< Psalmi 81 >

1 Asafa dziesma, dziedātāju vadonim uz Ģittit. Dziediet priecīgi Dievam, mūsu stiprumam, gavilējiet Jēkaba Dievam.
Fún adarí orin. Gẹ́gẹ́ bí ti gittiti. Ti Asafu. Kọrin sókè sí Ọlọ́run agbára wa ẹ hó ìhó ayọ̀ sí Ọlọ́run Jakọbu!
2 Uzdziedat dziesmas un dodiet šurp bungas, mīlīgas kokles ar stabulēm.
Ẹ mú orin mímọ́, kí ẹ sì mú ìlù wá, tẹ dùùrù dídùn pẹ̀lú ohun èlò orin mímọ́.
3 Pūtiet trumetes jaunā mēnesī, pilnā mēnesī, mūsu svētku laikā.
Ẹ fún ìpè ní oṣù tuntun àní nígbà tí a yàn; ní ọjọ́ àjọ wa tí ó ní ìrònú.
4 Jo tas ir likums iekš Israēla, tiesa no Jēkaba Dieva.
Èyí ni àṣẹ fún Israẹli, àti òfin Ọlọ́run Jakọbu.
5 To Viņš licis par liecību iekš Jāzepa, kad izgāja pār Ēģiptes zemi, kad es dzirdēju valodu, ko nesapratu.
Ó fi múlẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà fún Josẹfu nígbà tí ó la ilẹ̀ Ejibiti já. Níbi tí a ti gbọ́ èdè tí kò yé wa.
6 “Viņa kamiešiem Es esmu atņēmis nastu, un viņa rokas atsvabinājis no nestavas.
Ó wí pé, “Mo gbé àjàgà kúrò ní èjìká yín, a tú ọwọ́ wọn sílẹ̀ kúrò nínú apẹ̀rẹ̀.
7 Kad tu Mani piesauci bēdās, tad Es tevi izglābu; Es tevi paklausīju, paslēpies pērkona padebešos, Es tevi pārmanīju pie bāršanās ūdens.
Nínú ìnilára ni ẹ pè mo sì gbà yín là, mo dá a yín lóhùn nínú ìkọ̀kọ̀ àrá, mo dán an yín wò ní odò Meriba. (Sela)
8 Klausāties, Mani ļaudis, Es jums došu liecību; Israēl, kaut tu Mani klausītu!
“Gbọ́, ẹ̀yin ènìyàn mi, èmi ó sì kìlọ̀ fún un yín, bí ìwọ bá fetí sí mi, ìwọ Israẹli.
9 Lai tavā starpā nav cita Dieva, un tev nebūs pielūgt svešu Dievu.
Ẹ̀yin kì yóò ní Ọlọ́run ilẹ̀ mìíràn láàrín yín; ẹ̀yin kì yóò foríbalẹ̀ fún Ọlọ́run àjèjì.
10 Es esmu Tas Kungs, tavs Dievs, kas tevi izvedis no Ēģiptes zemes; atplet savu muti, lai Es to pildu.
Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó mú un yín jáde láti Ejibiti. Ẹ la ẹnu yín gbòòrò, èmi yóò sì kún un.
11 Bet Mani ļaudis neklausa Manu balsi un Israēlim Manis negribās.
“Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi kì yóò gbọ́ tèmi; Israẹli kò ní tẹríba fún mi.
12 Tad Es tos arī esmu pametis viņu cietam sirds prātam, ka tie staigā pēc saviem padomiem.
Nítorí náà ni mo ṣe fi wọ́n fún ọkàn líle wọn láti máa rìn ní ọ̀nà ẹ̀tàn wọn.
13 Kaut Mani ļaudis Man klausītu, un Israēls staigātu uz Maniem ceļiem!
“Bí àwọn ènìyàn mi yóò bá gbọ́ tèmi bí Israẹli yóò bá tẹ̀lé ọ̀nà mi,
14 Es pazemotu viņu ienaidniekus drīz un grieztu Savu roku pret viņu spaidītājiem.
ní kánkán ni èmi yóò ṣẹ́gun àwọn ọ̀tá wọn kí n sì yí ọwọ́ mi padà sí ọ̀tá wọn!
15 Kas To Kungu ienīst, tiem bija Viņam padoties, tad tie mūžīgi pastāvētu.
Àwọn tí ó kórìíra Olúwa yóò tẹríba níwájú rẹ̀. Ìjìyà wọn yóò sì pẹ́ títí láé.
16 Un Viņš tos barotu ar briedušiem kviešiem, un ar medu no akmens kalna Es tevi pieēdinātu.”
Ṣùgbọ́n a ó fi ọkà tí ó dára bọ́ ọ yín èmi ó tẹ́ ẹ yín lọ́rùn pẹ̀lú oyin inú àpáta.”

< Psalmi 81 >