< 1 Mpanjaka 11 >
1 F’ie nikoko ampela ambahiny maro t’i Selomò, tovo’ i anak’ ampela’ i Paròy, le ampela nte-Moabe, nte-Amone, nte Edome, nte-Tsidone, vaho nte-Kite;
Solomoni ọba fẹ́ ọ̀pọ̀ àjèjì obìnrin yàtọ̀ sí ọmọbìnrin Farao, àwọn ọmọbìnrin Moabu, àti ti Ammoni, ti Edomu, ti Sidoni àti ti àwọn ọmọ Hiti.
2 boak’ amo fifeheañe nitsarae’ Iehovà amo ana’ Israeleo ty hoe: Ko iolora’ areo, naho ko apoke hiharo-tihy ama’ areo; fa toe hampitolihe’ iereo amo ‘ndrahare’ iareoo ty arofo’ areo; ie nisazohe’ i Selomò am-pikokoañe.
Wọ́n wá láti orílẹ̀-èdè tí Olúwa ti wí fún àwọn ọmọ Israẹli pé, “Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ fẹ́ wọn níyàwó tàbí ní ọkọ, nítorí wọn yóò yí ọkàn yín padà sí òrìṣà wọn.” Síbẹ̀síbẹ̀ Solomoni fàmọ́ wọn ní ìfẹ́.
3 Nanambaly fiton-jato re ho tañanjomba’e naho sakeza telon-jato; vaho nampandrìke ty arofo’e o vali’eo.
Ó sì ní ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀rin obìnrin, àwọn ọmọ ọba àti ọ̀ọ́dúnrún àlè, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà.
4 Ie nibey, le nampitolihe’ o vali’eo mb’an-drahare ankafankafa, vaho tsy nigahiñe am’ Iehovà Andrianañahare’e ka ty tro’e manahake ty arofo’ i Davide rae’ey.
Bí Solomoni sì ti di arúgbó, àwọn ìyàwó rẹ̀ sì yí i ní ọkàn padà sí ọlọ́run mìíràn, ọkàn rẹ̀ kò sì ṣe déédé pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ọkàn Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
5 Songa norihe’ i Selomò t’i Asterote ‘ndrahare’ o nte-Tsidoneo, naho i Milkome ty haloloa’ o nte-Amoneo.
Solomoni tọ Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni lẹ́yìn, àti Moleki òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
6 Aa le nanao hatsivokarañe am-pivazohoa’ Iehovà t’i Selomò, ie tsy nañorike Iehovà an-kaliforan-troke, manahake i Davide rae’e.
Bẹ́ẹ̀ ni Solomoni ṣe búburú níwájú Olúwa; kò sì tọ Olúwa lẹ́yìn ní pípé, bí Dafidi baba rẹ̀ ti ṣe.
7 Niranjie’ i Selomò an-kaboañe ey ty Kemose, i haloloa’ i Moabey, am-bohitse atiñana’ Ierosalaime ey, naho ho amy Moleke, ty haloloa’ o nte-Amoneo.
Lórí òkè tí ń bẹ níwájú Jerusalẹmu, Solomoni kọ́ ibi gíga kan fún Kemoṣi, òrìṣà ìríra Moabu, àti fún Moleki, òrìṣà ìríra àwọn ọmọ Ammoni.
8 Nanoa’e izay amo vali’e ambahiny iaby nañoro emboke naho nanao soroñe aman-drahare’eo.
Bẹ́ẹ̀ ni ó sì ṣe bẹ́ẹ̀ fún gbogbo àwọn àjèjì obìnrin rẹ̀, ẹni tí ń sun tùràrí, tí wọ́n sì ń rú ẹbọ fún òrìṣà wọn.
9 Toly ndra niviñera’ Iehovà t’i Selomò, ty amy arofo’e nandifik’ am’ Iehovà Andrianañahare’ Israeley, ie fa niheo ama’e indroe;
Olúwa bínú sí Solomoni nítorí ọkàn rẹ̀ ti yípadà kúrò lọ́dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, tí ó ti fi ara hàn án lẹ́ẹ̀méjì.
10 vaho linili’e ama’e ty amo raha zao te tsy horihe’e o ‘ndrahare ila’eo; fe tsy nambena’e i nandilia’ Iehovà azey.
Bí o tilẹ̀ jẹ́ pé ó ti kìlọ̀ fún Solomoni kí ó má ṣe tọ àwọn ọlọ́run mìíràn lẹ́yìn, ṣùgbọ́n Solomoni kò pa àṣẹ Olúwa mọ́.
11 Aa le hoe t’Iehovà amy Selomò, Kanao zao ty an-tro’o, naho tsy tana’o i fañinakoy naho o fañèko liniliko azoo, le toe ho riateko ama’o ty fifehea’o vaho hatoloko am-pitam-pitoro’o.
Nítorí náà Olúwa wí fún Solomoni pé, “Nítorí bí ìwọ ti ṣe nǹkan yìí, tí ìwọ kò sì pa májẹ̀mú mi àti àṣẹ mi mọ́, tí mo ti pàṣẹ fún ọ, dájúdájú èmi yóò fa ìjọba ya kúrò lọ́wọ́ rẹ, èmi yóò sì fi fún ẹlòmíràn.
12 Fe tsy hanoeko amo andro’oo, ty amy Davide rae’o, te mone ho tavaneko an-tañan’ ana’o.
Ṣùgbọ́n, nítorí Dafidi baba rẹ, Èmi kì yóò ṣe é ní ọjọ́ rẹ. Èmi yóò fà á ya kúrò lọ́wọ́ ọmọ rẹ.
13 Tsy ho fonga tavaneko i fifeheañey, fa hatoloko ami’ty ana’o ty fifokoañe raike ty amy Davide mpitoroko; naho ty am’ Ierosalaime jinobokoy.
Síbẹ̀ èmi kì yóò fa gbogbo ìjọba náà ya, ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi, àti nítorí Jerusalẹmu tí èmi ti yàn.”
14 Le nampitroboe’ Iehovà rafelahy t’i Selomò; i Kadade nte-Edome, tirim-panjaka’ i Edome.
Nígbà náà ni Olúwa gbé ọ̀tá kan dìde sí Solomoni, Hadadi ará Edomu ìdílé ọba ni ó ti wá ní Edomu.
15 Ie te Edome añe t’i Davide, naho fa nionjomb’eo handenteke o nikoromakeo t’Ioabe mpifehe i valobohòkey, ie fonga zinevo’e ze atao lahilahy Edome—
Ó sì ṣe, nígbà tí Dafidi wà ní Edomu, Joabu olórí ogun sì gòkè lọ láti sin àwọn ọmọ-ogun Israẹli ti a pa lójú ogun, ó sì pa gbogbo ọkùnrin Edomu.
16 toe tàmbatse ao enem-bolañe t’Ioabe rekets’ Israele iaby ampara’ te naito’e ze fonga lahilahi’ i Edome—
Nítorí Joabu àti gbogbo Israẹli sì dúró níbẹ̀ fún oṣù mẹ́fà, títí wọ́n fi pa gbogbo ọkùnrin Edomu run.
17 le nitriban-day mb’e Mitsraime añe t’i Kadade naho ty ila’ o mpitoron-drae’eo, ie mbe anak’ ajaja t’i Kadade.
Ṣùgbọ́n Hadadi sálọ sí Ejibiti pẹ̀lú àwọn ará Edomu tí wọ́n jẹ́ ìránṣẹ́ baba rẹ̀. Hadadi sì wà ní ọmọdé nígbà náà.
18 Niavotse i Midiane iereo nivotrake e Parane, le nandrambe ondaty e Parane vaho nigodañe mb’e Mitsraime, mb’amy Parò Mpanjaka’ i Mitsraime mb’eo, le tinolo’e anjomba naho mahakama vaho tane.
Wọ́n sì dìde kúrò ní Midiani, wọ́n sì lọ sí Parani. Nígbà náà ni wọ́n mú ènìyàn pẹ̀lú wọn láti Parani wá, wọ́n sì lọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Farao ọba Ejibiti ẹni tí ó fún Hadadi ní ilé àti ilẹ̀, ó sì fún un ní oúnjẹ.
19 Nanjo fañisohañe ra’elahy am-pahaoniña’ i Parò t’i Kadade, kanao natolo’e aze ho tañanjomba’e ty rahavaven-tañanjomba’e, ty rahavave’ i Takpanese mpanjaka ampela.
Inú Farao sì dùn sí Hadadi púpọ̀ tí ó fi fún un ní arábìnrin aya rẹ̀ ní aya, arábìnrin Tapenesi, ayaba.
20 Nisamake i Genobate ana-dahi’e ho aze ty rahavave’ i Takpanese, ze nibeize’ i Takpanese añ’anjomba’ i Parò; vaho nitraok’ amo ana’ i Paròo añ’anjomba’ i Parò t’i Genobate.
Arábìnrin Tapenesi bí ọmọkùnrin kan fún un tí à ń pe orúkọ rẹ̀ ní Genubati, ẹni tí Tapenesi tọ́ dàgbà ní ààfin ọba. Níbẹ̀ ni Genubati ń gbé pẹ̀lú àwọn ọmọ Farao fúnra rẹ̀.
21 Aa ie jinanji’ i Kadade e Mitsraime añe te nitrao-pirotse aman-droae’e t’i Davide naho te nihomake t’Ioabe mpifehe’ i màroy, le hoe t’i Kadade amy Parò. Ampiavoto mb’ an-taneko añe.
Nígbà tí ó sì wà ní Ejibiti, Hadadi sì gbọ́ pé Dafidi ti sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, àti pé Joabu olórí ogun sì ti kú pẹ̀lú. Nígbà náà ni Hadadi wí fún Farao pé, “Jẹ́ kí n lọ, kí èmi kí ó le padà sí ìlú mi.”
22 Le hoe t’i Parò ama’e, Fa inoñe ty tsy niampe tamako kanao mipay hañavelo mb’an-tane’o añe irehe? Tsy eo, hoe re, Fe apoho handeha avao.
Farao sì wí fún un pé, “Kí ni ìwọ ṣe aláìní níbí, tí ìwọ fi fẹ́ padà lọ sí ìlú rẹ?” Hadadi sì wí pé, “Kò sí nǹkan, ṣùgbọ́n sá à jẹ́ kí èmi kí ó lọ!”
23 Mbore nampitroboen’ Añahare ty rafelahy raike ka, i Rezone ana’ i Eliadà, i nilay amy talè’e Hadadezere mpanjaka’ i Tsobày,
Ọlọ́run sì gbé ọ̀tá mìíràn dìde sí Solomoni, Resoni ọmọ Eliada, ẹni tí ó ti sá kúrò lọ́dọ̀ Hadadeseri olúwa rẹ̀, ọba Soba.
24 namory ondaty ho mpiama’e vaho nimpifehe firimboñañe, ie fa zinama’ i Davide o e Tsobào, le nimb’e Damesèke mb’eo iereo nimoneñe ao, vaho nifehe e Damesèke.
Ó sì kó ènìyàn jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, ó sì di olórí ogun ẹgbẹ́ kan, nígbà tí Dafidi fi pa ogun Soba run; wọ́n sì lọ sí Damasku, wọ́n ń gbé ibẹ̀, wọ́n sì jẹ ọba ní Damasku.
25 Nirafelahi’ Israele re amo hene andro’ i Selomòo, ie nitovoñe’e ty haemberañe nanoe’ i Kadadeo; niheje’e t’Israele vaho nifelek’ i Arame.
Resoni sì jẹ́ ọ̀tá Israẹli ní gbogbo ọjọ́ Solomoni, ó ń pa kún ibi ti Hadadi ṣe. Bẹ́ẹ̀ ni Resoni jẹ ọba ní Siria, ó sì ṣòdì sí Israẹli.
26 Nañonjo fitañe amy mpanjakay ka t’Iarovame ana’ i Nebate nte-Efratà boake Tseredà, mpitoro’ i Selomò; Tseroà ty tahinan-drene’e, vantotse.
Bákan náà Jeroboamu ọmọ Nebati sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọba. Ó sì jẹ́ ọ̀kan lára àwọn ìránṣẹ́ Solomoni, ará Efraimu ti Sereda, ìyá rẹ̀ sì jẹ́ opó, orúkọ rẹ̀ ni Serua.
27 Inao ty nañonjona’e fitañe amy mpanjakay: Niranjie’ i Selomò ty Milo vaho namboara’e o heba an-drova’ i Davide rae’eo.
Èyí sì ni ìdí tí ó fi ṣọ̀tẹ̀ sí ọba: Solomoni kọ́ Millo, ó sì di ẹ̀yà ìlú Dafidi baba rẹ̀.
28 Nifanalolahy an-kaozarañe t’Iarovame; le nioni’ i Selomò te nahimbañe i ajalahiy, vaho nampifehè’e aze o fitoloñañe añ’anjomba’ Iosefeo.
Jeroboamu jẹ́ ọkùnrin alágbára, nígbà tí Solomoni sì rí bí ọ̀dọ́mọkùnrin náà ti ṣe iṣẹ́ rẹ̀ dáradára, ó fi í ṣe olórí iṣẹ́ ìrú ilé Josẹfu.
29 Ie henane zay, naho niavotse Ierosalaime t’Iarovame, te tendrek’ ama’e amy lia’ey t’i Akià nte-Silò, nisikin-damba vao, ie nivahiny an-kivok’ añe iereo roe.
Ó sì ṣe, ní àkókò náà Jeroboamu ń jáde kúrò ní Jerusalẹmu. Wòlíì Ahijah ti Ṣilo sì pàdé rẹ̀ lójú ọ̀nà, ó sì wọ agbádá tuntun. Àwọn méjèèjì nìkan ni ó sì ń bẹ ní oko,
30 Rinambe’ i Akià i lamba vao ama’ey le niriate’e ho folo-ro’amby;
Ahijah sì gbá agbádá tuntun tí ó wọ̀ mú, ó sì fà á ya sí ọ̀nà méjìlá.
31 le hoe re amy Iarovame, Rambeso ty folo, fa hoe ty nafè’ Iehovà Andrianañahare’ Israele, Inao te ho riateko am-pità’ i Selomò i fifeheañey vaho hatoloko azo ty fifokoañe folo;
Nígbà náà ni ó sọ fún Jeroboamu pé, “Mú ọ̀nà mẹ́wàá fún ara rẹ, nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí pé, ‘Wò ó, èmi yóò fa ìjọba náà ya kúrò ní ọwọ́ Solomoni, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
32 le hanañe fifokoañe raike re ty amy Davide mpitorokoy naho Ierosalaime, rova nijoboñeko amo hene fifokoa’ Israeleo,
Ṣùgbọ́n nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi àti nítorí Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn nínú gbogbo ẹ̀yà Israẹli, òun yóò ní ẹ̀yà kan.
33 amy t’ie namorintseñe Ahy vaho mitalaho amy Astorete, mpanjaka-ampela’ o nte-Tsidoneo naho amy Kemose, ‘ndrahare’ o nte-Moabeo, naho amy Milkome, mpanjaka’ o ana’ i Amoneo vaho tsy mañavelo amo lalakoo hanoa’ iereo ty soa a masoko naho hifahatse amo fañèkoo vaho amo fepèkoo manahake i Davide rae’ey.
Èmi yóò ṣe èyí nítorí tí wọ́n ti kọ̀ mí sílẹ̀, wọ́n sì ti sin Aṣtoreti òrìṣà àwọn ará Sidoni, Kemoṣi òrìṣà àwọn ará Moabu, àti Moleki òrìṣà àwọn ọmọ Ammoni, wọn kò sì rìn ní ọ̀nà mi, tàbí ṣe èyí tí ó dára lójú mi, tàbí pa àṣẹ àti òfin mi mọ́ bí Dafidi baba Solomoni ti ṣe.
34 Tsy ho fonga tavaneko am-pità’e i fifeheañey; fa hanoeko mpifehe amo hene andro hiveloma’eo, ty amy Davide mpitoroko jinobokoy, ie nañambeñe o lilikoo naho o fañèkoo;
“‘Ṣùgbọ́n èmi kì yóò gba gbogbo ìjọba náà lọ́wọ́ Solomoni; èmi ti mú un jẹ́ olórí ní gbogbo ọjọ́ ayé rẹ̀ nítorí ti Dafidi ìránṣẹ́ mi, ẹni tí mo yàn, tí ó sì ti pa òfin mi àti àṣẹ mi mọ́.
35 fe ho rambeseko am-pità’ i ana’ey i fifeheañey, vaho hatoloko azo i fifokoañe folo rey.
Èmi yóò gba ìjọba náà ní ọwọ́ ọmọ rẹ̀, èmi yóò sì fi ẹ̀yà mẹ́wàá fún ọ.
36 Le ho tolorako fifokoañe raike i ana’ey, hanaña’ i Davide mpitoroko ty failo añatrefako nainai’e e Ierosalaime ao, i rova jinoboko ho Ahy ampipohako ty añarakoy.
Èmi yóò fi ẹ̀yà kan fún ọmọ rẹ kí Dafidi ìránṣẹ́ mi lè máa ní ìmọ́lẹ̀ níwájú mi nígbà gbogbo ní Jerusalẹmu, ìlú tí mo ti yàn láti fi orúkọ mi síbẹ̀.
37 Ho rambeseko irehe, le ho hene fehè’o ze satrin-tro’o, vaho ihe ty ho mpanjaka’ Israele.
Ṣùgbọ́n ní ti ìwọ, Èmi yóò mú ọ, ìwọ yóò sì jẹ ọba lórí ohun gbogbo tí ọkàn rẹ ń fẹ́; ìwọ yóò jẹ ọba lórí Israẹli.
38 Ie amy zao naho hene haoñe’o ze andiliako azo naho hañavelo amo lalakoo naho hanao ty vantañe a masoko, hañambeñe o fañèkoo naho o lilikoo manahake i Davide mpitorokoy le ho mpiama’o iraho vaho hanoako anjomba mijadoñe, manahake ty namboarako i Davide, vaho hatoloko ama’o t’Israele.
Bí ìwọ bá ṣe gbogbo èyí tí mo pàṣẹ fún ọ, tí o sì rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì ṣe èyí tí ó tọ́ lójú mi nípa pípa òfin àti àṣẹ mi mọ́, bí i Dafidi ìránṣẹ́ mi ti ṣe, Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ. Èmi yóò kọ́ ilé òtítọ́ fún ọ bí èyí tí mo kọ́ fún Dafidi, èmi yóò sì fi Israẹli fún ọ.
39 Ie amy zay hampisotriako ty tiri’ i Davide fe tsy ho kitro añ’afe’e.
Èmi yóò sì rẹ irú-ọmọ Dafidi sílẹ̀ nítorí èyí, ṣùgbọ́n kì í ṣe títí láé.’”
40 Aa le nipay hañoho-doza am’ Iarovame t’i Selomò; f’ie niongake nitriban-day mb’e Mitsraime añe, mb’amy Sisage mpanjaka’ i Mitsraime vaho nitambatse e Mitsraime añe ampara’ te nihomake t’i Selomò.
Solomoni wá ọ̀nà láti pa Jeroboamu, ṣùgbọ́n Jeroboamu sálọ sí Ejibiti, sọ́dọ̀ Ṣiṣaki ọba Ejibiti, ó sì wà níbẹ̀ títí Solomoni fi kú.
41 O fitoloña’ i Selomò ila’eo, naho o tolon-draha’e iabio, tsy fa sinokitse amy bokem-pitoloña’ i Selomòy hao?
Ìyókù iṣẹ́ Solomoni àti gbogbo èyí tí ó ṣe, àti ọgbọ́n rẹ̀, a kò ha kọ wọ́n sínú ìwé ìṣe Solomoni bí?
42 Ty hene andro nifehea’ i Selomò Israele e Ierosalaime ao le efa-polo taoñe.
Solomoni sì jẹ ọba ní Jerusalẹmu lórí gbogbo Israẹli ní ogójì ọdún.
43 Le nitrao-pirotse aman-droae’e t’i Selomò, naho nalentek’ an-drova’ i Davide rae’e ao; vaho nandimbe aze nifehe t’i Rekhavame, ana’e.
Nígbà náà ni Solomoni sì sùn pẹ̀lú àwọn baba rẹ̀, a sì sin ín ní ìlú Dafidi baba rẹ̀. Rehoboamu ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọba ní ipò rẹ̀.