< Ceturtā Mozus 22 >

1 Tad Israēla bērni cēlās un apmetās Moaba klajumos, viņpus Jardānes, Jērikum pretī.
Nígbà náà àwọn ọmọ Israẹli rin ìrìnàjò lọ sí pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu wọ́n sì pa ibùdó lẹ́gbẹ̀ẹ́ Jordani tí ó kọjá lọ sí Jeriko.
2 Kad nu Balaks, Cipora dēls, visu redzēja, ko Israēls bija darījis Amoriešiem,
Nísinsin yìí, Balaki ọmọ Sippori rí gbogbo ohun tí àwọn Israẹli ti ṣe sí àwọn ará Amori,
3 Tad Moabs ļoti bijās no tiem ļaudīm, jo to bija daudz, un Moabam bija bail no Israēla bērniem.
ẹ̀rù sì ba Moabu nítorí pé ọ̀pọ̀ ènìyàn wà níbẹ̀ nítòótọ́, Moabu kún fún ẹ̀rù nítorí àwọn ọmọ Israẹli.
4 Tāpēc Moabs sacīja uz Midijaniešu vecajiem: nu šī draudze visu apēdīs, kas mums visapkārt, itin kā vērsis apēd zāli virs zemes. Bet Balaks, Cipora dēls, bija tanī laikā Moabiešu ķēniņš.
Moabu sọ fún àwọn àgbàgbà Midiani pé, “Nísinsin yìí ni àwọn wọ̀nyí yóò lá gbogbo ohun tí ó yí wa ká, bí màlúù ṣe ń jẹ koríko tí ó wà nínú oko.” Bẹ́ẹ̀ ni Balaki ọmọ Sippori, tí ó jẹ́ ọba Moabu nígbà náà,
5 Un tas sūtīja vēstnešus pie Bileāma, Beora dēla, uz Petoru, kas pie tās lielupes, viņa ļaužu bērnu zemē, viņu aicināt, un sacīja: redzi, tur ir ļaudis izgājuši no Ēģiptes zemes, redzi, tie apklāj zemes virsu un ir apmetušies man pretī.
rán oníṣẹ́ pé Balaamu ọmọ Beori, tí ó wà ní Petori, ní ẹ̀bá odò Eufurate, ti ilẹ̀ àwọn ènìyàn rẹ. Balaki sọ pé, “Àwọn ènìyàn kan jáde wá láti Ejibiti; wọ́n bo gbogbo ilẹ̀ ayé wọ́n sì pa ibùdó súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi.
6 Un nu nāc jel un nolādi man šos ļaudis, - jo tie ir stiprāki nekā es, - ka es tos varētu apkaut un izdzīt no zemes; jo es zinu, ka ko tu svētī, tas ir svētīts, un ko tu nolādi, tas ir nolādēts.
Nísinsin yìí, wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú, nítorí wọ́n ní agbára jù fún mi. Nípa ṣíṣe èyí èmi ó ṣẹ́gun wọn, kí n sì lé wọn kúrò ní ilẹ̀ yìí. Nítorí tí mo mọ̀ pé ìbùkún ni fún àwọn tí ìwọ bá bùkún, ìfibú sì ni ẹni tí ìwọ bá fi bú.”
7 Tad Moabiešu vecaji un Midijaniešu vecaji gāja, un zīlēšanas alga bija viņu rokā, un tie nāca pie Bileāma un runāja uz viņu Balaka vārdus.
Àti àwọn àgbàgbà Moabu àti Midiani sì lọ pẹ̀lú owó àyẹ̀wò lọ́nà wọn, nígbà tí wọ́n dé ọ̀dọ̀ Balaamu, wọ́n sọ nǹkan tí Balaki sọ fún wọn.
8 Tad tas uz viņiem sacīja: paliekat šeit par nakti, tad es jums atsacīšu, kā Tas Kungs uz mani runās; un Moaba virsnieki palika pie Bileāma.
“Ẹ sùn níbí lálẹ́ yìí,” Balaamu sọ fún un pé, “èmi ó padà wá fún un yín ní èsì nǹkan tí Olúwa bá wí fún mi.” Nítorí tí àwọn ìjòyè Moabu dúró sọ́dọ̀ rẹ̀.
9 Un Dievs nāca pie Bileāma un sacīja: kas tie tādi ļaudis, kas pie tevis?
Ọlọ́run tọ Balaamu wá ó sì wí pé, “Ta ni àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ yìí?”
10 Tad Bileāms sacīja uz Dievu: Balaks, Cipora dēls, Moabiešu ķēniņš, pie manis sūtījis
Balaamu sọ fún Ọlọ́run pé, “Balaki ọmọ Sippori, ọba Moabu, rán iṣẹ́ yìí sí mi pé,
11 (Sacīdams): Redzi, ļaudis no Ēģiptes zemes ir izgājuši un apklāj zemes virsu, nāc nu, nolādi man tos, ka es pret tiem varētu karot un tos izdzīt.
‘Àwọn ènìyàn kan ti ilẹ̀ Ejibiti jáde wá tí wọ́n bo ojú ilẹ̀. Nísinsin yìí, wá, kí o wá fi wọ́n bú fún mi. Bóyá èmi yóò lè bá wọn jà, èmi ó sì lé wọn jáde.’”
12 Tad Dievs sacīja uz Bileāmu: tev nebūs iet ar viņiem, tev nebūs šos ļaudis nolādēt, jo tie ir svētīti.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run sọ fún Balaamu pé, “Má ṣe bá wọn lọ. Ìwọ kò gbọdọ̀ gé ègún lé àwọn ènìyàn náà lórí, nítorí a ti bùkún wọn.”
13 Tad Bileāms cēlās rītā agri un sacīja uz Balaka lielkungiem: ejat uz savu zemi, jo Tas Kungs aizliedz un neļauj Man iet ar jums.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaamu dìde ó sì sọ fún àwọn ìjòyè Balaki pé, “Ẹ padà sí orílẹ̀-èdè yín, nítorí tí Olúwa ti kọ̀ láti jẹ́ kí n tẹ̀lé yín.”
14 Tad Moaba virsnieki cēlās un nāca pie Balaka un sacīja: Bileāms ir liedzies, mums iet līdz.
Nígbà náà àwọn ìjòyè Moabu sì padà tọ Balaki lọ wọ́n sì wí pé, “Balaamu kọ̀ láti tẹ̀lé wa.”
15 Un Balaks atkal sūtīja vēl vairāk un jo cienīgus lielkungus.
Nígbà náà Balaki rán àwọn ìjòyè mìíràn tí wọ́n pọ̀ àwọn tí wọ́n sì níyì ju alákọ́kọ́ lọ.
16 Tie nāca pie Bileāma un uz to sacīja: tā saka Balaks, Cipora dēls: lūdzams, neliedzies nākt pie manis.
Wọ́n lọ sí ọ̀dọ̀ Balaamu wọ́n sì sọ pé, “Èyí ni ohun tí Balaki ọmọ Sippori sọ, má ṣe jẹ́ kí ohunkóhun kí ó dè ọ́ lọ́nà láti wá sí ọ̀dọ̀ mi,
17 Jo es tevi augsti godināšu un visu, ko tu man sacīsi, to es darīšu: tad nāc jel, nolād man šos ļaudis.
nítorí pé èmi yóò fún ọ ní ẹ̀bùn dáradára, èmi yóò sì ṣe ohunkóhun tí ìwọ bá sọ. Wá, kí o sì wá fi àwọn ènìyàn wọ̀nyí bú fún mi.”
18 Tad Bileāms atbildēja un sacīja uz Balaka kalpiem: kaut man Balaks savu namu dotu pilnu zelta un sudraba, tomēr es nevarētu pārkāpt Tā Kunga, sava Dieva, vārdu, darīt vai mazu vai lielu lietu.
Ṣùgbọ́n Balaamu dá wọn lóhùn pé, “Kódà tí Balaki bá fún mi ní ààfin rẹ̀ tí ó kún fún fàdákà àti wúrà, èmi kò ní ṣe ohunkóhun tí ó tóbi tàbí kéré tí ó kọjá òfin Olúwa Ọlọ́run mi.
19 Un nu paliekat jel arī šo nakti pie manis, tad es redzēšu, ko Tas Kungs atkal ar mani runās.
Nísinsin yìí ẹ dúró níbí di ọjọ́ kejì gẹ́gẹ́ bí àwọn tókù ti ṣe nígbà náà èmi yóò mọ ohun tí Olúwa yóò tún sọ fún mi.”
20 Tad Dievs nāca pie Bileāma naktī un uz to sacīja: ja tie vīri nākuši tevi aicināt, tad celies, ej viņiem līdz, bet tikai to tev būs darīt, ko Es uz tevi runāšu.
Ní alẹ́ ọjọ́ náà Ọlọ́run sì tọ Balaamu wá ó sì sọ wí pé, “Nígbà tí ọkùnrin yìí ti wá pè ọ́, lọ pẹ̀lú wọn, ṣùgbọ́n ẹnu nǹkan tí mo sọ fún ọ ni kí o ṣe.”
21 Tad Bileāms cēlās rītā agri un apsedloja savu ēzelieni un gāja tiem Moaba virsniekiem līdz.
Balaamu dìde ní òwúrọ̀, ó sì di ẹrù lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ òun pẹ̀lú àwọn ìjòyè Moabu.
22 Bet Dieva bardzība iedegās, tāpēc ka viņš gāja, un Tā Kunga eņģelis nostājās uz ceļa viņam par pretinieku; un viņš jāja uz savas ēzelienes, un viņa divi puiši viņam līdz.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run bínú gidigidi, angẹli Olúwa sì dúró lójú ọ̀nà láti dojú ìjà kọ ọ́. Balaamu ń gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ lọ, àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ méjì sì wà pẹ̀lú rẹ̀.
23 Un tā ēzeliene ieraudzīja Tā Kunga eņģeli uz ceļa stāvam, pliku zobenu rokā, un tā ēzeliene atkāpās no ceļa un gāja uz tīrumu; tad Bileāms sita to ēzelieni, viņu griezdams uz ceļu.
Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ náà sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà tí a fàyọ ní ọwọ́ rẹ̀, ó kọjú kúrò ní ọ̀nà lọ sínú oko. Balaamu sì lù ú pé kí ó gbé òhun padà lọ sí ojú ọ̀nà.
24 Bet Tā Kunga eņģelis nostājās ceļa šaurumā vīna dārzu starpā, kur abējās pusēs bija mūris.
Nígbà náà angẹli Olúwa dúró ní ojú ọ̀nà tóóró láàrín ọgbà àjàrà, pẹ̀lú ògiri ní ọ̀nà méjèèjì.
25 Kad nu tā ēzeliene Tā Kunga eņģeli ieraudzīja, tad tā spiedās pie mūra un piespieda Bileāma kāju pie mūra; tāpēc viņš to atkal sita.
Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó lẹ̀ mọ́ ẹ̀gbẹ́ ògiri, ó sì rún ẹsẹ̀ Balaamu mọ́ ògiri. Nígbà náà, ó tún nà án, lẹ́ẹ̀kan sí i.
26 Un Tā Kunga eņģelis gāja tālāki un nostājās kādā šaurā vietā, kur nebija kur atkāpties, ne pa labo, ne pa kreiso roku.
Nígbà náà angẹli Olúwa súnmọ́ wájú ó sì dúró níbi ọ̀nà tóóró níbi tí kò ti sí ọ̀nà láti yípadà, bóyá ní ọ̀tún tàbí òsì.
27 Kad nu tā ēzeliene Tā Kunga eņģeli ieraudzīja, tad tā pakrita uz ceļiem apakš Bileāma, un Bileāma dusmas iedegās un viņš to ēzelieni sita ar koku.
Nígbà tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí angẹli Olúwa, ó sì jókòó ní abẹ́ Balaamu, inú sì bí i tó sì nà án pẹ̀lú ọ̀pá rẹ̀.
28 Un Tas Kungs atvēra muti tai ēzelienei un tā sacīja uz Bileāmu: ko es tev esmu darījusi, ka tu man nu trīs reizes esi sitis?
Nígbà náà Olúwa ṣí ẹnu kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ó sì sọ fún Balaamu pé, “Kí ni mo ṣe fún ọ tí o fi nà mí lẹ́ẹ̀mẹ́ta?”
29 Un Bileāms sacīja uz to ēzelieni: tāpēc ka tu mani esi kaitinājusi! Kaut zobens būtu manā rokā, es tevi tagad nokautu!
Balaamu sọ fún kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ pé, “Nítorí ìwọ fi mí ṣẹ̀sín! Bí mo bá ní idà ní ọwọ́ ni èmi ìbá pa ọ́ nísinsin yìí.”
30 Tad tā ēzeliene sacīja uz Bileāmu: vai neesmu tava ēzeliene, uz kā tu esi jājis līdz šai dienai? Vai tas bijis man ieradums tev tā darīt? Viņš sacīja: nē.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sọ fún Balaamu pé, “Ṣé mi kì í ṣe kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ ni, tí o máa ń gùn ní gbogbo ìgbà, láti ìgbà pípẹ́ wá? Ǹjẹ́ mo hu irú ìwà báyìí sí ọ rí?” “Rárá,” Ó dáhùn.
31 Tad Tas Kungs Bileāmam atvēra acis, ka viņš Tā Kunga eņģeļi ieraudzīja uz ceļa stāvam, pliku zobenu rokā; tāpēc viņš klanījās un nometās uz savu vaigu.
Nígbà náà Olúwa ṣí ojú Balaamu, ó sì rí angẹli Olúwa tí ó dúró ní ojú ọ̀nà pẹ̀lú idà rẹ̀ tí ó fàyọ. Ó sì tẹ orí rẹ̀ ba.
32 Tad Tā Kunga eņģelis uz viņu sacīja: kāpēc tu savu ēzelieni nu trīs reiz sitis? Raugi, es esmu izgājis tev par pretinieku, jo tavs ceļš manā priekšā ir ļauns.
Nígbà náà angẹli Olúwa béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Kí ni ó dé tí o fi na kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ nígbà mẹ́ta yìí? Mo wá síbí láti kọ ojú ìjà sí ọ nítorí ọ̀nà rẹ kò tọ́ níwájú mi.
33 Bet tā ēzeliene mani redzējusi un nu trīs reiz no manis atkāpusies, un ja viņa nebūtu atkāpusies, tiešām es tevi būtu nokāvis un viņu pametis dzīvu.
Kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rí mi ó sì yà kúrò fún mi lẹ́ẹ̀mẹ́ta yìí. Tí ó bá jẹ́ wí pé kò yà kúrò. Èmi kì ìbá ti pa ọ́ pátápátá nísinsin yìí, ṣùgbọ́n Èmi yóò sì dá òun sí.”
34 Tad Bileāms sacīja uz Tā Kunga eņģeli: es esmu grēkojis, jo es nezināju, tevi uz ceļa man pretī stāvam, un nu, ja tev nepatīk, tad es iešu atpakaļ.
Balaamu sọ fún angẹli Olúwa pé, “Mo ti dẹ́ṣẹ̀, èmi kò mọ̀ pé o dúró níwájú ọ̀nà láti dojúkọ mí, nísinsin yìí tí inú rẹ kò bá dùn, èmi ó padà.”
35 Tad Tā Kunga eņģelis sacīja uz Bileāmu: ej tiem vīriem līdz; tomēr to vien, ko es uz tevi runāšu, to tev būs runāt. Tā Bileāms gāja Balaka lielkungiem līdz.
Angẹli Olúwa sọ fún Balaamu pé, “Lọ pẹ̀lú àwọn arákùnrin náà, ṣùgbọ́n nǹkan tí mo sọ fún ọ nìkan ni kí o sọ.” Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú àwọn ìjòyè Balaki.
36 Kad nu Balaks dzirdēja Bileāmu nākam, tad viņš tam izgāja pretī līdz tai Moabiešu pilsētai, kas ir Arnonas robežās, - pašā robežu malā.
Nígbà tí Balaki gbọ́ pé Balaamu ń bọ̀ wá, ó jáde lọ láti lọ pàdé rẹ̀ ní ìlú Moabu tí ó wà ní agbègbè Arnoni, ní ẹ̀gbẹ́ ilẹ̀ rẹ̀.
37 Un Balaks sacīja uz Bileāmu: vai es neesmu sūtīdams pie tevis sūtījis, tevi aicināt? Kāpēc tu neesi pie manis nācis? vai tad es nespēju tevi godināt?
Balaki sì sọ fún Balaamu pé, “Ǹjẹ́ èmi kò a ránṣẹ́ kánjúkánjú sí ọ? Kí ló dé tí ìwọ kò fi wá sí ọ̀dọ̀ mi? Ṣé èmi kò tó láti sọ ọ́ di ẹni ńlá?”
38 Tad Bileāms sacīja uz Balaku: redzi, es pie tevis esmu atnācis, bet vai es kautko varu runāt kā vien to vārdu, ko Dievs liks manā mutē? - To es runāšu.
Balaamu sì wí fún Balaki pé, “Kíyèsi, èmi tọ̀ ọ́ wá, èmi kò ha ní agbára kan nísinsin yìí rárá láti wí ohun kan? Mo gbọdọ̀ sọ nǹkan tí Ọlọ́run fi sí mi lẹ́nu.”
39 Un Bileāms gāja Balakam līdz un tie nonāca Kiriat Hucotā.
Nígbà náà Balaamu lọ pẹ̀lú Balaki sí Kiriati-Hosotia.
40 Un Balaks upurēja lielus un sīkus lopus un sūtīja Bileāmam un tiem lielkungiem, kas pie viņa bija.
Balaki rú ẹbọ akọ màlúù pẹ̀lú àgùntàn, ó sì fún Balaamu ní díẹ̀ pẹ̀lú àwọn ìjòyè tí ó wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀.
41 Un no rīta Balaks ņēma Bileāmu un to veda uz Baāla kalniem, un no turienes šis redzēja vienu galu no tiem ļaudīm.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì Balaki gbé Balaamu lọ sí Bamoti Baali, láti ibẹ̀ ló ti rí apá kan àwọn ènìyàn.

< Ceturtā Mozus 22 >