< Psalmi 22 >

1 Dāvida dziesma. Dziedātāju vadonim pēc: „rīta blāzmas stirna“. Mans Dievs! Mans Dievs! Kāpēc Tu mani esi atstājis? Tu esi tālu no manas palīdzības, no manas kaukšanas vārdiem.
Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀? Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là, àní sí igbe ìkérora mi?
2 Mans Dievs, es saucu dienā, bet Tu man neatbildi, un nakti es arī klusu neciešu.
Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn: àti ní òru èmi kò dákẹ́.
3 Bet Tu esi svēts, dzīvodams starp Israēla slavas dziesmām.
Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ; ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó.
4 Uz Tevi mūsu tēvi cerējuši, tie ir cerējuši, un Tu tos esi izglābis.
Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ; wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
5 Uz Tevi tie saukuši un ir izpestīti, tie cerējuši uz Tevi un nav palikuši kaunā.
Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà; ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.
6 Bet es esmu tārps un ne cilvēks, cilvēku apsmiekls un ļaužu nicināts.
Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn; mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn.
7 Visi, kas mani redz, mani apmēda, atplēš lūpas un krata galvu sacīdami:
Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà; wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
8 Viņš to Tam Kungam sūdzējis; lai Tas viņu izrauj un viņu izglābj, ja Tam pie viņa ir labs prāts.
“Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa; jẹ́ kí Olúwa gbà á là. Jẹ́ kí ó gbà á là, nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”
9 Tomēr Tu tas esi, kas mani izvedis no mātes miesām; Tu man licis paļauties uz Tevi no mātes krūtīm.
Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú; ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
10 Uz Tevi es esmu mests no mātes klēpja, no mātes miesām Tu esi mans Dievs.
Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá, nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.
11 Neesi tālu no manis, jo bailība ir tuvu, jo palīga nav.
Má ṣe jìnnà sí mi, nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.
12 Lieli vērši mani apstājuši, trekni buļļi ap mani apmetušies.
Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká; àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
13 Tie atplēš savu rīkli pret mani kā lauva, plezdams un rūkdams.
Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri, tí ń ké ramúramù.
14 Es esmu izgāzts kā ūdens, visi mani kauli ir izlauzti, mana sirds ir manās miesās kā izkausēts vasks.
A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi, gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀. Ọkàn mi sì dàbí i ìda; tí ó yọ́ láàrín inú mi.
15 Mans spēks ir izkaltis kā poda gabals, un mana mēle līp pie mana zoda, un Tu mani nolieci nāves pīšļos,
Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì, ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi; ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú. (questioned)
16 Jo suņi mani apstājuši, un ļaundarītāju bars ap mani ir apmeties, tie manas rokas un manas kājas ir izurbuši.
Àwọn ajá yí mi ká; ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́, wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀.
17 Es visus savus kaulus varu skaitīt, bet viņi skatās un lūko uz mani ar prieku.
Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi; àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
18 Tie dala manas drēbes savā starpā un met kauliņus par manu apģērbu.
Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
19 Bet Tu, ak Kungs, neesi tālu, mans stiprums, steidzies man palīgā.
Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi. Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
20 Izglāb manu dvēseli no zobena, manu vientuli no suņu varas.
Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà, àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
21 Izpestī mani no lauvas rīkles un paklausi mani no vēršu ragiem.
Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún; kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
22 Es sludināšu Tavu vārdu saviem brāļiem, es Tevi slavēšu draudzes vidū.
Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi; nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
23 Slavējiet To Kungu, jūs, kas Viņu bīstaties, viss Jēkaba dzimums lai Viņu godā, un bīstaties, viss Israēla dzimums.
Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín! Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un! Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
24 Jo Viņš nav nicinājis nedz apsmējis bēdīga bēdas, nedz no tā apslēpis Savu vaigu, un kad tas Viņu piesauca, tad Viņš paklausīja.
Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra ìpọ́njú àwọn tí a ni lára; kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.
25 No Tevis es dziedāšu tai lielā draudzē, es maksāšu savus solījumus to priekšā, kas Viņu bīstas.
Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá; ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
26 Tie bēdīgie ēdīs un būs paēduši, un kas To Kungu meklē, Viņu slavēs; jūsu sirds dzīvos mūžīgi.
tálákà yóò jẹ yóò sì yó; àwọn tí n wá Olúwa yóò yin jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!
27 Visi zemes gali to pieminēs un atgriezīsies pie Tā Kunga, un visas pagānu tautas klanīsies Viņa priekšā.
Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí wọn yóò sì yípadà sí Olúwa, àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
28 Jo Tam Kungam pieder tā valstība, un Viņš valda pār tām tautām.
nítorí ìjọba ni ti Olúwa. Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
29 Visi treknie virs zemes ēdīs un pielūgs, visi, kas pīšļos guļ, klanīsies Viņa priekšā, arī tie, kas nevarēja uzturēt savu dzīvību.
Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn; gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀ àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
30 Viņam būs dzimums, kas Viņam kalpos, par To Kungu sludinās līdz radu radiem;
Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín; a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa.
31 Nāks un sludinās Viņa taisnību tiem ļaudīm, kas vēl dzims, ka Viņš to ir darījis.
Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀ sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí, wí pé, òun ni ó ṣe èyí.

< Psalmi 22 >