< Ceturtā Mozus 32 >
1 Un Rūbena un Gada bērniem bija ļoti daudz lopu, un tie aplūkoja Jaēzeras un Gileādas zemi, un raugi, šī vieta bija vieta priekš ganāmiem pulkiem.
Àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, tí wọ́n ní ẹran ọ̀sìn àti ohun ọ̀sìn rí wí pé ilẹ̀ Jaseri àti Gileadi dára fún ohun ọ̀sìn.
2 Tad Gada bērni un Rūbena bērni nāca un runāja uz Mozu un uz priesteri Eleazaru un uz tiem draudzes virsniekiem un sacīja:
Àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni sì wá, wọ́n wá sí ọ̀dọ̀ Mose àti Eleasari àlùfáà àti sí olórí gbogbo ìlú, wọ́n sì wí pé,
3 Atarota un Dibona un Jaēzera un Nimra un Hešbona un Eleale un Sebana un Neba un Beona,
“Atarotu, Diboni, Jaseri, Nimra, Heṣboni, Eleale, Sebamu, Nebo, àti Beoni.
4 Tā zeme, ko Tas Kungs ir sitis Israēla draudzes priekšā, tā ir zeme priekš ganāmiem pulkiem, un mums, taviem kalpiem, ir ganāmi pulki.
Ni ilẹ̀ tí Olúwa ti ṣẹ́gun níwájú ìjọ Israẹli tí ó sì dára fún ohun ọ̀sìn, ṣáwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì ní ohun ọ̀sìn.”
5 Un tie sacīja: ja mēs žēlastību esam atraduši tavās acīs, tad lai šī zeme top dota taviem kalpiem par īpašumu un neliec mums iet pāri pār Jardāni.
Wọ́n wí pé, “Tí a bá rí ojúrere rẹ, jẹ́ kí a fi ilẹ̀ yìí fún ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ìní. Má ṣe jẹ́ kí a rékọjá odò Jordani.”
6 Bet Mozus sacīja uz Gada bērniem un uz Rūbena bērniem: vai tad jūsu brāļi ies karā un jūs paliksiet še?
Mose sọ fún àwọn ọmọ Gadi àti fún ọmọ Reubeni pé, “Ṣé kí àwọn arákùnrin yín lọ sí ogun, kí ẹ̀yin kí ó sì jókòó sí bí?
7 Kāpēc jūs Israēla bērniem sirdi novēršat, nenoiet uz to zemi, ko Tas Kungs viņiem devis? -
Kí ni ó dé tí o fi mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti lọ sí ibi ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn?
8 Tā jūsu tēvi darīja, kad es tos no Kādeš Barneas sūtīju, to zemi aplūkot.
Èyí ni nǹkan tí baba yín ṣe nígbà tí mo rán wọn láti Kadeṣi-Barnea láti lọ wo ilẹ̀ náà.
9 Kad tie bija nākuši pie Eškoles upes un to zemi bija izlūkojuši, tad tie novērsa Israēla bērnu sirdi, ka tie negribēja iet uz to zemi, ko Tas Kungs viņiem gribēja dot.
Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n lọ sí àfonífojì Eṣkolu tí wọ́n rí ilẹ̀ náà, wọ́n mú ìrẹ̀wẹ̀sì bá àwọn ọmọ Israẹli láti wọ ilẹ̀ tí Olúwa ti fi fún wọn.
10 Tad Tā Kunga bardzība iedegās tai dienā un Viņš zvērēja un sacīja:
Ìbínú Olúwa sì dìde sí wọn ní ọjọ́ náà, ó sì búra, wí pé,
11 Tiem vīriem, kas no Ēģiptes zemes ir nākuši, kam divdesmit gadi un pāri, tiem nebūs redzēt to zemi, ko Es viņu tēviem Ābrahāmam, Īzakam un Jēkabam esmu zvērējis, jo tie Man nav paklausījuši;
‘Nítorí wọn kò tẹ̀lé mi tọkàntọkàn, kì í ṣe ọ̀kan nínú àwọn ọkùnrin náà tí ó jẹ́ ogún ọdún tàbí jù bẹ́ẹ̀ lọ tí ó gòkè láti Ejibiti ni yóò rí ilẹ̀ tí mo pinnu gẹ́gẹ́ bí ìbúra fún Abrahamu, fún Isaaki àti fún Jakọbu:
12 Tik vien Kālebs, Jefunna dēls, tas ķenaisietis, un Jozuas, Nuna dēls, jo tie Tam Kungam ir paklausījuši.
kò sí ẹnìkankan àyàfi Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti àti Joṣua ọmọ Nuni, nítorí wọ́n tẹ̀lé Olúwa tọkàntọkàn.’
13 Tā Tā Kunga bardzība iedegās pret Israēli un lika tiem maldīties tuksnesī četrdesmit gadus, tiekams viss tas augums izmira, kas bija ļaunu darījis priekš Tā Kunga acīm.
Ìbínú Olúwa ru sí àwọn ọmọ Israẹli ó sì mú wọn rìn ní aginjù fún ogójì ọdún, títí tí àwọn ìran tí wọ́n ṣe búburú ní ojú rẹ̀ fi lọ.
14 Un nu redzi, jūs savu tēvu vietā esat nākuši, grēcīgu ļaužu dzimums, vairodami Tā Kunga bargo dusmību pret Israēli.
“Níbí ni ẹ̀yin wà, ẹ̀yin ẹlẹ́ṣẹ̀, ẹ̀yin dìde ní ipò baba yín, ẹ sì jẹ́ kí ìbínú gbígbóná Olúwa ru sí Israẹli.
15 Jo ja jūs nogriezīsities no Viņa, tad Viņš šiem vēl liks palikt tuksnesī, un jūs nomaitāsiet visus šos ļaudis.
Tí ẹ̀yin bá yípadà ní ẹ̀yìn rẹ̀ yóò sì fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí sílẹ̀ ní aginjù, ìwọ yóò sì mú un ṣe ìparun.”
16 Tad tie pie viņa piegāja un sacīja: mēs šeit gribam laidarus taisīt priekš saviem ganāmiem pulkiem un pilsētas priekš saviem bērniem;
Nígbà náà wọ́n wá sí òkè ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, “Àwa yóò fẹ́ láti kọ́ ilé ẹran níhìn-ín yìí fún ohun ọ̀sìn wa, àti ìlú fún àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa.
17 Bet mēs paši steigšus apbruņosimies Israēla bērnu priekšā, tiekams tos būsim aizveduši viņu vietā; bet mūsu bērni lai paliek stiprās pilsētās to zemes iedzīvotāju dēļ.
Ṣùgbọ́n àwa ṣetán láti dira ogun ṣáájú àwọn ọmọ Israẹli títí tí a yóò fi mú wọn dé ọ̀dọ̀ wọn lákokò yìí, àwọn obìnrin àti ọmọ wẹ́wẹ́ wa yóò gbé inú ìlú tí a mọ odi sí fún ìdáàbòbò wọn lọ́wọ́ olùgbé ilẹ̀ náà.
18 Mēs negriezīsimies atpakaļ uz savām mājām, tiekams Israēla bērni nebūs dabūjuši ikviens savu daļu.
A kì yóò padà sí ilẹ̀ wa láìṣe pé gbogbo àwọn ọmọ Israẹli ti gba ogún wọn.
19 Jo mēs neņemsim līdz ar viņiem savu daļu viņā Jardānes pusē, vai tālāki, bet mūsu daļa mums nāksies šai Jardānes pusē pret rītiem.
A kì yóò gba ogún kankan pẹ̀lú wọn ní òdìkejì Jordani, nítorí ogún ti wa, ti wá sí ọ̀dọ̀ wa ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani.”
20 Tad Mozus uz tiem sacīja: ja jūs šo lietu tā gribat darīt, ka jūs apbruņojaties Tā Kunga priekšā uz karu,
Nígbà náà ni Mose sọ fún wọn pé, “Tí ẹ̀yin yóò bá pa ara yín lára, níwájú Olúwa fún ogún.
21 Un ikviens no jums, kam bruņas, iesiet pār Jardāni Tā Kunga priekšā, kamēr Viņš Savus ienaidniekus Savā priekšā izdzīs, un tā zeme priekš Tā Kunga būs uzvarēta,
Bí gbogbo yín yóò bá lọ sí Jordani ní ìhámọ́ra níwájú Olúwa, títí yóò fi lé àwọn ọ̀tá rẹ̀ kúrò níwájú rẹ̀.
22 Tad jūs pēc tam varat iet atpakaļ un būsiet nenoziedzīgi Tā Kunga un Israēla priekšā, un šī zeme jums būs par daļu Tā Kunga priekšā.
Tí a ó sì fi ṣe ilẹ̀ náà níwájú Olúwa; ẹ̀yin lè padà tí yóò sì di òmìnira lọ́wọ́ ìdè níwájú Olúwa àti Israẹli. Ilẹ̀ yìí yóò sì jẹ́ tiyín níwájú Olúwa.
23 Bet ja jūs tā nedarīsiet, redzi, tad jūs pret To Kungu grēkosiet un jūs samanīsiet savus grēkus, kad tie jūs atradīs.
“Ṣùgbọ́n tí ẹ̀yin bá kọ̀ láti ṣe èyí, ẹ̀yin yóò máa dẹ́ṣẹ̀ sí Olúwa; kí ẹ̀yin kí ó sì mọ̀ dájú pé ẹ̀ṣẹ̀ yín yóò fi yín hàn.
24 Uztaisat sev pilsētas priekš saviem bērniem un laidarus priekš saviem sīkiem lopiem un dariet pēc tā vārda, kas no jūsu mutes izgājis.
Ẹ kọ́ ilé fún àwọn obìnrin yín àti ọmọ wẹ́wẹ́ yín, àti ilé fún agbo ẹran yín, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin kí ó ṣe ohun tí ẹ ti pinnu.”
25 Tad Gada bērni un Rūbena bērni runāja uz Mozu un sacīja: tavi kalpi darīs, kā mans kungs pavēl.
Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni sọ fún Mose pé, “Àwa ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti pàṣẹ.
26 Mūsu bērni, mūsu sievas, mūsu ganāmie pulki un visi mūsu lopi paliks tur Gileādas pilsētās;
Àwọn ọmọ wa àti ìyàwó wa, àwọn agbo ẹran àti ohun ọ̀sìn wa yóò dúró ní ìlú Gileadi.
27 Bet tavi kalpi, visi apbruņoti, noies karā Tā Kunga priekšā, kā mans kungs ir runājis.
Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ rẹ, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra ogun, yóò rékọjá lọ láti jà níwájú Olúwa; gẹ́gẹ́ bí olúwa wa ti sọ.”
28 Tad Mozus viņu dēļ pavēlēja priesterim Eleazaram un Jozuam, Nuna dēlam, un Israēla cilšu tēvu virsniekiem, un Mozus uz tiem sacīja:
Nígbà náà ni Mose pàṣẹ nípa wọn fún Eleasari àlùfáà àti Joṣua ọmọ Nuni àti sí gbogbo olórí ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
29 Ja Gada bērni un Rūbena bērni, ikviens kam bruņas, līdz ar jums ies karā pār Jardāni Tā Kunga priekšā, un tā zeme jūsu priekšā būs uzvarēta, tad dodat tiem Gileādas zemi par daļu.
Mose sì wí fún wọn pé, “Tí àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni, gbogbo ọkùnrin tí ó wọ ìhámọ́ra fún ogun rékọjá odò Jordani pẹ̀lú níwájú Olúwa, nígbà tí ẹ ṣẹ́gun ilẹ̀ náà níwájú yín, fún wọn ní ilẹ̀ Gileadi gẹ́gẹ́ bí ìní wọn.
30 Bet ja tie ar jums nenoies apbruņoti, tad tiem savu daļu būs dabūt jūsu starpā Kanaāna zemē.
Ṣùgbọ́n tí wọn kò bá fẹ́ bá yín rékọjá pẹ̀lú ìhámọ́ra, wọn gbọdọ̀ gba ìní wọn pẹ̀lú yín ní Kenaani.”
31 Tad Gada bērni un Rūbena bērni atbildēja un sacīja: ko Tas Kungs uz taviem kalpiem runājis, tā mēs darīsim.
Àwọn ọmọ Gadi àti ọmọ Reubeni dáhùn pé, “Ìránṣẹ́ rẹ yóò ṣe ohun tí Olúwa ti sọ.
32 Mēs aiziesim apbruņoti Tā Kunga priekšā uz Kanaāna zemi un savu iemantojamo īpašumu turēsim šai Jardānes pusē.
A máa rékọjá níwájú Olúwa lọ sí Kenaani pẹ̀lú ìhámọ́ra, ṣùgbọ́n ẹrù tí a jogún yóò wà ní ẹ̀bá Jordani.”
33 Tad Mozus viņiem deva, Gada bērniem un Rūbena bērniem un Manasus, Jāzepa dēla, pusciltij Sihona, Āmoriešu ķēniņa, valsti un Oga, Basanas ķēniņa, valsti, to zemi ar tām pilsētām viņu robežās, tās zemes pilsētas visapkārt.
Nígbà náà Mose fún àwọn ọmọ Gadi àti àwọn ọmọ Reubeni àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ọmọ Josẹfu ní ilẹ̀ ọba Sihoni ọba àwọn ọmọ Amori àti ilẹ̀ ọba Ogu ọba Baṣani ní gbogbo ilẹ̀ náà pẹ̀lú ìlú rẹ̀ àti agbègbè tí ó yí i ka.
34 Un Gada bērni uztaisīja Dibonu un Atarotu un Arveru
Àwọn ará Gadi wọ́n kọ́ Diboni, Atarotu, Aroeri;
35 Un Atarot-Zovanu un Jaēzeru, Jogabeū
pẹ̀lú Atrotu Ṣofani, Jaseri, àti Jogbeha,
36 Un Bet-Nimru un Betaranu, stipras pilsētas un sīku lopu laidarus.
pẹ̀lú Beti-Nimra, àti Beti-Harani ìlú olódi, àti agbo fún àgùntàn.
37 Un Rūbena bērni uztaisīja Hešbonu un Eleali un Ķīriataīmu
Àwọn ọmọ Reubeni sì kọ́ Heṣboni, Eleale, Kiriataimu,
38 Un Nebu un Baāl-Meonu ar citiem vārdiem un Sibmahu, un tie nosauca tās pilsētas, ko tie uztaisīja, ar citiem vārdiem.
pẹ̀lú Nebo pẹ̀lú Baali-Meoni (wọ́n pàrọ̀ orúkọ wọn) àti Sibma. Wọ́n sì sọ ìlú tí wọ́n tún kọ́ ní orúkọ mìíràn.
39 Un Mahira, Manasus dēla bērni, gāja uz Gileādu un to uzņēma un izdzina tos Amoriešus, kas tur bija.
Àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase lọ sí Gileadi, wọ́n sì lé àwọn ọmọ Amori tí ó wà níbẹ̀.
40 Tā Mozus Gileādu deva Mahiram, Manasus dēlam, un viņš tur dzīvoja.
Mose sì fi àwọn ọmọ Gileadi fún àwọn ọmọ Makiri àwọn ìran Manase, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
41 Un Jaīrs, Manasus dēls, gāja un uzņēma viņu ciemus un tos nosauca Avot-Jaīru.
Jairi, ọmọ Manase gba ibùjókòó wọn, ó sì pè wọ́n ní Haffotu Jairi.
42 Un Nobus gāja un uzņēma Kenatu ar viņas piederīgām vietām un to nosauca Nobu pēc sava vārda.
Noba gba Kenati àti àwọn ìtẹ̀dó rẹ̀, ó sì pè é ní Noba lẹ́yìn orúkọ ara rẹ̀.