< Ezekiela 6 >
1 Le niheo amako ty tsara’ Iehovà nanao ty hoe:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá wí pé,
2 O ana’ ondatio, ampitoliho amo vohi’ Israeleo ty tarehe’o naho itokio,
“Ọmọ ènìyàn, dojúkọ àwọn òkè Israẹli; kí o sì sọtẹ́lẹ̀ lòdì sí wọn
3 ami’ty hoe: Ry vohi’ Israeleo, tsanoño ty tsara’ Iehovà Talè: Hoe t’Iehovà Talè amo vohitseo naho o haboañeo, o torahañeo naho o vava-taneo; Inao! Izaho, toe Izaho, ty hinday fibara ama’ areo vaho harotsako o toets’abo areoo.
wí pé, ‘Ẹ̀yin òkè Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè. Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí sí ẹ̀yin òkè ńlá àti àwọn òkè kéékèèké, sí àwọn odò ṣíṣàn àti sí àfonífojì, èmi yóò mú idà wa sórí yín, èmí yóò sì pa ibi gíga yín run.
4 Hangoakoake o kitreli’ areoo, naho ho foy o fañemboha’ areoo, vaho havokovokoko ambane eo o zinamañeo añatrefa’ o samposampo’ areoo.
Èmi yóò wó pẹpẹ yín lulẹ̀, èmi yóò sì fọ́ pẹpẹ tùràrí yín túútúú; èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn yín síwájú àwọn òrìṣà wọn.
5 Le ho rohoteko aolo’ o samposampo’eo ty lolo’ o ana’ Israeleo; vaho hampivarakaiheko añ’ariari’ o kitreli’ areoo o taola’ areoo.
Èmi yóò tẹ́ òkú àwọn ará Israẹli síwájú òrìṣà wọn, èmi yóò sì fọ́n egungun wọn yí pẹpẹ wọn ká.
6 Ho fonga koromaheñe o rova an-toe-pimoneña’ areoo, naho songa ho koaheñe o haboañeo; soa te ho voravoraeñe naho farieñe o kitreli’ areoo, naho ho hene pozaheñe o samposampo’ areoo le hijihetse, naho sindre ho firaeñe ze fañemboha’ areo vaho ho faopaoheñe iaby o fitoloña’ areoo.
Gbogbo ibi tí ẹ ń gbé àti àwọn ibi gíga yín ni yóò di píparun, gbogbo pẹpẹ yín ni yóò di ahoro, àwọn òrìṣà yín yóò di fífọ́ túútúú, àwọn pẹpẹ tùràrí yín ni a ó gé lulẹ̀, gbogbo iṣẹ́ yín yóò parẹ́.
7 Hikorovok’ am-po’o ao o binaibaio, haharendreha’ areo te Izaho Iehovà.
Àwọn ènìyàn yín yóò ṣubú láàrín yín, ẹ ó sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
8 Fe apoko ty sehanga’e, soa te hadoke ho anahareo ze nahapoliotse amy fibaray amo fifeheañeo, ie avarakaheñe amo taneo.
“‘Ṣùgbọ́n èmi yóò dá àwọn kan sí nítorí pé díẹ̀ nínú yín ni yóò bọ́ lọ́wọ́ idà, nígbà tí a bá fọ́n yín ká sí gbogbo ilẹ̀ àti orílẹ̀-èdè.
9 Le hahatiahy ahy o nahafipoliotse mb’amo kilakila’ ndatioo, amy naneseañe iereo mb’ am-pandrohizañe añey, amy te nahafikoretse ahy ty hakarapiloan’ arofo’ iareo, ie nieng’ ahy, naho ty fihaino’ iareo mañarapilo mb’amo samposampoo; le nampalaim-bintañe ahy am’ iereo ze haratiañe nanoeñe amo halòtsere’ iareo iabio.
Àwọn ti ó bọ́ nínú yin yóò sì rántí mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè níbi tí wọn yóò dìwọ́n ní ìgbèkùn lọ, nítorí wọ́n yóò máa rántí mi bí wọ́n ti bà mí lọ́kàn jẹ́ nípa àgbèrè wọn, tí ó yà wọ́n kúrò lọ́dọ̀ mi àti nípa ojú wọn tí ó ṣàfẹ́rí àwọn òrìṣà. Wọn yóò sì ṣú ara wọn nítorí ìwà ibi tí wọ́n ti hù nípa gbogbo ìríra wọn.
10 Le ho fohi’ iareo te Izaho Iehovà; te tsy ami’ty tsy vente’e ty nivolañako te hanoeko o hankàñe zao.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; àti pé kì í ṣe lásán ni mo ń lérí pé èmi yóò mú ìdààmú bá wọn.
11 Aa hoe ty nafè’ Iehovà Talè: Mamofoha fitàñe, mandialia am-pandia’o, le ano ty hoe: Hoy abey! o halò-tsere’ i anjomba’ Israeleo, ie hampikorovohe’ ty fibara naho ty hasalikoañe vaho ty angorosy.
“‘Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí, Pàtẹ́wọ́ kí o tún fẹsẹ̀ janlẹ̀, kí o wá kígbe síta pé, “Ó ṣe!” Ilé Israẹli yóò ṣubú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn nítorí gbogbo ìwà ìríra búburú tí wọ́n hù. Wọn yóò ṣubú nípa idà àti ìyàn.
12 Hampivetrahe’ ty angorosy o lavitseo naho ho koromahem-pibara o marineo; le hampihomahe’ ty mosare o honka’e arikoboñeñeo; izay ty hampanintsiñe ty fiforoforoako.
Ẹni tó wà lókèèrè yóò kú pẹ̀lú àjàkálẹ̀-ààrùn, àti ẹni tó wà nítòsí yóò ṣubú pẹ̀lú idà, ìyàn ni yóò pa ẹni tó bá ṣẹ́kù sílẹ̀. Báyìí ni èmi yóò ṣe mú ìbínú gbígbóná mi wá sórí wọn.
13 Le ho fohi’ areo te Izaho Iehovà, ie mifitafita am-poto’ o samposampo’eo ondati’ iareo zinamañeo, ambone’ ze hene tamboho eo, an-dengo’ ze vohitse iaby, naho ambane’ ze hatae mandrevake vaho ambane’ ze kile mangonkòñe—o toetse nibanabanae’ iareo emboke marifondrifoñe amo samposampo’eoo.
Wọn yóò sì mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa, nígbà tí òkú àwọn ènìyàn wọn bá wà níbẹ̀ láàrín òrìṣà wọn yí pẹpẹ wọn ká, lórí àwọn òkè gíga gbogbo, àti lórí góńgó òkè àti lábẹ́ igi tútù àti lábẹ́ igi óákù, níbi tí wọ́n ti ń fi tùràrí olóòórùn dídùn rú ẹbọ sí gbogbo òrìṣà wọn.
14 Le hatorakitsiko am’iereo ty sirako, hanoeko hoake i taney, mandikoatse i fatram-bey mb’e Diblày añey, amy ze hene fitobea’ iareo; vaho ho fohi’ iareo te Izaho Iehovà.
Èmi yóò na ọwọ́ mi jáde sí wọn láti mú kí ilẹ̀ náà ṣòfò, kí ó sì dahoro dé aṣálẹ̀ ìhà Dibila—ní gbogbo ibùgbé wọn. Nígbà náà ni wọn yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.’”