< Isaia 25 >

1 Ry Iehovà, Andrianañahareko irehe, hañonjoñ’Azo iraho, ho bangoeko ty tahina’o, ty amo fitoloña’o fanjàkao; ihe nisafiry haehae am-pigahiñañe naho an-katò.
Olúwa, ìwọ ni Ọlọ́run mi; èmi yóò gbé ọ ga èmi ó sì fi ìyìn fún orúkọ rẹ nítorí nínú òtítọ́ aláìlẹ́gbẹ́ o ti ṣe ohun ńlá, àwọn ohun tí o ti gbèrò o rẹ̀ lọ́jọ́ pípẹ́.
2 Fa nanoe’o votre ty rova, naho fianto i rova fatra-piaroy; tsy rova ka i anjomban’ ambahiniy, vaho tsy hamboareñe ka.
Ìwọ ti sọ ìlú di àkójọ àlàpà, ìlú olódi ti di ààtàn, ìlú olódi fún àwọn àjèjì ni kò sí mọ́; a kì yóò tún un kọ́ mọ́.
3 Aa le hañonjoñe Azo ondaty manjofakeo, hañeveñe ama’o o rovam-pifeheañe mitromoroñeo.
Nítorí náà àwọn ènìyàn alágbára yóò bọ̀wọ̀ fún ọ; àwọn ìlú orílẹ̀-èdè aláìláàánú yóò bu ọlá fún ọ.
4 Fa nifipalira’ o rarakeo irehe, fitsoloha’ o misotrio, fiampirañe an-tio bey, fialofañe amy hatrovohañey; naho hoe tio-bey an-kijoly ty fikofoha’ o maharevendreveñeo.
Ìwọ ti jẹ́ ààbò fún àwọn òtòṣì ààbò fún aláìní nínú ìpọ́njú rẹ̀ ààbò kúrò lọ́wọ́ ìjì bòòji kúrò lọ́wọ́ ooru. Nítorí pé èémí àwọn ìkà dàbí ìjì tí ó bì lu ògiri
5 Manahake ty hatrevohañe an-tane maike eo, ty hampitsiña’o ty fikoraha’ o ambahinio; hambañe ami’ty talinjon-drahoñe amy fipisañañey, ty hampijomohoñe ty fibekoa’ o mangosasàkeo.
àti gẹ́gẹ́ bí ooru ní aginjù. O mú ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ bá rògbòdìyàn àwọn àjèjì, gẹ́gẹ́ bí òjìji kurukuru ṣe ń dín ooru kù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni orin àwọn ìkà yóò dákẹ́.
6 Ami’ty vohitse toy ty hañalankaña’ Iehovà’ i Màroy sabadidake amo raha mafirio ze kila ondaty, takataka aman-divay natadrètse, ty vondrake pea’ ty betron-taolañe, vaho divay soa-filomboke.
Ní orí òkè yìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò ti pèsè àsè oúnjẹ àdídùn kan fún gbogbo ènìyàn àpèjẹ ti ọtí wáìnì àtijọ́ ti ẹran tí ó dára jù àti ti ọtí wáìnì tí ó gbámúṣé.
7 Le hagedra’e ami’ty vohitse toy ty fikolopofañe ami’ty vinta’ ze kila-ondaty naho ty marerarera mandrongoñe o fifeheañeo.
Ní orí òkè yìí ni yóò pa aṣọ òkú tí ó ti ń di gbogbo ènìyàn, abala tí ó bo gbogbo orílẹ̀-èdè mọ́lẹ̀,
8 Hatele’e ho mongotse ty havilasy, vaho ho faohe’ i Rañandria Iehovà amy ze hene laharañe ty ranompihaino; hafaha’e ami’ty tane toy ty sirika’ondati’eo; izay ty nitsarà’ Iehovà.
Òun yóò sì gbé ikú mì títí láé. Olúwa Olódùmarè yóò sì nu gbogbo omijé nù, kúrò ní ojú gbogbo wọn, Òun yóò sì mú ẹ̀gàn àwọn ènìyàn rẹ̀ kúrò ní gbogbo ilẹ̀ ayé. Olúwa ni ó ti sọ ọ́.
9 Ho tseizeñe amy andro zay, ty hoe: Toe Ie t’i Andrianañaharentika nitamañe handrombake an-tikañey, Ie Iehovà niliñisan-tikañey, antao hifale naho hirebeke amy fandrombaha’ey.
Ní ọjọ́ náà wọn yóò sọ pé, “Nítòótọ́ eléyìí ni Ọlọ́run wa; àwa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ̀, òun sì gbà wá là. Èyí ni Olúwa, àwa gbẹ́kẹ̀lé e, ẹ jẹ́ kí a yọ̀ kí inú wa sì dùn nínú ìgbàlà rẹ̀.”
10 Fa ami’ty vohitse toy ty hitofà’ ty fità’ Iehovà, vaho ho lialiàñe an-toe’e eo t’i Moabe, hambañe ami’ty fandialiàñe ty ahetse an-ditsake ao.
Ọwọ́ Olúwa yóò sinmi lé orí òkè yìí ṣùgbọ́n a ó tẹ Moabu mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀; gẹ́gẹ́ bí a ti gún koríko mọ́lẹ̀ di ajílẹ̀.
11 Le ho velare’e añivo’iareo o fità’eo, manahake ty famelara’ ty pilaño hilañoa’e, fe harèke ty firengevoha’e rekets’ o taña-politì’eo
Wọn yóò na ọwọ́ wọn jáde nínú rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí òmùwẹ̀ tí ń na ọwọ́ rẹ̀ jáde láti lúwẹ̀ẹ́. Ọlọ́run yóò mú ìgbéraga wọn wálẹ̀ bó tilẹ̀ jẹ́ pé ìṣeféfé wà ní ọwọ́ wọn.
12 naho harotsa’e ambane o kijoli’o fatratse mitiotiotseo, eka, halama’e; hazevo’e an-tane, toe an-deboke ao.
Òun yóò sì bi gbogbo ògiri gíga alágbára yín lulẹ̀ wọn yóò sì wà nílẹ̀, Òun yóò sì mú wọn wá si ilẹ̀, àní sí erùpẹ̀ lásán.

< Isaia 25 >