< Lūkas Evaņg̒elijs 3 >
1 Piecpadsmitā ķeizara Tiberijus valdīšanas gadā, kad Poncius Pilatus bija zemes valdītājs Jūdejā un Hērodus valdnieks Galilejā un Filips, viņa brālis, valdnieks Iturejā un Trakonites tiesā un Lizanijus valdnieks Abilenē,
Ní ọdún kẹ́ẹ̀dógún ìjọba Tiberiu Kesari, nígbà tí Pọntiu Pilatu jẹ́ baálẹ̀ Judea, tí Herodu sì jẹ́ tetrarki Galili, Filipi arákùnrin rẹ̀ sì jẹ́ tetrarki Iturea àti ti Trakoniti, Lisania sì jẹ́ tetrarki Abilene,
2 Apakš tiem augstiem priesteriem Annasa un Kajafasa, Dieva vārds notika uz Jāni, Zaharijas dēlu, tuksnesī.
tí Annasi òun Kaiafa ń ṣe olórí àwọn àlùfáà, nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tọ Johanu ọmọ Sekariah wá ní ijù.
3 Un viņš gāja pa visu Jardānes apgabalu, sludinādams kristību uz atgriešanos no grēkiem par grēku piedošanu.
Ó sì wá sí gbogbo ilẹ̀ aginjù Jordani, ó ń wàásù ìtẹ̀bọmi ìrònúpìwàdà fún ìmúkúrò ẹ̀ṣẹ̀,
4 Itin kā rakstīts pravieša Jesajas grāmatā, kas saka: “Saucēja balss tuksnesī: “Sataisiet Tā Kunga ceļu, dariet līdzenas Viņa tekas.
bí a ti kọ ọ́ nínú ìwé ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah pé, “Ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ tún ọ̀nà Olúwa ṣe, ẹ mú ipa ọ̀nà rẹ̀ tọ́.
5 Visas ielejas lai top pildītas, un visi kalni un pakalni lai top zemoti, un kas nelīdzens, lai top līdzens, un kas celmains, par staigājamu ceļu;
Gbogbo ọ̀gbun ni a yóò kún, gbogbo òkè ńlá àti òkè kékeré ni a ó tẹ́ pẹẹrẹ. Wíwọ́ ni a ó ṣe ní títọ́, àti ọ̀nà gbọ́ngungbọ̀ngun ni a o sọ di dídán.
6 Un visa miesa redzēs Tā Kunga pestīšanu.””
Gbogbo ènìyàn ni yóò sì rí ìgbàlà Ọlọ́run.’”
7 Tāpēc viņš sacīja uz tiem ļaudīm, kas izgāja, ka no viņa tiktu kristīti: “Jūs odžu dzimums, kas jums ir rādījis izbēgt no nākamās dusmības?
Nígbà náà ni ó wí fún ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn tí ó wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin ìran paramọ́lẹ̀, ta ni ó kìlọ̀ fún un yín láti sá kúrò nínú ìbínú tí ń bọ̀?
8 Tāpēc nesiet pienākamus atgriešanās augļus; un nesākat savā prātā sacīt: “Mums ir Ābrahāms par tēvu.” Jo Es jums saku, ka Dievs no šiem akmeņiem Ābrahāmam spēj bērnus radīt.
Nítorí náà kí ẹ̀yin kí ó so èso tí ó yẹ fún ìrònúpìwàdà, kí ẹ má sì ṣe sí í wí nínú ara yín pé, ‘Àwa ní Abrahamu ní baba.’ Kí èmi kí ó wí fún un yín, Ọlọ́run lè gbé ọmọ dìde fún Abrahamu nínú òkúta wọ̀nyí.
9 Jau arī cirvis kokiem pie saknes pielikts; tāpēc ikkatrs koks, kas nenes labus augļus, top nocirsts un ugunī iemests.”
Àti nísinsin yìí pẹ̀lú, a fi àáké lé gbòǹgbò igi náà, gbogbo igi tí kò bá so èso rere, a óò ge lulẹ̀, a sì wọ jù sínú iná.”
10 Un tie ļaudis tam jautāja un sacīja: “Ko tad mums būs darīt?”
Àwọn ènìyàn sì ń bi í pé, “Kí ni kí àwa kí ó ṣe?”
11 Viņš atbildēja un uz tiem sacīja: “Kam divi svārki, tas lai dod tam, kam nav; un kam ir barība, lai dara tāpat.”
Ó dáhùn ó sì wí fún wọn pé, “Ẹni tí ó bá ní ẹ̀wù méjì, kí ó fi ọ̀kan fún ẹni tí kò ní; ẹni tí ó bá sì ní oúnjẹ, kí ó ṣe bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú.”
12 Bet arī muitnieki nāca, ka liktos kristīties, un uz to sacīja: “Mācītāj, ko mums būs darīt?”
Àwọn agbowó òde sì tọ̀ ọ́ wá láti ṣe ìtẹ̀bọmi lọ́dọ̀ rẹ̀, wọ́n sì bi í pé, “Olùkọ́, kí ni àwa ó ha ṣe?”
13 Un viņš uz tiem sacīja: “Neņemiet vairāk, nekā jums ir nospriests.”
Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe fi agbára gbà jù bí a ti rán yín lọ mọ́.”
14 Bet arī karavīri tam jautāja un sacīja: “Ko tad mums būs darīt?” Un viņš uz tiem sacīja: “Nedariet nevienam pāri, neapmelojiet nevienu un esat mierā ar savu algu.”
Àwọn ọmọ-ogun sì béèrè lọ́dọ̀ rẹ̀ pé, “Àti àwa, kí ni àwa ó ṣe?” Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe hùwà ipá sí ẹnikẹ́ni, kí ẹ má sì ṣe ka ẹ̀sùn èké sí ẹnikẹ́ni; kí òwò ọ̀yà yín tó yín.”
15 Bet tiem ļaudīm gaidot un visiem savā prātā par Jāni domājot, vai tas neesot Kristus,
Bí àwọn ènìyàn sì ti ń retí, tí gbogbo wọn sì ń rò nínú ara wọn nítorí Johanu, bí òun ni Kristi tàbí òun kọ́;
16 Jānis visiem atbildēja sacīdams: “Es jūs gan kristīju ar ūdeni, bet Viens nāks, spēcīgāks, nekā es, Tam es neesmu cienīgs atraisīt Viņa kurpju siksnas. Tas jūs kristīs ar Svētu Garu un uguni;
Johanu dáhùn ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Lóòótọ́ ni èmi ń fi omi bamitiisi yín, ṣùgbọ́n ẹni tí ó lágbára jù mí lọ ń bọ̀, okùn bàtà ẹsẹ̀ ẹni tí èmi kò tó tú, Òun ni yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ àti iná bamitiisi yín.
17 Tam vēteklis rokā, un Viņš tīrīs Savu klonu caur caurim un sakrās kviešus Savā klētī, bet pelavas sadedzinās ar neizdzēšamu uguni.”
Ẹni tí àtẹ rẹ̀ ń bẹ ní ọwọ́ rẹ̀, láti gbá ilẹ̀ ìpakà rẹ̀ mọ́ tó tó, kí ó sì kó alikama rẹ̀ sínú àká; ṣùgbọ́n ìyàngbò ni yóò fi iná àjóòkú sun.”
18 Arī vēl daudz citu ko mācīdams, viņš pasludināja tiem ļaudīm prieka vēsti.
Johanu lo oríṣìíríṣìí ọ̀rọ̀ púpọ̀ láti gba àwọn ènìyàn níyànjú àti láti wàásù ìyìnrere fún wọn.
19 Bet Hērodus, viens no tiem četriem valdniekiem, no viņa pārmācīts Hērodeijas, Filipa, sava brāļa, sievas dēļ, un visa ļauna dēļ, ko Hērodus bija darījis,
Ṣùgbọ́n nígbà ti Johanu bú Herodu tetrarki, tí ó bá wí nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀, àti nítorí ohun búburú gbogbo tí Herodu tí ṣe,
20 Pie visa tā arī šo vēl darīja, ka Jāni ieslēdza cietumā.
Ó fi èyí parí gbogbo rẹ̀ nígbà tí ó fi Johanu sínú túbú.
21 Un notikās, kad visi ļaudis tapa kristīti, un arī Jēzus bija kristīts un Dievu pielūdza, tad debesis atvērās,
Nígbà tí a ṣe ìtẹ̀bọmi àwọn ènìyàn gbogbo tán, ó sì ṣe, a bamitiisi Jesu pẹ̀lú, bí ó ti ń gbàdúrà, ọ̀run ṣí sílẹ̀,
22 Un Svētais Gars nolaidās uz Viņu redzamā ģīmī kā balodis; un balss atskanēja no debesīm sacīdama: “Tu esi Mans mīļais Dēls, pie Tevis Man ir labs prāts.”
Ẹ̀mí Mímọ́ sì sọ̀kalẹ̀ sí orí rẹ̀ ní àwọ̀ àdàbà, ohùn kan sì ti ọ̀run wá, tí ó wí pé, “Ìwọ ni àyànfẹ́ ọmọ mi; ẹni tí inú mi dùn sí gidigidi.”
23 Un Viņš pats, Jēzus, bija trīsdesmitā gadā un bija pēc ļaužu domām Jāzepa dēls, tas bija Elus dēls,
Jesu tìkára rẹ̀ ń tó bí ẹni ọgbọ̀n ọdún, nígbà tí ó bẹ̀rẹ̀ iṣẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ ó jẹ́ (bí a ti fi pè) ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Eli,
24 Tas Matata, tas Levja, tas Melkus, tas Janna, tas Jāzepa dēls,
tí í ṣe ọmọ Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi, tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Janai, tí í ṣe ọmọ Josẹfu,
25 Tas Matatijas, tas Amosa, tas Naūma, tas Eslus, tas Nagaja dēls,
tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Amosi, tí í ṣe ọmọ Naumu, tí í ṣe ọmọ Esili, tí í ṣe ọmọ Nagai,
26 Tas Maāta, tas Matatijas, tas Zemeja, tas Jāzepa, tas Jūdas dēls,
tí í ṣe ọmọ Maati, tí í ṣe ọmọ Mattatia, tí í ṣe ọmọ Ṣimei, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Joda,
27 Tas Jāņa, tas Rezas, tas Corobabeļa, tas Zalatiēļa, tas Nerus dēls,
tí í ṣe ọmọ Joana, tí í ṣe ọmọ Resa, tí í ṣe ọmọ Serubbabeli, tí í ṣe ọmọ Ṣealitieli, tí í ṣe ọmọ Neri,
28 Tas Melķus, tas Addas, tas Kozama, tas Elmodama, tas Era dēls,
tí í ṣe ọmọ Meliki, tí í ṣe ọmọ Adi, tí í ṣe ọmọ Kosamu, tí í ṣe ọmọ Elmadamu, tí í ṣe ọmọ Eri,
29 Tas Jāzepa, tas Eliēcera, tas Jorema, tas Matata, tas Levja dēls,
tí í ṣe ọmọ Joṣua, tí í ṣe ọmọ Elieseri, tí í ṣe ọmọ Jorimu, tí í ṣe Mattati, tí í ṣe ọmọ Lefi,
30 Tas Sīmeana, tas Jūdas, tas Jāzepa, tas Jonana, tas Eliaķima dēls,
tí í ṣe ọmọ Simeoni, tí í ṣe ọmọ Juda, tí í ṣe ọmọ Josẹfu, tí í ṣe ọmọ Jonamu, tí í ṣe ọmọ Eliakimu,
31 Tas Meleas, tas Menas, tas Matatas, tas Natana, tas Dāvida dēls,
tí í ṣe ọmọ Melea, tí í ṣe ọmọ Menna, tí í ṣe ọmọ Mattata, tí í ṣe ọmọ Natani, tí í ṣe ọmọ Dafidi,
32 Tas Isajus, tas Obeda, tas Boasa, tas Zalmana, tas Nahšona dēls,
tí í ṣe ọmọ Jese, tí í ṣe ọmọ Obedi, tí í ṣe ọmọ Boasi, tí í ṣe ọmọ Salmoni, tí í ṣe ọmọ Nahiṣoni,
33 Tas Aminadaba, tas Arama, tas Hecrona, tas Vāreca, tas Jūdas dēls,
tí í ṣe ọmọ Amminadabu, tí í ṣe ọmọ Ramu, tí í ṣe ọmọ Hesroni, tí í ṣe ọmọ Peresi, tí í ṣe ọmọ Juda.
34 Tas Jēkaba, tas Īzaka, tas Ābrahāma, tas Tārus, tas Nahora dēls,
Tí í ṣe ọmọ Jakọbu, tí í ṣe ọmọ Isaaki, tí í ṣe ọmọ Abrahamu, tí í ṣe ọmọ Tẹra, tí í ṣe ọmọ Nahori,
35 Tas Serugs, tas Regus, tas Pelegs, tas Ēbera, tas Šalus dēls,
tí í ṣe ọmọ Serugu, tí í ṣe ọmọ Reu, tí í ṣe ọmọ Pelegi, tí í ṣe ọmọ Eberi, tí í ṣe ọmọ Ṣela.
36 Tas Kainana, tas Arvaksada, tas Zema, tas Noas, tas Lāmeha dēls,
Tí í ṣe ọmọ Kainani, tí í ṣe ọmọ Arfaksadi, tí í ṣe ọmọ Ṣemu, tí í ṣe ọmọ Noa, tí í ṣe ọmọ Lameki,
37 Tas Matuzalas, tas Enoha, tas Jareda, tas Mahalaleēla, tas Kainana dēls,
tí í ṣe ọmọ Metusela, tí í ṣe ọmọ Enoku, tí í ṣe ọmọ Jaredi, tí í ṣe ọmọ Mahalaleli, tí í ṣe ọmọ Kainani.
38 Tas Enosa, tas Seta, tas Ādama dēls, tas Dieva.
Tí í ṣe ọmọ Enosi, tí í ṣe ọmọ Seti, tí í ṣe ọmọ Adamu, tí í ṣe ọmọ Ọlọ́run.