< Eksodosy 24 >

1 Le hoe re amy Mosè, Mionjona mb’ am’ Iehovà mb’etoy, ihe naho i Aharone, i Nadabe naho i Abiho naho ty fitompolo amo androanavi’ Israeleo vaho mitalahoa ey nahareo.
Ní ìgbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé, “Gòkè tọ Olúwa wá, ìwọ àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli. Ẹ̀yin kì ó sìn ni òkèèrè réré.
2 I Mosè avao ty hañarivo Iehovà, le tsy hañarine ey iereo vaho tsy hindre ama’e hañambone mb’eo ondatio.
Ṣùgbọ́n Mose nìkan ṣoṣo ni yóò súnmọ́ Olúwa; àwọn tókù kò gbọdọ̀ súnmọ́ tòsí ibẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ènìyàn kò gbọdọ̀ gòkè wá pẹ̀lú rẹ̀.”
3 Nomb’eo amy zao t’i Mosè nita­lily am’ondatio ze hene tsara’ Iehovà naho o fañè’eo; le songa nanoiñe am-piarañanañañe raike ondatio, ty hoe, Ho henefa’ay ty tsara iaby nanoe’ Iehovà.
Nígbà ti Mose lọ láti sọ fún àwọn ènìyàn, gbogbo ọ̀rọ̀ àti òfin Olúwa, wọ́n wí ní ohùn kan pé, “Gbogbo ohun ti Olúwa wí ni àwa yóò ṣe.”
4 Aa le sinoki’ i Mosè o hene tsara’ Iehovào naho nañaleñaleñe namboatse kitrely am-poto’ i vohitsey vaho nampitroatse anakòreñe folo-ro’amby ty ami’ty ia’ o rofoko folo-roe-ambi’ Israeleo,
Nígbà náà ni Mose kọ gbogbo ohun tí Olúwa sọ sílẹ̀. Ó dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì mọ pẹpẹ ni ẹsẹ̀ òkè náà. Ó ṣe ọ̀wọ́n òkúta méjìlá. Èyí ti ó dúró fún àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá.
5 le nañiraha’e ajalahy ana’ Israele hibanabana enga horoañe naho añombe ho sorom-panintsiñañe am’Iehovà.
Nígbà náà ni ó rán àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Israẹli, wọ́n sì rú ẹbọ sísun, wọ́n fi ọ̀dọ́ màlúù rú ẹbọ àlàáfíà si Olúwa.
6 Navì’ i Mosè am-pinga ao ty vaki’ i lioy vaho naretsa’e amy kitreliy ty ila’e.
Mose bu ìlàjì ẹ̀jẹ̀ ẹran sínú abọ́, ó sì fi ìlàjì tókù wọn ara pẹpẹ.
7 Rinambe’e amy zao i bokem-pañinay le vinaki’e am-pijanjiña’ ondatio; le hoe iereo, Hanoe’ay ze hene tsara’ Iehovào vaho ho haoñe’ay.
Nígbà náà ni ó sì mú ìwé májẹ̀mú, ó sì kà á sí àwọn ènìyàn. Wọ́n dáhùn pé, “Àwa yóò ṣe gbogbo ohun tí Olúwa wí. Àwa yóò sì gbọ́rọ̀.”
8 Le rinambe’ i Mosè i lioy naho nafitse’e am’ondatio vaho nanao ty hoe, Ingo ty liom-pañina nanoe’ Iehovà ama’ areo amy hene tsara rezay.
Nígbà náà ni Mose gbé ẹ̀jẹ̀, ó sì wọn sí àwọn ènìyàn náà lára pé, “Èyí ni ẹ̀jẹ̀ májẹ̀mú tí Olúwa ti ṣe pẹ̀lú yín ni ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí.”
9 Niañambone amy zao t’i Mosè naho i Aharone, i Nadabe naho i Abiho vaho ty androanavy fitompolo’ Israele;
Mose àti Aaroni, Nadabu àti Abihu àti àádọ́rin àwọn àgbàgbà Israẹli gòkè lọ.
10 le niisa’ iereo t’i Andrianañahare’ Israele; le hoe linamike safira ty ambane’ o fandia’eo vaho nanahake o likerañeo ami’ ty fikantsokantsoña’e.
Wọ́n sì rí Ọlọ́run Israẹli. Ní abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀ ni ohun kan bí i pèpéle ti a fi òkúta safire ṣe wà. Èyí ti ó mọ́ nigínnigín bí àwọ̀ sánmọ̀ fúnra rẹ̀.
11 Le ie tsy napao-pitàñe amo androanavi’ Israeleo, f’ie nahaisake i Andrianañahare naho nikama vaho ninoñe.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kò gbé ọwọ́ rẹ̀ sókè sí àwọn àgbàgbà Israẹli wọ̀nyí; wọ́n ri Ọlọ́run, wọ́n jẹ, wọ́n sì mu.
12 Hoe t’Iehovà amy Mosè, Miañambonea mb’amako mb’etoa, le mitambara atoy, fa ho tolo­rako ravem-bato reketse Hake naho lily sinokiko hañòhañe iareo.
Olúwa sì sọ fún Mose pé, “Gòkè wá sí ọ̀dọ̀ mi, kí o sì dúró níhìn-ín. Èmi yóò sì fún ọ ní wàláà òkúta pẹ̀lú òfin àti ìlànà tí mo ti kọ sílẹ̀ fún ìtọ́sọ́nà wọn.”
13 Aa le niongake t’i Mosè naho Iehosoa mpitoro’e vaho nionjoñe mb’ amy vohin’ Añahare amboney mb’eo t’i Mosè.
Nígbà náà ni Mose jáde lọ pẹ̀lú Joṣua arákùnrin rẹ̀. Mose lọ sí orí òkè Ọlọ́run.
14 Le hoe re amy androanavy rey, Liñiso etoan-jahay, ampara’ ty impolia’ay; ama’ areo t’i Aharone naho i Khòre, hiheova’ ze aman-kalahatse.
Ó sì wí fún àwọn àgbàgbà pé, “Ẹ dúró dè wá níhìn-ín yìí, títí àwa yóò fi tún padà tọ̀ yín wá, sì kíyèsi i, Aaroni àti Huri ń bẹ pẹ̀lú yín, bí ẹnìkan bá ni ọ̀ràn kan, kí ó tọ̀ wọ́n lọ.”
15 Aa le niañambone’ i vohi­tsey t’i Mosè vaho kinolopo’ ty rahoñe i vohi­tsey.
Nígbà tí Mose gun orí òkè lọ, ìkùùkuu bo orí òkè náà.
16 Nivotrak’ ambohi-Sinay eo ty enge’ Iehovà, le nanaroñe aze eneñ’ andro i rahoñey; ie ami’ty andro fahafito, nikanjie’e boak’amy rahoñey t’i Mosè.
Ògo Olúwa sì wà ní orí òkè Sinai. Ìkùùkuu bo orí òkè náà fún ọjọ́ mẹ́fà, ni ọjọ́ keje ni Olúwa kọ sí Mose láti inú ìkùùkuu náà wá.
17 Le nihoe afo nisolebotse ambone’ i vohitsey ty Enge’ Iehovà am-pihaino’ o ana’Israeleo.
Ni ojú àwọn ọmọ Israẹli ògo Olúwa náà dàbí iná ajónirun ni orí òkè.
18 Nizilik’ amy rahoñey t’i Mosè, niañambone i vohitsey. Le tambatse am-bohitse ao efapolo andro naho efapolo haleñe t’i Mosè.
Nígbà náà ni Mose wọ inú ìkùùkuu náà bí ó ti ń lọ ní orí òkè. Ó sì wà ni orí òkè náà ni ogójì ọ̀sán àti ogójì òru.

< Eksodosy 24 >