< Psalmi 105 >

1 Pateiciet Tam Kungam, piesauciet Viņa Vārdu, dariet zināmus starp tiem ļaudīm Viņa darbus.
Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, ké pe orúkọ rẹ̀, jẹ́ kí a mọ ohun tí ó ṣe láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
2 Dziediet Viņam, slavējiet Viņu ar dziesmām, pārdomājiet visus Viņa brīnumus.
Kọrin sí i, kọrin ìyìn sí i; sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ̀ gbogbo.
3 Slavējiet Viņa svēto vārdu; lai tās sirdis priecājās, kas To Kungu meklē.
Ṣògo nínú orúkọ mímọ́ rẹ̀, jẹ́ kí ọkàn àwọn tí ń wá Olúwa kí ó yọ̀.
4 Vaicājiet pēc Tā Kunga un pēc Viņa spēka, meklējiet vienmēr Viņa vaigu.
Wá Olúwa àti ipá rẹ̀; wa ojú rẹ̀ nígbà gbogbo.
5 Pieminiet Viņa brīnumus, ko Viņš ir darījis, Viņa brīnuma darbus un Viņa mutes tiesas, -
Rántí àwọn ìyanu tí ó ti ṣe, ìyanu rẹ̀, àti ìdájọ́ tí ó sọ,
6 Tu Ābrahāma, Viņa kalpa dzimums, jūs Jēkaba bērni, Dieva izredzētie!
ẹ̀yin ìran Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀, ẹ̀yin ọmọkùnrin Jakọbu, àyànfẹ́ rẹ̀.
7 Viņš ir Tas Kungs, mūsu Dievs; Viņa tiesas iet pār visu zemi.
Òun ni Olúwa Ọlọ́run wa: ìdájọ́ rẹ̀ wà ní gbogbo ayé.
8 Viņš piemin Savu derību mūžam, to vārdu, ko Viņš ir iecēlis tūkstošiem dzimumiem,
Ó rántí májẹ̀mú rẹ̀ láéláé, ọ̀rọ̀ tí ó pàṣẹ, fún ẹgbẹẹgbẹ̀rún ìran,
9 Ko Viņš ar Ābrahāmu derējis un ko zvērējis Īzakam.
májẹ̀mú tí ó dá pẹ̀lú Abrahamu, ìbúra tí ó ṣe pẹ̀lú fún Isaaki.
10 To Viņš arī Jēkabam ir iecēlis par likumu, Israēlim par mūžīgu derību,
Ó ṣe ìdánilójú u rẹ̀ fún Jakọbu gẹ́gẹ́ bí àṣẹ, sí Israẹli, gẹ́gẹ́ bi májẹ̀mú ayérayé:
11 Sacīdams: tev Es došu Kanaāna zemi, jūsu mantības daļu;
“Fún ìwọ ni èmi ó fún ní ilẹ̀ Kenaani gẹ́gẹ́ bí ìpín tí ìwọ ó jogún.”
12 Kad tie vēl bija mazs pulciņš, ne daudz, un svešinieki iekš tās,
Nígbà tí wọn kéré níye, wọ́n kéré jọjọ, àti àwọn àjèjì níbẹ̀
13 Un staigāja no vienas tautas pie otras, no vienas valsts pie otras valsts ļaudīm,
wọ́n rìn kiri láti orílẹ̀-èdè sí orílẹ̀-èdè, láti ìjọba kan sí èkejì.
14 Viņš nevienam neļāva tos apbēdināt, Viņš arī ķēniņus sodīja viņu dēļ:
Kò gba ẹnikẹ́ni láààyè láti pọ́n wọn lójú; ó fi ọba bú nítorí tiwọn:
15 Neaizskariet Manus svaidītos un nedariet ļauna Maniem praviešiem!
“Má ṣe fọwọ́ kan ẹni àmì òróró mi; má sì ṣe wòlíì mi níbi.”
16 Viņš aicināja badu pār zemi, Viņš atņēma visu maizes padomu.
Ó pe ìyàn sórí ilẹ̀ náà ó sì pa gbogbo ìpèsè oúnjẹ wọn run;
17 Viņš sūtīja viņu priekšā vienu vīru; Jāzeps tapa pārdots par kalpu.
Ó sì rán ọkùnrin kan síwájú wọn Josẹfu tí a tà gẹ́gẹ́ bí ẹrú.
18 Viņa kājas tapa spaidītas siekstā, viņa miesas nāca dzelzīs,
Wọn fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ bọ ẹsẹ̀ rẹ̀ a gbé ọrùn rẹ̀ sínú irin,
19 Tiekams viņa vārds notika, un Tā Kunga sludinājums to pārbaudīja.
títí ọ̀rọ̀ tí ó sọtẹ́lẹ̀ fi ṣẹ títí ọ̀rọ̀ Olúwa fi dá a láre.
20 Tas ķēniņš sūtīja un lika to atraisīt, tas ļaužu valdītājs to atlaida vaļā.
Ọba ránṣẹ́ lọ tú u sílẹ̀ àwọn aláṣẹ ènìyàn tú u sílẹ̀
21 Viņš to iecēla par kungu savam namam un par valdnieku visai savai mantai.
Ó fi jẹ olúwa lórí ilẹ̀ rẹ̀, aláṣẹ lórí ohun gbogbo tí ó ní,
22 Ka tas saistītu viņa lielkungus pēc sava prāta un mācītu gudrību viņa vecākajiem.
gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ̀, kí ó máa ṣe àkóso àwọn ọmọ-aládé kí ó sì kọ́ àwọn àgbàgbà rẹ̀ ní ọgbọ́n.
23 Tā Israēls nāca Ēģiptes zemē un Jēkabs piemita Hama zemē.
Israẹli wá sí Ejibiti; Jakọbu sì ṣe àtìpó ní ilé Hamu.
24 Un Viņš Saviem ļaudīm lika augumā augt un tos darīja jo varenus nekā viņu pretiniekus.
Olúwa, sì mú àwọn ọmọ rẹ̀ bí sí i ó sì mú wọn lágbára jù àwọn ọ̀tá wọn lọ
25 Viņš pārvērsa viņu sirdi, ienīdēt Viņa ļaudis un ar viltu glūnēt uz Viņa kalpiem.
Ó yí wọn lọ́kàn padà láti kórìíra àwọn ènìyàn láti ṣe àrékérekè sí àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
26 Viņš sūtīja Mozu, Savu kalpu, un Āronu, ko Viņš bija izredzējis.
Ó rán Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, àti Aaroni tí ó ti yàn.
27 Tie darīja viņu starpā Dieva brīnumus un brīnuma zīmes Hama zemē.
Wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ìyanu láàrín wọn ó ṣe iṣẹ́ ìyanu ní Hamu.
28 Viņš sūtīja tumsu, tad kļuva tumšs; un tie Viņa Vārdam neturējās pretī.
Ó rán òkùnkùn, o sì mú ilẹ̀ ṣú wọn kò sì sọ̀rọ̀-òdì sí ọ̀rọ̀ rẹ̀.
29 Viņš pārvērsa viņu ūdeņus par asinīm un nokāva viņu zivis.
Ó sọ omi wọn di ẹ̀jẹ̀, ó pa ẹja wọn.
30 Viņu zeme mudžēja no vardēm viņu ķēniņu kambaros.
Ilẹ̀ mú ọ̀pọ̀lọ́ jáde wá, èyí tí ó lọ sí ìyẹ̀wù àwọn ọba wọn.
31 Viņš runāja, tad nāca kukaiņi, utis visās viņu robežās.
Ó sọ̀rọ̀, onírúurú eṣinṣin sì dìde, ó sì hu kantíkantí ní ilẹ̀ wọn
32 Viņš tiem deva krusu lietus vietā, uguns liesmas viņu zemē,
Ó sọ òjò di yìnyín, àti ọ̀wọ́-iná ní ilẹ̀ wọn;
33 Un sasita viņu vīna kokus un viņu vīģes kokus un salauzīja kokus viņu robežās.
Ó lu àjàrà wọn àti igi ọ̀pọ̀tọ́ wọn ó sì dá igi orílẹ̀-èdè wọn.
34 Viņš runāja, tad nāca siseņi un vaboles neizskaitāmā pulkā,
Ó sọ̀rọ̀, eṣú sì dé, àti kòkòrò ní àìníye,
35 Kas apēda visu zāli viņu zemē, un norija viņu zemes augļus.
wọn sì jẹ gbogbo ewé ilẹ̀ wọn, wọ́n sì jẹ èso ilẹ̀ wọn run.
36 Viņš kāva arī visus pirmdzimtos viņu zemē un visu viņu pirmo stiprumu.
Nígbà náà, ó kọlu gbogbo àwọn ilẹ̀ wọn, ààyò gbogbo ipá wọn.
37 Un tos izveda ar sudrabu un zeltu, un neviena gurdena nebija viņu ciltīs.
Ó mú Israẹli jáde ti òun ti fàdákà àti wúrà, nínú ẹ̀yà rẹ̀ kò sí aláìlera kan.
38 Ēģiptes zeme priecājās, kad tie izgāja, jo viņu bailes uz tiem bija kritušas.
Inú Ejibiti dùn nígbà tí wọn ń lọ, nítorí ẹ̀rù àwọn Israẹli ń bá wọ́n.
39 Viņš deva padebesi par apsegu, un uguni naktī par gaismu.
Ó ta àwọsánmọ̀ fún ìbòrí, àti iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ lálẹ́.
40 Tie lūdza un viņš lika nākt paipalām un tos ēdināja ar debes'maizi.
Wọn béèrè, ó sì mú ẹyẹ àparò wá, ó sì fi oúnjẹ ọ̀run tẹ́ wọn lọ́rùn.
41 Viņš pāršķēla klinti, tad ūdens iztecēja, un upes skrēja tuksnesī.
Ó sì la àpáta, ó sì mú omi jáde; gẹ́gẹ́ bí odò tí ń sàn níbi gbígbẹ.
42 Jo Viņš pieminēja Savu svēto vārdu un Ābrahāmu, Savu kalpu.
Nítorí ó rántí ìlérí mímọ́ rẹ̀ àti Abrahamu ìránṣẹ́ rẹ̀.
43 Tā Viņš izveda Savus ļaudis ar prieku un Savus izredzētos ar gavilēšanu,
Ó sì fi ayọ̀ mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde pẹ̀lú ayọ̀ ní ó yan àyànfẹ́ rẹ̀
44 Un tiem deva pagānu zemes; tie iemantoja tautu sviedrus,
Ó fún wọn ní ilẹ̀ ìní náà, wọ́n sì jogún iṣẹ́ àwọn ènìyàn náà,
45 Lai turētu Viņa likumus un sargātu Viņa bauslību. Alleluja.
kí wọn kí ó lè máa pa àṣẹ rẹ̀ mọ́ kí wọn kí ó lè kíyèsi òfin rẹ̀. Ẹ fi ìyìn fún Olúwa.

< Psalmi 105 >