< Jeremia 21 >
1 Ty tsara’ Iehovà am’Iirmeà, ie nirahe’ i Tsidkià ama’e t’i Paskore ana’ i Malkià naho i Tsefanià ana’ i Maaseia mpisoroñe nanao ama’e ty hoe:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 Ehe, mihalalia ho anay am’ Iehovà; amy te maname aly aman-tika t’i Nebokadnetsare mpanjaka’ i Bavele; hera hitoloñe ho antika t’Iehovà manahake i hene fitoloña’e fanjaka rezay, hampihakañe aze aman-tika.
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 Le hoe t’Iirmeà am’ iereo: Ty hoe ty ho saontsie’ areo amy Tsidkià:
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Hoe t’Iehovà Andrianañahare’ Israele: Inao! hafoteko o fialiañe ampità’ areoo, o fialia’ areo amy mpanjaka’ i Baveleio, naho amo nte-Kasdy mamalañe anahareo alafe’ o kijolioo, fa hatontoko an-drova atoy iereo.
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 Le Izaho avao ty hialy ama’ areo am-pità’ natorakìtsy naho an-tsirañe maozatse, naho an-kaboseke mileveleve, vaho am-pifombo miforoforo.
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 Le ho lafaeko o mpimone’ ty rova toio, ndra ondaty ndra biby; hampihomahe’ ty angorosy jabajaba.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 Ie heneke, hoe t’Iehovà, le haseseko am-pità’ i Nebokadnetsare mpanjaka’ i Bavele naho am-pità’ o rafelahi’eo, naho am-pità’ o mipay ty fiai’eo t’i Tsidkià mpanjaka’Iehodà naho o mpitoro’eo, naho ze ondati’ an-drova atoy sinisa’ i angorosiy naho i fibaray, naho i hasalikoañey; vaho ho lafae’e an-kasiom-pibara, le tsy hihevea’e, tsy hiferenaiña’e, vaho tsy hitretreza’e.
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 Le hoe ty hatao’o am’ondaty retoa: Hoe ty nafè’ Iehovà: Hehe te apoko aolo’ areo eo ty lalan-kaveloñe naho ty lalam-pikoromahañe.
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Ze tambatse an-drova atoy ho vonoe’ ty fibara naho ty kerè, vaho ty angorosy; fe ho veloñe ze miakatse, miambane amo nte-Kasdy mañarikatok’ anahareoo, le ho tamben-ali’e ty fiai’e.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 Fe nampiatrefeko ami’ty rova toy ty tareheko ho hekoheko fa tsy hasoa, hoe t’Iehovà; ie hatolotse am-pità’ i mpanjaka’ i Baveley, vaho ho forototoe’e amañ’afo.
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 Le i anjombam-panjaka’ Iehodày, janjiño ty tsara’ Iehovà;
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Ry anjomba’ i Davide, hoe t’Iehovà: Ano ty hatò boak’andro, vaho avotsoro am-pità’ ty mpamorekeke i nikamereñey, tsy mone hionjoñe hoe afo ty habosehako, hamorototoako tsy ho lefe vonoeñe, ty amo haloloam-pitoloña’ areoo.
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Hehe te miatrek’azo raho ry mpimoneñe am-bavatane ao, hoe t’ie vato a montoñe ey, hoe t’Iehovà: amy ty fatao’ areo ty hoe: Ia ty hizotso haname anay? ndra ia ty himoak’ añ-akiba’ay atoa.
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Toe ho liloveko ty amo vokam-pitoloña’ areoo, hoe t’Iehovà; naho hamiañako afo i ala’ey, vaho fonga ho tomontoñe ze mañohok’ aze.
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”