< Ezra 6 >

1 Aa le namantoke t’i Dariavese vaho nihotsohotsoeñe i anjombam-pañajan-taratasiy, am-panontonam-bara e Bavele ao.
Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
2 Le nitendrek’ amy anjomba e Akmetà ao, amy faritane’ o nte-Madaioy ty boke-peleke, le sinokitse ama’e ao ty hoe: Ty talily:
A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
3 Amy taom-baloha’ i Korese, mpanjakay, le nanao tsey t’i Korese mpanjaka: I anjomban’ Añahare e Ierosala­i­mey, te hamboareñe i anjombay, i fañengà’ iareo soroñey naho añoreñañe fatratse o mananta’eo; ty haabo’e, kiho enempolo naho ty ampohe’e, kiho enempolo;
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
4 naho firiritam-bato jabajaba, telo naho fidadañam-bodan-katae vao, le ho tolo­rañe boak’ añ’ anjomba’ i mpanjakay ty drala’e;
pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
5 le ampolieñe ka o fanake volamena naho volafotin’ anjomban’ Añahare nakare’ i Nebokad­netsare boak’ añ’ an­jomba’e e Ierosalaime ao naho nendese’e mb’e Bavele mb’eoo; hahereñe, songa an-toe’e añ’ anjomba e Ierosalaime vaho hapok’ amy anjom­ban’ Añaharey.
Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
6 Ie amy zao, ry Tate­nay mpifelek’ alafe’ i Sakay naho i Setar-botsenay naho o mpiama’ areo nte Afaresake alafe’ i Sakaio, ihalaviro;
Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
7 apoho hanoeñe i fitoloñañe amy anjomban’ Añahareiy; le angao handranjy i anjomban’ Añaharey an-toe’e eo ty mpifehe o nte-Iehodao naho o mpiaolo’ Iehodao.
Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
8 Mbore tseizeko ty hanoa’ areo amo mpiaolo’ o nte-Iehoda mpamboatse i anjomban’ Añahareioo; te hatolotse am-pahimbañañe boak’ amo varam-panjaka amy haba alafe’ i Sakaio am’ indaty rey ze drala paiae’e, vaho tsy ho sebañeñe.
Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
9 Le ze paia’ iareo, amo baniao naho o añondrilahio naho o vik’ añondrio, hisoroñañe amy Andrianañaharen-dikerañey; vare-bolè, sira, divay naho menake. Le ze saontsi’ o mpisoroñe e Ierosalaimeo ty amahana’o aze boak’ andro boak’ andro vaho tsy hilesa;
Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
10 hañengàñe soroñe marifondrifoñe amy Andrianañaharen-dindiñey naho ihalaliañe ty havelo’ i mpanjakay naho o anadahi’eo.
Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
11 Tovoñako ty hoe te ze mañova o entañe zao ro hañakarañe boda amy anjomba’ey, le honjoñen-dre hapitek’ ama’e; vaho hanoeñe votrim-porompotse i traño’ey;
Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
12 vaho ehe te harotsan’ Añahare nampimoneñe ty tahina’e ao ze mpanjaka ndra ondaty te hañity fitàñe hañova izay, hampianto i anjomban’ Añahare e Ierosalaimey. Izaho Dariavese ty mitsey: ee t’ie ho henefañe masìka.
Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
13 Aa le nihavatse nitoloñe t’i Tatenay, mpifelek’ alafe’ i Sakay naho i Setar-botsenay naho o mpiama’eo ty amy nampihitrife’ i Dariavese mpanjakay.
Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
14 Le nandranjy naho niraorao o mpiaolo-nte-Iehodao ty amy fitokia’ i Kagaý mpitoky naho i Zekarià ana’ Idòy. Ie namboatse iereo ro nahafonitse i nandilian’ Añahare’ Israeley naho nitseize’ i Korese naho i Dariavese naho i Artaksastà mpanjaka’ i Parase rey.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
15 Le nifonitse amy andro fahatelo’ i volan-Kiahiaiy i anjombay, an-taom-paha-ene’ i Dariavese, mpanjakay.
A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
16 Le nitana’ o ana’ Israeleo naho o mpisoroñeo naho o nte-Levio vaho ty ila’ o anam-pandrohizañeo am-pirebehañe ty fañorizañe i anjomban’ Añaharey,
Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
17 ie nañenga añombelahy zato naho añondri-lahy roanjato naho vik’ añondry efa-jato amy fañorizañe i anjomban’ Añahareiy; le oselahy folo-ro’ amby ho engan-kakeo’ Israele iaby, ty ami’ty ia’ i fifokoa’ Israele rey.
Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
18 Le nalahatse am-pirimboñañe o mpisoroñeo naho o nte-Levio, songa am-piosoña’e hitoroñe an’ Andrianañahare e Ierosalaime ao; ty amy sinokitse amy boke’ i Moseiy.
Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
19 Le nitana’ o anam-pandrohizañeo amy andro faha-folo-efats’ ambi’ i volam-baloha’eiy i Fihelañ’ Amboney.
Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
20 Le nitrao-pañeferañe o mpisoroñeo naho o nte-Levio; songa nalio; le linenta’ iareo i fihelañ’ amboney ho amo anam-pandrohizañe iabio naho o mpisoroñe roahalahi’ iareoo naho o vata’ iareoo.
Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
21 Le songa nikama o ana’ Israele nimpoly boak’ am-pandrohizañeo naho o nivìke ho am’ iereo boak’ ami’ty haleora’ o kilakila’ ondati’ i taneio, hipay Iehovà Andrianañahare’ Israele,
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
22 naho nitana’ iareo an-kaehake fito andro i sabadida-mofo-tsi-aman-dali­vaiy; amy te nampinembanembañ’ iareo t’Iehovà vaho nampitolihe’e am’ iereo ty arofo’ i mpanjaka’ i Asorey; nampaozatse ty fità’ iareo amy fitoloñañe añ’ anjomban’ Añahare, Andrianañahare’ Israeley.
Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.

< Ezra 6 >