Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ yí padà, wọ́n sì kọlu Debiri.
39 ri­nambe’e rekets’ i mpanjaka’ey naho o ro­va’eo le linafa’ iareo an-dela-pibara naho namongotse ze fonga ondaty ao; leo sehanga’e tsy napo’e; manahake ty nanoe’e Amy Kebrone ty nanoa’e Amy Debire naho i mpan­jaka’ey, hambañe amy nanoe’e amy Libnày naho i mpan­jaka’eiy.
Wọ́n gba ìlú náà, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú wọn, wọ́n sì fi idà pa wọ́n. Gbogbo ènìyàn inú rẹ̀ ni wọ́n parun pátápátá. Wọn kò sì dá ẹnìkankan sí. Wọ́n ṣe sí Debiri àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wọn ti ṣe sí Libina àti ọba rẹ̀ àti sí Hebroni.
40 Aa le hene finofo’ Iehosoa o am-bohibohitseo naho i Atimoy naho i vavatanen-drano manganahanay naho o mpanjaka’e iabio; tsy napo’e sehanga’e fa fonga nimongore’e ze raha nikofòke, ty amy linili’ ­Iehovà Andrianañahare’ Israeley.
Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ṣẹ́gun gbogbo agbègbè náà, ìlú òkè, gúúsù, ìlú ẹsẹ̀ òkè ti ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè pẹ̀lú gbogbo ọba, wọn kò dá ẹnìkankan sí. Ó pa gbogbo ohun alààyè run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti pàṣẹ.
41 Fonga linafa’ Iehosoa boake Kadese-barnea pak’ Aza naho an-tane Go­sene iaby pake Gibone.
Joṣua sì ṣẹ́gun wọn láti Kadeṣi-Barnea sí Gasa àti láti gbogbo agbègbè Goṣeni lọ sí Gibeoni.
42 Rinambe’ Ieho­soa indrai-mipaoke i mpanjaka rey naho o tane’eo amy te nialy ho a Israele t’Iehovà Andrianañahare’ Israele.
Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí àti ilẹ̀ wọn ní Joṣua ṣẹ́gun ní ìwọ́de ogun ẹ̀ẹ̀kan, nítorí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, jà fún Israẹli.
43 Aa le nimpoly mb’an-tobe’ i Gilgale mb’eo t’Iehosoa naho Israele iaby.
Nígbà náà ni Joṣua padà sí ibùdó ní Gilgali pẹ̀lú gbogbo Israẹli.

< Josoa 10 >