< 1 Samoela 9 >
1 Ie amy zao, teo t’ondaty nte-Beniamine atao Kise, ana’ i Abiele, ana’ i Tserore, ana’ i Bekorate, ana’ i Afiàke, ana’ Ieminý, ondaty fatratse.
Ará Benjamini kan wà, ẹni tí ó jẹ́ aláàánú ọlọ́rọ̀, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiṣi, ọmọ Abieli, ọmọ Serori, ọmọ Bekorati, ọmọ Afiah ti Benjamini.
2 Amañ’ ana-dahy re, i Saòle ty tahina’e, ajalahy montsotsòre. Tsy amo ana’ Israele iabio ty nisoa vintañe te ama’e, le an-tsoro’e mañambone ty nilikoare’e ondaty iabio.
Ó ní ọmọkùnrin kan tí à ń pè ní Saulu, ọ̀dọ́mọkùnrin tí ó yanjú, tí ó jẹ́ arẹwà, tí kò sí ẹni tó ní ẹwà jù ú lọ láàrín gbogbo àwọn ọmọ Israẹli—láti èjìká rẹ̀ lọ sí òkè, ó ga ju gbogbo àwọn ènìyàn tókù lọ.
3 Nimotso amy zao o borìke-rene’ i Kise, rae’ i Saoleo. Le hoe t’i Kise amy Saole ana’e, Endeso ty mpitoroñe vaho miongaha, akia, paiao i borìke rey.
Nísinsin yìí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó jẹ́ ti Kiṣi baba Saulu sì sọnù. Nígbà náà, Kiṣi sọ fún Saulu ọmọ rẹ̀ pé, “Mú ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́ pẹ̀lú rẹ kí ẹ lọ láti wá àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà.”
4 Nisoroke ty vohi’ Efraime re vaho niranga mb’an-tane’ Salisà añe, f’ie tsy nioniñe. Aa le niary mb’ an-tane Salime fe tsy tao, niranga ty tane’ o nte-Beniamineo, f’ie tsy niisa’ iareo.
Bẹ́ẹ̀ ní ó kọjá láàrín àwọn ìlú olókè Efraimu, ó sì kọjá ní àyíká ilẹ̀ Ṣaliṣa, ṣùgbọ́n wọn kò rí wọn. Wọ́n sì kọjá lọ sí òpópó Ṣaalimu, ṣùgbọ́n àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ kò sí níbẹ̀. Nígbà náà, ó kọjá ní agbègbè Benjamini, wọn kò sì rí wọn.
5 Aa ie nivotrak’ an-tane’ Tsofaý añe le hoe re amy mpitoro’ey, Antao hibalike hera hapon-draeko ty fihakahakà’e amo borìkeo vaho itika ka ty himarimariha’e.
Nígbà tí wọ́n dé agbègbè Sufu, Saulu sọ fún ìránṣẹ́ tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Wá, jẹ́ kí á padà sẹ́yìn, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, baba mi yóò dá ìrònú rẹ̀ dúró nípa àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ yóò sì bẹ̀rẹ̀ àníyàn nípa wa.”
6 Le hoe re ama’e, Inao te an-drova aroa-hoekeo ty ondatin’ Añahare aman-kasy le tsy mete tsy mifetsake ze hene saontsie’e; antao ho mb’eo, hera hatalili’e ty lala-komban-tika.
Ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ náà fún un ní èsì pé, “Wò ó, ní inú ìlú yìí ọkùnrin ènìyàn Ọlọ́run kan wà; ó jẹ́ ẹni tí wọ́n ń bu ọlá fún, àti gbogbo ohun tí ó bá sọ ní ó máa ń jẹ́ òtítọ́. Jẹ́ kí á lọ síbẹ̀ nísinsin yìí, bóyá yóò sọ fún wá ọ̀nà tí a yóò gbà.”
7 Aa hoe t’i Saole amy mpitoro’ey, Aa naho miheo mb’eo tika, ino ty ho banabanaen-tika am’indatiy? fa ritse ty mofo an-karon-tikañ’ ao vaho tsy eo ty ravoravo hatolotse am’indatin’ Añaharey; ino ty aman-tika?
Saulu sọ fún ìránṣẹ́ rẹ̀, “Tí àwa bá lọ, kín ni àwa lè fún ọkùnrin náà? Oúnjẹ inú àpò wa ti tán. A kò sì ní ẹ̀bùn láti mú lọ sọ́dọ̀ ènìyàn Ọlọ́run. Kí ni a ní?”
8 Le hoe ty natovo’ i mpitoroñey amy Saole, Intoy an-tañako ty fah’ efa’ ty bogady volafoty, hatoloko am’ indatin’ Añaharey hitoroa’e ty homban-tikañe,
Ìránṣẹ́ sì dá a lóhùn lẹ́ẹ̀kan sí i. “Wò ó,” ó wí pé, “Mo ní ìdámẹ́rin ṣékélì fàdákà lọ́wọ́. Èmi yóò fún ènìyàn Ọlọ́run náà kí ó lè fi ọ̀nà hàn wá.”
9 (Ie te taolo e Israele ao, naho nimb’eo t’indaty hañontane aman’ Añahare, le hoe re: Antao homb’ amy mpioniñey: fa natao mpioniñe henane zay ty atao mpitoky henaneo.)
(Tẹ́lẹ̀ ní Israẹli tí ọkùnrin kan bá lọ béèrè lọ́dọ̀ Ọlọ́run, yóò wí pé, “Wá, jẹ́ kí a lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì náà,” nítorí àwọn alásọtẹ́lẹ̀ ìsinsin yìí ni wọ́n ń pè ní wòlíì).
10 Aa le hoe t’i Saole amy mpitoro’ey, To o reha’oo, antao hizilike, le nimoak’ an-drova’ indatin’ Añaharey ao.
Saulu sọ fún ìránṣẹ́ ẹ rẹ̀ pé ó dára, “Jẹ́ kí a lọ.” Wọ́n jáde lọ sí ìlú tí ènìyàn Ọlọ́run náà ń gbé.
11 Aa ie nañambone’ i fitroarañe mb’ amy rovay mb’eoy, le nitendreke somondrara niakatse hitoha rano, vaho nanoa’e ty hoe: Eo v’i mpioniñey?
Bí wọ́n ṣe ń lọ ní orí òkè sí ìlú náà, wọ́n pàdé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin tí ó ń jáde í bọ̀ láti wá pọn omí. Wọ́n sì bi wọ́n, “Ṣé wòlíì náà wà níbí?”
12 Le hoe ty natoi’e, Eo re; toe aolo’ areo; ihitrifo henaneo, ie nimb’ an-drova mb’eo anindroany, amy te fisoroñañe ho a ondatio ty an-kaboañe ey te anito.
“Ó wà,” wọ́n dáhùn. “Ó ń bẹ níwájú u yín, múra nísinsin yìí, ó ṣẹ̀ṣẹ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wa lónìí ni, nítorí àwọn ènìyàn ní ẹbọ rírú ni ibi gíga.
13 Ie mimoak’ an-drova nahareo le ho tendrek’ ama’e aolo’ ty hitroara’e mb’ an-kaboañe mb’eo hikama; fa tsy hikama ondatio naho tsy miheo mb’eo hey re, amy t’ie ty mpitata i soroñey; izay vaho mikama o nambaràñeo. Aa le mionjona henaneo; fa ho oni’ areo.
Kété tí ẹ bá ti wọ ìlú, ẹ ó rí i kí ó tó lọ sí ibi gíga láti lọ jẹun. Àwọn ènìyàn kò sì ní bẹ̀rẹ̀ sí jẹun títí tí yóò fi dé. Torí ó gbọdọ̀ bùkún ẹbọ náà; lẹ́yìn náà, àwọn tí a pè yóò jẹun. Gòkè lọ nísinsin yìí, ó yẹ kí ẹ rí i ní àkókò yìí.”
14 Aa le nionjom-b’an-drova mb’eo iereo; le ie nimoak’ amy rovay, hehe te boak’ ao hifanampe am’ iereo t’i Samoele, mihitrike mb’an’ kaboañe mb’eo.
Wọ́n gòkè lọ sí ìlú náà, bí wọ́n ti ń wọlé, níbẹ̀ ni Samuẹli, ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ wọn bí ó ti ń lọ ibi gíga náà.
15 Ie amy zao fa nabenta’ Iehovà amy Samoele, an-dravembia’e omale te hivotrake t’i Saole, ami’ty hoe:
Olúwa ti sọ létí Samuẹli ní ọjọ́ kan kí Saulu ó tó dé pé,
16 Hamaray hoe zao, ty hañirahako ama’o t’indaty boak’an-tane Beniamine, ie ty horiza’o ho mpanjaka hifehe’ ondatiko Israeleo, le ie ty handrombake ondatikoo am-pità’ o nte Pilistio; fa nisarieko ondatikoo, le niheo amako ty fitoreova’ iareo.
“Ní ìwòyí ọ̀la, èmi yóò ran ọmọkùnrin kan sí ọ láti ilẹ̀ Benjamini. Fi òróró yàn án gẹ́gẹ́ bí olórí lórí àwọn ọmọ Israẹli, yóò gba àwọn ènìyàn mi kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Filistini. Mo ti bojú wo àwọn ènìyàn mi, nítorí igbe wọn ti dé ọ̀dọ̀ mi.”
17 Aa ie niisa’ i Samoele t’i Saole, le hoe t’Iehovà ama’e, Hehek’ indaty nanoeko ama’o ty hoe: Io hoekeo ty hifeleke ondatikoo.
Nígbà tí Samuẹli fojúrí Saulu, Olúwa sọ fún un pé, “Èyí ni ọkùnrin tí mo sọ fún ọ nípa rẹ̀, yóò darí àwọn ènìyàn mi.”
18 Nitotok’ amy Samoele t’i Saole an-dalambey eo, nanao ty hoe: Ehe, isaontsio te aia ty anjomba’ i mpioniñey.
Saulu sì súnmọ́ Samuẹli ní ẹnu-ọ̀nà ìlú, ó sì wí pé, “Sọ fún mi èmi ń bẹ̀ ọ́ níbo ni ilé wòlíì náà wà.”
19 Aa le hoe ty natoi’ i Samoele, Izaho o mpioniñeo; miaoloa ahy mb’ ankaboañe ey, amy t’ie hitrao-pikama amako anito; le hapoko hañavelo te maray vaho hene ho taroñeko ama’o ze añ’arofo’o.
Samuẹli dáhùn pé, “Èmi ni wòlíì náà. Ẹ máa gòkè lọ ṣáájú mi, ní ibi gíga, ẹ ó sì bá mi jẹun lónìí. Ní òwúrọ̀ ni èmi yóò tó jẹ́ kí ẹ lọ, gbogbo ohun tí ó wà ní ọkàn rẹ ní èmi yóò sọ fún ọ.
20 Le i borì’o ni-motso telo andro zay, ko vetsevetse’o; fa nirendreke. Aa vaho ama’ ia ty fisalala’ Israele iaby? Tsy ama’o hao naho amy anjomban-drae’oy?
Fún ti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ tí ó sọnù fún ọjọ́ mẹ́ta sẹ́yìn, má ṣe dààmú nípa wọ́n: a ti rí wọn. Sí ta ni gbogbo ìfẹ́ Israẹli wà? Bí kì í ṣe sí ìwọ àti sí gbogbo ilé baba à rẹ.”
21 Nanoiñe ami’ ty hoe t’i Saole: Tsy nte-Beniamine hao iraho, ty kede amo fifokoa’ Israele iabio? ty hasavereña’ay ka ro kede amo hene’ hasavereña’ i Beniamineo? aa vaho ino o saontsia’oo?
Saulu dáhùn pé, “Ṣùgbọ́n èmi kì í há ṣe ẹ̀yà Benjamini? Kékeré nínú ẹ̀yà Israẹli. Ìdílé mi kò ha rẹ̀yìn jùlọ nínú gbogbo ẹ̀yà Benjamini? Èéṣì ti ṣe tí ìwọ sọ̀rọ̀ yìí sí mi?”
22 Nendese’ i Samoele t’i Saole naho i mpitoro’ey, naho nampihovae’e añ’anjomba’e vaho nampiambesare’e an-dohà’ o nambaràñe iabio; nitelo-polo varañe ondatio.
Nígbà náà ni Samuẹli mú Saulu pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ inú gbọ̀ngán, ó sì mú wọn jókòó sí iwájú àwọn tí a pè—tí wọn tó ọgbọ̀n.
23 Le hoe t’i Samoele amy mpanokoñey, Azotsò i fate-kena natoloko azoy, i nataoko ty hoe: Apoho añ’ila’o.
Samuẹli sọ fún alásè pé, “Mú ìpín ẹran tí mo fún ọ wá, èyí tí mo sọ fún ọ pé kí o yà sọ́tọ̀.”
24 Aa le rinambe’ i mpanokoñey ty sokataña’e reketse ze ama’e vaho nazotso’e amy Saole. Le hoe t’i Samoele: Ingo o navìkeo! apoho añatrefa’o le mikamà; fa nahaja ho azo amo famantañañe zao; hoe ka ty asako: Fa nambaràko ondaty reo. Aa le nitrao-pikama amy Samoele t’i Saole amy andro zay.
Alásè náà sì gbé ẹsẹ̀ náà pẹ̀lú ohun tí ó wà lórí i rẹ̀, ó sì gbé e síwájú Saulu. Samuẹli wí pé, “Èyí ni ohun tí a fi pamọ́ fún ọ. Jẹ, nítorí a yà á sọ́tọ̀ fún ọ, fún ìdí yìí, láti ìgbà tí mo ti wí pé, ‘Mo ní àlejò tí a pè.’” Saulu sì jẹun pẹ̀lú Samuẹli ní ọjọ́ náà.
25 Aa ie nizotso mb’ an-drova mb’eo boak’ an-kaboañey, le nifanaontsy amy Saole an-tafon’anjomba.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọn ti sọ̀kalẹ̀ láti ibí gíga náà wá sí inú ìlú, Samuẹli sì bá Saulu sọ̀rọ̀ lórí òrùlé ilé e rẹ̀.
26 Aa le nañaleñaleñe iereo, naho kinanji’ i Samoele t’i Saole homb’ an-tafo mb’eo te manjirike àndro, ami’ty hoe: Mitroara fa haseseko. Aa le niongake t’i Saole naho niavotse mb’eo ie roe.
Wọ́n sì dìde ní àfẹ̀mọ́júmọ́, ó pe Saulu sórí òrùlé pé, “Múra, èmi yóò rán ọ lọ.” Nígbà tí Saulu múra tán òun àti Samuẹli jọ jáde lọ síta.
27 Ie nizotso mb’am-pigadoña’ i rovay mb’eo le hoe t’i Samoele amy Saole: Ampandenao aolon-tika mb’eo o mpitoro’oo—aa le nionjom-beo re; fa ihe mijohaña hey, hampijanjiñako ty tsaran’ Añahare.
Bí wọ́n ti ń sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìpẹ̀kun ìlú náà, Samuẹli wí fún Saulu pé, “Sọ fún ìránṣẹ́ náà kí ó máa lọ ṣáájú u wa,” ìránṣẹ́ náà sì ṣe bẹ́ẹ̀, “Ṣùgbọ́n kí ìwọ kí ó dúró díẹ̀, kí èmi kí ó lè sọ ọrọ̀ láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run fún ọ.”