< Eksodosy 5 >
1 Tampetse izay le niheo mb’amy Parò mb’eo t’i Mosè naho i Aharone, nanao ty hoe, Hoe t’Iehovà Andrianañahare’ Israele: Angao hañavelo mb’eo ondatikoo hanoe’ iereo sabadidak’ amako am-patrambey añe.
Lẹ́yìn náà ni Mose àti Aaroni tọ Farao lọ, wọ́n sì wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ, ‘Jẹ́ kí àwọn ènìyàn mi kí ó lọ, kí wọn kí ó lè ṣe àjọ mi ní ijù.’”
2 Aa hoe t’i Parò, Ia ze o Iehovà zao te ho haoñeko ty feo’e hampiavotako Israele. Amoeako ze o Iehovà zao vaho tsy hapoko hionjoñe ka t’Israele.
Farao dáhùn wí pé, “Ta ni Olúwa, tí èmi yóò fi gbọ́rọ̀ sí i lẹ́nu, tí èmi yóò fi jẹ́ kí Israẹli ó lọ? Èmi kò mọ Olúwa, èmi kò sì ní jẹ́ kí Israẹli ó lọ.”
3 Le hoe iereo, Nifañaoñe ama’ay t’i Andrianañahare’ o nte-Evreo; aa le hañavelo lia telo andro mb’ ampatrañe añe zahay hisoroñe am’ Iehovà Andrianañahare’ay, tsy mone hampiambotraha’e am’ angorosy ndra fibara.
Lẹ́yìn náà ni wọ́n wí pé, “Ọlọ́run àwọn Heberu tí pàdé wa. Ní ìsinsin yìí, jẹ́ kí a lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú aginjù láti rú ẹbọ sí Olúwa Ọlọ́run wa, kí Ó má ba á fi àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí idà bá wa jà.”
4 Fe hoe ty mpanjaka’ i Mitsraime am’ iereo. O Mosè naho Aharone, inom-bao ty hampisitahañe ondatio amo fitoloña’eo? Mimpolia amo fijinia’areoo!
Ṣùgbọ́n ọba Ejibiti sọ wí pé, “Mose àti Aaroni, èéṣe ti ẹ̀yin fi mú àwọn ènìyàn kúrò lẹ́nu iṣẹ́ wọn? Ẹ padà sẹ́nu iṣẹ́ yín.”
5 Tinovo’ i Parò ty hoe, Ingo te maro t’indaty an-tane ao henaneo vaho ipaia’ areo hitroatse tsy hitoloñe!
Nígbà náà ni Farao sọ pé, “Ẹ wò ó àwọn ènìyàn náà ti pọ̀ sí ì nílẹ̀ yìí ní ìsinsin yìí, ẹ̀yin sì ń dá wọn dúró láti máa bá iṣẹ́ lọ.”
6 Aa le linili’ i Parò amy andro zay amo mpanao bozizi’ iareoo naho amo mpisari’ iareoo, ty hoe:
Ní ọjọ́ yìí kan náà ni Farao pàṣẹ fún àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn ti ń ṣe alábojútó iṣẹ́ lórí àwọn ènìyàn.
7 Tsy hatolotse ahetse ka ondatio fe hamboatse birike mira amy teoy; angao hatonto’ iareo ze ahetse paiaeñe.
“Ẹ̀yin kò ní láti pèsè koríko gbígbẹ fún bíríkì sísun mọ́ fún àwọn ènìyàn wọ̀nyí; ẹ jẹ́ kí wọn máa wá koríko gbígbẹ fún ara wọn.
8 Le ampano’ areo birike mira amy nanoeñe taoloy, tsy haketrake, amy t’ie votro, izay ty mampitoreo iareo ami’ty hoe: Apoho hiavotse añe hisoroñe aman’ Añahare’ay.
Ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn ó ṣe iye bíríkì kan náà bí ì ti àtẹ̀yìnwá, kí ẹ má ṣe dín iye rẹ̀ kú. Ọ̀lẹ ni wọ́n, ìwà ọ̀lẹ yìí náà ló mú wọn pariwo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Ọlọ́run wa.’
9 Anovoño asa ondatio, hifanehafa’ iareo tsy hitsanom-bolam-bande.
Ẹ mú iṣẹ́ náà le fún wọn, kí wọn bá a le è tẹramọ́ iṣẹ́ wọn, ẹ má fi ààyè gba irọ́ wọn.”
10 Aa le niakatse mb’eo o mpanao bozizio naho o mpisari’ ondatioo, nanao ty hoe am’ondatio, Hoe t’i Parò, Tsy hitolorako ahetse.
Ní ìgbà náà ni àwọn akóniṣiṣẹ́ àti àwọn tí ń ṣe alábojútó iṣẹ́ jáde tọ̀ wọ́n lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn náà pé, “Èyí ni ohun tí Farao sọ, ‘Èmi kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ mọ́.
11 Akia, atontono ahetse amy ze hahatendreha’ areo, fe tsy haketrake ty fitoloña’ areo.
Ẹ lọ wá koríko gbígbẹ ni ibi tí ẹ bá ti lè rí i, ṣùgbọ́n iṣẹ́ yín kí yóò dínkù.’”
12 Aa le fonga niparaitak’ an-tane Mitsraime ao ondatio nanontone tain-ava hasolo i bokay.
Gbogbo wọn sí fọ́n káàkiri ni ilẹ̀ Ejibiti láti sa ìdì koríko tí wọn yóò lò bí ì koríko gbígbẹ fún sísun bíríkì.
13 Tinaentae’ o mpanao bozizio ka ami’ty hoe, Henefo ty fitoloña’ areo lomoñandro ho mira amy fasiañ’ ahetse teoy.
Àwọn akóniṣiṣẹ́ sì ń ni wọ́n lára, wọ́n wí pé, “Ẹ parí iṣẹ́ tí ẹ ni láti ṣe fún ọjọ́ kan bí ìgbà ti a ń fún un yin ní koríko gbígbẹ.”
14 Finofoke ka o talèm-pitoloña’ o ana’ Israele najado’ o mpanao bozizi’ i Paròo am’ iareoo, ami’ty hoe, Akore te tsy nihenefa’ areo anindroany naho omale ty lili’areo amo birike manahake te taoloo?
Àwọn alábojútó iṣẹ́ tí àwọn akóniṣiṣẹ́ Farao yàn lára ọmọ Israẹli ni wọn ń lù, tí wọn sì ń béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin kò ṣe iye bíríkì ti ẹ̀yin ń ṣe ní àná ní òní bí i tí àtẹ̀yìnwá?”
15 Aa le niheo mb’amy Parò mb’eo o talè ana’ Israeleo nitoreo ty hoe, Ino ty anoa’o hoe zao o mpitoro’oo?
Nígbà náà ni àwọn alábojútó iṣẹ́ tí a yàn lára àwọn ọmọ Israẹli tọ Farao lọ láti lọ bẹ̀bẹ̀ pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ọwọ́ líle mú àwa ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ báyìí?
16 Tsy ho tolorañe boka o mpitoro’oo, fa hoe iereo ama’ay, Mañamboara birike! Hehe te finofoke zahay vaho manao hakeo ondati’oo.
Wọn kò fún àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ wọn sọ fún wa pé, ‘Ẹ ṣe bíríkì!’ Wọ́n na àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ, ṣùgbọ́n ẹ̀bi náà wá láti ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ.”
17 Hoe re, Mikopiso avao ty tembo retia, izay ty atao’ areo ty hoe, Angao hisoroñe amy Iehovà.
Farao sí dáhùn wí pé, “Ọ̀lẹ ni yín, ọ̀lẹ! Èyí ni ó mú kí ẹ̀yin máa sọ ní ìgbà gbogbo pé, ‘Ẹ jẹ́ kí a lọ, kí a sì rú ẹbọ sí Olúwa.’
18 Akia, arè, mitromaha fe tsy homeañe ahetse vaho mbe hasese’ areo ty anjara’ birike.
Nísinsin yìí ẹ padà lọ sí ẹnu iṣẹ́ yín, a kò ní fún un yín ni koríko gbígbẹ, síbẹ̀ ẹ gbọdọ̀ ṣe iye bíríkì tí ó yẹ kí ẹ ṣe.”
19 Nirendre’ o talè, ana’ Israeleo, t’ie am-poheke amy saontsi’ey, ty hoe, Tsy haketra’ areo ty anjara birike lomoñandro.
Àwọn ọmọ Israẹli tí ó jẹ́ alábojútó iṣẹ́ mọ̀ dájú wí pé àwọn ti wà nínú wàhálà ńlá ní ìgbà tí a sọ fún wọn pé, “Ẹ kò ní láti dín iye bíríkì tí ẹ ń ṣe ni ojoojúmọ́ kù.”
20 Ie nienga i Parò, le nifanjò amy Mosè naho i Aharone nijohañe ey hifanalaka am’iereo,
Ní ìgbà tí wọ́n kúrò ni ọ̀dọ̀ Farao wọ́n rí Mose àti Aaroni tí ó dúró láti pàdé wọn.
21 vaho hoe ty nanoa’ iareo, Ee t’ie ho vazohoe’ Iehovà naho hizaka! Akore ty nañaimboa’ areo anay am-pihaino’ i Parò naho am-pihaino o mpitoro’eo, hanolorañe fibara am-pità’ iareo hañohofa’e loza.
Wọn sì wí pé, “Kí Olúwa kí ó wò yín, kí ó sì ṣe ìdájọ́! Ẹ̀yin ti mú wa dàbí òórùn búburú fún Farao àti àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀, ẹ sì ti fún wọn ni idà láti fi pa wá.”
22 Nitolik’ am’ Iehovà indraike t’i Mosè nanao ty hoe, Ry Talè, akore ty fanilofañe ondaty retoañe? Ino o namantoha’o ahio?
Mose padà tọ Olúwa lọ, ó sì wí pé, “Olúwa, èéṣe tí ìwọ fi mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí? Ṣe torí èyí ni ìwọ fi rán mi?
23 Fa boak’ ami’ty niheovako amy Parò hivolañe amy tahina’oy, le nanoe’e samporerake ondaty retoa vaho tsy rinomba’o ondati’oo.
Láti ìgbà ti mo ti tọ Farao lọ láti bá a sọ̀rọ̀ ni orúkọ rẹ ni ó ti mú ìyọnu wá sí orí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kò sì gba àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀ rárá.”