< Ceturtā Mozus 35 >

1 Un Tas Kungs runāja uz Mozu Moaba klajumos pie Jardānes pret Jēriku un sacīja:
Lórí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní Jordani tí ó rékọjá láti Jeriko, Olúwa sọ fún Mose pé,
2 Pavēli Israēla bērniem, lai tie no savas iemantojamās daļas dod pilsētas Levitiem, kur dzīvot, un lai tie dod Levitiem arī apgabalus ārā ap viņu pilsētām.
“Pàṣẹ fún àwọn ọmọ Israẹli láti fún àwọn Lefi ní ilẹ̀ láti gbé lára ogún tí àwọn ọmọ Israẹli yóò jogún. Kí ẹ sì fún wọn ní ilẹ̀ lára pápá oko tútù, káàkiri ìlú.
3 Un tās pilsētas tiem būs, lai tie tur dzīvo, bet tie apgabali lai ir priekš viņu lieliem un sīkiem lopiem un priekš visiem viņu ganāmiem pulkiem.
Nígbà náà, wọn yóò ní ìlú tí wọn yóò gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn, ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú gbogbo ìní wọn.
4 Un tie pilsētu apgabali, ko jūs Levitiem dosiet, lai ir no pilsētas mūriem uz āru tūkstošas olektis uz visām pusēm.
“Ilẹ̀ pápá oko tútù káàkiri ìlú tí ẹ ó fi fún àwọn ọmọ Lefi, wíwọ̀n rẹ̀ yóò jẹ́ ẹgbẹ̀rún ìgbọ̀nwọ́ (1,500 ẹsẹ̀ bàtà) láti ògiri ìlú náà.
5 Un jums būs mērot pilsētas āra pusē pret rītiem divtūkstoš olektis un pret dienas vidiem divtūkstoš olektis un pret vakariem divtūkstoš olektis un pret ziemeļiem divtūkstoš olektis, ka pilsēta ir vidū; šie būs viņiem tie pilsētu apgabali.
Lẹ́yìn ìlú náà, wọn ẹgbẹ̀rún méjì ìgbọ̀nwọ́ lápá ibi ìhà ìlà-oòrùn, ẹgbẹ̀rún méjì ẹsẹ̀ bàtà ní ìhà gúúsù, ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti ẹgbẹ̀rún méjì ní ìhà àríwá, kí ìlú náà sì wà ní àárín. Wọn yóò ní agbègbè yìí gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ pápá oko tútù fún ìlú náà.
6 Un to pilsētu starpā, ko jūs dosiet Levitiem, lai ir sešas glābšanas pilsētas, kas jums jādod, ka tas nokāvējs uz turieni bēg, un pie tām klāt viņiem būs dot vēl četrdesmit divas pilsētas.
“Mẹ́fà lára ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi yóò jẹ́ ìlú ààbò, tí ẹni tí ó bá pa ènìyàn yóò sá sí. Ní àfikún, ẹ fún wọn ní méjìlélógójì ìlú sí i.
7 Visas pilsētas, ko jūs dosiet Levitiem, lai ir četrdesmit astoņas pilsētas līdz ar viņu apgabaliem.
Ní gbogbo rẹ̀, kí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi ní méjìdínláàádọ́ta ìlú lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
8 Un no tām pilsētām, ko jūs dosiet no Israēla bērnu daļas, jums būs ņemt daudz no tiem, kam ir daudz, un maz no tiem, kam ir maz; ikvienam no savām pilsētām būs dot Levitiem pēc savas daļas, ko tas mantojis.
Ìlú tí ẹ fún àwọn ọmọ Lefi láti ara ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli jogún, olúkúlùkù kí ó fi nínú ìlú rẹ̀ fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìní rẹ̀ tí ó ní. Gba púpọ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní púpọ̀ àti díẹ̀ lọ́wọ́ ẹ̀yà tí ó ní díẹ̀.”
9 Un Tas Kungs runāja uz Mozu un sacīja:
Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mose pé,
10 Runā uz Israēla bērniem un saki tiem: kad jūs iesiet pāri pār Jardāni uz Kanaāna zemi,
“Sọ̀rọ̀ sí àwọn ọmọ Israẹli, kí o sì sọ fún wọn: ‘Nígbà tí ẹ bá rékọjá odò Jordani sí Kenaani,
11 Tad jums būs iecelt pilsētas, kas jums lai ir par glābšanas pilsētām, ka uz turieni tas nokāvējs var bēgt, kas kādu cilvēku netīši nokāvis.
yan àwọn ìlú kan láti jẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìlú ààbò fún yín, kí apani tó pa ènìyàn ní àìmọ̀ máa sálọ síbẹ̀.
12 Un šīs pilsētas lai jums ir par glābšanu no atriebēja, ka tam nokāvējam nav jāmirst, tiekams viņš nav stāvējis draudzes priekšā iztiesāšanas dēļ.
Wọn yóò jẹ́ ibi ìsásí kúrò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san, kí ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn má ba à kú kí ó tó dúró níwájú àwọn ìjọ àwọn ènìyàn ní ìdájọ́.
13 Un tās pilsētas, ko jūs dosiet, lai jums ir sešas glābšanas pilsētas.
Mẹ́fà nínú ìlú tí ẹ ó fi fún wọn yóò jẹ́ ìlú ààbò fún yín.
14 Trīs no šīm pilsētām noliekat viņpus Jardānes un trīs no tām pilsētām noliekat Kanaāna zemē, - glābšanas pilsētas lai tās ir.
Yan ìlú mẹ́ta ní ìhà ti Jordani, kí ẹ sì yan ìlú mẹ́ta ní ìhà Kenaani tí yóò máa jẹ́ ìlú ìsásí.
15 Šīs pilsētas lai Israēla bērniem ir par glābšanu, arī svešiniekam un piedzīvotājam jūsu starpā, ka uz turieni var bēgt ikviens, kas kādu cilvēku netīši nokāvis.
Ìlú mẹ́fà yìí yóò jẹ́ ìlú ìsásí fún àwọn ọmọ Israẹli, fún àjèjì àti ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbé láàrín wọn, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn ní àìmọ̀ sálọ síbẹ̀.
16 Bet ja viņš to ar dzelzs ieroci sitis, ka mirst, tas ir slepkava, šim slepkavam būs tapt nokautam.
“‘Bí ọkùnrin kan bá fi ohun èlò irin lu ènìyàn tí ó kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa, apànìyàn náà.
17 Vai ja viņš to sit ar akmeni rokā, ar ko var nokaut, tā ka mirst, tas ir slepkava, tam būs tapt nokautam.
Tàbí tí ènìyàn bá mú òkúta tí ó lè pa ènìyàn lọ́wọ́ tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni, pípa ni a ó pa apànìyàn náà.
18 Vai ja viņš to sit ar koka gabalu, ar ko var nokaut, tā ka mirst, tas ir slepkava, tam būs tapt nokautam.
Tàbí tí ènìyàn bá mú ohun èlò igi ní ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì lẹ̀ ẹ́ pa ènìyàn, tí ó sì fi lu ènìyàn, tí ó sì kú, apànìyàn ni; pípa ní a ó pa apànìyàn náà.
19 Asiņu atriebējs lai nonāvē to slepkavu; kad tas viņu sastop, lai viņu nokauj.
Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà; tí ó bá bá a, yóò pa á.
20 Un ja viņš nīdēdams to grūdis, vai tīši uz to ko sviedis, ka tas mirst,
Tí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń yan odì pẹ̀lú ìríra tí ẹlòmíràn tàbí ju nǹkan sí i pẹ̀lú èrò, tí ó sì kú.
21 Vai ja viņš nīdēdams to sitis ar savu roku, ka tas mirst, tad tam būs tapt nokautam; jo viņš ir slepkava; asiņu atriebējs lai to nokauj, kad viņu sastop.
Tàbí pẹ̀lú ìjà gbangba lù ú pẹ̀lú ìkùùkuu tí ó sì kú, pípa ni a ó pa ẹni bẹ́ẹ̀; apànìyàn ni. Olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ yóò pa apànìyàn náà tí ó bá bá a.
22 Bet ja viņš netīši bez ienaida grūdis, vai no nejauši kādu rīku uz to sviedis;
“‘Ṣùgbọ́n bí ó bá fi nǹkan gún un lójijì láìṣọ̀ta, tàbí tí ó sọ ohunkóhun lù ú láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ ṣe
23 Vai akmenim, caur ko tas var mirt, netīši tam licis uzkrist, tā ka tas mirst, un nav bijis viņa ienaidnieks, nedz meklējis viņa nelaimi,
tàbí, láìri, ju òkúta sí tí ó lè pa á, tí ó sì kú, nígbà tí kì í ṣe ọ̀tá rẹ̀, láti ṣe é léṣe.
24 Tad lai draudze tiesā starp nokāvēju un asiņu atriebēju pēc šiem likumiem.
Àwọn àpéjọ gbọdọ̀ dájọ́ láàrín rẹ̀ àti olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ìlànà.
25 Un draudzei nokāvēju būs izglābt no asiņu atriebēja rokas, un draudzei būs to novest viņa glābšanas pilsētā, kurp viņš bija bēdzis, un tur tam būs palikt, kamēr augstais priesteris miris, kas ir svaidīts ar svēto eļļu.
Àpéjọ gbọdọ̀ dá ààbò bo ẹni tí a fi ẹ̀sùn ìpànìyàn kàn, kí a sì rán an padà lọ sí ìlú ìsásí tí ó ti wá. Ó gbọdọ̀ dúró níbẹ̀ títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú, ẹni tí a fi àmì òróró yàn.
26 Bet ja nokāvējs iziedams izies no savas glābšanas pilsētas robežām, kurp bija nobēdzis.
“‘Ṣùgbọ́n ti ẹni tí a fi sùn kan bá jáde kọjá ààlà ìlú ìsásí tí ó sá sí.
27 Un asiņu atriebējs ārpus viņa glābšanas pilsētas robežām to atradīs un nokaus, tad tas nav noziedzīgs pie viņa asinīm.
Tí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ sì ri ní ìta ìlú náà, olùgbẹ̀san lè pa ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn láìjẹ̀bi ẹ̀sùn ìpànìyàn.
28 Jo tam bija jāpaliek savā glābšanas pilsētā, kamēr augstais priesteris nomirs; bet pēc tā augstā priestera miršanas nokāvējs lai griežas atpakaļ uz savu zemes daļu.
Ẹni tí a fi ẹ̀sùn kàn gbọdọ̀ dúró nínú ìlú ìsásí títí di ìgbà tí olórí àlùfáà bá kú; lẹ́yìn ikú olórí àlùfáà, ni ó tó lè padà sí ibi tí dúkìá rẹ̀ wà.
29 Un tas lai jums ir par tiesas likumu pie jūsu pēcnākamiem visās jūsu māju vietās.
“‘Wọ̀nyí ni ó jẹ́ ìlànà ìdájọ́ fún yín ní ìran yín tó ń bọ̀, ní ibikíbi tí ẹ bá ń gbé.
30 Ja kas kādu cilvēku nosit, tad uz liecinieku vārdu slepkavam būs tapt nokautam, bet vienam lieciniekam vien nebūs liecību dot pret kādu cilvēku, ka tam būtu jāmirst.
“‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá pa ènìyàn gbọdọ̀ kú gẹ́gẹ́ bí apànìyàn lórí ìjẹ́rìí àwọn ènìyàn. Ṣùgbọ́n ẹlẹ́rìí kan ṣoṣo. Kì yóò jẹ́rìí sí ẹnìkan láti pa.
31 Tev arī nebūs ņemt atpirkšanas maksu par slepkavu, kas nāvi pelnījis, jo tam būs tapt nokautam.
“‘Má ṣe gba ohun ìràpadà fún ẹ̀mí apànìyàn, tí ó jẹ̀bi kí ó kú. Ṣùgbọ́n pípa ni kí a pa á.
32 Jums arī nebūs ņemt atpirkšanas maksu par to, kas savā glābšanas pilsētā ir nobēdzis, ka tas atkal nāktu dzīvot savā zemes daļā, pirms augstais priesteris miris.
“‘Má ṣe gba ìràsílẹ̀ fún ẹnikẹ́ni tí ó bá lọ sí ìlú ìsásí, pe kí ó padà máa gbé ní ilẹ̀ tirẹ̀ kí ó tó di ìgbà ikú olórí àlùfáà.
33 Un jums nebūs sagānīt to zemi, kur jūs esat; jo tās tādas asinis sagāna to zemi, un to zemi nevar salīdzināt to asiņu dēļ, kas tur izlietas, kā vien caur tā asinīm, kas tās izlējis.
“‘Má ṣe sọ ilẹ̀ tí ẹ wà di àìmọ́. Ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sọ ilẹ̀ náà di àìmọ́. Àtúnṣe kì yóò sí fún ilẹ̀ tí a ti ta ẹ̀jẹ̀ lé lórí, àyàfi ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó ta á sílẹ̀.
34 Tad nu nesagāniet to zemi, kur jūs dzīvojat, un kur Mans dzīvoklis, jo Es esmu Tas Kungs, kas dzīvo Israēla bērnu vidū.
Má ṣe sọ di àìmọ́, ilẹ̀ tí ẹ ń gbé, àti èyí tí mo ń gbé, nítorí Èmi Olúwa ń gbé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.’”

< Ceturtā Mozus 35 >