< Asan'ny Apostoly 2 >
1 Ie tondroke i andro Halimampoloy, songa nitraok’ an-toetse raik’ ao,
Nígbà tí ọjọ́ Pentikosti sì dé, gbogbo wọn fi ọkàn kan wà ní ibìkan.
2 le nivovoa’ ty feo boak’ an-dikerañe ao manahake ty fikofaon-tio-bey nañatseke ty anjomba niambesara’ iereo.
Lójijì ìró sì ti ọ̀run wá, gẹ́gẹ́ bí ìró ẹ̀fúùfù líle, ó sì kún gbogbo ilé níbi tí wọ́n gbé jókòó.
3 Le nisodehañe añ’atrefa’ iereo ty raha hoe lel-afo nitsiriaria, vaho sindre nivotraha’e.
Ẹ̀là ahọ́n bí i iná sì yọ sí wọn, ó pín, ó sì bà lé olúkúlùkù wọn.
4 Songa nilifore’ i Arofo Masiñey vaho namototse nisaontsy an-tsaontsy an-kafaankafa, amy nampisaontsie’ i Arofoy.
Gbogbo wọn sì kún fún Ẹ̀mí Mímọ́, wọn sì bẹ̀rẹ̀ sí í fi èdè mìíràn sọ̀rọ̀, gẹ́gẹ́ bí Ẹ̀mí ti fi fún wọn ni ohùn.
5 Ie henane zay, nañialo e Ierosaleme ao ty Jiosy, ondaty vañoñe boak’amy ze pato-razañe ambanen-dikerañeo.
Àwọn Júù olùfọkànsìn láti orílẹ̀-èdè gbogbo lábẹ́ ọ̀run sì ń gbé Jerusalẹmu.
6 Ie nahajanjiñe i feo zay le nifanontoñe ho valobohoke, nidaba amy te songa nahajanjiñe ty saontsi’e.
Nígbà tí wọn sì gbọ́ ìró yìí, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn péjọ pẹ̀lú ìyàlẹ́nu, nítorí tí olúkúlùkù gbọ́ tí wọ́n ń sọ̀rọ̀ ní èdè rẹ̀.
7 Sindre nilatsa naho nivereñe vaho nifanao ty hoe: Inao! tsy nte-Galilia v’ondaty iaby milañoñeo?
Ẹnu sì yà wọ́n, wọn ń wí fún ara wọn pé, “Ǹjẹ́ ara Galili kọ́ ni gbogbo àwọn tí ń sọ̀rọ̀ wọ̀nyí jẹ́?
8 Aa vaho akore tika ro songa mahajanjiñe ty saontsy nibeizeñe aze?
Èéha sì tí ṣe ti olúkúlùkù wa fi ń gbọ́ bí wọ́n tí ń fi èdè sọ̀rọ̀?
9 Nte Partia naho nte Media naho nte Elama, naho o mpimoneñe e Mesopotamia naho e Iehodà naho e Kapadokia naho e Ponto vaho Asiao;
Àwọn ará Partia, àti Media, àti Elamu; àti àwọn tí ń gbé Mesopotamia, Judea, àti Kappadokia, Pọntu àti Asia.
10 o Frigia naho Pamfilia, Egipte naho am-paripari’ i Libià mañohoke i Kirenà naho ambahiny hirike Romao: Jiosy naho o niova ho Jiosio
Frigia, àti Pamfilia, Ejibiti, àti agbègbè Libia níhà Kirene; àti àwọn àtìpó Romu, àwọn Júù àti àwọn aláwọ̀ṣe Júù
11 le nte Kreta vaho Arabo, sindre mijanjiñe ami’ty saontsi’e te nitaliliañe o fitoloñan’ Añahare ra’elahio.
(àti àwọn Júù àti àwọn tí a ti ipa ẹ̀sìn sọ di Júù); àwọn ará Krete àti Arabia; àwa gbọ́ tí wọ́n sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu ńlá Ọlọ́run ni èdè wa.”
12 Ie fonga nilatsà naho vata’e niembetse le nifanao ty hoe: Inom-bao ty taly izao?
Ẹnu sì ya gbogbo wọn, wọ́n sì wárìrì. Wọn wí fún ara wọn pé, “Kí ni èyí túmọ̀ sí?”
13 Hoe ka ty nikobiha’ ty ila’e: Etsa-divai-vao ondatio.
Ṣùgbọ́n àwọn ẹlòmíràn ń ṣẹ̀fẹ̀, wọn sí wí pé, “Àwọn ọkùnrin wọ̀nyí kún fún wáìnì tuntun”.
14 Niharo nijohañe amy folo raik’ amby rey t’i Petera, ie nipoña-peo nanao ty hoe: Ry nte-Iehodao! ry mpimoneñ’ e Ierosaleme iabio, mahafohìna vaho tomiro o entakoo:
Nígbà náà ni Peteru dìde dúró pẹ̀lú àwọn mọ́kànlá yòókù, ó gbé ohùn rẹ̀ sókè, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin Júù ènìyàn mi àti gbogbo ẹ̀yin tí ń gbé Jerusalẹmu, ẹ jẹ́ kí èyí kí ó yé yin; kí ẹ sì fetísí ọ̀rọ̀ mi.
15 Tsy jike ondaty retoañe amy fitsakorea’ areo azey, ie vaho amy ora fahatelo’ i àndroiy.
Àwọn wọ̀nyí kò mu ọtí yó, bí ẹ̀yin tí rò ó; wákàtí kẹta ọjọ́ sá à ni èyí.
16 Fa hoe ty nampisaontsieñe i Joela mpitoky:
Bẹ́ẹ̀ kọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ ti a ti sọ láti ẹnu wòlíì Joẹli wá pé:
17 Ho tondrok’ amo andro hengaha’eo, hoe t’i Andrianañahare, te ho kofòhako boak’ an-troko ao ze atao nofotse, le hitoky o anadahi’ areoo naho o anak’ampela’ areoo, naho hioniñe aroñaroñe o ajalahi’ areoo, vaho hañinofy nofy o adroanavi’ areoo.
“Ọlọ́run wí pé, ‘Ní ìkẹyìn ọjọ́, Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mí jáde sára ènìyàn gbogbo, àwọn ọmọ yín ọkùnrin àti àwọn ọmọ yín obìnrin yóò máa sọtẹ́lẹ̀ àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín yóò sì máa ríran, àwọn arúgbó yín yóò sì máa lá àlá,
18 Hadoako amo mpitoroko lahilahy naho ampelao ty Troko amy andro rezay, le hitoky iereo.
àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi ọkùnrin àti sára àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ mi obìnrin, ni Èmi yóò tú nínú Ẹ̀mí mi jáde ni ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì: wọn yóò sì máa sọtẹ́lẹ̀.
19 Ho toroako halatsàñe andindìñe eñe naho viloñe an-tane ambane atoy: Lio naho afo vaho evon-katoeñe.
Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìyanu hàn lójú ọ̀run, àti àwọn àmì nísàlẹ̀ ilẹ̀; ẹ̀jẹ̀ àti iná àti rírú èéfín;
20 Hafotetse ho fimoromoroñañe i àndroy naho ho lio i volañey aolo’ ty itondroha’ i andro ra’elahy bei-volonahe’ i Talèy.
A ó sọ oòrùn di òkùnkùn, àti òṣùpá di ẹ̀jẹ̀, kí ọjọ́ ńlá àti ọjọ́ ológo Olúwa tó dé.
21 Ie amy zay hene ho rombaheñe ze mikanjy ty tahina’ Iehovà.
Yóò sì ṣe, ẹnikẹ́ni tí ó bá ké pe orúkọ Olúwa ni a ó gbàlà.’
22 Ry nte Israeleo, janjiño o tsara zao: Iesoà nte Nazareta, indaty niventèn’ Añahare ama’ areo amo raha tsi-tantane naho halatsàñe vaho viloñe nanoen’ Añahare añama’e añivo’ areooy, ze toe fohi’ areo;
“Ẹ̀yin ènìyàn Israẹli, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Jesu tí Nasareti, ọkùnrin tí a mọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá nípa iṣẹ́ agbára àti tí ìyanu, àti àmì ti Ọlọ́run ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe láàrín yín, bí ẹ̀yin tìkára yín ti mọ̀ pẹ̀lú.
23 ie nasese amy fisafirin’ Añahare mahatafetetsey naho amy faharofoanan’ Añahare miaoloy le rinambe’ areo naho pinèke an-tañan-tsi-aman-Kake vaho vinono;
Ẹni tí a ti fi lé yín lọ́wọ́ nípa ìpinnu ìmọ̀ àti ìmọ̀tẹ́lẹ̀ Ọlọ́run; àti ẹ̀yin pẹ̀lú, tí a sì pa á pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ àwọn ènìyàn búburú, a kàn mọ́ àgbélébùú.
24 f’ie natroan’ Añahare naho fa navotso’e amo halovilovia’ i Havilasiio, amy t’ie tsy nilefe’e tambozoreñe.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run jí dìde kúrò nínú òkú, gbà á kúrò nínú ìrora ikú, nítorí tí kò ṣe é ṣe fún ikú láti dìímú.
25 Le hoe t’i Davide ty ama’e: Nitreako te añatrefako nainai’e t’Iehovà, an-tañan-kavanako eo le tsy hasiotse iraho.
Dafidi tí wí nípa tirẹ̀ pé: “‘Mo rí Olúwa nígbà gbogbo níwájú mí, nítorí tí ó ń bẹ lọ́wọ́ ọ̀tún mi, a kì ó ṣí mi ní ipò.
26 Aa le nirebeke ty troko naho nifale ty lelako; vaho hitofa am-pitamàñe o nofokoo,
Nítorí náà inú mi dùn, ahọ́n mi sì yọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ara mi yóò sì sinmi ní ìrètí.
27 amy te tsy hado’o an-tsikeokeok’ ao ty fiaiko, vaho tsy hapo’o ho momoke i Masi’oy. (Hadēs )
Nítorí tí ìwọ kí yóò fi ọkàn mi sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kí yóò jẹ́ kí Ẹni Mímọ́ rẹ rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs )
28 Fa nampandrendrehe’o ahy o lalan-kaveloñeo; ho lifore’o haehake raho am-piatrefa’o eo.
Ìwọ mú mi mọ ọ̀nà ìyè, ìwọ yóò mú mi kún fún ayọ̀ ni iwájú rẹ.’
29 Ry longo, hitaroñe i Davide raentika iraho, t’ie nivilasy vaho nalenteke, naho amantika atoy pake henàne i kibori’ey.
“Ará, èmí lè sọ fún yín pẹ̀lú ìgboyà pé Dafidi baba ńlá kú, a sì sin ín, ibojì rẹ̀ sì ń bẹ lọ́dọ̀ wa títí di òní yìí.
30 F’ie nimpitòky, nahafohiñe te nifanta an-titike añama’e t’i Andrianañahare, hampitroatse boak’ amo tarira’eo ty hiambesatse amy fiambesa’ey.
Ṣùgbọ́n ó jẹ́ wòlíì, àti bí ó mọ́ pé, Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún òun nínú ìbúra pé nínú irú-ọmọ inú rẹ̀, òun yóò mú ọ̀kan jókòó lórí ìtẹ́ rẹ̀.
31 Aa kanao nioni’e taolo, le nitoky i fivañonan-ko velo’ i Norizañeiy, te tsy hadòke an-tsikeokeok’ ao ty arofo’e vaho tsy hihomake i fañova’ey. (Hadēs )
Ní rí rí èyí tẹ́lẹ̀, ó sọ ti àjíǹde Kristi, pé a kò fi ọkàn rẹ̀ sílẹ̀ ni isà òkú, bẹ́ẹ̀ ni ara rẹ̀ kò rí ìdíbàjẹ́. (Hadēs )
32 Toe natroan’ Añahare Iesoà izay, valolombeloñe zahay iaby.
Jesu náà yìí ni Ọlọ́run ti jí dìde sí ìyè, àwa pẹ̀lú sì jẹ́rìí sí èyí.
33 Aa ie nampionjonem-pitàn-kavanan’ Añahare, naho nandrambe aman-dRae i nampitamañey, i Arofo Masiñey, vaho naili’e o isa’ areo naho janji’ areoo.
A ti gbéga sí ọwọ́ ọ̀tún Ọlọ́run, ó ti gba ìlérí Ẹ̀mí Mímọ́ láti ọ̀dọ̀ Baba, ó tu èyí tí ẹ̀yin rí àti gbọ́ nísinsin yìí síta.
34 Toe tsy i Davide ty nonjoneñe mb’ andindìñe añe, fa hoe ty natao’e: Hoe t’Iehovà amy Talèkoy: Miambesara an-tañan-kavanako etoa.
Nítorí Dafidi kò gòkè lọ sí ọ̀run ṣùgbọ́n òun tìkára rẹ̀ wí pé, “‘Olúwa sọ fún Olúwa mi pé: “Jókòó ní ọwọ́ ọ̀tún mi
35 Ampara’ te anoeko fitongoam- pandia’o o rafelahi’oo.
títí èmi yóò fi sọ àwọn ọ̀tá rẹ dí àpótí ìtìsẹ̀ fún ẹsẹ̀ rẹ.”’
36 Aa le mahafohìna an-katò ry anjomba’ Israele iabio te nanoen’ Añahare Talè naho Noriza’e t’Iesoà pinè’ areo.
“Ǹjẹ́ kí gbogbo ilé Israẹli mọ̀ dájúdájú pé, Ọlọ́run ti fi Jesu náà, ti ẹ̀yin kàn mọ́ àgbélébùú, ṣe Olúwa àti Kristi.”
37 Ie nahajanjiñe, le nitsipoheñe añ’arofo vaho nanao ty hoe amy Petera naho amo Firàheñe ila’eo: O ry longo, Ino ty hanoe’ay?
Nígbà tí wọ́n sì gbọ́, ọkàn wọn gbọgbẹ́, wọn sì wí fún Peteru àti àwọn aposteli yòókù pé, “Ará, kín ni àwa yóò ṣe?”
38 Le hoe t’i Petera am’iereo: Misolohoa, le songa milipora amy tahina’ Iesoà Norizañey hañahàn-kakeo vaho andrambesam-palalàñe, i Arofo Masiñey.
Peteru sì wí fún wọn pé, “Ẹ ronúpìwàdà, kí a sì bamitiisi olúkúlùkù yín ní orúkọ Jesu Kristi fún ìdáríjì ẹ̀ṣẹ̀ yín. Ẹ̀yin yóò sì gba ẹ̀bùn Ẹ̀mí Mímọ́.
39 Ho anahareo i nampitamàñey naho ho a o ana’ areoo vaho ho a o an-tsietoitane añe iabio, ndra iaia kanjie’ Iehovà Andrianañaharen-tika ho ama’e.
Nítorí fún yín ni ìlérí náà, àti fún àwọn ọmọ yín, àti fún gbogbo àwọn tí ó jìnnà réré, àní gbogbo àwọn tí Olúwa Ọlọ́run wa yóò pè.”
40 Aa le tinovo’e tsara maro, nimane taroñe naho osike, ami’ty hoe: Mirombaha ami’ty tariratse mengoke toy.
Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ púpọ̀ mìíràn ni ó fi ń kìlọ̀ tí ó sì ń fi ń rọ̀ wọ́n wí pé, “Ẹ gba ara yín là lọ́wọ́ ìran àrékérekè yìí.”
41 Aa le nalipotse an-kafaleañe o Nandrambe i tsara’eio, vaho nitovoñe ondaty telo arivo amy andro zay.
Nítorí náà àwọn tí ó fi ayọ̀ gba ọ̀rọ̀ rẹ̀ a bamitiisi wọn, lọ́jọ́ náà a sì kà ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkàn kún wọn.
42 Ie nifahatse ami’ty fañoha’ o Firàheñeo naho am-pilongoañe naho am-pitraofam-pikama vaho am-pitalahoañe.
Wọ́n sì dúró ṣinṣin nínú ẹ̀kọ́ àwọn aposteli, àti ní ìdàpọ̀, ní bíbu àkàrà àti nínú àdúrà.
43 Fonga nivotraham-pañeveñañe, naho maro ty halatsàñe naho viloñe nanoe’ o Firàheñeo.
Ẹ̀rù sí ba gbogbo ọkàn; iṣẹ́ ìyanu àti iṣẹ́ àmì púpọ̀ ni a ti ọwọ́ àwọn aposteli ṣe.
44 Le niharo ao iaby o mpiatoo vaho nifampitraoke amy ze he’e,
Gbogbo àwọn tí ó sì gbàgbọ́ wà ni ibìkan, wọn ní ohun gbogbo sọ́kàn;
45 nandetake fanañañe naho vara vaho nifanjara tsahatse ty hampahaeneñe ze nipaia’ ondaty iabio.
Wọn si ń ta ohun ìní àti ẹrù wọn, wọn sì ń pín wọn fún olúkúlùkù, gẹ́gẹ́ bí ẹnikẹ́ni tí í ṣe aláìní sí.
46 Ie nitoloñe an-troke raik’ añ’ anjomban’ Añahare ao boak’ andro naho nitsatsà-traño namola-mofo vaho nitrao-pikama an-kaehake naho an-tso-po,
Wọ́n fi ọkàn kan dúró lójoojúmọ́ nínú tẹmpili. Wọ́n ń bu àkàrà ní ilé wọn, wọn ń fi inú dídùn àti ọkàn òtítọ́ jẹ oúnjẹ wọn.
47 nandrenge an’ Andrianañahare naho nisohe’ ze hene ondaty; vaho nitovoña’ i Talè boak’ andro o nirombaheñeo.
Wọ́n yín Ọlọ́run, wọn sì rí ojúrere lọ́dọ̀ ènìyàn gbogbo, Olúwa sí ń yàn kún wọn lójoojúmọ́, àwọn tí à ń gbàlà.