< Eksodosy 15 >

1 Le nisabo ty takasy toy am’ Iehovà t’i Mosè naho o ana’ Israeleo, nipoña-peo ami’ty hoe: Ho saboeko t’Iehovà, onjono an-tiotiotse ey, Nafetsa’e an-driak’ ao ty soavala reke-mpiningi’e.
Nígbà náà ni Mose àti àwọn ọmọ Israẹli kọ orin yìí sí Olúwa, Èmi yóò kọrin sí Olúwa, nítorí òun pọ̀ ní ògo. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún ni ó ti sọ sínú Òkun.
2 Haozarako naho saboko t’Iehovà, Ie fandrombahañe ahiko henaneo. Andrianañahareko re, le ho rengeko, Andrianañaharen-draeko, vaho honjoñeko.
Olúwa ni agbára àti orin mi; òun ti di Olùgbàlà mi, òun ni Ọlọ́run mi, èmi ó yìn ín, Ọlọ́run baba mi, èmi ó gbé e ga.
3 Fanalolahy añ’ aly t’Iehovà, Iehovà ty Tahina’e.
Ológun ni Olúwa, Olúwa ni orúkọ rẹ,
4 Navokovoko’e an-driak’ ao o sarete’ i Paròo naho i valobohò’ey. Nampiopoe’e an-dRia-Binda ao o roandria jinobo’eo.
kẹ̀kẹ́ ogun Farao àti ogun rẹ̀ ni ó mú wọ inú Òkun. Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáfáfá jùlọ ni ó rì sínú Òkun Pupa.
5 Manafots’iareo i lalekey, nilempotse an-dalek’ ao hoe vato.
Ibú omi bò wọ́n mọ́lẹ̀; wọ́n sì rì sí ìsàlẹ̀ omi òkun bí òkúta.
6 Toe engeñe an-kaozarañe o fità’o havanao, ry Iehovà. Fa dinorodemom-pitàn-kavana’o i rafelahiy, ry Iehovà.
“Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, pọ̀ ní agbára. Ọwọ́ ọ̀tún rẹ, Olúwa, fọ́ àwọn ọ̀tá túútúú.
7 Ami’ty hajabahinam-bolonahe’o ty anjevoña’o ambane o mivoala ama’oo. Ampihitrife’o mb’eo ty haviñera’o mahatomonto iareo hoe tain’ ava.
“Nínú agbára ńlá rẹ ti ó tóbi ìwọ bi àwọn ti ó dìde sí ọ ṣubú. Ìwọ rán ìbínú gbígbóná rẹ; tí ó run wọ́n bí àgémọ́lẹ̀ ìdí koríko.
8 Ami’ty fikofòm-piantsona’o ty nivotria’ i ranoy. Nitroatse hoe rindriñe i sorotombahañey; Nizitse an-tro’ i riakey o lalekeo.
Pẹ̀lú èémí imú rẹ ni omi fi ń wọ́jọ pọ̀. Ìṣàn omi dìde dúró bí odi; ibú omi sì dìpọ̀ láàrín Òkun.
9 Hoe ty asa’ i rafelahiy: Ho horidañeko, ho trako, Ho zaraeko o dinohitseo; ie hañeneke ty haveloko. Hapontsoako ty fibarako, handrotsaha’ ty tañako.
Ọ̀tá ń gbéraga, ó ń wí pé, ‘Èmi ó lépa wọn, èmi ó bá wọn. èmi ó pín ìkógun; èmi ó tẹ́ ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ mi lọ́run lára wọn. Èmi yóò fa idà mi yọ, ọwọ́ mi yóò pa wọ́n run.’
10 Fe nitiofe’o an-kofò’o Le nandipotse iareo i riakey. Nilempotse hoe firake An-drano nitabohazake ao.
Ìwọ fẹ́ èémí rẹ, òkun ru bò wọ́n mọ́lẹ̀. Wọ́n rì bí òjé ni àárín omi ńlá.
11 Ia amo ndrahareo ty mañirinkiriñe Azo ry Iehovà? Ia ty hambañe ama’o? Tsomerentsereñe an-kamasiñañe, mampañeveñe an-drenge, ry mpitolon-kalatsàñeo!
Ta ni nínú àwọn òrìṣà tó dàbí rẹ, Olúwa? Ta ló dàbí rẹ: ní títóbi, ní mímọ́ Ẹlẹ́rù ni yìn, tí ń ṣe ohun ìyanu?
12 Nahiti’o ty fità’o havana vaho nabea’ i taney iereo.
“Ìwọ na apá ọ̀tún rẹ, ilẹ̀ si gbé wọn mì.
13 Am-pikokoa-migahiñe ty niaoloa’o ondaty nijebañe’oo. An-kafatrara’o ty nitehafa’o mb’añ’akiban-kamasiña’o mb’eo.
Nínú ìfẹ́ rẹ ti kì í sákí Ìwọ ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn náà tí Ìwọ ti rà padà. Nínú agbára rẹ Ìwọ yóò tọ́ wọn, lọ sí ibi ìjókòó rẹ mímọ́.
14 Nahajanjiñe o kilakila ondatio vaho nititititike; Fineveneverañe ty nametreke o nte-Pilistio
Orílẹ̀-èdè yóò gbọ́ wọn yóò wárìrì. Ìkáàánú yóò mi àwọn ènìyàn Filistia.
15 Nirevendreveñe o mpifehe’ i Edomeo nihondrahondra o roandria’ i Moabeo, fonga nitranake o nte-Kanàneo;
Ìbẹ̀rù yóò mú àwọn ìjòyè Edomu, àwọn olórí Moabu yóò wárìrì. Àwọn ènìyàn Kenaani yóò sì yọ́ dànù.
16 nivotraha’ ty havorombeloñe naho ty hetraketrake, ami’ty haozaram-pità’o nizitse hoe vato iereo— Ampara’ te nitsake ondati’oo ry Iehovà, ampara’ te nitsake ondaty vinili’oo.
Ìbẹ̀rù bojo yóò ṣubú lù wọ́n, nítorí nína títóbi apá rẹ̀ wọn yóò dúró jẹ́ẹ́ láì mira bí i òkúta, títí àwọn ènìyàn rẹ yóò fi rékọjá, Olúwa, títí tí àwọn ènìyàn tí o ti rà yóò fi rékọjá.
17 Hampimoahe’o ao iereo vaho haore’o am-bohi’ i lova’oy— i toem-pimoneña’o hinalanka’oy, ry Iehovà, i fipalirañe naorem-pità’oy ry Talè.
Ìwọ yóò mú wọn wá láti gbìn wọ́n ni orí òkè ti ìwọ jogún, ní ibi ti ìwọ ṣe fún ara rẹ, Olúwa. Láti máa gbé ibi mímọ́ ti ìwọ fi ọwọ́ rẹ gbé kalẹ̀, Olúwa.
18 Mifehe nainai’e donia t’Iehovà.
“Olúwa yóò jẹ ọba láé àti láéláé.”
19 Fa nisorogodañ’ an-driak’ ao o soavala i Paròo rekets’ o sarete’eo naho o mpiningi’eo, le nampoli’ Iehovà am’ iereo o ranon-driakeo, vaho nitsake añivo’ i riakey an-tane maike o ana’ Israeleo.
Nígbà ti ẹṣin Farao, kẹ̀kẹ́ ogun àti àwọn ẹlẹ́ṣin rẹ̀ wọ inú Òkun, Olúwa mú kí omi òkun padà bò wọ́n mọ́lẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli rìn lórí ìyàngbẹ ilẹ̀ la òkun kọjá.
20 Nandrambe kantsàñe amy zao t’i Miriamae mpitoky, rahavave’ i Aharone, le nañorik’ aze an-kantsàñe naho tsinjake o rakemba iabio
Miriamu wòlíì obìnrin, arábìnrin Aaroni, mú ohun èlò orin ni ọwọ́ rẹ̀, gbogbo àwọn obìnrin sì jáde tẹ̀lé e pẹ̀lú ìlù òun ijó.
21 vaho nitakasie’ i Miriamae: Misaboa am’ Iehovà fa nandreketse am-pandreketam-bolonahetse. Navokovoko’e an-driak’ ao ty soavala reke-piningi’e.
Miriamu kọrin sí wọn báyìí pé, “Ẹ kọrin sí Olúwa, nítorí òun ni ológo jùlọ. Ẹṣin àti ẹni tí ó gùn ún, ni òun bi ṣubú sínú Òkun.”
22 Aa le nendese’ i Mosè nienga i Ria-Binday t’Israele naho nionjomb’ an-dRatraratra’ i Sore. Nañavelo telo andro am-patrambey ao iereo fe tsy nahatendreke rano.
Nígbà náà ni Mose ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn Israẹli jáde láti Òkun Pupa lọ sínú ijù Ṣuri. Wọ́n lọ ní ìrìn ọjọ́ mẹ́ta sínú ijù náà, wọn kò sì rí omi.
23 Ie pok’e Marà ao, le tsy nihay kamaeñe i rano’ i Marày fa nafaitse. (Izay ty nanoañe ty hoe Marà i aoy.)
Nígbà tí wọ́n dé Mara, wọn kò lè mu omi Mara nítorí omi náà korò. (Nítorí náà ni a ṣe pe ibẹ̀ ni Mara: ibi ìkorò.)
24 Aa le niñeoñeo amy Mosè ondatio ami’ty hoe: Ino ty hinome’ay?
Àwọn ènìyàn ń kùn sí Mose wí pé, “Kí ni àwa yóò mu?”
25 Le nitoreo am’Iehovà re naho nitoroa’ Iehovà ty hatae, ze nahifi’e an-drano ao nahamamy i ranoy. Teo ty nanoa’ Iehovà fañè naho zaka vaho teo ty nitsoha’e iareo.
Mose sì ké pe Olúwa, Olúwa sì fi igi kan hàn án, ó sì sọ igi náà sínú omi, omi náà sì dùn. Níbẹ̀ ni Olúwa ti gbé ìlànà àti òfin kalẹ̀ fún wọn, níbẹ̀ ni ó sì ti dán wọn wò.
26 Hoe re: Naho imanea’o haoñe ty fiarañanaña’ Iehovà Andria­nañahare’o naho manao ty hahiti’e am-pivazohoa’e naho mijanjiñe o fandilia’eo vaho miambeñe o fañè’e iabio, le tsy hapoko ama’o o areteñe nafetsako amo nte-Mitsraimeoo, fa Izaho Iehovà Mpampijangañe azo.
Ó wí pé, “Bí ìwọ bá fetísílẹ̀ dáradára sí òfin Olúwa Ọlọ́run, ti ìwọ sì ṣe ohun tí ó tọ́ ni ojú rẹ̀, ti ìwọ sì tẹ̀lé ohun tí ó pàṣẹ, ti ìwọ si pa ìlànà rẹ̀ mọ́. Èmi kì yóò jẹ́ kí èyíkéyìí nínú àwọn ààrùn wọ̀n-ọn-nì ti mo mú wá sórí àwọn ará Ejibiti wá sí ara rẹ, nítorí Èmi ni Olúwa ti ó mú ọ láradá.”
27 Le nitotsake Elìme ao iereo, toetse an-dohan-drano manganahana folo ro’ amby naho satrañe fitom-polo; vaho nañialo marine’ o ranoo eo.
Nígbà ti wọ́n dé Elimu, níbi ti kànga omi méjìlá àti àádọ́rin ọ̀pẹ gbé wà, wọ́n pàgọ́ síbẹ̀ ni etí omi.

< Eksodosy 15 >