< Nechemijas 6 >

1 Un notikās, kad Sanbalats un Tobija un Arābs Gešems un mūsu citi ienaidnieki dzirdēja, ka mēs to mūri bijām uzcēluši un iekš tā caurums neatlikās, (jebšu es līdz šim durvis vēl nebiju iecēlis vārtos),
Nígbà tí Sanballati, Tobiah Geṣemu ará Arabia àti àwọn ọ̀tá wa tókù gbọ́ pé, mo ti tún odi náà mọ, kò sì sí àlàfo kankan tí ó ṣẹ́kù nínú rẹ̀—bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò ì tí ì ri àwọn ìlẹ̀kùn ibodè ní àkókò náà.
2 Tad Sanbalats un Gešems pie manis sūtīja un lika sacīt: nāc, saiesim kopā Onus klajuma ciemos. Bet tie domāja, man ļaunu darīt.
Sanballati àti Geṣemu rán iṣẹ́ yìí sí mi pé, “Wá jẹ́ kí a jọ pàdé pọ̀ nínú ọ̀kan lára àwọn ìletò ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Ono.” Ṣùgbọ́n wọ́n ń gbèrò láti ṣe mí ní ibi;
3 Un es sūtīju vēstnešus pie tiem un liku sacīt: man liels darbs darāms, ka nevaru nonākt; kāpēc šim darbam būs kavēties, ka es to pamestu un pie jums nonāktu?
bẹ́ẹ̀ ni mo rán oníṣẹ́ padà pẹ̀lú èsì yìí pé, “Èmi ń ṣe iṣẹ́ ńlá kan, èmi kò le è sọ̀kalẹ̀ wá. Èéṣe tí iṣẹ́ náà yóò fi dúró, nígbà tí mo bá fi í sílẹ̀ tí mo sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ yín wá?”
4 Un tie gan četras reizes pie manis sūtīja ar šo pašu valodu, un es sūtīju pie tiem atpakaļ ar to pašu valodu.
Wọ́n rán iṣẹ́ náà sí mi nígbà mẹ́rin ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀, mo sì fún wọn ní èsì bákan náà fún ìgbà kọ̀ọ̀kan.
5 Tad Sanbalats piektā reizē pie manis sūtīja savu puisi tāpat ar neaiztaisītu grāmatu viņa rokā. Iekš tās bija rakstīts:
Ní ìgbà karùn-ún, Sanballati rán ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀ sí mi pẹ̀lú irú iṣẹ́ kan náà, lẹ́tà kan tí a kò fi sínú àpò ìwé wà ní ọwọ́ rẹ̀
6 Ļaudis dzird, un Gešems saka, ka tu ar tiem Jūdiem domā atkāpties un tāpēc to mūri uztaisi, un ka tu viņiem gribi būt par ķēniņu, - tā runā, -
tí a kọ sínú un rẹ̀ pé, “A ròyìn rẹ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, Geṣemu sì sọ pé, òtítọ́ ni, pé ìwọ àti àwọn Júù ń gbèrò láti ṣọ̀tẹ̀, nítorí náà ni ẹ ṣe ń mọ odi. Síwájú sí i, gẹ́gẹ́ bí ìròyìn yìí, ìwọ sì ń gbèrò láti di ọba wọn
7 Ka tu arī praviešus iecēlis, kas lai izsauc par tevi Jeruzālemē un saka: viņš ir ķēniņš iekš Jūda. Un nu ķēniņš tādu valodu dzirdēs; nāc tad jel un lai mēs kopā sarunājamies.
àti pé ó ti yan àwọn wòlíì kí wọn lè kéde nípa rẹ̀ ní Jerusalẹmu: ‘Ọba kan wà ní Juda!’ Nísinsin yìí, ìròyìn yìí yóò padà sí ọ̀dọ̀ ọba; nítorí náà wá, jẹ́ kí a bá ara wa sọ̀rọ̀.”
8 Bet es sūtīju pie viņa sacīdams: no tā, ko tu runā, nekas nav noticis; no savas sirds tu to esi izdomājis.
Mo dá èsì yìí padà sí i pé, “Kò sí ohun kan nínú irú ohun tí ìwọ sọ tí ó ṣẹlẹ̀; ìwọ kàn rò wọ́n ní orí ara rẹ ni.”
9 Jo visi tie mūs baidīja un sacīja: viņu rokām būs no tā darba atstāties, ka tas netop darīts. Un nu, stiprini Tu, (ak Dievs), manas rokas.
Gbogbo wọn múra láti dẹ́rùbà wá, wọ́n ń rò ó wí pé, “Ọwọ́ wọn kò ní ran iṣẹ́ náà, àti wí pé wọn kò ní parí rẹ̀.” Ṣùgbọ́n mo gbàdúrà pé, “Nísinsin yìí Ọlọ́run fi agbára fún ọwọ́ mi.”
10 Kad es nu nācu Šemajas namā, - tas bija Delajas, Mehetabeēļa dēla, dēls, (bet viņš bija ieslēdzies), tad viņš sacīja: sanāksim Dieva namā, pašā Dieva nama vidū, un lai mēs Dieva nama durvis aizslēdzam, jo tie nāks, tevi nokaut, pašā naktī tie nāks, tevi nokaut.
Ní ọjọ́ kan mo lọ sí ilé Ṣemaiah ọmọ Delaiah, ọmọ Mehetabeeli, ẹni tí a há mọ́ sínú ilé rẹ̀. Ó wí pé, “Jẹ́ kí a pàdé ní ilé Ọlọ́run nínú tẹmpili, kí o sì jẹ́ kí a pa àwọn ìlẹ̀kùn tẹmpili dé, nítorí àwọn ènìyàn ń bọ̀ láti pa ọ́, ní òru ni wọn yóò wá láti pa ọ́.”
11 Bet es sacīju: vai tādam vīram, kā es, būs bēgt? Vai tādam, kā es, Dieva namā būs iet, lai paliktu dzīvs? Es neiešu.
Ṣùgbọ́n mo wí pé, “Ǹjẹ́ ó yẹ kí irú ènìyàn bí èmi sálọ? Tàbí kí ènìyàn bí èmi sálọ sínú tẹmpili láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là? Èmi kò ní lọ!”
12 Jo redzi, es manīju, ka Dievs viņu nebija sūtījis. Bet viņš runāja šo sludināšanu uz mani, tāpēc ka Tobija un Sanebalats viņu bija derējuši.
Èmi wòye pé Ọlọ́run kò rán an, ṣùgbọ́n ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí mi nítorí Tobiah àti Sanballati ti bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀.
13 Viņš bija derēts, lai es izbīstos un tā daru un apgrēkojos, ka tie kādu ļaunu slavu atrastu, ar ko mani varētu nievāt.
Wọ́n bẹ̀ ẹ́ ní ọ̀wẹ̀ láti dẹ́rùbà mí nítorí kí èmi lè dẹ́ṣẹ̀ nípa ṣíṣe èyí, kí wọn lè bà mí lórúkọ jẹ́, kí n sì di ẹni ẹ̀gàn.
14 Piemini, mans Dievs, Tobiju un Sanbalatu pēc šiem darbiem un arī pravieti Noadiju un tos citus praviešus, kas ir meklējuši, mani darīt bailīgu!
A! Ọlọ́run mi, rántí Tobiah àti Sanballati, nítorí ohun tí wọ́n ti ṣe; kí o sì tún rántí Noadiah wòlíì obìnrin àti àwọn wòlíì tókù tí wọ́n ń gbèrò láti dẹ́rùbà mí.
15 Tad nu tas mūris tapa pabeigts Elula mēneša divdesmit piektā dienā, piecdesmit divās dienās.
Bẹ́ẹ̀ ni a parí odi náà ní ọjọ́ kẹẹdọ́gbọ̀n oṣù Eluli, láàrín ọjọ́ méjìléláàádọ́ta.
16 Un kad visi mūsu ienaidnieki to dzirdēja, tad visi apkārtējie pagāni bijās un viņu drošība zuda, jo tie samanīja, ka šis darbs ar mūsu Dieva palīgu bija padarīts.
Nígbà tí àwọn ọ̀tá wa gbọ́ èyí, gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè tí ó yí wa ká bẹ̀rù jìnnìjìnnì sì mú wọn, nítorí wọ́n wòye pé iṣẹ́ yìí di ṣíṣe pẹ̀lú ìrànlọ́wọ́ Ọlọ́run wa.
17 Tanīs dienās arī daudz virsnieki no Jūda rakstīja grāmatas; tās tapa sūtītas pie Tobijas, un Tobija sūtīja atkal pie tiem.
Bákan náà, ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ọlọ́lá Juda ń kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ lẹ́tà ránṣẹ́ sí Tobiah, èsì láti ọ̀dọ̀ Tobiah sì ń wá sí ọ̀dọ̀ wọn.
18 Jo daudzi iekš Jūda viņam bija zvērējuši, tāpēc ka tas bija Šehanijas, Arahus dēla, znots, un viņa dēls Jehohanans bija apņēmis Mešulama, Bereķijas dēla, meitu.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Juda ti mulẹ̀ pẹ̀lú rẹ̀, nítorí tí ó jẹ́ àna Ṣekaniah ọmọ Arah (Sanballati fẹ́ ọmọ Ṣekaniah), ọmọ rẹ̀ Jehohanani sì tún fẹ́ ọmọbìnrin Meṣullamu ọmọ Berekiah.
19 Tie runāja arīdzan labu par viņu manā priekšā, un manus vārdus tie nonesa pie viņa; tad Tobija sūtīja grāmatas, ka tas mani biedinātu.
Síwájú sí í, wọ́n túbọ̀ ń ròyìn iṣẹ́ rere rẹ̀ fún mi, wọ́n sì ń sọ ohun tí mo sọ fún un. Tobiah sì ń kọ àwọn lẹ́tà ránṣẹ́ sí mi láti dẹ́rùbà mí.

< Nechemijas 6 >