< 1 Tantara 25 >

1 Mbore zinara’ i Davide naho o mpifehe’ i valobohòkeio amo fitoloñañeo o ana’ i Asafeo naho i Hemaneo vaho Iedotoneo, ze hitoky ie ama’ marovany naho aman-jejobory vaho amam-pikantsañañe: le ty ia’ o nitoloñe amy fitoroñañeio:
Pẹ̀lúpẹ̀lú Dafidi àti àwọn olórí àwọn ọmọ-ogun, ó sì yà díẹ̀ sọ́tọ̀ lára àwọn ọmọ Asafu, Hemani àti Jedutuni fún ìsìn àsọtẹ́lẹ̀, pẹ̀lú dùùrù, ohun èlò orin olókùn àti kimbali. Èyí sì ní àwọn iye àwọn ọkùnrin ẹni tí ó ṣe oníṣẹ́ ìsìn yìí.
2 o ana’ i Asafeo: i Zakore naho Iosefe naho i Netanià vaho i Asarelà; songa ana’ i Asafe ambanem-pità’ i Asafe, mpitoky ambanem-pità’ i mpanjakay.
Nínú àwọn ọmọ Asafu: Sakkuri, Josẹfu, Netaniah àti Asarela, àwọn ọmọ Asafu ni wọ́n wà lábẹ́ ìbojútó Asafu, ẹni tí ó sọtẹ́lẹ̀ lábẹ́ ìbojútó ọba.
3 Iedotone: o ana’ Iedotoneo, i Gedalià, i Tserý, Iesaià, i Kasabià naho i Matitià, eneñe, ambanem-pitàn-drae’e Iedotone, mpitoky añoza-marovany, mpañandriañe naho mpandrenge Iehovà.
Gẹ́gẹ́ bí ti Jedutuni, nínú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀: Gedaliah, Seri, Jeṣaiah, Ṣimei, Haṣabiah àti Mattitiah, mẹ́fà nínú gbogbo wọn, lábẹ́ ìbojútó baba wọn Jedutuni, ẹni tí ó sọtẹ́lẹ̀, ẹni tí ó lo dùùrù láti dúpẹ́ àti láti yin Olúwa.
4 I Hemane, o ana’ i Hemaneo: i Bokià, i Matanià, i Oziele, i Seboele naho Ierimote, i Kananià, i Kananý, i Eliatà, i Gidaltý naho i Romamtiezere, Iosbekasà, i Malotý, i Makaziote.
Gẹ́gẹ́ bí ti Hemani, nínú àwọn ọmọ rẹ̀: Bukkiah, Mattaniah, Usieli, Ṣubaeli àti Jerimoti; Hananiah, Hanani, Eliata, Giddalti, àti Romamtieseri, Joṣbekaṣa, Malloti, Hotiri, Mahasiotu.
5 Songa ana’ i Hemane, mpitoki’ i mpanjakay ty amy ze mioza aman’ Añahare, hañonjonañe i tsifay. Tinolon’ Añahare ana-dahy folo-efats’ amby naho anak’ ampela telo t’i Hemane.
Gbogbo àwọn wọ̀nyí sì ni ọmọ Hemani àti wòlíì ọba. Wọ́n sì fi wọ́n fún nípa ìlérí Ọlọ́run láti máa gbé ìwo sókè. Ọlọ́run sì fún Hemani ní ọmọkùnrin mẹ́rìnlá àti àwọn ọmọbìnrin mẹ́ta.
6 Songa ambanem-pitàn-drae’e hisabo añ’ anjomba’ Iehovà ao reketse fikantsañañe, jejobory naho marovany, hitoroñe i anjomban’ Añaharey, ambanem-pità’ i mpanjakay, amy Asafe, amy Iedotone vaho amy Hemane.
Gbogbo àwọn ọkùnrin yìí ni wọ́n wà lábẹ́ ìbojútó àwọn baba wọn fún ohun èlò orin ilé Olúwa, pẹ̀lú kimbali, ohun èlò orin olókùn àti dùùrù, fún ìsìn ilé Olúwa. Asafu, Jedutuni àti Hemani sì wà lábẹ́ ọba.
7 Ty ia’ iareo naho o rahalahi’ iareoo naòke hisabo am’ Iehovà, ze hene nahimbañe le roanjato-tsi-valompolo-valo’ amby.
Àwọn ìdílé wọn pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó mòye àti àwọn tí a kọ́ ní ohun èlò orin fún Olúwa, iye wọn sì jẹ́ ọ̀rìnlélúgba ó lé mẹ́jọ.
8 Sindre nanao ki-tsapake ho amy fi­to­loña’ey, ty kede naho ty bey, ty mpañoke vaho ty mpioke.
Kékeré àti àgbà bákan náà, olùkọ́ àti gẹ́gẹ́ bí ti akẹ́kọ̀ọ́, ṣẹ́ kèké fún iṣẹ́ wọn.
9 Ty tsapake valoha’e ho a’ i Asafe le Iosefe; ty faharoe, a i Gedalià; ie naho o raha­lahi’eo naho o ana-dahi’eo, folo-ro’ amby.
Kèké èkínní èyí tí ó jẹ́ ti Asafu, jáde sí Josẹfu, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá èkejì sì ni Gedaliah, òun àti àwọn ìdílé rẹ̀ àti àwọn ọmọ rẹ̀, méjìlá
10 Ty fahatelo a i Zakore, o rahalahi’e naho ana-dahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹta sí Sakkuri, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé, méjìlá
11 Ty fahefatse a i Itsrý; o ana’dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’ amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin sí Isiri, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
12 Ty fahalime, a i Netanià, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀karùnún sí Netaniah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
13 Ty fah’eneñe, a i Bokià, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà sí Bukkiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
14 Ty faha-fito a i Iesarelà, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀keje sí Jasarela, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
15 Ty fahavalo a i Iesaià, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’ amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹjọ sí Jeṣaiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
16 Ty fahasive a i Matanià, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹsàn-án sí Mattaniah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
17 Ty fahafolo a i Simey, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’ amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹwàá sí Ṣimei, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ jẹ́, méjìlá
18 Ty fahafolo-raik’amby, a i Azarele, o ana-dahi’eo naho o raha­lahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kọkànlá sí Asareeli, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
19 Ty fahafolo-ro’ amby, a i Kasabià, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹjìlá sí Haṣabiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
20 Ty fahafolo-telo’amby, a i Sobaele, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’ amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹtàlá sí Ṣubaeli, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
21 Ty fahafolo-efats’amby, a i Matitià, o ana-dahi’eo naho o raha­lahi’eo, folo-ro’ amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrìnlá sí Mattitiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
22 Ty fahafolo-lim’ amby, a i Iere­mote, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹẹ̀dógún sí Jerimoti, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
23 Ty fahafolo-eneñ’amby, a i Kananià, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’ amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrìndínlógún sí Hananiah, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
24 Ty fahafolo-fito’amby, a i Iosbe­kasà; o ana-dahi’eo naho o raha­lahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹtàdínlógún sí Joṣbekaṣa, àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
25 Ty faha­folo-valo’amby, a i Kananý, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kejìdínlógún sí Hanani, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
26 Ty fahafolo-sive’amby, a i Ma­lotý, o ana-dahi’eo naho o raha­lahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kọkàndínlógún sí Malloti, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
27 Ty faha-roa­polo, a i Eliatà, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’ amby.
ogún sí Eliata, àwọn ọmọ rẹ̀ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
28 Ty faha-roapolo-raik’amby, a i Hotire, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kọkànlélógún sí Hotiri, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
29 Ty faha-roapolo-ro’ amby, a i ­Gidaltý, o ana-dahi’eo naho o raha­lahi’eo, folo-ro’ amby.
ẹlẹ́ẹ̀kejìlélógún sí Giddalti, àwọn ọmọ rẹ̀ àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
30 Ty faha-roapolo-telo’amby, a i Makaziote, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹtàlélógún sí Mahasiotu, àwọn ọmọ rẹ àti ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá
31 Ty faha-roapolo-efats’ amby, a i Romamtiezere, o ana-dahi’eo naho o rahalahi’eo, folo-ro’amby.
ẹlẹ́ẹ̀kẹrìnlélógún sí Romamtieseri àwọn ọmọ rẹ̀, àti àwọn ìdílé rẹ̀ sì jẹ́, méjìlá.

< 1 Tantara 25 >