< Genesisy 36 >
1 Iretoy ro tarira’ i Esave (i Edòme).
Wọ̀nyí ni ìran Esau, ẹni tí a ń pè ní Edomu.
2 Nangala-baly amo anak’ampela nte-Kanàneo t’i Esave: i Adàe ana’ i Elòne nte-Kìte, i Oholibamà ana’ i Anà ana’ i Tsibòne nte-Kive,
Nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani ni Esau ti fẹ́ àwọn ìyàwó rẹ̀: Adah ọmọbìnrin Eloni ará Hiti àti Oholibama, ọmọbìnrin Ana, ọmọ ọmọ Sibeoni ará Hifi.
3 naho i Bosemàte ana’ Iesmaèle, rahavave’ i Nebaiòte.
Ó sì tún fẹ́ Basemati ọmọ Iṣmaeli arábìnrin Nebaioti.
4 Nisamake i Elifàze amy Esave t’i Adàe; nisamake i Reoèle t’i Bosemate;
Adah bí Elifasi fún Esau, Basemati sì bí Reueli,
5 le nisamake i Elifaze, Ieìse, Ialàme, naho i Kòrahke t’i Oholibamà. Ie ro ana’ i Esave nasama’e an-tane Kanàne ao.
Oholibama pẹ̀lú sì bí Jeuṣi, Jalamu, àti Kora. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ tí Esau bí ní Kenaani.
6 Nendese’ i Esave o vali’eo, o ana-dahi’eo, o anak’ ampela’eo, naho ze hene añ’anjomba’e, naho o añombe’eo, o hare fiandraze’e iabio naho ze fonga vara natonto’e an-tane Kanàne ao vaho nisese mb’an-tane hisitaha’e an-daharan-drahalahi’e Iakòbe añe,
Esau sì mú àwọn aya rẹ̀, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀, àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ àti gbogbo àwọn ará ilé rẹ̀, àwọn ohun ọ̀sìn rẹ̀ àti àwọn ẹran ọ̀sìn mìíràn àti gbogbo ohun ìní mìíràn tí ó ní, ni Kenaani, ó sì kó lọ sí ilẹ̀ mìíràn, jìnà sí ibi tí Jakọbu arákùnrin rẹ̀ wà.
7 amy te loho maro ty fanaña’ iareo roe, tsy haha-fiharo-pimoneñañe; tsy nitsahatse iareo i tane nañialoa’iareoy ty amo hare’ iareoo.
Ohun ìní wọn pọ̀ ju èyí tí àwọn méjèèjì lè máa gbé ní ojú kan lọ. Ilẹ̀ tí wọ́n wà kò le gba àwọn méjèèjì nítorí àwọn ohun ọ̀sìn wọn.
8 Aa le nitoetse am-bohi’ Seire ao t’i Esave; Edome ‘nio t’i Esave.
Báyìí ni Esau (tí a tún mọ̀ sí Edomu) tẹ̀dó sí àwọn orílẹ̀-èdè olókè tí Seiri.
9 Iretoañe ro tarira’ i Esave, rae’ o nte-Edomeo, am-bohi’ Seire ao.
Èyí ni ìran Esau baba àwọn ará Edomu ní àwọn orílẹ̀-èdè olókè Seiri.
10 Ty tahina’ o ana’ i Esaveo le: i Elifaze ana’ i Adàe, vali’ i Esave; i Reoèle, ana’ i Bosmate vali’ i Esave.
Wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ọmọ Esau: Elifasi ọmọ Adah aya Esau àti Reueli, ọmọ Basemati tí í ṣe aya Esau pẹ̀lú.
11 O ana’ i Elifazeo: i Temane, i Omare, i Tsefò, naho i Gatame, vaho i Kenaze.
Àwọn ọmọ Elifasi ni ìwọ̀nyí: Temani, Omari, Sefi, Gatamu, àti Kenasi.
12 (Sakeza’ i Elifaze, ana’ i Esave t’i Timnàe nisamake i Amalek’ amy Elifaze.) Iereo ro ana’ i Adae, vali’ i Esave.
Elifasi ọmọ Esau sì tún ní àlè tí a ń pè ní Timna pẹ̀lú, òun ló bí Amaleki fún un. Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ ọmọ Adah aya Esau.
13 Iretoy ro ana’ i Reoele: i Nàkate, naho i Zèrake, i Samà, vaho i Mizà. Iereo ro ana’ i Bosemate, vali’ i Esave.
Àwọn ọmọ Reueli: Nahati, Sera, Ṣamma àti Missa. Àwọn ni ọmọ ọmọ Basemati aya Esau.
14 Iretoy ro ana’ i Oholibamàe, ana’ i Anà, ana’ i Tsibone, vali’ i Esave: nisamahe’e amy Esave t’Ieose naho Ialame vaho i Korake.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Oholibama ọmọbìnrin Ana ọmọ ọmọ Sibeoni: tí ó bí fún Esau: Jeuṣi, Jalamu àti Kora.
15 Iretoy ro fifokoa’ o ana’ i Esaveo. O ana’ i Elifaze, tañoloñoloña’ i Esaveo: i Temane talè, i Omare talè, i Zefò talè, i Kenaze talè,
Àwọn wọ̀nyí ni olórí nínú àwọn ọmọ Esau: àwọn ọmọ Elifasi, àkọ́bí Esau, Temani, Omari, Sefi, Kenasi,
16 i Korake talè, i Gatame talè, i Amaleke talè; ie o talè boak’amy Elifaze ana’ i Adae an-tane Edomeo.
Kora, Gatamu àti Amaleki. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Elifasi ní Edomu wá, wọ́n jẹ́ ọmọ ọmọ Adah.
17 Iretoy ro ana’ i Reoèle ana’ Esave: i Nakàte talè, i Zeràke talè, i Samà talè, vaho i Mizà talè; ie ro talè boak’ i Reoèle an-tane Edome ao, ana’ i Basemate vali’ i Esave.
Wọ̀nyí sì ni àwọn ọmọ Esau, ọmọ Rueli: Nahati olórí, Sera olórí, Ṣamma olórí, Missa olórí. Àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Reueli jáde ní Edomu. Ọmọ ọmọ Basemati aya Esau ni wọ́n jẹ́.
18 Intoy o ana’ i Oholibamàe, vali’ i Esaveo: t’Ieòse talè, Ialame talè, vaho i Kòrake talè; ie ro talè nasama’ i Oholibamàe, vali’ i Esave naho ana’ i Anà.
Àwọn ọmọ Oholibama aya Esau: Jeuṣi, Jalamu, àti Kora, àwọn wọ̀nyí ló jẹ́ olórí ìdílé tí ó ti ọ̀dọ̀ Oholibama ọmọ Ana, ìyàwó Esau wá.
19 Ie ro ana’ i Esave (i Edome), naho o talè’eo.
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Esau (ti o túmọ̀ sí Edomu). Àwọn wọ̀nyí ni olórí wọn.
20 Intoy o ana’ i Seire nte-Khorý mpimoneñe amy taneio: i Lotane naho i Sòbale naho i Tsibòne naho i Anà,
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Seiri ará Hori tí ó ń gbé ní ilẹ̀ náà: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
21 naho i Disone, naho i E’tsere, vaho i Disane; ie ro talè’ o nte-Khorio, ana’ i Seire an-tane’ Edome ao.
Diṣoni, Eseri, àti Diṣani, àwọn wọ̀nyí olórí ènìyàn Hori, àwọn ọmọ Seiri ni ilẹ̀ Edomu.
22 Le o ana’ i Lotàneo: i Khorý, naho i Hemame vaho i Timnae rahavave’ i Lotane.
Àwọn ọmọ Lotani: Hori àti Homamu: Timna sì ni arábìnrin Lotani.
23 O ana’ i Sòbaleo: i Alvane naho i Manakate, naho i Ebale, i Sefò vaho i Oname.
Àwọn ọmọ Ṣobali: Alifani, Manahati, Ebali, Ṣefo àti Onamu.
24 O ana’ i Tsiboneo: i Aià naho i Anà ie roe; i Anà ty nahatendreke o rano mae am-patrañeo ie niarake o borìke’ i Tsibone rae’eo.
Àwọn ọmọ Sibeoni: Aiah àti Ana. Èyí ni Ana tí ó rí ìsun omi gbígbóná ní inú aginjù bí ó ti ń da àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ Ṣebeoni baba rẹ̀.
25 O ana’ i Anào: i Disone naho i Oholibamàe anak’ ampela’ i Anà.
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Ana: Diṣoni àti Oholibama ọmọbìnrin Ana.
26 O ana’ i Disoneo: i Kemdane, naho i Esbane, naho Iit’rane, vaho i Kerane.
Àwọn ọmọ Diṣoni ni: Hemdani, Eṣbani, Itrani àti Kerani.
27 O ana’ i E’tsereo: i Bilhane, naho i Zaavane, vaho i Akane.
Àwọn ọmọ Eseri: Bilhani, Saafani àti Akani.
28 O ana’ i Disaneo: i Otse naho i Arane.
Àwọn ọmọ Diṣani ni: Usi àti Arani.
29 O talè’ o nte-Khorio: i Lotane talè, i Sobale talè, i Tsibone talè, i Anà talè,
Àwọn wọ̀nyí ni olórí ìdílé Hori: Lotani, Ṣobali, Sibeoni, Ana,
30 i Disone talè, i Etsere talè, i Disane talè; ie ro talè’ o nte-Kkorio; o mpiaolon-tane Seireo.
Diṣoni Eseri, àti Diṣani. Àwọn ni olórí ìdílé àwọn ará Hori gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn ní ilẹ̀ Seiri.
31 Intoy o mpanjaka nifehe an-tane’ Edome ao aolo’ te amam-panjaka nifehe o ana’ Israeleoo.
Àwọn wọ̀nyí ni ọba tí ó jẹ ní Edomu kí ó tó di pé ọba kankan jẹ lórí Israẹli:
32 Nifehe ty rova atao Dinhabà e Edome ao t’i Belà ana’ i Beore.
Bela ọmọ Beori jẹ ní Edomu. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Dinhaba.
33 Nivilasy t’i Belà le nandimbe aze ho mpanjaka t’Iobabe ana’ i Zeràke nte-Botsrà.
Nígbà tí Bela kú, Jobabu ọmọ Sera ti Bosra sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
34 Nivilasy t’Iobabe le nandimbe aze ho mpanjaka t’i Khosàme tan-tane’ o Temanio.
Nígbà tí Jobabu kú, Huṣamu láti ilẹ̀ Temani sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
35 Nivilasy t’i Khosàme, le nandimbe aze ho mpanjaka t’i Hadade ana’ i Bedade, i nahagioke i Midiane a monto’ i Moabey; atao Avite i rova’ey.
Nígbà tí Huṣamu kú, Hadadi ọmọ Bedadi tí ó kọlu Midiani ní ìgbẹ́ Moabu, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Afiti.
36 Nivilasy t’i Hadade, le nandimbe aze ho mpanjaka t’i Samlà nte-Masrekà.
Nígbà tí Hadadi sì kú, Samla láti Masreka, ó sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
37 Nivilasy t’i Samlà, le nandimbe aze ho mpanjaka t’i Saòle nte-Rekhobòte boak’ amy sakay añe.
Samla sì kú, Saulu ti Rehoboti, létí odò sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
38 Nivilasy t’i Saole, le nandimbe aze ho mpanjaka t’i Baal-kanàne ana’ i Akbore.
Nígbà tí Saulu kú, Baali-Hanani ọmọ Akbori jẹ ọba ní ipò rẹ̀.
39 Nivilasy t’i Baal-kanàne ana’ i Akbore, le nandimbe aze ho mpanjaka t’i Hadare; natao Paò i rova’ey; Mehetabèle anak’ ampela i Matrède, anak’ ampela’ i Mezahabe ty vali’e.
Nígbà tí Baali-Hanani ọmọ Akbori kú, Hadadi ni ó jẹ ọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Pau, orúkọ ìyàwó sì ni Mehetabeeli ọmọbìnrin Matiredi, ọmọbìnrin Mesahabu.
40 Zao o tahina’ o talè’ i Esave amo hasavereña’eo naho o rova’eoo; ty tahina’ iareo: i Timnà talè, i Alvà talè, Ietète talè,
Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn baálẹ̀ tí ó ti ọ̀dọ̀ Esau jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí: baálẹ̀ Timna, baálẹ̀ Alfa, baálẹ̀ Jeteti.
41 i Aholibamae talè, i Elà talè, i Pinone talè,
Baálẹ̀ Oholibama, baálẹ̀ Ela, baálẹ̀ Pinoni,
42 i Kenaze talè, i Temane talè, i Mibtsare talè,
baálẹ̀ Kenasi, baálẹ̀ Temani, baálẹ̀ Mibsari,
43 i Magdiele talè, Irame talè; ie ro mpiaolo’ i Edome ty amo akiba’ iareo an-tane fanaña’ iareoo. (rae’ o nte-Edomeo t’i Esave)
Magdieli, àti Iramu. Àwọn wọ̀nyí ni baálẹ̀ Edomu, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà. Èyí ni Esau baba àwọn ará Edomu.