< 2 Mpanjaka 5 >
1 Ni-ondaty ra’elahy aman-talè’e t’i Naamane, mpifeleke ty valobohò’ i Arame, nanan-kasy amy te tinolo’ Iehovà fandrebahañe ho a i Arame; fanalolahy nahasibeke ondatio, f’ie niangamae.
Naamani jẹ́ olórí ogun ọba Aramu. Ó jẹ́ ènìyàn ńlá níwájú ọ̀gá rẹ̀, wọ́n sì bu ọlá fún un, nítorí nípasẹ̀ rẹ̀ ni Olúwa ti fi ìṣẹ́gun fún Aramu. Òun jẹ́ alágbára, akọni ọkùnrin ṣùgbọ́n, ó dẹ́tẹ̀.
2 Teo te niakatse am-pirimboñañe o nte-Arameo naho ninday ty ajaja ampela an-drohy boak’ an-tane’ Israele añe, ie ty niatrake ty tañanjomba’ i Naamane.
Nísinsin yìí ẹgbẹgbẹ́ láti Aramu ti jáde lọ láti mú ọmọ obìnrin kékeré kan ní ìgbèkùn láti Israẹli, ó sì sin ìyàwó Naamani.
3 Le hoe re amy rakemba talè’ey, Lonike te tamy mpitoky e Somerone añey ty talèko, le ho nijangañ’ amy haangamae’ey.
Ó sọ fún ọ̀gá rẹ̀ obìnrin pé, “Tí ó bá jẹ́ wí pé ọ̀gá mi lè rí wòlíì tí ó wà ní Samaria! Yóò wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
4 Aa le nimb’eo re nitalily aman-talè’e ty hoe: Hoe zao naho ty hoe ty natalili’ i anak’ ampatañe boak’ an-tane’ Israeley.
Naamani lọ sí ọ̀dọ̀ ọ̀gá rẹ̀ ó sì wí fún un ohun tí ọmọbìnrin Israẹli ti sọ.
5 Le hoe ty mpanjaka’ i Arame. Akia, henaneo, le hañitrifako taratasy ty mpanjaka’ Israele. Le nienga re ninday talenta volafoty folo naho bogady volamena eneñ-arivo vaho fiovan-tsaroñe folo.
“Ní gbogbo ọ̀nà, lọ,” ọba Aramu dá a lóhùn pé, “Èmi yóò fi ìwé ránṣẹ́ sí ọba Israẹli.” Bẹ́ẹ̀ ni Naamani lọ, ó sì mú pẹ̀lú rẹ̀ tálẹ́ǹtì fàdákà mẹ́wàá, ẹgbẹ̀rún mẹ́fà ìwọ̀n wúrà àti ìpààrọ̀ aṣọ mẹ́wàá.
6 Le nendese’e mb’amy mpanjaka’ Israeley añe i taratasy nanao ty hoe: Ie henaneo, ami’ty fiavi’ ty taratasy toy ama’oy, ingo fa niraheko mb’ama’o t’i Naamane mpitoroko, hañafaha’o i haangamae’ey.
Ìwé tí ó mú lọ sọ́dọ̀ ọba Israẹli kà pé, “Pẹ̀lú ìwé yìí èmi ń rán ìránṣẹ́ mi Naamani sí ọ pé o lè wò ó sàn kúrò nínú ẹ̀tẹ̀ rẹ̀.”
7 Aa ie namaky i taratasiy i mpanjakay le rinia’e o siki’eo nanao ty hoe, Andrianañahare v’iraho hahafate naho hahaveloñe, te nirahe’ ondatio amako t’indaty toy hañafahañe ty haangamae ama’e? Aa le isafirio naho oniño t’ie manao lie-drokoñe amako.
Bí ọba Israẹli ti ka ìwé náà ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì wí pé, “Èmi ha jẹ́ Ọlọ́run? Ǹjẹ́ èmi le pa kí n sì mú wá sí ààyè padà? Kí ni ó dé tí eléyìí rán ènìyàn sí mi láti wo ààrùn ẹ̀tẹ̀ rẹ sàn, kí ẹ wo bí ó ti ń wá ọ̀nà láti wá ìjà pẹ̀lú mi!”
8 Aa ie jinanji’ i Elisà, ondatin’ Añahare, te nandriatse ty saro’e i mpanjakay, le nirahe’e mb’amy mpanjakay ty hoe: Akore ty nandriata’o saroñe? Ampombao mb’ amako mb’ etoa hahafohina’e te amam-pitoky t’Israele.
Nígbà tí Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run gbọ́ pé ọba Israẹli ti ya aṣọ rẹ̀, ó sì rán iṣẹ́ yìí sí i pé, “Kí ni ó dé tí o fi fa aṣọ rẹ ya? Jẹ́ kí ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi. Òun yóò sì mọ̀ pé wòlíì wà ní Israẹli.”
9 Aa le nimb’eo t’i Naamane rekets’ o soavala’eo, naho i sarete’ey, vaho nijohañe an-dala’ i Elisà eo.
Bẹ́ẹ̀ ni Naamani sì lọ pẹ̀lú ẹṣin rẹ̀ àti kẹ̀kẹ́ rẹ̀ ó sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà ilé Eliṣa.
10 Nañitrifa’ i Elisà ìrake nanao ty hoe: Akia, misasà im-pito am’ Iordaney, le ho jangañe ty sandri’o vaho halio.
Eliṣa rán ìránṣẹ́ láti lọ sọ fún un pé, “Lọ, wẹ̀ ara rẹ ní ìgbà méje ní odò Jordani, ẹran-ara rẹ yóò sì tún padà bọ̀ sípò, ìwọ yóò sì mọ́.”
11 Fe niavotse mb’eo t’i Naamane, le hoe re amy hatorifi’ey: Inay ie, nataoko te tsy mete tsy ho niakatse amako, ho nijohañe eo nikanjy ty tahina’ Iehovà Andrianañahare’e, le hañelahela fitañe ambone’ i rarey hañafaha’e i haangamaey.
Ṣùgbọ́n Naamani lọ pẹ̀lú ìbínú ó sì wí pé, “Mo lérò pé yóò sì dìde jáde wá nítòótọ́ sí mi, yóò sì pe orúkọ Olúwa Ọlọ́run, fi ọwọ́ rẹ̀ lórí ibẹ̀ kí ó sì wo ẹ̀tẹ̀ mi sàn.
12 Tsy lombolombo’ ze hene rano’ Israele hao ty Amanà naho ty Par’pare, oñe e Damesèk’ ao? Tsy hamake hisasa ami’ty raik’ am’ iereo haliovako? Le nitsambolitio’e fa nitorìtotse.
Abana àti Fapari, odò Damasku kò ha dára ju gbogbo omi Israẹli lọ? Ṣé èmi kò le wẹ̀ nínú wọn kí n sì mọ́?” Bẹ́ẹ̀ ni ó yípadà, ó sì lọ pẹ̀lú ìrunú.
13 Niharinea’ o mpitoro’eo nanao ty hoe. O roaeko, naho nampanoe’ i mpitokiy raha ra’elahy, tsy ho nanoe’o? Àntsake t’ie nanao ty hoe: Misasà, halio?
Ìránṣẹ́ Naamani lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi, tí wòlíì bá ti sọ fún ọ láti ṣe ohun ńlá kan, ṣé ìwọ kì bá ti ṣe, mélòó mélòó nígbà náà, nígbà tí ó sọ fún ọ pé, ‘Wẹ̀ kí o sì mọ́’!”
14 Aa le nizotso mb’eo re nilipotse im-pito am’ Iordaney, ty amy saontsi’ indatin’ Àñahareiy; le nibalike indraike ho hambañe ami’ty nofon’ anak’ ajaja ty nofo’e, vaho nalio,
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ ó sì tẹ ara rẹ̀ bọ inú odò Jordani ní ìgbà méje, gẹ́gẹ́ bí ènìyàn Ọlọ́run ti sọ fún un, ẹran-ara rẹ̀ sì tún padà sí mímọ́ gẹ́gẹ́ bí ọmọkùnrin kékeré.
15 le nibalike mb’am’ indatin’ Añaharey, ie naho o mpindre-lia ama’e iabio; nimbeo re nijohañe añatrefa’e, nanao ty hoe: Fohiko henaneo te tsy aman-Añahare ty tane toy naho tsy e Israele ao avao. Ie amy zao, ehe, andrambeso ravoravo amo mpitoro’oo.
Nígbà náà Naamani àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ padà lọ sí ọ̀dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Ó sì dúró níwájú rẹ̀ ó sì wí pé, “Nísinsin yìí èmi mọ̀ pé kò sí Ọlọ́run ní gbogbo àgbáyé àyàfi ní Israẹli nìkan. Jọ̀wọ́ gba ẹ̀bùn láti ọwọ́ ìránṣẹ́ rẹ.”
16 Fa hoe re: Kanao veloñe t’Iehovà ijohañako, izaho tsy handrambe. Ndra te nosihe’e handrambe, nifoneñe.
Wòlíì náà dáhùn pé, “Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, ẹni tí mo ń sìn, èmi kò nígbà ohun kan,” bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Naamani rọ̀ ọ́ láti gbà á, ó kọ̀.
17 Le hoe t’i Naamane, Miambane ama’o, tsy hatolotse amo mpitoro’oo hao ty tane ho entam-borìke roe? Amy te le lia’e tsy hañenga horoañe ndra hanao soroñe amo ‘ndrahare ila’eo o mpitoro’oo henane zao naho tsy am’ Iehovà avao.
Naamani wí pé, “Tí o kò bá nígbà, jọ̀wọ́ jẹ́ kí a fi fún èmi ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀pọ̀ ẹrù erùpẹ̀ tí ìbáaka méjì le rù, nítorí láti òní lọ ìránṣẹ́ rẹ kì yóò rú ẹbọ sísun àti rú ẹbọ sí ọ̀kan lára àwọn ọlọ́run mìíràn mọ́ bí kò ṣe sí Olúwa.
18 Fe amo raha zao, ehe, te hapo’ Iehovà ty hakeom-pitoro’o, te ie mimoak’ an-kiboho’ i Rimone ty talèko hitalaho naho manazok’ an-tañako hibokoboko an-kiboho’ i Rimone ao; te hado’ Iehovà i tahi’ o mpitoro’ooy, izaho miambane an-kiboho’ i Rimone ao.
Ṣùgbọ́n kí Olúwa kí ó dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún nǹkan yìí. Nígbà tí ọ̀gá mi wọ inú ilé Rimoni láti fi orí balẹ̀ tí ó sì fi ara ti ọwọ́ mi tí mo sì tẹ ara mi ba pẹ̀lú níbẹ̀. Nígbà tí èmi tẹ ara mi ba ní ilé Rimoni, kí Olúwa dáríjì ìránṣẹ́ rẹ fún èyí.”
19 Le hoe re ama’e Akia, an-kanintsiñe. Aa ie nisitake eroa hoek’ eo,
Eliṣa wí pé, “Máa lọ ní àlàáfíà.” Lẹ́yìn ìgbà tí Naamani tí rin ìrìnàjò tí ó jìnnà,
20 le hoe ty natao’ i Gekazý mpitoro’ i Elisà, indatin’ Añaharey, Inge te napo’ i talèko t’i Naamane nte-Arame, ie tsy nandrambe am-pità’e o nendese’eo. Aa kanao veloñe t’Iehovà, hihitrihitry mb’ama’e iraho hangalak’ ama’e.
Gehasi, ìránṣẹ́ Eliṣa ènìyàn Ọlọ́run, ó wí fún ara rẹ̀ pé, “Ọ̀gá mi jẹ́ ẹni tí ó rọ́nú lórí Naamani, ará Aramu, nípa pé kò gba ohunkóhun ní ọwọ́ rẹ̀ ohun tí ó mú wá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti ń bẹ láààyè, èmi yóò sá tẹ̀lé e èmi yóò sì gba ohun kan ní ọwọ́ rẹ̀.”
21 Aa le niheañe’ i Gekazý t’i Naamane, le ie niisa’ i Naamane t’ie nañeañe aze, le nizotso an-tsarete’e hifañaoñe ama’e, vaho hoe re: manintsiñe hao?
Bẹ́ẹ̀ ni Gehasi sáré tẹ̀lé Naamani. Nígbà tí Naamani rí i tí ó ń sáré tẹ̀lé e, ó sì sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ̀. “Ṣé gbogbo nǹkan wà dáradára?” ó béèrè.
22 Le hoe re, Mbe soa, fa nañirak’ ahy i talèkoy, hinday ty hoe: Inao, pok’ amako aniany ty ajalahy roe anam-pitoky boak’ am-bohi’ Efraime añe, Ehe, anoloro talenta volafoty naho fiovan-tsiky roe.
“Gbogbo nǹkan wà dáradára,” Gehasi dá a lóhùn. “Ọ̀gá mi rán mi láti sọ wí pé, ‘Àwọn ọ̀dọ́ ọmọkùnrin méjì láti ọ̀dọ̀ ọmọ wòlíì wọ́n ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ mi láti orí òkè ìlú ti Efraimu. Jọ̀wọ́ fún wọn ní ẹ̀bùn fàdákà àti ìpààrọ̀ aṣọ méjì.’”
23 Le hoe t’i Naamane, Aa naho tea’o rambeso talenta roe. Le nañosik’ aze vaho nafato’e an-koroñe roe ao ty talenta volafoty roe mitraok’ ami’ty fiovan-tsaroñe roe naho nampipoha’e ami’ty mpitoro’e roe vaho nendese’ iareo aolo’e mb’eo.
Naamani wí pé, “Ní gbogbo ọ̀nà, mú ẹ̀bùn méjì.” Ó sì rọ Gehasi láti gbà wọ́n, ó sì di ẹ̀bùn méjì náà ti fàdákà ní inú àpò méjì, pẹ̀lú ìpààrọ̀ aṣọ méjì, ó sì fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì, wọ́n sì kó wọn lọ sọ́dọ̀ Gehasi.
24 Ie avy an-tamboho ey, le rinambe’e am-pità’ iareo o rahao, naho napo’e añ’ anjomba ao; naho nirahe’e mb’ eo indaty rey vaho nienga. Nimoak’ ao re nijohañe añatrefa’ i talè’ey.
Nígbà tí Gehasi sì dé ibi ilé ìṣọ́, ó gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn, ó sì tó wọ́n sínú ilé, ó sì jọ̀wọ́ àwọn ọkùnrin náà lọ́wọ́ lọ, wọ́n sì jáde lọ.
25 Le hoe t’i Elisà ama’e. Hirik’ aia v’iheo Gekazý? Le hoe re: Tsy nimb’ aia o mpitoro’oo.
Nígbà náà ó sì wọlé wá ó sì dúró níwájú ọ̀gá rẹ̀ Eliṣa. “Níbo ni o ti wà Gehasi?” Eliṣa béèrè. “Ìránṣẹ́ rẹ kò lọ sí ibìkan kan.” Gehasi dá a lóhùn.
26 Aa hoe re tama’e: Tsy nindre ama’o hao ty troko, ie nitolik’ amy sarete’ey indatiy hifanalaka ama’o? Andro handrambesan-drala ke handrambesan-tsikiñe naho tanen’ olive naho tanembahe naho añondry naho añombe naho lahilahy mpitoroñe vaho ampela mpitoroñe hao henaneo?
Ṣùgbọ́n Eliṣa wí fún un pé, “Ẹ̀mí mi kò ha wà pẹ̀lú rẹ nígbà tí ọkùnrin náà sọ̀kalẹ̀ lórí kẹ̀kẹ́ láti pàdé rẹ? Ṣé àsìkò tí ó yẹ láti gba owó nìyìí, tàbí láti gba aṣọ, ọgbà olifi, ọgbà àjàrà, àgùntàn, màlúù tàbí ìránṣẹ́kùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin?
27 Aa le hipitek’ ama’o naho amo tiri’oo nainai’e ty haangamae’ i Naamane. Aa le angamae foty mikatsatsaoke re te niavota’e.
Ẹ̀tẹ̀ Naamani yóò lẹ̀ mọ́ ọ àti sí irú-ọmọ rẹ títí láé.” Nígbà náà Gehasi kúrò níwájú Eliṣa, ó sì di adẹ́tẹ̀, ó sì funfun gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ̀n òwú.