< 1 Tantara 15 >

1 Namboatse anjomba ho am-bata’e an-drova’ i Davide ao t’i Davide, le nañajaria’e toetse i vatan’ Añaharey vaho nañoreña’e kivoho.
Lẹ́yìn ìgbà tí Dafidi ti kọ́ ilé fún ara rẹ̀ ní ìlú Dafidi. Ó sì fi ààyè sílẹ̀ fún àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ó sì pàgọ́ fún un.
2 Le hoe t’i Davide: Tsy eo ty hinday i vatan’ Añaharey naho tsy o nte-Levio avao; amy t’ie ty jinobo’ Iehovà hitarazo i vatan’ Añaharey naho ty hito­roñe Aze nainai’e.
Nígbà náà Dafidi wí pé, kò sí ẹnìkan àyàfi àwọn ọmọ Lefi ni ó lè gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run, nítorí Olúwa yàn wọ́n láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa àti láti máa ṣe ìránṣẹ́ níwájú rẹ̀ títí láé.
3 Natonto’ i Davide e Ierosa­laime ao t’Isra­ele iaby, haneseañe ty vata’ Iehovà mb’ an-toe’e nihajarie’e ho aze.
Dafidi kó gbogbo àwọn ọmọ Israẹli jọ ní Jerusalẹmu láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ibi tí ó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
4 Le navori’ i Davide o ana’ i Aharoneo naho o nte-Levio;
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Aaroni àti àwọn ọmọ Lefi tí Dafidi péjọ papọ̀.
5 amo ana’ i Kehàteo: i Oriele ty talè naho o rahalahi’eo, zato tsy roapolo;
Ọgọ́fà nínú àwọn ọmọ Kohati; Urieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
6 amo ana’ i Merario: i Asaià ty talè naho o rahalahi’eo: roanjato-tsi-roapolo;
Igba ó lé ogún nínú àwọn ọmọ Merari; Asaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
7 amo ana’ i Gersomeo: Ioele ty talè’e naho o rahalahi’eo; zato-tsi-telopolo;
Àádóje nínú àwọn ọmọ Gerṣoni; Joẹli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
8 amo ana’ i Eli­tsafaneo; i Semaià ty talè naho o rahalahi’eo, roanjato;
Igba nínú àwọn ọmọ Elisafani; Ṣemaiah olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
9 amo ana’ i Kebroneo; i Eliele ty talè naho valopolo o rahalahi’eo;
Ọgọ́rin nínú àwọn ọmọ Hebroni; Elieli olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
10 amo ana’ i Ozieleo; i Aminadabe ty talè naho zato-tsi-folo-ro’ amby o rahalahi’eo.
Méjìléláàádọ́fà nínú àwọn ọmọ Usieli; Amminadabu olórí àti àwọn ẹbí rẹ̀.
11 Kinanji’ i Davide amy zao t’i Tsadoke naho i Abiatare mpisoroñe naho amo nte-Levio, i Oriele naho i Asaià naho Ioele naho i Semaià naho i Eliele vaho i Aminadabe,
Dafidi sì ránṣẹ́ pe Sadoku, Abiatari tí wọ́n jẹ́ àlùfáà, àti Urieli, Asaiah. Joẹli, Ṣemaiah, Elieli àti Amminadabu tí wọ́n jẹ́ Lefi.
12 le nanoa’e ty hoe: Inahareo ro talèn’ anjomban-droae nte-Levio; mañamasiña vatañe, ie naho o longo’ areoo, hanesea’ areo mb’etoy i vata’ Iehovà Andrianañahare’ Israeley, mb’amy nihajariakoy.
Ó sì fi fún wọn pé, “Ẹ̀yin ni olórí àwọn ìdílé Lefi; ẹ̀yin àti àwọn Lefi ènìyàn yín, ẹ ya ara yín sí mímọ́ kí ẹ lè gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, lọ sí ibi tí mó ti pèsè sílẹ̀ fún un.
13 Ie tsy nendesa’ areo am-baloha’ey ty nitosira’ Iehovà Andrianañahare aman-tika, amy te tsy nihalalian-tika i fañè zay.
Nítorí tí ẹ̀yin ọmọ Lefi kò gbe gòkè wá ní ìgbà àkọ́kọ́ ti Olúwa Ọlọ́run fi ìbínú rẹ̀ ko lù wá. Àwa kò sì ṣe ìwádìí lọ́wọ́ rẹ̀ nípa bí a ti ń ṣe é gẹ́gẹ́ bí ọ́nà tí a là sílẹ̀.”
14 Aa le nañefe-batañe o mpisoroñeo naho o nte-Levio, hampionjoñe i vata’ Iehovà Andrianañahare’ Israeley.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi ya ara wọn sí mímọ́ láti gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa gòkè wá, Ọlọ́run Israẹli.
15 Aa le nitarazoe’ o ana’ i Levio an-tsoroke am-boda’e i vatan’ Añaharey, amy nandilia’ i Mosè ty amy tsara’ Iehovàiy.
Nígbà náà ni àwọn Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run pẹ̀lú ọ̀pá ní èjìká wọn gẹ́gẹ́ bí Mose ti pa á láṣẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa.
16 Le nisaontsy amy mpiaolo’ o nte-Levio t’i Davide hijoboña’e amo rahalahi’eo o mpisaboo, reke-pititihañe ara-tsabo, am-pipoñafeñe jejo-bory naho marovany naho fikaran­tsañe vaho ­ionjonam-peo an-drebeke.
Dafidi sọ fún àwọn olórí àwọn Lefi láti yan àwọn arákùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí akọrin láti kọ orin ayọ̀, pẹ̀lú àwọn ohun èlò orin olókùn, dùùrù, àti símbálì.
17 Aa le jinobo’ o nte-Levio t’i Hemane ana’ Ioele; naho o rahalahi’eo, i Asafe, ana’ i Berekia; naho o ana’ i Merario, i Etane ana’ i Kosaià;
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Lefi yan Hemani ọmọ Joẹli; àti nínú àwọn arákùnrin rẹ̀, Asafu ọmọ Berekiah, àti nínú àwọn ọmọ Merari arákùnrin wọn, Etani ọmọ Kuṣaiah;
18 naho o rahalahi’e amy saranga faharoeio: i Zekarià, i Bene naho Iaaziele naho i Semiramote naho Iekiele naho i Oný, i Eliabe naho i Benaià naho i Maaseià naho i Matitià naho i Elifeleho vaho i Mikneià naho i Ovededome naho Ieiele, songa mpiamben-dalambey.
àti pẹ̀lú wọn àwọn arákùnrin wọn tí a yàn bí olùrànlọ́wọ́ wọn: Sekariah, Jaasieli, Ṣemiramotu, Jehieli, Unni, Eliabu, Benaiah, Maaseiah, Mattitiah, Elifelehu, Mikimeiah, àti Obedi-Edomu àti Jeieli, àwọn aṣọ́bodè.
19 Tinendre hampikorintseñe o katsàñe torisikeo t’i Hemane naho i Asafe vaho i Etane, mpisabo;
Àwọn akọrin sì ni Hemani, Asafu, àti Etani ti àwọn ti kimbali idẹ tí ń dún kíkan;
20 le songa an-jejobory, am-peo abo t’i Zeka­rià naho i Aziele naho i Semiramote naho Iehiele naho i Oný naho Eliabe naho i Maaseià vaho i Benaià.
Sekariah, Asieli, Ṣemiramotu, Jehieli, àti Unni, Eliabu, Maaseiah àti Benaiah àwọn tí ó gbọdọ̀ ta ohun èlò orin olókùn gẹ́gẹ́ bí alamoti,
21 Le an-tali-valo hitarihañe o feo ambaneo t’i Matitià naho i Elifeleho naho i Mikneià naho i Ovede­dome naho Ieiele vaho i Azazià.
àti Mattitiah, Elifelehu, Mikneiah, Obedi-Edomu, Jeieli àti Asasiah ni ó ní láti ta ohun èlò olóhùn gooro, láti darí gẹ́gẹ́ bí ṣeminiti.
22 Natao mpañoniñe t’i Kenanià, talè’ o nte-Levio, amy hilala’e onin-tsaboy, toe nahihitse.
Kenaniah olórí àwọn ará Lefi ni ó wà ní ìkáwọ́ orin èyí sì ni ojúṣe nítorí ó mòye nípa rẹ̀.
23 Nimpitan-dala’ i vatay t’i Berekià naho i Elkanà.
Berekiah àti Elkana ni kí ó wà gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
24 I Sebanià naho Iehosafate naho i Netanele naho i Amasay naho i Zekarià naho i Benaià naho i Eliezere, mpisoroñe, songa nampipopò trompetra aolo’ i vatan’ Añaharey; vaho nimpitan-dala’ i vatay t’i Ovededome naho Iekià.
Ṣebaniah, Jehoṣafati, Netaneli, Amasai, Sekariah, Benaiah àti Elieseri ní àwọn àlùfáà, tí o ń fún ìpè níwájú àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run. Obedi-Edomu àti Jehiah ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ olùṣọ́nà fún àpótí ẹ̀rí.
25 Aa le nimb’eo t’i Davide naho o roandria’ Israeleo naho o mpifelek’ arivoo, hampionjona’ iereo mb’eo i vatam-pañina’Iehovày boak’ añ’anjomba’ i Ovededome ao an-dre­beke.
Bẹ́ẹ̀ ni Dafidi àti àwọn àgbàgbà Israẹli àti àwọn olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún lọ láti gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa láti ilé Obedi-Edomu, pẹ̀lú inú dídùn.
26 Ie amy zao, kanao nañolotse o nte-Levy nitarazo i vatam-pañina’ Iehovàio t’i Andrianañahare, le nisoroñañe bania fito naho añondrilahy fito.
Nítorí Ọlọ́run tì ràn wọ́n lọ́wọ́ àwọn ará Lefi ẹni tí ó gbé àpótí ẹ̀rí ti májẹ̀mú Olúwa, akọ màlúù méje pẹ̀lú àgbò méje láti fi ṣé ìrúbọ.
27 Nisaroñe leny mireparepa t’i Davide naho o nte-Levy nitarazo i vataio naho o mpisaboo vaho i Kenanià talè’ o mpi­sabo amo oniñeoo; le nampiombeañe kitam­be leny t’i Davide.
Dafidi sì wọ efodu; aṣọ ìgúnwà ọ̀gbọ̀ dáradára, àti gbogbo àwọn ọmọ Lefi tí ń ru àpótí ẹ̀rí náà, àti àwọn akọrin, àti Kenaniah olórí pẹ̀lú àwọn akọrin. Dafidi sì wọ aṣọ ìgúnwà funfun.
28 Aa le songa nampionjoñe i vatam-pañina’ Iehovày am-pazake t’Israele, am-pitiofañe tsifa naho am-pipopòn-trompetra naho am-pikarantsañe naho am-pipoñafam-peo reke-jejobory naho marovany.
Bẹ́ẹ̀ ni gbogbo Israẹli gbé àpótí ẹ̀rí àti májẹ̀mú Olúwa gòkè wá pẹ̀lú ariwo, pẹ̀lú àyíká ìhó ayọ̀ àti láti fọn fèrè ti ìpè, àti kimbali, àti láti ta ohun èlò orin olókùn àti dùùrù olóhùn gooro.
29 Ie nimoak’ an-drova’ i Davide ao i vatam-pañina’ Iehovày, le nitilihitse an-dalan-kede t’i Mikale ana’ i Saole nahaisake i Davide nitsinjake naho niankahake ey vaho nitorifiha’e an-trok’ ao.
Bí àpótí ẹ̀rí Olúwa ti ń wọ ìlú ńlá Dafidi, Mikali ọmọbìnrin Saulu ń wò láti ojú fèrèsé nígbà tí ó sì rí ọba Dafidi ń jó, ó sì ń ṣe àjọyọ̀, ó sì kẹ́gàn rẹ̀ ní ọkàn rẹ̀.

< 1 Tantara 15 >