< Ezekiela 33 >

1 Niheo amako ty tsara’ Iehovà manao ty hoe:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
2 O ana’ ondatio, misaontsia amo ana’ ondati’oo vaho ano ty hoe: Naho endesako fibara i taney, naho manga­lake ondaty boak’ amo efe’eo, ondati’ i taney, naho hajadoko ho mpijilo’ iareo;
“Ọmọ ènìyàn sọ̀rọ̀ sí àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ kí ó sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí mo bá fi idà kọlu ilẹ̀ kan, tí àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà yan ọ̀kan lára àwọn ọkùnrin wọn láti jẹ́ alóre wọn,
3 le ie oni’e te miheo mb’amy taney mb’eo i fibaray, ho tiofe’e i antsivay hitalily am’ondatio,
tí ó sì rí i pé idà ń bọ̀ lórí ilẹ̀ náà, tí ó sì fọn ìpè láti kìlọ̀ fún àwọn ènìyàn,
4 le ndra ia ia mahajanjiñe ty fipopò’ i antsivay fe tsy mañaoñe i hatahata’ey; vaho maniotse aze añe ty fitorotosi’ i fibaray, le ho ama’e ty lio’e.
nígbà náà tí ẹnikẹ́ni bá gbọ́ ìpè ṣùgbọ́n tí kò gbọ́ ìkìlọ̀, tí idà náà wá tí ó sì gba ẹ̀mí rẹ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà lórí ara rẹ̀.
5 Jinanji’e ty feo i antsivay fe tsy hinao’e i hatahatay; ho ama’e i lio’ey, ie ho nandrombak’ay te hinao’e i hatahatay.
Nítorí tí ó gbọ́ ohùn ìpè ṣùgbọ́n tí kò sì gbọ́ ìkìlọ̀, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí ara rẹ̀. Tí ó bá gbọ́ ìkìlọ̀, òun ìbá ti gba ara rẹ̀ là.
6 Aa naho oni’ i mpijiloy te miheo mb’eo i fibaray fe tsy tiofe’e i antsivay le tsy hatahataeñe ondatio, aa naho asiom-pibara t’indaty boak’am’ iereo ao, le hendeseñe ty amo tahi’eo indatiy; fe ho paiako am-pità’ i mpijiloy ty lio’e.
Ṣùgbọ́n bí alóre bá rí idà tí o ń bọ̀, tí kò sì fọn ìpè láti ki àwọn ènìyàn nílọ̀, tí idà náà wá, tí ó sì gba ẹ̀mí ọ̀kan nínú wọn, a yóò mú ọkùnrin náà lọ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n èmi yóò béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ̀.’
7 Ihe, ry ana’ ondatio, ty najadoko ho mpijilo i anjomba’ Israeley; aa le ho janjiñe’o ty taroñem-bavako vaho ho hatahatae’o ty amako iereo.
“Ọmọ ènìyàn, èmi fi ọ ṣe alóre fún ilé Israẹli; nítorí náà gbọ́ ọ̀rọ̀ tí mo sọ, kí o sì fún wọn ni ìkìlọ̀ láti ọ̀dọ̀ mi.
8 Aa naho volañeko i lo-tserekey ty hoe, O ty lo-tsereke tia, toe havetrake irehe; aa naho tsy hatahatae’o i lo-tserekey ty amo sata-rati’eo, le hivetrake amo hakeo’eo re, fe ho paiako am-pità’o ty lio’e.
Nígbà ti mo bá sọ fún ẹni búburú pé, ‘A! Ẹni búburú, ìwọ yóò kú dandan,’ ti ìwọ kò sì sọ̀rọ̀ síta láti yí i lọ́kàn padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ẹni búburú náà yóò kú nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, èmi yóò sì béèrè ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ lọ́wọ́ rẹ.
9 Aa naho talilie’o i lo-tserekey o sata-rati’ eo, hibalintoa’e, fe tsy ambohoa’e i sata’ey, le hikenkañe amo tahi’eo, fe ho rinomba’o ka ty fiai’o.
Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá kìlọ̀ fún ẹni búburú láti yí padà kúrò ni ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, tí òun kò sì ṣe bẹ́ẹ̀, òun yóò kú nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ ti gba ọkàn rẹ̀ là.
10 Aa ihe ry ana’ondatio, misaontsia amy Anjomba’ Israeley: Le ano ty hoe: Hoe nahareo: Amantika o fiolàñe naho tahin-tikañeo, le fa mampinike an-tika. Aa vaho akore arè ty hiveloman-tika?
“Ọmọ ènìyàn; sọ fún ilé Israẹli, ‘Èyí yìí ní ìwọ sọ: “Àwọn ìrékọjá àti ẹ̀ṣẹ̀ wa tẹ orí wa ba, àwa sì ń ṣòfò dànù nítorí wọn. Bá wó wa ni a ṣe lè yè?”’
11 Ano ty hoe am’iereo: Kanao velon-dRaho, hoe t’Iehovà Talè, Tsy mipay ty fikoromaha’ o lo-tserekeo iraho, fa t’ie hibalintoa amo sata’eo ho veloñe; mitoliha arè, mibalintoaña amo sata-rati’ areoo, fa ino ty hihomaha’ areo ry anjomba’ Israeleo?
Sọ fún wọn pé, ‘Níwọ́n ìgbà tí mo wà láààyè ni Olúwa Olódùmarè wí, èmi kò ní inú dídùn sí ikú ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, kí wọ̀nyí padà kúrò ní ọ̀nà wọn gbogbo kì wọn kì ó sì yè. Yí! Yípadà kúrò ni ọ̀nà búburú gbogbo! Kí ló dé tí ìwọ yóò kú ẹ̀yin ènìyàn Israẹli?’
12 Tovoño ty hoe, Ry ana’ ondatio, ano ty hoe o ana’ ondati’oo; Tsy haharombake ty vaño ty havañona’e amy andro iolà’ey; naho tsy hahatsikapy ty lo-tsereke i halò-tsere’ey amy andro ifotera’ey; vaho tsy hahaveloñe i vañoñey ty havañona’e amy andro andilara’ey.
“Nítorí náà, ọmọ ènìyàn, sọ fún àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ, ‘Ìṣòdodo ti olódodo ènìyàn kì yóò gbà á nígbà tí òun bá ṣe àìgbọ́ràn, ìwà búburú ènìyàn búburú kì yóò mú kí o ṣubú nígbà tí ó bá yí padà kúrò nínú rẹ̀. Bí olódodo ènìyàn bá ṣẹ̀, a kò ni jẹ́ kí ó yè nítorí òdodo rẹ̀ ti tẹ́lẹ̀.’
13 Ie anoeko ty hoe i vañoñey, Toe ho velon-drehe; fa iatoa’e i havañona’ey vaho mandilatse, le tsy ho tiahy i hamarentane’ey; fa i hakeo nanoe’ey, ty hihomaha’e.
Bí mo bá sọ fún olódodo ènìyàn pé òun yóò yè, ṣùgbọ́n nígbà náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé òdodo rẹ̀ tí ó sì ṣe búburú, a kò ní rántí nǹkan kan nínú iṣẹ́ òdodo tí o ti ṣe sẹ́yìn; òun yóò kú nítorí búburú tí ó ṣe.
14 Aa naho hataoko ty hoe i lo-tserekey: Tsy mete tsy hikoromake irehe; le ie mibalintoa amo tahi’eo, naho manao ty fahiti’e naho ty havantañañe,
Bí mo bá sọ fún ènìyàn búburú pé, ‘Ìwọ yóò kú dandan,’ ṣùgbọ́n tí ó bá yípadà kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ti o sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí o yẹ.
15 naho avaha’ i lo-tserekey i natsoa’ey, naho ampolie’e i nikamere’ey naho añaveloa’e o fañèn-kaveloñeo vaho tsy mandilatse ka, le toe ho velon-dre, fa tsy hikoromake.
Tí ó bá mu ògo padà, tí o sì da ohun tí o ti jí gbé padà, tí ó sì tẹ̀lé òfin tí ó ń fún ni ní ìyè, tí kò sì ṣe búburú, òun yóò yè dandan; òun kì yóò kú.
16 Leo raik’ amo hakeo nanoe’eo tsy hivolili­añe. Fa nanoe’e i havañonañey naho i havantañañey, le ho velon-dre.
A kò ní rántí ọ̀kan nínú ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ti dá. Ó ti ṣe èyí tí ó tọ àti èyí tí o yẹ; òun yóò sì yè dájúdájú.
17 Fa hoe o ana-dahi’ ondati’oo, Tsy mahity ty sata’ i Talè; toe i sata’ iareoy ty tsy mahity.
“Síbẹ̀ àwọn ènìyàn ilẹ̀ rẹ sọ pé, ‘Ọ̀nà Olúwa kò tọ́.’ Ṣùgbọ́n ọ̀nà tí àwọn ní ó tọ́.
18 Naho miamboho amy havañona’ey ty vañoñe naho manao hakeo, le hivetrake.
Bí olódodo ènìyàn ba yípadà kúrò nínú òdodo rẹ̀, tí o sì ṣe búburú, òun yóò kú nítorí rẹ̀.
19 Naho mibalintoa amo sata-rati’eo ty lo-tsereke, vaho manao ty havantañañe naho ty havañonañe; le ho velon-dre.
Bí ènìyàn búburú bá yípadà kúrò nínú búburú rẹ̀, tí ó sì ṣe èyí tí ó tọ́ àti èyí tí ó yẹ, òun yóò yè nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀.
20 Fa anoe’ areo ty hoe, Tsy vantañe ty lala’ i Talè. Ry anjomba’ Israele, Ho zakaeko nahareo, songa ty amo sata’eo.
Síbẹ̀, ilé Israẹli ìwọ wí pé, ‘Ọ̀nà Olúwa ki i ṣe òtítọ́.’ Ṣùgbọ́n èmi yóò ṣe ìdájọ́ ẹnìkọ̀ọ̀kan gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ ṣe rí.”
21 Aa amy andro faha-lime’ i volam-paha folo’ i taom-paha-folo-ro’ ambi’ i fandrohiza’aiy, le niheo amako ty nahapolititse am’ Ierosalaime, le nanoa’e ty hoe, Fa rotsake i rovay.
Ní ọjọ́ karùn-ún oṣù kẹwàá, ọdún kejìlá ìkólọ wa, ọkùnrin kan tí ó sá kúrò ni Jerusalẹmu wá sọ́dọ̀ mi, ó sì wí pé, “Ìlú ńlá náà ti ṣubú!”
22 Toe tamako ty fità’ Iehovà amy haleñe aolo’ ty nivotraha’ i nipolititsey, nanokake ty vavako aolo’ t’ie nipok’ amako amy maraiñey; aa le nisokake ty vavako le tsy nimoañe ka.
Ní ìrọ̀lẹ́ ọjọ́ tí ó ku ọ̀la tí ẹni tí ó sálọ náà yóò dé, ọwọ́ Olúwa sì níbẹ̀ lára mi, o sì ya ẹnu mi ki ọkùnrin náà tó wá sọ́dọ̀ mi ní òwúrọ̀. Ẹnu mí sì ṣí, èmi kò sì yadi mọ́.
23 Niheo amako ty tsara’ Iehovà nanao ty hoe:
Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
24 O ana’ ondatio, hoe ty saontsi’ ondaty mimoneñe an-dratraratra’ Israele ao, Raike t’i Avrahame, le nifanaña’e i taney, fe maro tikañe, vaho natolotse an-tika ho fanañañe i taney.
“Ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn tí ó ń gbé nínú ìparun ní ilẹ̀ Israẹli ń wí pé, ‘Abrahamu jẹ́ ọkùnrin kan, síbẹ̀ o gba ilẹ̀ ìní náà. Ṣùgbọ́n àwa pọ̀, lóòótọ́ a ti fi ilẹ̀ náà fún wa gẹ́gẹ́ bí ìní wa.’
25 Aa le isaontsio ty hoe, Hoe ty nafè’ Iehovà Talè; Fikamà’ areo ty raha aman-dio naho fiandrà’ areo o samposampo’ areoo, vaho mampiori-dio; aa ho fanaña’ areo hao i taney?
Nítorí náà, sọ fún wọn pé, ‘Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Níwọ́n ìgbà tí ẹ̀yin jẹ ẹran pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀ ni inú rẹ̀, tí ẹ̀yin sì wó àwọn ère yín, tí ẹ sì ta ẹ̀jẹ̀ sílẹ̀, ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?
26 Ie miato amy fibara’ areoy, mikitro-draha raty, vaho songa mandeotse ty tañanjomban-drañe’e; aa vaho ho hanaña’ areo hao i taney?
Ẹ̀yin gbẹ́kẹ̀lé idà yín, ẹ̀yin ṣe nǹkan ìríra, ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú yín ba á obìnrin aládùúgbò rẹ̀ jẹ́. Ẹ̀yin yóò ha gba ilẹ̀ náà?’
27 Isaon­tsio ty hoe: Inao ty nafè’ Iehovà Talè: Kanao velon-dRaho, toe ho tsingoroem-pibara o an-dratraratrao, le ho faha­nako o bibio hampibo­tseke ty an-kivok’ ao, naho hampive­trahe’ ty angorosy o an-kijoly vaho an-dakatoo.
“Sọ èyí fún wọn: ‘Èyí yìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Bí mo ti wà láààyè, àwọn tí ó kúrò nínú ìparun yóò ti ipa idà ṣubú, àwọn tí ẹranko búburú yóò pajẹ, àwọn tí ó sì wà ní ilé ìṣọ́ àti inú ihò òkúta ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò pa.
28 Fa hanoeko ratraratra naho bangìñe i taney, le hijihetse ty firengevoha’ i haozara’ey; le ho koake ty vohi’ Israele, tsy ho amam-piranga.
Èmi yóò mú kí ilẹ̀ náà di ahoro, ọ̀ṣọ́ ńlá agbára rẹ̀ kì yóò sí mọ́, àwọn òkè Israẹli yóò sì di ahoro, tí ẹnikẹ́ni kò ní le là á kọjá.
29 Le ho fohi’ iereo te Izaho Iehovà, naha-bangiñe naho ratraratra i taney ty amo haloloañe nanoe’ iereoo.
Nígbà náà, wọn yóò mọ̀ pé èmi ni Olúwa, nígbà tí mo bá mú ilẹ̀ náà di ahoro nítorí gbogbo ohun ìríra tí wọ́n ti ṣe.’
30 Aa ihe, ry ana’ ondatio, Mbe mifosa azo marine’ o kijolio naho an-dala’ o anjombao o ana-dahi’ ondati’oo, sambe mivesoveso an-drahalahi’e ty hoe: Antao ito hijanjiñe ty tsara aboak’ Iehovà.
“Ní tìrẹ, ọmọ ènìyàn, àwọn ènìyàn ìlú n sọ̀rọ̀ nípa rẹ ní ẹ̀gbẹ́ ògiri àti ní ẹnu-ọ̀nà ilé wọn, wọ́n ń sọ sí ara wọn wí pé, ‘Ẹ wá gbọ́ iṣẹ́ ti a ran láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá.’
31 Aa le hiropak’ ama’o hoe fi­rimboña’ ondaty hiatrek’ azo ondatikoo naho ho janjiñe’ iereo o saontsi’oo, fe tsy hanoe’ iereo; amy te mitsi­riry avao o falie’eo, naho maño­rike ty fitsikiriha’ iareo o tro’eo.
Àwọn ènìyàn mi wá sọ́dọ̀ rẹ, gẹ́gẹ́ bí wọn ṣe ń ṣe, wọn sì jókòó níwájú rẹ láti fetísí ọ̀rọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n wọn kò mú wá sí ìṣe. Ẹnu wọn ni wọ́n fi n sọ̀rọ̀ ìfọkànsìn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn ní ìwọra èrè tí kò tọ́.
32 Ingo manahake te mpibekom-pikokoañe am’ iereo irehe, talango-am-peo, mahafititike marovany; toe tsendreñe’ iareo o saontsi’oo, fe tsy hanoe’ iereo.
Nítòótọ́ lójú wọn, ìwọ jẹ́ ẹni kan tí ó ń kọrin ìfẹ́ pẹ̀lú ohun dídára àti ohun èlò orin kíkọ, nítorí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ ṣùgbọ́n wọn kò mu wá sí ìṣe.
33 Aa ie mifetsake izay; (heheke te ho tondroke), le ho fohi’ iereo te tañivo’ iareo ao ty mpitoky.
“Nígbà tí gbogbo ìwọ̀nyí bá ṣẹ tí yóò sì ṣẹ dandan, nígbà náà wọn yóò mọ̀ pé wòlíì kan ti wa láàrín wọn rí.”

< Ezekiela 33 >