< Jeremia 46 >
1 Niheo am’Iirmeà, mpitoky ty tsara’ Iehovà ty amo fifeheañeo;
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa àwọn Orílẹ̀-èdè.
2 ty amy Mitsraime, i mpirai-lian-dahin-defo’ i Parò-Neko mpanjaka’ i Mitsraimey, ie añolo’ i Saka-Perate e Karkemise ao, le ginio’ i Nebokadnetsare mpanjaka’ i Bavele, amy taom-paha-efa’ Iehoiakime ana’ Iosià mpanjaka’ Iehodày.
Nípa Ejibiti. Èyí ni ọ̀rọ̀ nípa àwọn ọmọ-ogun Farao Neko ọba Ejibiti ẹni tí a borí rẹ̀ ní Karkemiṣi, ní odò Eufurate láti ọwọ́ Nebukadnessari ọba Babeli ní ọdún kẹrin Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda:
3 Ihentseño ty fañeba naho ty fikalan-defo, vaho itotoho i hotakotakey.
“Ẹ múra àpáta, èyí tí ó tóbi, àti èyí tí ó kéré, kí ẹ sì súnmọ́ ojú ìjà!
4 Aombeo laboridy o soavalao, naho miningira, ry mpiningi-tsoavalao; mijohaña eo reketse kalan-doha; fotìo o lefoñeo, aombeo o sarom-bìo.
Ẹ di ẹṣin ní gàárì, kí ẹ sì gùn ún. Ẹ dúró lẹ́sẹẹsẹ pẹ̀lú àṣíborí yín! Ẹ dán ọ̀kọ̀ yín, kí ẹ sì wọ ẹ̀wù irin.
5 Akore t’ie treako hoe lonjetse naho miamboho? Finofok’ ambane o fanalolahi’eo, fa nitriban-day mb’eo, vaho tsy nitolik’ am-boho, fa niarikatoha’ ty firevendreveñañe, hoe t’Iehovà.
Kí ni nǹkan tí mo tún rí? Wọ́n bẹ̀rù, wọ́n sì ń padà sẹ́yìn, wọ́n ti ṣẹ́gun àwọn jagunjagun. Wọ́n sá, wọn kò sì bojú wẹ̀yìn, ìbẹ̀rù sì wà níbi gbogbo,” ni Olúwa wí.
6 Tsy hahafiorotse ty masìka, tsy hahafivoratsake ty fanalolahy; mitsikapy vaho mikorovoke mb’avaratse añe iereo, marine i Saka-Peratey.
“Ẹni tí ó yára kì yóò le sálọ, tàbí alágbára kò ní lè sá àsálà. Ní àríwá ní ibi odò Eufurate wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
7 Ia ty hambañ’am’Ieore mitroatroakey, manahake o saka misorotombake hanginahina’eo?
“Ta ni èyí tí ó gòkè wá bí odò Ejibiti, tí omi rẹ̀ ń ru gẹ́gẹ́ bí odò wọ̀n-ọn-nì?
8 Manahake Ieore t’i Mitsraime amy fitabatroaha’ o rano’eoy; ie manao ty hoe: Hitroatse iraho, hanginahina naho hampiopo ty tane toy, toe harotsako i rovay naho o mpimoneñe ama’eo.
Ejibiti dìde bí odò náà, bí omi odò tí ń ru. Ó sì wí pé, ‘Èmi yóò dìde, n ó sì bo gbogbo ilẹ̀ ayé.’ Èmi yóò pa ìlú àti àwọn ènìyàn rẹ̀ run.
9 Mionjona ry soavalao, mionara ry sareteo; ampivavaro mb’etoy o fanalolahio, o nte-Kose naho nte-Pote mahafitàm-pikalan-defoñeo, o nte-Lode mahatañe naho mahafibitsoke faleo.
Ẹ gòkè wá ẹ̀yin ẹṣin, ẹ sì sáré kíkankíkan ẹ̀yin kẹ̀kẹ́. Kí àwọn alágbára túbọ̀ tẹ̀síwájú, àwọn ará Kuṣi àti àwọn ará Puti tí ń di asà mú; àti àwọn ará Lidia tí ń fa ọrun.
10 Amy te hanañ’ androm-pañondroha’e t’i Talè Iehovà’ i Màroy, hamalea’e fate o rafelahi’eo, hampibotsehañe i fibaray ampara’ te etsake naho mamo ami’ty lio’ iareo; fa manao soroñe t’i Talè, Iehovà’ i Màroy, an-tane avaratse, marine’ i Saka-Peratey.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà jẹ́ ti Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, ọjọ́ ìgbẹ̀san, ìgbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀. Idà yóò sì jẹ́ títí yóò fi ní ìtẹ́lọ́rùn, títí yóò fi pa òǹgbẹ rẹ̀ rẹ́ pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀. Nítorí pé Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò rú ẹbọ ní ilẹ̀ gúúsù ní odò Eufurate.
11 Mionjona mb’e Gilade mb’eo, mitohà fatevo ry anak’ ampela’ i Mitsraimeo; fonga tsy jefa’e o aoly anoe’oo, toe tsy eo ty hampijangañe azo.
“Gòkè lọ sí Gileadi, kí o sì mú ìkunra, ìwọ wúńdíá ọmọbìnrin Ejibiti. Ṣùgbọ́n ní asán ni ìwọ ń lo oògùn, kì yóò sí ìwòsàn fún ọ.
12 Fa jinanji’ o kilakila’ ndatio ty fisalara’o, vaho manitsike ty tane toy ty fikoikoiha’o, fa nitsikapy amy maozatsey ty fanalolahy, sindre nihotrake.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ nípa ìtìjú rẹ, igbe rẹ yóò kún gbogbo ayé. Jagunjagun yóò máa ṣubú lu ara wọn lórí rẹ, àwọn méjèèjì yóò sì jọ ṣubú papọ̀.”
13 Ty tsara’ Iehovà am’ Iirmeà mpitoky, te hanao akore ty hionjona’ i Nebokadnetsare mpanjaka’ i Bavele mb’an-tane Mitsraime mb’eo handafa aze?
Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó bá Jeremiah wòlíì nì sọ nípa wíwá Nebukadnessari ọba Babeli láti lọ dojú ìjà kọ Ejibiti:
14 Tseizo’ areo e Mitsraime ao, koiho e Migdole, koiho-lava e Nofe naho e Tafanese, vaho ano ty hoe: Mijohaña vaho mihentseña fa hampibotsek’ añ’ariary azo i fibaray.
“Kéde èyí ní Ejibiti, sì sọ ọ́ ní Migdoli, sọ ọ́ ní Memfisi àti Tafanesi: ‘Dúró sí ààyè rẹ kí o sì múra sílẹ̀, nítorí pé idà náà ń pa àwọn tí ó yí ọ ká.’
15 Akore te nafaoke añe o maoza’oo? Ie tsy nahafitroatse amy te tinindri’ Iehovà ambane.
Èéṣe tí àwọn akọni rẹ fi ṣubú? Wọn kò ní le dìde dúró, nítorí Olúwa yóò tì wọ́n ṣubú.
16 Maro ty tsinikapi’e; eka songa mifampikorovoke vaho manao ty hoe: Miongaha, antao himpoly mb’am’ondatin-tika mb’eo, mb’an-tane nahatoly an-tikañe añe, hienga ty fijoia’ i fibaray.
Wọn yóò máa ṣubú léraléra wọn yóò máa ṣubú lu ara wọn. Wọn yóò sọ wí pé, ‘Ẹ dìde, ẹ jẹ́ kí a padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn wa àti ilẹ̀ ìbí wa, kúrò níbi idà àwọn aninilára.’
17 Ty hoe ty nikoihe’ iereo añe: Koràk’ avao t’i Parò mpanjaka’ i Mitsraime; Napo’e hihelañe añe i ni-fantañañey.
Níbẹ̀ ni wọn ó kígbe pé, ‘Ariwo lásán ni Farao ọba Ejibiti pa, ó ti sọ àǹfààní rẹ̀ nù.’
18 Kanao velon-dRaho hoe i Mpanjakay, Iehovà’ i Màroy ty tahina’e, Toe hanahak’ i Tabore am-bohitsey naho i Karmele añ’olon-driake añe, Ty higodaña’e mb’etoy.
“Bí èmi ti wà láààyè,” ni ọba, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Nítòótọ́ gẹ́gẹ́ bí Tabori láàrín àwọn òkè àti gẹ́gẹ́ bi Karmeli lẹ́bàá Òkun bẹ́ẹ̀ ni òun yóò dé.
19 O ry anak’ampela mpimoneñe e Mitsraime ao, mivatia handenà’o mb’am-pandrohizañe añe, fa ho tanàn-taolo ty Nofe, hampangoakoaheñe tsy ho amam-pimoneñe.
Ìwọ, ọmọbìnrin ti ń gbé Ejibiti pèsè ohun èlò ìrìnàjò fún ara rẹ nítorí Memfisi yóò di ahoro a ó sì fi jóná, láìní olùgbé.
20 Kiloa fanjaka t’i Mitsraime fe boak’ avaratse añe ty lale-boròñe hamongotse—toe ho avy.
“Ẹgbọrọ abo màlúù tó lẹ́wà ní Ejibiti ṣùgbọ́n eṣinṣin ìparun dé, ó dé láti àríwá.
21 Manahake ty sarak’ an-jolok’ ao, o lahin-defo mpikarama añivo’eo, fa nivalike ka iereo; niharo nibotatsake, tsy nahafijohañe, fa tondroke ty andron-kankà’ iareo, ty androm-pitilihañe iareo.
Àwọn jagunjagun rẹ̀ dàbí àbọ́pa akọ màlúù. Àwọn pẹ̀lú yóò yípadà, wọn ó sì jùmọ̀ sá, wọn kò ní le dúró, nítorí tí ọjọ́ ibi ń bọ̀ lórí wọn àsìkò láti jẹ wọ́n ní ìyà.
22 Hoe mereñe ty fikosasaha’e ie misoroke o lahindefo’eo, mikovovoke mb’am-pisorohañ’aze o lahindefoñeo, ie mitoañ’ aze am-pekoñe hoe mpañatsak’ ala.
Ejibiti yóò pòṣé bí ejò tí ń sá bí ọmọ-ogun ṣe ń tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú agbára. Wọn ó tọ̀ ọ́ wá pẹ̀lú àáké, gẹ́gẹ́ bí i ti agégi.
23 Hinatsa’ iareo i alay, hoe t’Iehovà, fa tsy lefe volilieñe; amy t’ie maro te amo valalao, mitozantozañe.
Wọn o gé igbó rẹ̀ lulẹ̀,” ni Olúwa wí, “nítorí ti a kò le rídìí rẹ̀. Nítorí pé wọ́n pọ̀ ju ẹlẹ́ǹgà lọ, wọ́n sì jẹ́ àìníye.
24 Nisalareñe ty anak’ ampela’ i Mitsraime; fa natolotse am-pità’ ondaty avaratse añe.
A ó dójútì ọmọbìnrin Ejibiti, a ó fà á lé ọwọ́ àwọn ènìyàn àríwá.”
25 Hoe t’Iehovà’ i Màroy, t’i Andrianañahare’ Israrele, Ho liloveko t’i Amone nte-No naho i Parò, naho i Mitsraime, rekets’ o ‘ndrahare’eo, naho o mpanjaka’eo; toe i Parò naho ze miato ama’e.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí pé: “Èmi yóò rọ̀jò ìyà mi sórí Amoni òrìṣà Tebesi, sórí Farao, sórí Ejibiti àti àwọn òrìṣà rẹ̀ àti sórí àwọn ọba rẹ̀ àti sórí àwọn tó gbẹ́kẹ̀lé Farao.
26 Hatoloko am-pità’ o mipay ty fiai’eo naho am-pità’ i Nebokadnetsare mpanjaka’ i Bavele naho am-pità’ o mpitoro’eo; ie añe, le ho fimoneñañe indraike re manahake te taolo, hoe t’Iehovà.
Èmi ó sì fi wọ́n lé àwọn tó wá ẹ̀mí wọn lọ́wọ́, lé Nebukadnessari ọba Babeli, ṣùgbọ́n lẹ́yìn ìgbà díẹ̀, Ejibiti yóò sì di gbígbé bí i ti àtijọ́,” ni Olúwa wí.
27 Aa le ko hemban-drehe ry Iakobe mpitoroko, naho ko lonjetse ry Israele; fa ho rombaheko boake tsietoitane añe, naho ty tiri’o an-tanem-pandrohiza’ iareo; himpoly t’Iakobe, naho hierañerañe, le tsy eo ty hañembañe aze ka.
“Má bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má fòyà, ìwọ Israẹli. Dájúdájú èmi ó gbà ọ́ láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ ọmọ rẹ ní ilẹ̀ ìgbèkùn. Jakọbu yóò tún ní àlàáfíà àti ààbò, kò sì ṣí ẹni tí yóò dẹ́rùbà á.
28 Ko hemban-drehe ry Iakobe mpitoroko, hoe t’Iehovà, fa mpiama’o iraho; ho fonga mongoreko o fifeheañe nandroahako azoo, f’ihe tsy ho mongoreko; ho liloveko an-jaka-to, fe tsy hapoko tsy ho liloveñe.
Má bẹ̀rù, Jakọbu ìránṣẹ́ mi, nítorí pé mo wà pẹ̀lú rẹ,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, láàrín àwọn tí mo fọ́n yín ká sí. Èmi kò ní run yín tán. Èmi yóò jẹ ọ́ ní ìyà lórí òdodo, èmi kí yóò jọ̀wọ́ rẹ lọ́wọ́ lọ láìjẹ ọ́ ní yà.”