< Nechemijas 2 >

1 Un notika Nīsana mēnesī, ķēniņa Artakserksus divdesmitā gadā, kad vīns bija viņa priekšā, tad es pacēlu to vīnu un devu ķēniņam; un es (citkārt) nebiju noskumis bijis viņa priekšā.
Ní oṣù Nisani, ní ogún ọdún ìjọba ọba Artasasta, nígbà tí a gbé wáìnì wá fún un, mo gbé wáìnì náà, mo fi fún ọba, ìbànújẹ́ kò hàn ní ojú mi rí ní iwájú rẹ̀.
2 Un ķēniņš uz mani sacīja: kādēļ tavs vaigs izskatās noskumis? Vai tu esi slims? Tā gan nav, bet tava sirds ir noskumusi. Tad es bijos ļoti.
Nítorí náà ni ọba béèrè lọ́wọ́ mi pé, “Èéṣe tí ojú rẹ fi fàro nígbà tí kò rẹ̀ ọ́? Èyí kì í ṣe ohun mìíràn bí kò ṣe ìbànújẹ́ ọkàn.” Ẹ̀rù bà mí gidigidi,
3 Un es sacīju uz ķēniņu: lai ķēniņš dzīvo mūžīgi! Kā lai mans vaigs nav noskumis? Jo tā pilsēta, kur manu tēvu kapi, ir postā, un viņas vārti no uguns aprīti.
ṣùgbọ́n mo wí fún ọba pé, “Kí ọba kí ó pẹ́! Èéṣe tí ojú mi ko ṣe ní fàro, nígbà tí ìlú tí a sin àwọn baba mi sí wà ní ahoro, tí a sì ti fi iná run àwọn ibodè rẹ̀?”
4 Un ķēniņš uz mani sacīja: ko tad tu nu gribi? Tad es pielūdzu to debesu Dievu
Ọba wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Nígbà náà, ni mo gbàdúrà sí Ọlọ́run ọ̀run,
5 Un sacīju uz ķēniņu: ja tas ķēniņam patīk un ja tavs kalps ir patīkams tavā priekšā, tad sūti mani uz Jūdu, uz to pilsētu, kur manu tēvu kapi, ka es to uzceļu.
mo sì dá ọba lóhùn pé, “Ti ó bá wu ọba, tí ìránṣẹ́ rẹ bá sì rí ojúrere ní ojú rẹ, jẹ́ kí ó rán mi lọ sí ìlú náà ní Juda níbi tí a sin àwọn baba mi nítorí kí èmi lè tún un kọ́.”
6 Tad ķēniņš uz mani sacīja, ķēniņienei viņam blakām sēžot: cik ilgi tad tu paliksi ceļā un kad tu nāksi atpakaļ? Un ķēniņam patika, mani sūtīt, kad es viņam laiku biju nolicis.
Nígbà náà ni ọba, pẹ̀lú ìyàwó rẹ̀ tí ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ rẹ̀, bi mí pé, “Báwo ni ìrìnàjò náà yóò ṣe pẹ́ ọ tó, nígbà wo sì ni ìwọ yóò padà?” Ó dùn mọ́ ọba láti rán mi lọ, bẹ́ẹ̀ ni mo dá àkókò kan.
7 Un es sacīju uz ķēniņu: Ja tas ķēniņam patīk, tad lai man grāmatas dod pie zemes valdītājiem viņpus upes, lai tie mani pārvada, tiekams nākšu uz Jūdu,
Mo sì tún wí fún ọba pé, “Bí ó bá wu ọba, kí ó fún mi ní lẹ́tà sí àwọn baálẹ̀ òkè odò Eufurate kí wọ́n le mú mi kọjá títí èmi yóò fi dé Juda láìléwu.
8 Un arī grāmatu pie Asafa, ķēniņa mežu uzrauga, lai tas man dod baļķus priekš Dieva nama pils vārtu nostiprināšanas un priekš pilsētas mūra un priekš tā nama, kur es ieiešu. Un ķēniņš man deva, tāpēc ka Dieva labā roka bija pār mani.
Kí èmi sì gba lẹ́tà kan lọ́wọ́ fún Asafu, olùṣọ́ igbó ọba, nítorí kí ó lè fún mi ní igi láti fi ṣe àtẹ́rígbà fún ibodè ilé ìṣọ́ tẹmpili àti fún odi ìlú náà àti fún ilé tí èmi yóò gbé?” Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi wà lórí mi, ọba fi ìbéèrè mi fún mi.
9 Tad es nācu pie tiem zemes valdītājiem viņpus upes un tiem devu ķēniņa grāmatas. Un ķēniņš man bija sūtījis līdz virsniekus un jātniekus.
Bẹ́ẹ̀ ni mo lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, mo sì fún wọn ní àwọn lẹ́tà ọba. Ọba sì ti rán àwọn ológun àti àwọn ẹlẹ́ṣin ogun pẹ̀lú mi.
10 Kad nu Sanebalats, tas Horonietis, un Tobija, tas kalps, tas Amonietis, to dzirdēja, tad tas viņiem nepavisam nepatika, ka viens cilvēks bija nācis, ko laba meklēt priekš Israēla bērniem.
Nígbà tí Sanballati ará Horoni àti Tobiah ará a Ammoni tí wọ́n jẹ́ ìjòyè gbọ́ nípa èyí pé, ẹnìkan wá láti mú ìtẹ̀síwájú bá àlàáfíà àwọn ará Israẹli inú bí wọn gidigidi.
11 Un es nācu uz Jeruzālemi un tur biju trīs dienas.
Mo sì lọ sí Jerusalẹmu, lẹ́yìn ìgbà tí mo dúró níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta.
12 Tad es cēlos naktī, es un kādi vīri līdz ar mani, un nestāstīju nevienam, ko Dievs manā sirdī bija devis pie Jeruzālemes darīt, un nekāda lopa man nebija līdz, bez tā, uz kā es jāju.
Mo jáde ní òru pẹ̀lú àwọn ọkùnrin díẹ̀. Èmi kò sì sọ fún ẹnìkankan ohun tí Ọlọ́run mi ti fi sí ọkàn mi láti ṣe fún Jerusalẹmu. Kò sí ẹranko kankan pẹ̀lú mi, bí kò ṣe ọ̀kan ṣoṣo tí mo gùn.
13 Un es izjāju naktī caur Ielejas vārtiem pret Pūķa aku līdz Mēslu vārtiem, un es aplūkoju Jeruzālemes mūrus, kas bija nolauzīti un viņas vārtus, kas no uguns bija aprīti.
Ní òru, mo jáde lọ sí àfonífojì ibodè sí ìhà kànga Jakali àti sí ẹnu ibodè Ààtàn àti ẹnu ibodè rẹ̀ èyí tí ó ti wó odi Jerusalẹmu tí ó lulẹ̀, tí a ti fi iná sun.
14 Un es aizjāju uz Akas vārtiem un Ķēniņa dīķi, un tas lops, uz kā es jāju, tur nevarēja tikt cauri.
Nígbà náà ni mo lọ sí ẹnu ibodè orísun àti sí adágún omi ọba, ṣùgbọ́n kò sí ààyè tó fún ẹranko mi láti kọjá;
15 Tad es devos naktī augšām gar upi un aplūkoju to mūri un griezos atpakaļ un iejāju caur Ielejas vārtiem; tā es griezos atpakaļ.
bẹ́ẹ̀ ni mo gòkè àfonífojì ní òru, mo ń wo odi. Ní ìparí, mo padà sẹ́yìn, mo sì tún wọlé láti ibodè àfonífojì.
16 Bet tie valdnieki nezināja, kurp es biju gājis un ko es darīju; jo līdz šim es vēl neko nebiju zināmu darījis ne Jūdiem, ne priesteriem, ne tiem cienīgiem, ne tiem priekšniekiem, ne tiem citiem, kas to darbu darīja.
Àwọn olórí kò mọ ibi tí mo lọ tàbí mọ ohun tí mo ń ṣe, nítorí èmi kò tí ì sọ fún àwọn ará Júù tàbí àwọn àlùfáà tàbí àwọn ọlọ́lá tàbí àwọn ìjòyè tàbí ẹnikẹ́ni mìíràn tí yóò máa ṣe iṣẹ́ náà.
17 Tad es uz tiem sacīju: jūs redzat to nelaimi, kurā mēs esam, ka Jeruzāleme ir postā un viņas vārti ar uguni sadedzināti, - nāciet, uzcelsim Jeruzālemes mūrus, ka vairs neesam par apsmieklu.
Nígbà náà ni mo sọ fún wọn pé, “Ṣé ẹ rí wàhálà tí a ni: Jerusalẹmu wà nínú ìparun, ibodè rẹ̀ ni a sì ti fi iná jó. Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tún odi Jerusalẹmu mọ, àwa kò sì ní jẹ́ ẹni ẹ̀gàn mọ́”.
18 Un es tiem stāstīju sava Dieva roku, kas bija laba bijusi pār mani, un arī ķēniņa vārdus, ko viņš uz mani bija sacījis. Tad tie sacīja: celsimies un būvēsim. Un tie stiprināja savas rokas uz labu.
Èmi sì tún sọ fún wọn nípa bí ọwọ́ àánú Ọlọ́run mi ṣe wà lára mi àti ohun tí ọba ti sọ fún mi. Wọ́n dáhùn wí pé, “Ẹ jẹ́ kí a bẹ̀rẹ̀ àtúnmọ rẹ̀.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ rere yìí.
19 Kad nu Sanebalats, tas Horonietis un Tobija, tas kalps, tas Amonietis, un Gešems, tas Arābs, to dzirdēja, tad tie mūs apsmēja un mūs nicināja un sacīja: kas tas tāds darbs, ko jūs darāt? Vai jūs gribat dumpi celt pret ķēniņu?
Ṣùgbọ́n nígbà tí Sanballati ará a Horoni, Tobiah ara olóyè Ammoni àti Geṣemu ará a Arabia gbọ́ nípa rẹ̀, wọ́n fi wá ṣe ẹlẹ́yà, wọ́n sì fi wá ṣe ẹ̀sín. Wọ́n béèrè pé, “Kí ni èyí tí ẹ ń ṣe yìí? Ṣé ẹ ń ṣọ̀tẹ̀ sí ọba ni?”
20 Tad es tiem atbildēju un uz tiem sacīju: Dievs debesīs mums dos, ka tas mums labi izdosies, un mēs, viņa kalpi, celsimies un (to) uztaisīsim; bet jums nav nekādas daļas, nedz tiesas, nedz piemiņas Jeruzālemē.
Mo dá wọn lóhùn, mo wí fún wọn pé, “Ọlọ́run ọ̀run yóò fún wa ní àṣeyọrí. Àwa ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò bẹ̀rẹ̀ láti tún un mọ, ṣùgbọ́n fún un yin, ẹ̀yin kò ní ìpín tàbí ipa tàbí ẹ̀tọ́ ohunkóhun tí ó jẹ mọ́ ìtàn ní Jerusalẹmu.”

< Nechemijas 2 >