< Raudu Dziesmas 3 >
1 Es esmu tas vīrs, kas redzējis bēdas caur viņa dusmības rīksti.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 Viņš mani vedis un licis iet tumsībā un ne gaismā.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Tiešām, pret mani Viņš turējis Savu roku arvien atkal cauru dienu.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Manu miesu un manu ādu Viņš darījis vecu, manus kaulus Viņš satriecis.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Viņš pret mani cēlis un ap mani stādījis žulti un rūgtumu.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Tumsā Viņš mani nolicis, tā kā tos, kas sen miruši.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Viņš mani aizmūrējis, ka es nevaru iziet, Viņš mani licis grūtos pinekļos.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 Un jebšu es saucu un brēcu, tomēr Viņš aizslēdz Savas ausis priekš manas lūgšanas.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Viņš manu ceļu aizmūrējis ar izcirstiem akmeņiem, Viņš manas tekas aizķīlājis.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Viņš ir glūnējis uz mani kā lācis, kā lauva slepenās vietās.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Viņš man no ceļa licis noklīst, Viņš mani saplosījis, Viņš mani postījis.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Viņš savu stopu uzvilcis un mani bultai licis par mērķi.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Viņš savas bultas iešāvis manās īkstīs.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Es visiem saviem ļaudīm esmu par apsmieklu, viņiem par dziesmiņu cauru dienu.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Viņš mani ēdinājis ar rūgtumiem, Viņš mani dzirdinājis ar vērmelēm.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Viņš manus zobus ar zvirgzdiem(grants akmeņiem) sagrūdis, Viņš mani aprausis ar pelniem.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Tu manai dvēselei esi atņēmis mieru, man labums jāaizmirst.
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 Tad es sacīju: mana drošība un mana cerība uz To Kungu ir pagalam.
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Piemini manas bēdas un manu grūtumu, tās vērmeles un to žulti.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 Pieminēdama to piemin mana dvēsele un zemojās iekš manis.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 To es likšu pie savas sirds, tāpēc es gribu cerēt.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 Tā Kunga žēlastība to dara, ka mēs vēl neesam pagalam, jo Viņa apžēlošanās ir bez gala.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Tā ir ik rītu jauna, Tava uzticība ir ļoti liela.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 Tas Kungs ir mana daļa, saka mana dvēsele, tādēļ es gribu cerēt uz Viņu.
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 Tas Kungs ir labs tiem, kas uz Viņu gaida, tai dvēselei, kas Viņu meklē.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 Tā ir laba lieta, klusā garā gaidīt uz Tā Kunga palīdzību.
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 Tas ir labi cilvēkam, ka viņš jūgu nes savā jaunībā.
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 Viņš sēž vientulis un cieš klusu, kad tam nasta uzlikta,
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Lai krīt uz savu muti pīšļos, - varbūt vēl cerība, -
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Lai padod savu vaigu tam, kas viņu sit, un saņem nievāšanas papilnam.
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 Jo Tas Kungs neatmet mūžīgi.
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 Bet Viņš gan apbēdina, un tad Viņš apžēlojās pēc Savas lielās žēlastības.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Jo ne no Savas sirds Viņš moka un apbēdina cilvēka bērnus.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Kad apakš kājām min visus cietumniekus virs zemes,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 Kad loka vīra tiesu tā Visuaugstākā priekšā,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 Kad pārgroza cilvēka tiesu, vai Tas Kungs to neredz?
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 Kas ko sacījis un tas noticis, ko Tas Kungs nav pavēlējis?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 Vai no tā Visuaugstākā mutes nenāk labums un ļaunums?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Ko tad cilvēks kurn visu savu mūžu? Ikviens lai kurn pret saviem grēkiem.
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Izmeklēsim un pārbaudīsim savus ceļus un atgriezīsimies pie Tā Kunga.
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Pacelsim savu sirdi un savas rokas uz Dievu debesīs (sacīdami):
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Mēs esam grēkojuši un esam bijuši neklausīgi, tāpēc Tu neesi žēlojis.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Tu esi ģērbies dusmībā un mūs vajājis, nokāvis un neesi žēlojis.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Tu ar padebesi esi apsedzies, ka lūgšana nevarēja tikt cauri.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Tu mūs esi licis par mēsliem un īgnumu tautu vidū.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Visi mūsu ienaidnieki atpleš savu muti pret mums.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Bailes un bedre nāk pār mums, nelaime un posts.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Manas acis plūst kā ūdens upes manas tautas meitas posta dēļ.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Manas acis plūst un nevar stāties, mitēšanās nav,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 Tiekams Tas Kungs no debesīm skatīsies un ņems vērā.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Mana acs dara grūti manai dvēselei visu manas pilsētas meitu dēļ.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Mani ienaidnieki vajāt mani vajājuši kā putnu bez vainas.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Tie manu dzīvību nomaitājuši bedrē un akmeņus metuši uz mani.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Ūdeņi plūda pār manu galvu; tad es sacīju: nu esmu pagalam.
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Es piesaucu, ak Kungs, Tavu vārdu no dziļās bedres,
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Un Tu paklausīji manu balsi. Tu neapslēpi Savu ausi no manām vaimanām, no manas kliegšanas.
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Tu nāci tuvu klāt tai dienā, kad es Tevi piesaucu, un sacīji: “Nebīsties!”
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Tu, Kungs, iztiesā manas dvēseles tiesu, Tu izpestī manu dzīvību.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Tu, Kungs, redzi to netaisnību, kas man notiek, - tiesā tu manu tiesu!
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Tu redzi visu viņu atriebšanos, visas viņu domas pret mani.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Tu, Kungs, dzirdi viņu nievāšanu, visas viņu domas pret mani,
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Manu pretinieku lūpas un viņu domas pret mani cauru dienu.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Lūko jel: Vai tie sēž vai ceļas, es esmu viņu dziesmiņa.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Tu tiem atmaksāsi, Kungs, maksu pēc viņu roku darbiem.
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Tu tiem dosi apstulbotu sirdi, - Tavi lāsti lai ir pār viņiem!
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Tu tos vajāsi ar dusmību un tos izdeldēsi apakš Tā Kunga debesīm.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.