< 1 Samoela 16 >

1 Hoe t’Iehovà amy Samoele: Pak’ombia t’ie mbe handala i Saole kanao fa nadòko tsy ho mpanjaka’ Israele ka? lipolipò menake i tsifa’oy le akia, fa hiraheko mb’am’ Iisay nte-Betlekheme mb’eo fa nijoboñeko mpanjaka ho ahy ty raik’ amo ana’eo.
Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Yóò ha ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò máa dárò Saulu, nígbà tí ó jẹ́ pé mo ti kọ̀ ọ́ ní ọba lórí Israẹli? Rọ òróró kún inú ìwo rẹ, kí o sì mú ọ̀nà rẹ pọ̀n, Èmi rán ọ sí Jese ará Bẹtilẹhẹmu. Èmi ti yan ọ̀kan lára àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ láti jẹ ọba.”
2 Le hoe t’i Samoele, Akore ty handenàko mb’eo? ke ho rendre’ i Saole, hañohofa’e loza. Le hoe t’Iehovà. Andeso tamana vaho anò ty hoe: Pok’ atoy iraho hanao soroñe am’ Iehovà.
Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Báwo ni èmi yóò ṣe lọ? Bí Saulu bá gbọ́ nípa rẹ̀, yóò pa mi.” Olúwa wí pé, “Mú abo ẹgbọrọ màlúù kan pẹ̀lú rẹ, kí o sì wí pé, ‘Èmi wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa.’
3 Kanjio t’Iisay hiatrefa’e i soroñey, le hatoroko azo ze hanoe’o, vaho horiza’o ho ahy ty hitoñonako añarañe.
Pe Jese wá sí ibi ìrúbọ náà, Èmi yóò sì fi ohun tí ìwọ yóò ṣe hàn ọ́. Ìwọ yóò fi òróró yàn fún mi, ẹni tí èmi bá fihàn ọ́.”
4 Le nanoe’ i Samoele i tsinara’ Iehovày vaho niheo mb’e Betlekheme mb’eo. Le ninevenevetse amy fitotsaha’ey o androanavi’ i rovaio nanao ty hoe: An-kanintsiñe hao ty ivotraha’o atoy?
Samuẹli ṣe ohun tí Olúwa sọ. Nígbà tí ó dé Bẹtilẹhẹmu, àyà gbogbo àgbàgbà ìlú já, nígbà tí wọ́n pàdé rẹ̀. Wọ́n béèrè pé, “Ṣé àlàáfíà ní ìwọ bá wá?”
5 Le hoe re, Fañanintsiñe, pok’ eo iraho hisoroñe amy Iehovà; mañefera vatañe, naho mindreza amako mb’ amy soroñey; le nefera’e ka t’Iisay naho o ana’eo vaho nambara’e homb’ amy soroñey.
Samuẹli sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni àlàáfíà ni; mo wá láti wá rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ ya ara yín sí mímọ́, kí ẹ sì wá rú ẹbọ pẹ̀lú mi.” Nígbà náà ni ó sì ya Jese sí mímọ́ pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì pè wọ́n wá sí ibi ìrúbọ náà.
6 Ie nihirike, le nitalare’e t’i Eliabe, nitsakore ty hoe; Toe añatrefa’ Iehovà eo i horìza’ey.
Nígbà tí wọ́n dé, Samuẹli rí Eliabu, ó rò nínú ara rẹ̀ pé lóòótọ́ ẹni òróró Olúwa dúró níbí níwájú Olúwa.
7 Fe hoe t’Iehovà amy Samoele; Ko mandrèndreke ty lahara’e ndra ty haabo’ ty fijohaña’e, amy t’ie fa nadòko; toe tsy ami’ty fahaisaha’ ondatio ro ie, amy te mandrèndreke ty vinta’e alafe’e ondatio, vaho mandrendrek’ arofo t’Iehovà.
Ṣùgbọ́n Olúwa sọ fún Samuẹli pé, “Má ṣe wo ti ìrísí rẹ̀ tàbí ti gíga rẹ̀, nítorí èmi ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀. Olúwa kì í wo ohun tí ènìyàn máa ń wò. Ènìyàn máa ń wo òde ara ṣùgbọ́n Olúwa máa ń wo ọkàn.”
8 Kinanji’ Iisay t’i Abinadabe vaho nampiarie’e añatrefa’ i Samoele. Fa hoe re, Tsy jinobo’ Iehovà toke.
Nígbà náà ni Jese pe Abinadabu, ó sì jẹ́ kí ó rìn kọjá ní iwájú Samuẹli. Ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí.”
9 Nampiarie’ Iisay ama’e ka t’i Samà, fa hoe re, toe tsy jinobo’ Iehovà ka toke.
Jese sì jẹ́ kí Ṣamma rìn kọjá ní iwájú Samuẹli, ṣùgbọ́n Samuẹli wí pé, “Olúwa kò yan ẹni yìí náà.”
10 Aa le nampiarie’ Iisay añatrefa’ i Samoele ty ana-dahi’e fito, fa hoe t’i Samoele am’ Iisay, Tsy jinobo’ Iehovà o retoañe.
Jese jẹ́ kí àwọn ọmọ rẹ̀ méje rìn kọjá ní iwájú Samuẹli ṣùgbọ́n Samuẹli sọ fún un pé, “Olúwa kò yan àwọn wọ̀nyí.”
11 Le hoe t’i Samoele am’Iisay, Etoañ’ iaby hao o ana’oo? le hoe re: Mbe añe ty tsitso’e; toe miarak’ añondry. Le hoe t’i Samoele am’ Iisay: Ampañitrifo; fa tsy hivory tika ampara’ t’ie pok’eo.
Nígbà náà ni ó béèrè lọ́wọ́ Jese pé, “Ṣé èyí ni gbogbo àwọn ọmọ rẹ?” Jese dáhùn pé, “Ó ku àbíkẹ́yìn wọn, ó ń tọ́jú agbo àgùntàn.” Samuẹli sì wí pé, “Rán ìránṣẹ́ lọ pè é wá; àwa kò ní jókòó títí òun yóò fi dé.”
12 Aa le nampañitrife’e naho nampizilihe’e. Volovoloen-dre, niloeloe o maso’eo naho naràm-bintañe; vaho hoe t’Iehovà: Miongaha orizo, ie toke.
Ó sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n sì mú un wọlé wá, ó jẹ́ ẹni tó mọ́ra, àwọ̀ ara rẹ̀ dùn ún wò, ó jẹ́ arẹwà gidigidi. Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Dìde kí o sì fi òróró yàn án, òun ni ẹni náà.”
13 Aa le rinambe’ i Samoele i tsifa ama’ menakey naho noriza’e añivo’ o longo’eo; vaho namparin­gatse i Davide henane zay ty Arofo’ Iehovà. Le niongake t’i Samoele nimb’ e Ramà mb’eo.
Nígbà náà ni Samuẹli mú ìwo òróró, ó sì ta á sí i ní orí ní iwájú àwọn ẹ̀gbọ́n rẹ̀, láti ọjọ́ náà lọ, Ẹ̀mí Mímọ́ Olúwa wá sí orí Dafidi nínú agbára. Samuẹli sì lọ sí Rama.
14 Ie amy zao, fa nienga i Saole ty Arofo’ Iehovà, vaho nañangara’ ty fañahy raty boak’ am’ Iehovà.
Nísinsin yìí, ẹ̀mí Olúwa ti kúrò lára Saulu, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa sì ń yọ ọ́ lẹ́nu.
15 Le hoe o mpitoro’ i Saoleo ama’e: Eo hey, toe fañahy raty boak’ aman’ Añahare ty mañangatse azo henaneo;
Àwọn ìránṣẹ́ Saulu sì wí fún un pé, “Wò ó, ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ń yọ ọ́ lẹ́nu.
16 ee te hafanto’ i talè’ay henaneo o mpitoro’e miatrek’ azeo, ty hitsoeke mpititike maro-taly mahimbañe; aa ie mañangats’ ama’o i fañahy raty boak’ aman’ Añaharey, le hititiha’e am-pità’e, hampanintsiñ’ azo.
Jẹ́ kí olúwa wa pàṣẹ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó wà níhìn-ín láti wa ẹnìkan tí ó lè fi dùùrù kọrin. Yóò sì ṣe é nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run bá bà lé ọ, ìwọ yóò sì sàn.”
17 Le hoe t’i Saole amo mpitoro’eo: Paiao ho ahy henaneo t’indaty mahafititike, le endeso mb’amako mb’etoa.
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ wá ẹnìkan tí ó lè kọrin dáradára kí ẹ sì mú u wá fún mi.”
18 Aa hoe ty natoi’ ty ajalahy, Inao, nitrea’ay ty ana’ Iisay nte-Betlekheme, mpititike mahay, ie fanalolahy naho lahindefoñe, mahity am-pitoloñañe, ondaty soa vintañe vaho ama’e t’Iehovà.
Ọ̀kan nínú ìránṣẹ́ náà dáhùn pé, “Èmi ti ri ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Jese ti Bẹtilẹhẹmu tí ó mọ orin kọ, ó jẹ́ alágbára àti ológun. Ó ní ọgbọ́n ọ̀rọ̀ òun sì dára ní wíwò. Olúwa sì wà pẹ̀lú u rẹ̀.”
19 Aa le nahitri’ i Saole am’Iisay ty hoe: Iraho mb’ amako mb’etoa i Davide ana’o mpiarak’ añondriy.
Saulu sì rán oníṣẹ́ sí Jese wí pé, “Rán Dafidi ọmọ rẹ sí mi, ẹni tí ó ń ṣọ́ àgùntàn.”
20 Le nandrambe borìke t’Iisay naho nampilogologoe’e mofo naho ty zonjòn-divay naho ty vik’ose vaho nampihitrife’e mb’ amy Saole mb’eo añamy Davide, ana’e.
Jese sì mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ti a di ẹrù lé àti ìgò ọtí wáìnì àti ọmọ ewúrẹ́; ó sì rán wọn nípa ọwọ́ Dafidi ọmọ rẹ̀ sí Saulu.
21 Nimb’ amy Saole mb’eo t’i Davide naho nijohañe añatrefa’e; le vata’e nikokoa’e; vaho nanoe’e mpinday ty fikala’e.
Dafidi sì tọ Saulu lọ, ó sì dúró níwájú rẹ̀, òun sì fẹ́ ẹ gidigidi, Dafidi sì wá di ọ̀kan nínú àwọn tí ń ru ìhámọ́ra rẹ̀.
22 Le nahitri’ i Saole am’ Iisay ty hoe: Ehe, iantofo te hijohañe añatrefako t’i Davide, ie nanjo fañisohañe am-pahatreavako.
Nígbà náà ni Saulu ránṣẹ́ sí Jese pé, “Jẹ́ kí Dafidi dúró níwájú mi, nítorí tí ó wù mí.”
23 Aa ndra mb’ia nañangaram-pañahy boak’ aman’ Añahare t’i Saole le rinambe’ i Davide i marovaniy naho nititihe’e am-pità’e; le nitotòtse t’i Saole, vaho nanintsiñe fa nisitak’ ama’e i anga-dratiy.
Ó sì ṣe, nígbà tí ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá bá dé sí Saulu, Dafidi a sì fi ọwọ́ rẹ̀ kọrin lára dùùrù: a sì san fún Saulu, ara rẹ̀ a sì dá; ẹ̀mí búburú náà a sì fi sílẹ̀.

< 1 Samoela 16 >