< Michas 7 >

1 Vai man, jo es esmu, kā kad koku augļi sakrāti, kā kad vīna ogas otru reiz nolasītas; neviena ķekara ko ēst, nevienas agrīnās vīģes, kas manai dvēselei gribās.
Ègbé ni fún mi! Nítorí èmi sì dàbí ẹni tí ń kó èso ẹ̀ẹ̀rùn jọ, ìpèsè ọgbà àjàrà; kò sì ṣí odidi àjàrà kankan láti jẹ, kò sì ṣí àkọ́so ọ̀pọ̀tọ́ nítorí tí ebi ń pa mí.
2 Dievbijīgie iznīkuši no zemes, un taisna nav cilvēku vidū; tie visnotaļ glūn uz asinīm, cits citam tie met tīklus.
Àwọn olódodo sì ti kúrò ní ilẹ̀ náà, kò sì ṣí ẹnìkan tí ó ṣẹ́kù tí ó jọ olóòtítọ́; gbogbo wọn sì ń purọ́ ní dídúró nítorí ìtàjẹ̀ sílẹ̀, olúkúlùkù wọ́n sì ń fi àwọ̀n de arákùnrin rẹ̀.
3 Abām rokām tie dara ļaunu cik spēdami; valdnieks prasa un soģis tiesā par maksu, un lielskungs izrunā savas sirds kārību, un tā tie to sapin.
Ọwọ́ wọn méjèèjì ti múra tán láti ṣe búburú; àwọn alákòóso ń béèrè fún ẹ̀bùn, àwọn onídàájọ́ sì ń gba owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ alágbára sì ń pàṣẹ ohun tí wọ́n fẹ́, gbogbo wọn sì jùmọ̀ ń dìtẹ̀.
4 Tas labākais no tiem ir kā ērkšķis, un tas taisnākais kā ērkšķu krūms. Tavu sargu diena, tava piemeklēšana nāk - tad tie būs izsamisuši.
Ẹni tí ó sàn jùlọ nínú wọn sì dàbí ẹ̀gún, ẹni tí ó jẹ́ olódodo jùlọ burú ju ẹ̀gún ọgbà lọ. Ọjọ́ àwọn olùṣọ́ rẹ̀ ti dé, àti ọjọ́ tí Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ wò. Nísinsin yìí ní àkókò ìdààmú wọn.
5 Neticat tuvākam un nepaļaujaties uz draugu; pasargi savas mutes durvis priekš tās, kas guļ tavā klēpī.
Ẹ má ṣe gba ọ̀rẹ́ kan gbọ́; ẹ má sì ṣe gbẹ́kẹ̀lé amọ̀nà kankan. Pa ìlẹ̀kùn ẹnu rẹ fún ẹni tí ó sùn ní oókan àyà rẹ.
6 Jo dēls nicina tēvu, meita ceļas pret savu māti, vedekla pret savu vīra māti, cilvēka ienaidnieki ir viņa paša mājas ļaudis.
Nítorí tí ọmọkùnrin kò bọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọbìnrin sì dìde sí ìyá rẹ̀, aya ọmọ sí ìyá ọkọ rẹ̀, ọ̀tá olúkúlùkù ni àwọn ará ilé rẹ̀.
7 Bet es cerēšu uz To Kungu, es gaidīšu uz Dievu, savu Pestītāju; mans Dievs mani paklausīs.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi ní ìwòye ní ìrètí sí Olúwa, èmi dúró de Ọlọ́run olùgbàlà mi; Ọlọ́run mi yóò sì tẹ́tí sí mi.
8 Nepriecājies, mana ienaidniece! Kad es esmu kritis, es atkal celšos; kad es sēžu tumsībā, tad Tas Kungs ir mans gaišums.
Má ṣe yọ̀ mí, ìwọ ọ̀tá mi. Bí mó bá ṣubú, èmi yóò dìde. Nígbà tí mo bá jókòó sínú òkùnkùn Olúwa yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ fún mi.
9 Es nesīšu Tā Kunga dusmību, jo es pret Viņu esmu grēkojis, tiekams Viņš iztiesās manu tiesas lietu un man nesīs tiesu. Viņš mani vedīs gaismā, es redzēšu ar prieku Viņa taisnību.
Nítorí èmi ti dẹ́ṣẹ̀ sí i, èmi yóò faradà ìbínú Olúwa, títí òun yóò ṣe gba ẹjọ́ mi rò, tí yóò sì ṣe ìdájọ́ mi. Òun yóò sì mú mi wá sínú ìmọ́lẹ̀; èmi yóò sì rí òdodo rẹ̀.
10 Un mana ienaidniece to redzēs un taps apsegta ar kaunu, - kas uz mani saka: kur ir Tas Kungs, tavs Dievs? Manas acis redzēs, ka viņu samīs kā dubļus ielā.
Nígbà náà ni ọ̀tá mi yóò rí i ìtìjú yóò sì bo ẹni tí ó wí fún mi pé, “Níbo ni Olúwa Ọlọ́run rẹ wà?” Ojú mi yóò rí ìṣubú rẹ̀; nísinsin yìí ni yóò di ìtẹ̀mọ́lẹ̀ bí ẹrẹ̀ òpópó.
11 Nāks diena, tad tavi mūri taps uzcelti, tanī dienā robeža tālu sniegsies.
Ọjọ́ tí a ó mọ odi rẹ yóò dé, ọjọ́ náà ni àṣẹ yóò jìnnà réré.
12 Tanī dienā pie tevis nāks no Asura un Ēģiptes pilsētām, un no Ēģiptes līdz lielupei, un no vienas jūras līdz otrai un no viena kalna līdz otram.
Ní ọjọ́ náà àwọn ènìyàn yóò wá sọ́dọ̀ rẹ láti Asiria àti ìlú ńlá Ejibiti àní láti Ejibiti dé Eufurate láti Òkun dé Òkun àti láti òkè ńlá dé òkè ńlá.
13 Bet zeme taps postā savu iedzīvotāju dēļ, viņu darba augļu dēļ.
Ilẹ̀ náà yóò di ahoro fún àwọn olùgbé inú rẹ̀, nítorí èso ìwà wọn.
14 Tu tad gani Savus ļaudis ar Savu zizli, Savas mantības ganāmo pulku, kas savrup dzīvo Karmeļa mežā; lai tie gana pa Basanu un Gileādu tā kā vecos laikos.
Fi ọ̀pá rẹ bọ́ àwọn ènìyàn, agbo ẹran ìní rẹ, èyí tí ó ń dágbé nínú igbó ní àárín Karmeli. Jẹ́ kí wọn jẹun ní Baṣani àti Gileadi bí ọjọ́ ìgbàanì.
15 Es tiem likšu brīnumus redzēt, kā tanīs dienās, kad jūs izgājāt no Ēģiptes zemes.
“Bí i ọjọ́ tí ó jáde kúrò ní Ejibiti wá, ni èmi yóò fi ohun ìyanu hàn án.”
16 Pagāni to redzēs un taps kaunā ar visu savu varu, tie roku liks uz muti, viņu ausis taps kurlas.
Orílẹ̀-èdè yóò rí i, ojú yóò sì tì wọ́n, nínú gbogbo agbára wọn. Wọn yóò fi ọwọ́ lé ẹnu wọn, etí wọn yóò sì di.
17 Tie laizīs pīšļus kā čūska, kā zemes tārpi tie trīcēs savās pilīs, tie bīsies To Kungu, mūsu Dievu, un baiļosies no Tevis.
Wọn yóò lá erùpẹ̀ bí ejò, wọn yóò sì jáde kúrò nínú ihò wọn bí ekòló. Wọn yóò bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, wọn yóò sì bẹ̀rù nítorí rẹ̀.
18 Kur ir tāds Dievs kā Tu? Kas piedod noziegumu un pamet pārkāpumu Savas mantības atlikušiem; Viņš nepatur Savu dusmību mūžīgi, jo Viņam ir labs prāts žēlot.
Ta ni Ọlọ́run bí rẹ̀, ẹni tí ó dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì, tí ó sì fojú fo ìrékọjá èyí tókù ìní rẹ̀? Kì í dúró nínú ìbínú rẹ̀ láéláé nítorí òun ní inú dídùn sí àánú.
19 Viņš atkal par mums apžēlosies, Viņš deldēs mūsu noziegumus. Tiešām, Tu visus viņu grēkus metīsi jūras dziļumos.
Òun yóò tún padà yọ́nú sí wa; òun yóò tẹ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa mọ́lẹ̀, yóò sì fa gbogbo àìṣedéédéé wa sínú ibú Òkun.
20 Jēkabam Tu parādīsi uzticību, Ābrahāmam žēlastību, ko mūsu tēviem esi zvērējis no vecām dienām.
Ìwọ yóò fi òtítọ́ hàn sí Jakọbu ìwọ yóò sì fi àánú hàn sí Abrahamu, bí ìwọ ṣe búra fún àwọn baba wa láti ọjọ́ ìgbàanì.

< Michas 7 >