< 1 Tantara 27 >
1 Ty famoliliañe o ana’ Israeleo, o talèn’ anjomban-droae naho o mpifelek’ arivo naho zatoo naho o roandriañe mpitoroñe i mpanjakaio aman-dra inoñ’ inoñe amo firimboñañe mimoak’ ao naho miavotse mb’eo am-bolañ’ am-bolañe amo hene volan-taoñeo, ie songa ro’ale-tsi-efats’ arivo ami’ty firimboñañe.
Wọ̀nyí ni ìwé àkójọ orúkọ àwọn ọmọ Israẹli, àwọn olórí àwọn ìdílé, àwọn balógun ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti àwọn balógun ọ̀rọ̀ọ̀rún àti àwọn ìjòyè wọn. Tí ó n sin ọba nínú gbogbo ohun tí ó kan ìpín àwọn ọmọ-ogun tí ó wà lẹ́nu iṣẹ́ ìsìn ní oṣooṣù ní gbogbo ọdún. Ìpín kọ̀ọ̀kan jẹ́ ẹgbàá méjìlá ọkùnrin.
2 Ambone’ ty firimboñam-bolam-baloha’e t’Iasobeame ana’ i Zabdiele,
Ní ti alákòóso lórí ìpín kìn-ín-ní fún oṣù kìn-ín-ní jẹ́ Jaṣobeamu ọmọ Sabdieli àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní abẹ́ ìpín tirẹ̀.
3 tarira’ i Peretse, ie nitalèm-pifehe’ i valobohòkey amy volam-baloha’ey.
Ó jẹ́ ìran ọmọ Peresi àti olóyè fún gbogbo àwọn ìjòyè ológun fún oṣù kìn-ín-ní.
4 Ambone’ i firimboñam-bolam-paharoey t’i Doday nte Akoký, i Miklote nitalè’ i firimboñañey; ro’ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Alákòóso fún ìpín àwọn ọmọ-ogun fún oṣù kejì jẹ́ Dodai ará Ahohi; Mikloti jẹ́ olórí ìpín tirẹ̀. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
5 I Benaià ana’ Iehoiada, mpisoroñe, mpiaolo, nimpifehe’ fahatelo’ i valobohòkey ho am-bolam-pahatelo, ro’ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Olórí àwọn ọmọ-ogun ẹlẹ́ẹ̀kẹta fún oṣù kẹta jẹ́ Benaiah ọmọ Jehoiada àlùfáà. Ó jẹ́ olóyè, àwọn ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
6 Ie i Benanià nifanalolahy amy telopoloy naho nifehe i telopoloy; talè i firimboña’ey t’i Amizabade ana’e.
Èyí ni Benaiah náà tí ó jẹ́ ọkùnrin ńlá láàrín àwọn ọgbọ̀n àti lórí àwọn ọgbọ̀n. Ọmọ rẹ̀ Amisabadi jẹ́ alákòóso lórí ìpín tirẹ̀.
7 Ty fah’ efatse ho am-bolam-pahefatse le i Asaele, rahalahi’ Ioabe naho i Zebadià ana’e ty nandimbe aze; ro’ ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Ẹlẹ́ẹ̀kẹrin fún oṣù kẹrin, jẹ́ Asaheli arákùnrin Joabu: ọmọ rẹ̀ Sebadiah jẹ́ arọ́pò rẹ̀. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
8 Ty fahalime ho am-bolam-pahalime i Samhote nte Iizrake; ni-ro’ ale-tsi-efats’ arivo amy firimboña’ey.
Ẹ̀karùnún fún oṣù karùn-ún, jẹ́ olórí Ṣamhuti ará Israhi. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ní ó wà ní ìpín tirẹ̀.
9 Ty fah’ eneñe ho am-bolam-pah’ eneñe i Irà ana’ Ikese nte-Tekoy; ro’ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Ẹ̀kẹfà fún oṣù kẹfà jẹ́ Ira ọmọ Ikẹsi, ará Tekoi. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
10 Ty faha-fito ho am-bolam-pahafito, i Keletse, nte-Pelone, tarira’ i Efraime; ro’ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Èkeje fún oṣù keje jẹ́ Helesi ará Peloni, ará Efraimu. Ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni o wà ní ìpín rẹ̀.
11 Ty fahavalo ho am-bolam-pahavalo i Sibekay nte Kosate, tarira’ i Zerake; ro’ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Ẹ̀kẹjọ fún oṣù kẹjọ jẹ́ Sibekai ará Huṣati, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
12 Ty fahasive ho am-bolam-pahasive, i Abiezere, nte Anatote, tarira’ i Beniamine; ro’ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Ẹ̀kẹsànán fún oṣù kẹsànán jẹ́. Abieseri ará Anatoti, ará Benjamini ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
13 Ty fahafolo ho am-bolam-pahafolo, i Makray, nte Netofate, tarira’ i Zarkry, ro’ ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Ẹ̀kẹwàá fún oṣù kẹwàá jẹ́ Maharai ará Netofa, ará Sera ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín rẹ̀.
14 Ty fahafolo-raik’ amby ho am-bolam-pahafolo-raik’ amby, i Benaià, nte Pirato, tarira’ i Efraime; ro’ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Ìkọkànlá fún oṣù kọkànlá jẹ́ Benaiah ará Piratoni ará Efraimu ọkùnrin ẹgbàá méjìlá ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
15 Ty fahafolo-ro’ amby ho am-bolam-pahafolo-ro’ amby, i Keldày nte-Netofate, tarira’ i Otniele, ro’ ale-tsi-efats’ arivo ro amy firimboña’ey.
Èkejìlá fún oṣù kejìlá jẹ́ Heldai ará Netofa láti ìdílé Otnieli. Ẹgbàá méjìlá ọkùnrin ni ó wà ní ìpín tirẹ̀.
16 Aa naho ty nifehe’ o fifokoa’ Israeleo: Amo nte-Reobeneo, i Eliezere ana’ i Zikrý, nitalè; amo nte-Simoneo, i Sefatià, ana’ i Maakà;
Àwọn ìjòyè lórí àwọn ẹ̀yà tí Israẹli: lórí àwọn ará Reubeni: Elieseri ọmọ Sikri; lórí àwọn ọmọ Simeoni: Ṣefatia ọmọ Maaka;
17 amy Levý, i Kasabià, ana’ i Kemoele; amy Aharone, i Tsadoke;
lórí Lefi: Haṣabiah ọmọ Kemueli; lórí Aaroni: Sadoku;
18 amy Iehodà, i Elihò, rahalahi’ i Davide; amy Isakare, i Omrý ana’ i Mikaele;
lórí Juda: Elihu arákùnrin Dafidi; lórí Isakari: Omri ọmọ Mikaeli;
19 amy Zebolone, Ismaià ana’ i Obadià; amy Naftalý, Ierimote ana’ i Azriele;
lórí Sebuluni: Iṣmaiah ọmọ Obadiah; lórí Naftali: Jerimoti ọmọ Asrieli;
20 amo ana’ i Efraimeo, i Hoseà ana’ i Azazià; amy vakim-pifokoa’ i Menasèy, Ioele ana’ i Pedaià;
lórí àwọn ará Efraimu: Hosea ọmọ Asasiah; lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase: Joẹli ọmọ Pedaiah;
21 amy vakim-pifokoa’ i Menasè e Giladey, Idò ana’ i Zekarià; amy Beniamine, Iaasiele, ana’ i Abnere;
lórí ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ní Gileadi: Iddo ọmọ Sekariah; lórí Benjamini: Jaasieli ọmọ Abneri;
22 amy Dane, i Azarele, ana’ Ierokame. Ie ro mpiaolo o fifokoa’ Israeleo.
lórí Dani: Asareeli ọmọ Jerohamu. Wọ̀nyí ni àwọn ìjòyè lórí ẹ̀yà Israẹli.
23 Tsy niahe’ i Davide ze ambane ty roapolo taoñe, ami’ty nafè’ Iehovà te hampitomboe’e manahake o vasian-dikerañeo t’Israele.
Dafidi kò kọ iye àwọn ọkùnrin náà ní ogún ọdún sẹ́yìn tàbí dín nítorí Olúwa ti ṣe ìlérí láti ṣe Israẹli gẹ́gẹ́ bí iye ìràwọ̀ ojú ọ̀run.
24 Toe niorotse nañiake t’Ioabe ana’ i Tseroià fe tsy nahatafetetse naho nifetsak’ am’ Israele ty haviñerañe vaho tsy nazilik’ amo talili’ i Davide, mpanjakao, i iakey.
Joabu ọmọ Seruiah bẹ̀rẹ̀ sí ní kà wọ́n, ṣùgbọ́n kò parí kíkà wọ́n nítorí, ìbínú dé sórí àwọn Israẹli nípasẹ̀ kíka iye àti iye náà, a kò kọ ọ́ sínú ìwé ìtàn ayé ti ọba Dafidi.
25 Nifehe o fanontonam-bara’ i mpanjakaio t’i Azmavete ana’ i Adiele; le nifehe o trañom-bara an-kivok’ ey naho amo rovao naho amo tanàñeo vaho amo fitalakesañ’ aboo t’Iehonatane, ana’ i Otsià.
Asmafeti ọmọ Adieli wà ní ìdí ilé ìṣúra ti ọba. Jonatani ọmọ Ussiah wà ní ìdí ilé ìṣúra ní iwájú agbègbè nínú àwọn ìlú, àwọn ìletò àti àwọn ilé ìṣọ́.
26 Le nifehe o nitoloñe an-tetek’ ao o mpiava-taneo, t’i Etsrý ana’ i Kelobe;
Esri ọmọ Kelubu wà ní ìdí àwọn òṣìṣẹ́ lórí pápá, tí wọ́n ń ko ilẹ̀ náà.
27 le nifehe o tanem-baheo t’i Simeý nte Ramà; le nifehe ty voka’ o tanembaheo ho amo lakaton-divaio t’i Zabdý nte-Sifmý;
Ṣimei ará Ramoti wà ní ìdí àwọn ọgbà àjàrà. Sabdi ará Sifmi wà ní ìdí mímú jáde ti èso àjàrà fún ọpọ́n ńlá tí a ń fi ọ̀tún èso àjàrà sí.
28 nifehe o zaite naho sakoañe amo vavataneoo t’i Baale-kanane nte-Gedere; naho nifehe o lakato-menakeo t’Ioase.
Baali-Hanani ará Gederi wà ní ìdí olifi àti àwọn igi sikamore ní apá ìhà ìwọ̀-oòrùn àwọn ní ẹ̀ṣẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀. Joaṣi wà ní ìdí fífún ni ní òróró olifi.
29 Le nifehe o mpirai-troke nandrazeñe e Saroneo t’i Sitraý nte-Sarone; naho nifehe o mpirai-troke am-bavataneo t’i Safate, ana’ i Adlaý;
Ṣitrai ará Ṣaroni wà ní ìdí fífi ọwọ́ ẹran jẹ oko ní Ṣaroni. Ṣafati ọmọ Adlai wà ní ìdí àwọn ọ̀wọ́ ẹran ní àwọn pẹ̀tẹ́lẹ̀.
30 nifehe o ramevao ka t’i Obile nte-Ismaele; naho nifehe o birìkeo t’Iekdeià nte-Meronote;
Obili ará Iṣmaeli wà ní ìdí àwọn ìbákasẹ. Jehdeiah ará Meronoti wà ní ìdí àwọn kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
31 le nifehe o lia-raikeo t’Iazize, nte-Hagrý. Ie ro mpifehe ty vara’ i Davide mpanjaka.
Jasisi ará Hagari wà ní ìdí àwọn agbo ẹran. Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn oníṣẹ́ tí wọ́n wà ní ìdí ẹrù ọba Dafidi.
32 Nimpanoro-kevetse naho ondaty mahihitse vaho mpanokitse t’Ionatane rahalahin-drae’ i Davide; mpañabey o anam-panjakao t’Iekiele ana’ i Kakmoný.
Jonatani, arákùnrin Dafidi jẹ́ olùdámọ̀ràn, ọkùnrin onímọ̀ àti akọ̀wé. Jehieli ọmọ Hakmoni bojútó àwọn ọmọ ọba.
33 Nimpanolo-heve’ i mpanjakay t’i Akitofele naho mpiamy mpanjakay t’i Kosay nte-Ereke;
Ahitofeli jẹ́ olùdámọ̀ràn ọba. Huṣai ará Arki jẹ́ ọ̀rẹ́ ọba.
34 nandimbe i Akitofele t’Iehoiadà ana’ i Benaià naho i Abiatare; vaho nimpifehe o lahindefo’ i mpanjakaio t’Ioabe.
(Jehoiada ọmọ Benaiah àti nípasẹ̀ Abiatari jẹ ọba rọ́pò Ahitofeli.) Joabu jẹ́ olórí ọmọ-ogun ọba.