< Eksodosy 40 >

1 Nitsara amy Mosè t’Iehovà nanao ty hoe:
Olúwa sì wí fún Mose pé,
2 Atroaro ami’ty andro valoha’ i volam-baloha’ey i kivohon-kibohom-pamantañañey.
“Ní ọjọ́ kìn-ín-ní, oṣù kìn-ín-ní ni kí ó gbé àgọ́ náà, àgọ́ àjọ náà ró.
3 Apoho ao i vatam-pañinay vaho ampiavaho amy lamba fañefetsey i vatay.
Gbé àpótí ẹ̀rí sí inú rẹ̀, kí ó sì bo àpótí náà pẹ̀lú aṣọ títa.
4 Aziliho ao i rairaiy le hajario ama’e o harao’eo naho endeso ao i fitàn-jiroy vaho areheto i jiro’e rey.
Gbé tábìlì náà wọ ilé, kí o sì to àwọn ohun tí ó jẹ́ tirẹ̀ lé e lórí. Nígbà náà gbé ọ̀pá fìtílà wọlé, kí o sì to àwọn fìtílà rẹ̀.
5 Apoho aolo’ i vatam-pañinay i kitreli-pañembohañe volamenay vaho apetaho ami’ty lala’ i kivohoy i lamba-fañefe’ey.
Gbé pẹpẹ wúrà ti tùràrí sí iwájú àpótí ẹ̀rí, kí o sì fi aṣọ títa ẹnu-ọ̀nà sí ara àgọ́ náà.
6 Le apoho aolo’ ty lala’ i kivohon-kibohom-pamantañañey i kitrely fisoroñañey.
“Gbé pẹpẹ ẹbọ sísun sí iwájú ẹnu-ọ̀nà àgọ́ náà, àgọ́ àjọ;
7 Le apoho añivo’ i kibohom-pamantañañey naho i kitreliy i fanasàñey vaho ampidoaño rano;
gbé agbada sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ, kí o sì fi omi sí inú rẹ̀.
8 hajario ty añ’ariari’ i kiririsay vaho aradoradò amy lalan-kiririsay i lamba fañefe’ey.
Gbé àgbàlá ró yìí ka, kí ó sì fi aṣọ títa sí ẹnu-ọ̀nà àgbàlá náà.
9 Rambeso amy zao i mena-pañorizañey naho hene orizo i kivohoy naho ze ama’e ao vaho tokano rekets’ o fana’e iabio hiavake;
“Mú òróró ìtasórí, kí ó sì ta á sára àgọ́ náà àti ohun gbogbo tí ó wà nínú rẹ̀, yà pẹpẹ sí mímọ́ àti gbogbo ọ̀ṣọ́ rẹ̀, yóò sì jẹ́ mímọ́.
10 le orizo i kitrely fisoroñañey naho ze hene harao’e vaho tokano i kitreliy, hiavahe’ i kitreliy do’e.
Ta òróró sára pẹpẹ ẹbọ sísun àti gbogbo ohun èlò rẹ̀, ya pẹpẹ náà sí mímọ́, yóò sì jẹ́ mímọ́ jùlọ.
11 Le orizo ka i fanasàñey naho o tombo’eo vaho ampiavaho.
Ta òróró sára agbada náà àti ẹsẹ̀ rẹ, kí o sì yà wọ́n sí mímọ́.
12 Endeso mb’amy lalan-kibohom-pamantañañey mb’eo t’i Aharone naho o anadahi’eo vaho ampandrò an-drano;
“Mú Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ, kí o sì wẹ̀ wọ́n pẹ̀lú omi.
13 le aombeo amy Aharone o saro miavakeo naho orizo vaho ampiavaho hitoroñ’ ahy ho mpisoroñe.
Nígbà náà wọ Aaroni ní aṣọ mímọ́, ta òróró sí i ní orí, kí o sì yà á sí mímọ́, nítorí kí ó lè máa sìn mi bí àlùfáà.
14 Ampombao mb’eo o ana’eo vaho añombeo saroñe.
Mú àwọn ọmọ rẹ̀ kí o sì fi aṣọ àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀ wọ́n.
15 Orizo mana­hake i nañoriza’o an-drae’ iareoy hitoroñ’ ahy ho mpisoroñe; fa ho fisoroñañe tsy modo amo fifokoa’ iareo mifandimbeo ty fañorizañe iareo.
Ta òróró sí wọn ní orí gẹ́gẹ́ bí o ti ta òróró sí baba wọn ní orí, nítorí kì wọn lè máa sìn mi bí àlùfáà. Ìtasórí wọn yóò jẹ́ iṣẹ́ àlùfáà ti yóò máa lò fún gbogbo ìrandíran tó ń bọ̀.”
16 Nanoe’ i Mosè irezay hambañe amy nandilia’ Iehovà azey.
Mose ṣe ohun gbogbo gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún un.
17 Aa le natroatse ami’ty andro valoha’ i volam-baloha’ i taoñe faha-roey i kivohoy.
Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé àgọ́ náà ró ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní ní ọdún kejì.
18 Natroa’ i Mosè i kivohoy naho najado’e an-toe’e o tombo’eo, hinalanka’e o varambañeo, nazili’e o saka’eo vaho natroa’e o anakòre’eo.
Nígbà tí Mose gbé àgọ́ náà ró ó fi ihò ìtẹ̀bọ̀ sí ààyè rẹ̀, ó to pákó rẹ̀, ó fi ọ̀pá rẹ̀ bọ̀ ọ́, ó sì gbé àwọn òpó rẹ̀ ró.
19 Le vinela’e ambone’ i kivohoy i kibohotsey naho nalafi’e ambone’ izay i rakokey, amy nandilia’ Iehovà amy Mosèy.
Ó na aṣọ àgọ́ náà sórí àgọ́, ó sì fi ìbòrí bo orí àgọ́ náà, bí Olúwa ṣe pàṣẹ fún Mose.
20 Rinambe’e i fañinay le najo’e amy vatay, le nazili’e amo ravake amy vataio i baoñe rey vaho napo’e ambone’ i vatay i toem-pijebañañey;
Ó mu ẹ̀rí, ó sì fi sínú àpótí, ó so àwọn òpó mọ́ àpótí náà, ó sì fi àánú bo orí rẹ.
21 le nendese’e amy kivohoy i vatay, nahanto’e i lamba fañefetsey vaho nefera’e i vatam-pañinay amy nandilia’ Iehovà i Mosèy.
Ó sì gbé àpótí náà wá sínú àgọ́; ó sì sọ aṣọ títa, ó sì ta á bo àpótí ẹ̀rí, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
22 Napo’e amy kibohom-pamantañañeio i rairaiy, avara’ i kivohoy, alafe’ i lamba fañefetsey,
Mose gbé tábìlì sínú àgọ́ àjọ sí ìhà àríwá àgọ́ náà lẹ́yìn aṣọ títa,
23 le hinajari’e hiriritse ama’e ty mofo añatrefa’ Iehovà, amy nandilia’ Iehovà i Mosèy.
ó sì to àkàrà sórí rẹ̀ níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
24 Napo’e amy kibohom-pamantañañeio i fitàn-jiroy, tandrife i rairaiy, añ’ila atimo’ i kivohoy,
Ó gbé ọ̀pá fìtílà sínú àgọ́ àjọ ní òdìkejì tábìlì ní ìhà gúúsù àgọ́ náà.
25 le narehe’e i jiro rey añatrefa’ Iehovà ami’ty nandilia’ Iehovà i Mosè.
Ó sì tan àwọn fìtílà náà níwájú Olúwa, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
26 Napo’e aolo’ i lamba fañefetsey amy kibohom-pamantañañeio i kitrely volamenay
Mose gbé pẹpẹ wúrà sínú àgọ́ àjọ níwájú aṣọ títa
27 le na­tsotse ama’e i emboke aman-kafiriañe mañitsey, amy nandilia’ Iehovà amy Mosèy.
ó sì jó tùràrí dídùn lórí rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
28 Natroa’e an-dalambei’ i kivohoy i lamba fañefetsey.
Ó sì ta aṣọ títa sí ẹnu-ọ̀nà àgọ́ náà.
29 Napo’e an-dalam-pimoahañe amy kivohoy—i kibohom-pamantañañey—i kitreli-pisoroñañey, le nañenga soroñe naho enga-mahakama ama’e, amy nandilia’ Iehovà amy Mosèy.
Ó gbé pẹpẹ ẹbọ sísun sí ẹ̀gbẹ́ ẹnu-ọ̀nà àgọ́ àjọ, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
30 Napo’e añivo’ i kibohom-pamantañañey naho i kitreliy i fanasàñey vaho nañiliña’e rano fanasàñe;
Ó gbé agbada sí àárín àgọ́ àjọ àti pẹpẹ, ó sì pọn omi sínú rẹ̀ fún wíwẹ̀,
31 hanasa’ i Mosè naho i Aharone vaho o ana’eo fitàñe naho fandia;
Mose, Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ lò ó láti fi wẹ ọwọ́ àti ẹsẹ̀ wọn.
32 hisasa’ iareo naho hizilike amy kibohom-pamantañañeio ndra hañarine i kitreliy, amy nandilia’ Iehovà amy Mosèy.
Wọ́n máa ń wẹ̀ nígbàkígbà tí wọ́n bá wọ àgọ́ àjọ tàbí tí wọ́n bá súnmọ́ pẹpẹ, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
33 Vaho, natroa’e ty fahe’ i kiririsa añariari’ i kivohoy naho i kitreliy vaho naradorado’e i lamba fañefetse an-dalambein-kiririsaiy. Aa le nifonira’ i Mosè i fitoloñañey.
Mose sì gbé àgbàlá tí ó yí àgọ́ náà kà ró àti pẹpẹ, ó sì ta aṣọ títa ti ẹnu-ọ̀nà sí àgbàlá náà. Bẹ́ẹ̀ ni Mose ṣe parí iṣẹ́ náà.
34 Nakopo’ i rahoñey amy zao i kibohom-pamantañañey vaho nandifotse i kivohoy ty enge’ Iehovà.
Nígbà náà ni àwọsánmọ̀ bo àgọ́ àjọ, ògo Olúwa bo àgọ́ náà.
35 Aa le tsy nimete nizilik’ amy kibohom-pamantañañeio t’i Mosè amy te nivotrak’ ama’e i rahoñey vaho nandifotse i kivohoy ty enge’ Iehovà.
Mose kò sì lè wọ inú àgọ́ àjọ, nítorí àwọsánmọ̀ wà ní orí àgọ́, ògo Olúwa sì ti kún inú àgọ́ náà.
36 Ndra mbia’mbia nionjoñe ambone’ i kivohoy i rahoñey, le nionjoñe mb’amo hene fañaveloa’ iareoo mb’eo o nte’ Israeleo.
Ní gbogbo ìrìnàjò àwọn ọmọ Israẹli nígbàkígbà tí a bá ti fa ìkùùkuu àwọsánmọ̀ náà sókè kúrò lórí àgọ́, wọ́n máa ń jáde lọ;
37 Fa naho tsy nionjoñe i rahoñey le tsy nionjon-dia ka iereo ampara’ ty andro ionjona’e.
ṣùgbọ́n tí àwọsánmọ̀ kò bá gòkè wọn kò ní jáde títí di ọjọ́ tí ó bá gòkè.
38 Tambone’ i kivohoy ty raho’ Iehovà naho antoandro, le afo ty tama’e naho haleñe aolom-pihaino ze hene anjomba’ Israele amo fiavota’ iareo iabio.
Nítorí náà àwọsánmọ̀ Olúwa wà lórí àgọ́ ní ọ̀sán, iná sì wà nínú àwọsánmọ̀ ní alẹ́, ní ojú gbogbo ilé Israẹli ní gbogbo ìrìnàjò wọn.

< Eksodosy 40 >