< 1 Mpanjaka 6 >
1 Aa ie amy taom-paha-efajato-tsi-valompolo niavota’ o ana’ Israeleo an-tane’ i Mitsraimey, amy taom-paha-efam-pifehea’ i Selomò Israeley, amy volantatakey, i volam-paharoey, ty namotorañe ty fañamboara’e i anjomba’ Iehovày.
Ní ìgbà tí ó pe ọ̀rìnlénírinwó ọdún lẹ́yìn ìgbà tí àwọn ọmọ Israẹli ti jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, ní ọdún kẹrin ìjọba Solomoni lórí Israẹli, ní oṣù Sifi, tí ń ṣe oṣù kejì, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ ilé Olúwa.
2 Ty anjomba rinanji’ i Selomò am’ Iehovà, ie kiho enem-polo ty andava’e naho kiho roapolo ty am-pohe’e vaho kiho telopolo ty haabo’e.
Ilé náà tí Solomoni ọba kọ́ fún Olúwa sì jẹ́ ọgọ́ta ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn, ogún ìgbọ̀nwọ́ ní ìbú àti ọgbọ̀n ìgbọ̀nwọ́ ní gíga.
3 Ty lavaranga aolo’ i efe-bei’ i anjombay le roapolo kiho ty andava’e, mira ami’ty am-pohe’ i anjombay; vaho folo kiho ty am-pohe’e aolo’ i anjombay eo.
Ìloro níwájú tẹmpili ilé náà, ogún ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn rẹ̀, ìbú ilé náà, ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá láti iwájú ilé náà.
4 Nandranjia’e lalan-kede i anjombay, bey ty ampohe’ ty añate’e naho maifitse ty alafe’e.
Ó sì ṣe fèrèsé tí kò fẹ̀ fún ilé náà.
5 Natratrañà’e o rindri’ i anjombaio mañarikatoke i anjombay, naho i efetse beiy vaho i efe-miavakey; aa le nandranjia’e efets’ efetse ty mañariary aze;
Lára ògiri ilé náà ni ó bu yàrá yíká; àti tẹmpili àti ibi mímọ́ jùlọ ni ó sì ṣe yàrá yíká.
6 o efetse ambaneo le kiho lime ty ampohe’e, naho enen-kiho ty añivo’e vaho kiho fito ty fahatelo’e; nandranjia’e soñy i rindriñe alafe’ i anjombay mañariary azey, soa tsy hifahatse amo rindri’ i anjombaio o manantañeo; amy te,
Yàrá ìsàlẹ̀ sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní ìbú, ti àárín sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́fà ní ìbú, àti ẹ̀kẹta ìgbọ̀nwọ́ méje sì ni ìbú rẹ̀. Nítorí lóde ilé náà ni ó dín ìgbọ̀nwọ́ kọ̀ọ̀kan káàkiri, kí igi àjà kí ó má ba à wọ inú ògiri ilé náà.
7 ie narafitse i anjombay, le narafitse am-bato nihentseñeñe am-pihaliañe añe; vaho tsy nijanjiñeñe amy anjombay am-pandranjiañe aze ty ana-bato ndra fekoñe ndra haraotse viñe.
Ní kíkọ́ ilé náà, òkúta tí a ti gbẹ́ sílẹ̀ kí a tó mú un wá ibẹ̀ nìkan ni a lò, a kò sì gbúròó òòlù tàbí àáké tàbí ohun èlò irin kan nígbà tí a ń kọ́ ọ lọ́wọ́.
8 Ty lala’ o mizakitse añ’ila ankavana’ i anjombaio, le nionjoñe am-panongañe nivanditse mb’amo mizakitse añivoo, vaho boak’ amy añivoy pak’ amy fahateloy.
Ẹnu-ọ̀nà yàrá ìsàlẹ̀ sì wà ní ìhà gúúsù ilé náà; wọ́n sì fi àtẹ̀gùn tí ó lórí gòkè sínú yàrá àárín, àti láti yàrá àárín bọ́ sínú ẹ̀kẹta.
9 Aa le rinanji’e i anjombay naho nifonira’e; vaho kinape’e varambañe naho boda mendoraveñe i anjombay.
Bẹ́ẹ̀ ni ó kọ́ ilé náà, ó sì parí rẹ̀, ó sì bo ilé náà pẹ̀lú àwọn ìtí igi àti pákó kedari.
10 Le rinanji’e vatsa hañarikatoke i anjombay, songa kiho lime ty haabo’e; ie nirampy amy anjombay am-boda-mendoraveñe.
Ó sì kọ́ yàrá ẹ̀gbẹ́ sí gbogbo ilé náà. Gígùn ọ̀kọ̀ọ̀kan sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún, ó sì so wọ́n mọ́ ilé náà pẹ̀lú ìtì igi kedari.
11 Aa le niheo amy Selomò ty tsara’ Iehovà nanao ty hoe:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Solomoni wá wí pé,
12 O anjomba amboare’oo: ie añaveloa’o o fañèkoo naho anoe’o o nafepèkoo vaho hene ambena’o o lilikoo, hañaveloa’o, le hajadoko ama’o i entako nitsaraeko amy Davide rae’oy,
“Ní ti ilé yìí tí ìwọ ń kọ́ lọ́wọ́, bí ìwọ bá tẹ̀lé àṣẹ mi, tí ìwọ sì ṣe ìdájọ́ mi, tí o sì pa òfin mi mọ́ láti máa ṣe wọ́n, Èmi yóò mú ìlérí tí mo ti ṣe fún Dafidi baba rẹ̀ ṣẹ nípa rẹ̀.
13 te himoneñe añivo’ o ana’ Israeleo iraho, vaho tsy haforintseko ondatiko Israeleo.
Èmi yóò sì máa gbé àárín àwọn ọmọ Israẹli, èmi kì ó sì kọ Israẹli ènìyàn mi.”
14 Aa le rinanji’ i Selomò i anjombay vaho nahafonitse.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni kọ́ ilé náà, ó sì parí rẹ̀.
15 Le rinanji’e am-baramba mendoraveñe o rindriñe amy anjombaio boak’ an-tane pak’ an-tsazo’e ambane riha eo; le nilafiha’e hatae o añate’e iabio vaho nilafiha’e haradranto ty ambane eo.
Ó sì fi pákó kedari tẹ́ ògiri ilé náà nínú, láti ilẹ̀ ilé náà dé àjà rẹ̀, ó fi igi bò wọ́n nínú, ó sì fi pákó firi tẹ́ ilẹ̀ ilé náà.
16 Natratraña’e kiho roapolo ty amboli’ i anjombay, am-baramba mendoraveñe mifototse an-tane pak’ an-tapenake, nanoa’e efetse añate’e ao ho toem-pitsarañe, ho toetse masiñe do’e.
Ó pín ogún ìgbọ̀nwọ́ sí ẹ̀yìn ilé náà, láti ilẹ̀ dé àjà ilé ni ó fi pákó kedari kọ́, èyí ni ó kọ sínú, fún ibi tí a yà sí mímọ́ àní Ibi Mímọ́ Jùlọ.
17 I trañoy—i efetse aolo’ i masiñe do’eiy, le efa-polo kiho ty an-dava’e.
Ní iwájú ilé náà, ogójì ìgbọ̀nwọ́ ni gígùn rẹ̀ jẹ́.
18 Sinokitse sarem-bebeke naho voñe miborake o mendoraveñe añate’ i anjombaio; ama’ mendoraveñe iaby izay, tsy nahaisaham-bato.
Inú ilé náà sì jẹ́ kedari, wọ́n ṣe iṣẹ́ ọnà rẹ̀ pẹ̀lú ìrudí àti ìtànná. Gbogbo rẹ̀ sì jẹ́ kedari; a kò sì rí òkúta kan níbẹ̀.
19 Hinalanka’e amy anjombay i toe-miavakey, hampidona’e i vatam-pañina’ Iehovày.
Ó sì múra ibi mímọ́ jùlọ sílẹ̀ nínú ilé náà láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa ka ibẹ̀.
20 Kiho roapolo ty andava’e miaolo i toe-miavakey, naho kiho roapolo ty am-pohe’e le kiho roapolo ty haabo’e, le nitemere’e volamena ki’e; napo’e ao ka ty kitrely, le sinaro’e mendoraveñe.
Inú ibi mímọ́ náà sì jẹ́ ogún ìgbọ̀nwọ́ ní gígùn, ogún ìgbọ̀nwọ́ ní ìbú, àti ogún ìgbọ̀nwọ́ ní gíga. Ó sì fi kìkì wúrà bo inú rẹ̀ ó sì fi igi kedari bo pẹpẹ rẹ̀.
21 Nitemere’ i Selomò am-bolamena ki’e ka i trañoy, naho kinazaza’e silisily volamena ty aolo’ i toe-miavakey vaho nandafiha’e volamena.
Solomoni sì fi kìkì wúrà bo inú ilé náà, ó sì tan ẹ̀wọ̀n wúrà dé ojú ibi mímọ́ jùlọ, ó sì fi wúrà bò ó.
22 Hene nitemere’e am-bolamena i trañoy, ampara’ te nifonitse i trañoy; vaho nipakora’e volamena iaby ty kitreli’ i toe-miavakey.
Gbogbo ilé náà ni ó fi wúrà bò títí ó fi parí gbogbo ilé náà, àti gbogbo pẹpẹ tí ó wà níhà ibi mímọ́ jùlọ, ni ó fi wúrà bò.
23 Nandranjia’e kerobe roe an-talý i toe-miavakey, songa kiho folo ty haabo’e.
Ní inú ibi mímọ́ jùlọ ni ó fi igi olifi ṣe kérúbù méjì, ọ̀kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá ní gíga.
24 Kiho lime ty ela’ ty kerobe raike, naho kiho lime i ela ila’ey; kiho folo ty boak’an-dengon-ela’e raike pak’an-dengo’ i ila’ey.
Apá kérúbù kìn-ín-ní sì jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún ní gíga, àti apá kérúbù kejì ìgbọ̀nwọ́ márùn-ún; ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá láti ṣóńṣó apá kan dé ṣóńṣó apá kejì.
25 Nivelatse kiho folo ka i kerobe raikey, songa aman-jehe mira naho aman-kabey mira i kerobe roe rey.
Ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá sì ni kérúbù kejì pẹ̀lú, nítorí kérúbù méjèèjì jọ ara wọn ní ìwọ̀n ní títóbi àti títẹ̀wọ̀n bákan náà.
26 Folo kiho ty haabo’ ty kerobe raike, mira ama’e ty ila’e.
Gíga kérúbù kọ̀ọ̀kan jẹ́ ìgbọ̀nwọ́ mẹ́wàá.
27 Napo’e añivo’ i efetse añate’ey i kerobe rey, le nivelareñe ty ela’ o kerobeo naho nioza ami’ty rindriñe ty ela’ ty raike naho nioza an-drindriñe tandrife’e ka ty ela’ i kerobe raike vaho nifañoza añivo’ i efetsey ty lengon-ela’ iareo ila’e.
Ó sì gbé àwọn kérúbù náà sínú ilé ti inú lọ́hùn ún, pẹ̀lú ìyẹ́ apá wọn ní nínà jáde. Ìyẹ́ apá kérúbù kan sì kan ògiri kan, nígbà tí ìyẹ́ apá èkejì sì kan ògiri kejì, ìyẹ́ apá wọn sì kan ara wọn láàrín yàrá náà.
28 Pinako’e am-bolamena i kerobe rey.
Ó sì fi wúrà bo àwọn kérúbù náà.
29 Le nanokira’e sare kerobe naho satrañe mb’eo mb’eo amo rindri’ i anjombay iabio, vaho nandafiha’e voñe miborake añate’e naho alafe’e.
Lára àwọn ògiri tí ó yí ilé náà ká, nínú àti lóde, ó sì ya àwòrán àwọn kérúbù sí i àti ti igi ọ̀pẹ, àti ti ìtànná ewéko.
30 Nandafiha’e am-bolamena ka ty ambane’ i anjombay, i añate’ey naho i alafe’ey.
Ó sì tún fi wúrà tẹ́ ilẹ̀ ilé náà nínú àti lóde.
31 Nandranjia’e lalañe an-talý i toe-miavakey, ze napetak’ an-dahin-dalañe an-drirañe lime.
Nítorí ojú ọ̀nà ibi mímọ́ jùlọ ni ó ṣe ìlẹ̀kùn igi olifi sí pẹ̀lú àtẹ́rígbà àti òpó ìhà jẹ́ ìdámárùn-ún ògiri.
32 Aman-talý i lalañe roe rey; le nanokira’e sare-kerobe naho satrañe vaho voñe miborake, le nipakora’e volamena o kerobeo naho o satrañeo.
Àti lára ìlẹ̀kùn igi olifi náà ni ó ya àwòrán àwọn kérúbù, igi ọ̀pẹ àti ti ìtànná ewéko sí, ó sì fi wúrà bò wọ́n, ó sì tan wúrà sí ara àwọn kérúbù àti sí ara igi ọ̀pẹ.
33 Izay ka ty nanoa’e i fimoahañe i anjombay, lahindalañe an-talý, an-drira’e efatse.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe òpó igi olifi onígun mẹ́rin fún ìlẹ̀kùn ilé náà.
34 Haradranto i lalañe roe rey; miodikodiñ’ an-tsoavili’e ty lela roe ty lalañe raike, vaho miodiñe ka ty lela roe’ i lalañe ila’ey.
Ó sì tún fi igi firi ṣe ìlẹ̀kùn méjì, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn sì ní ewé méjì tí ó yí sí ihò ìtẹ̀bọ̀.
35 Le nanokira’e kerobe naho satrañe naho voñe miborake vaho nipakora’e volamena natsifitse soa amy sinokitsey.
Ó sì ya àwòrán kérúbù, àti ti igi ọ̀pẹ àti ti ìtànná ewéko sí ara wọn, ó sì fi wúrà bò ó, èyí tí ó tẹ́ sórí ibi tí ó gbẹ́.
36 Namboare’e am-bato nivañeñe telo sosoke naho soso’e raik’ am-boda mendoraveñe ty kiririsa añate’e.
Ó sì fi ẹsẹẹsẹ òkúta mẹ́ta gbígbẹ, àti ẹsẹ̀ kan ìtí kedari kọ́ àgbàlá ti inú lọ́hùn ún.
37 Ie am-bolan-tatak’ i taom-pah’ efatsey ty nampijadoñañe o mananta’ i anjomba’ Iehovàio;
Ní ọdún kẹrin ni a fi ìpìlẹ̀ ilé Olúwa lé ilẹ̀, ní oṣù Sifi.
38 vaho ami’ty vatravatra, volam-paha-valo’ i taom-paha-folo-raik’ ambiy ty nahafonirañe i anjombay ami’ty lafi’e iaby ty amy ze hene nisafirieñe ama’ey. Aa le fito taoñe ty namboara’e aze.
Ní ọdún kọkànlá ní oṣù Bulu, oṣù kẹjọ, a sì parí ilé náà jálẹ̀ jálẹ̀, pẹ̀lú gbogbo ìpín rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí ó yẹ. Ó sì lo ọdún méje ní kíkọ́ ilé náà.