< Sog̒u 7 >

1 Tad JerubBaāls, tas ir Gideons, un visi ļaudis, kas pie viņa, agri cēlās un apmetās pie Aroda avota, tā ka Midijaniešu karaspēks viņam bija pret ziemeļa pusi, aiz Mores pakalna, ielejā.
Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù Jerubbaali (èyí ni Gideoni) pẹ̀lú gbogbo àwọn ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kó ogun jọ lẹ́bàá a orísun Harodi. Àwọn ogun Midiani sì wà ní apá àríwá tí wọ́n ní àfonífojì tí ó wà ní ẹ̀bá òkè More.
2 Un Tas Kungs sacīja uz Gideonu: Pārāk daudz ļaužu ir pie tevis, nekā Es dotu Midijaniešus viņu rokā; lai Israēls pret Mani nelielās un nesaka: mana roka mani izpestījusi.
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọmọ-ogun tí o kójọ sọ́dọ̀ ti pọ̀jù fún mi láti fi àwọn ogun Midiani lé wọn lọ́wọ́, kí Israẹli má ba à gbé ara rẹ̀ ga sí mi wí pé agbára òun ni ó gbà á là,
3 Tad izsauc jel to ļaužu ausīs un saki: kas šaubīgs un bailīgs, lai griežas atpakaļ un steidzās projām no Gileāda kalna. Tad no tiem ļaudīm griezās atpakaļ divdesmit divi tūkstoši, un tik desmit tūkstoši atlika.
sì kéde sí àwọn ènìyàn nísinsin yìí pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá ń gbọ̀n, tí ó sì ń bẹ̀rù lè padà sẹ́yìn, kí ó sì kúrò lórí òkè Gileadi.’” Báyìí ni Gideoni ṣe ya àwọn ènìyàn náà. Ẹgbẹ̀rún méjìlélógún ọkùnrin sì padà sẹ́yìn àwọn ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá sì dúró.
4 Un Tas Kungs sacīja uz Gideonu: ļaužu vēl ir par daudz; noved tos pie ūdens, tur Es tos tev pārbaudīšu, un par kuru Es uz tevi sacīšu: šim būs iet ar tevi, tas lai iet ar tevi, bet par kuru Es tev sacīšu, tam nebūs iet ar tevi, tas lai neiet.
Olúwa sì tún sọ fún Gideoni pé, “Àwọn ènìyàn yìí sì tún pọ̀jù. Kó wọn lọ sí ibi tí omi wà, èmi yóò sì yọ̀rọ̀ wọn níbẹ̀ fún ọ. Bí mo bá wí pé eléyìí yóò bá ọ lọ yóò lọ, ṣùgbọ́n tí mo bá sọ pé, ‘Eléyìí kò ní bá ọ lọ,’ òun kò gbọdọ̀ lọ.”
5 Un viņš tos ļaudis noveda pie ūdens. Tad Tas Kungs sacīja uz Gideonu: ikkatru, kas ar savu mēli ūdeni laks, kā suns lok, to nostādi par sevi, un tāpat ikkatru, kas nometīsies ceļos dzert.
Gideoni sì kó àwọn ọkùnrin náà lọ sí ibi ìsun omi. Níbẹ̀ ni Olúwa ti wí fún un pé, “Kí ó pín àwọn ènìyàn náà sí ọ̀nà méjì. Ya àwọn tí ó fi ahọ́n wọn lá omi bí ajá kúrò lára àwọn tí ó kúnlẹ̀ láti mu omi pẹ̀lú ọwọ́ wọn.”
6 Un to pulks, kas no savas rokas pie mutes bija lakuši, bija trīssimt vīri, bet visi citi ļaudis bija ūdeni dzēruši ceļos nometušies.
Ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin ni ó lá omi pẹ̀lú ahọ́n wọn. Gbogbo àwọn ìyókù ni ó kúnlẹ̀ láti mu mi.
7 Un Tas Kungs sacīja uz Gideonu: caur šiem trīs simti vīriem, kas lakuši, Es jūs izpestīšu un nodošu Midijaniešus tavā rokā; tāpēc atlaid visus citus ļaudis, ikvienu uz savu vietu.
Olúwa wí fún Gideoni pé, “Àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin tí ó lá omi ni èmi yóò lò láti gbà yín là àti láti fi ogun Midiani lé yín lọ́wọ́. Jẹ́ kí àwọn tókù padà sí ilé wọn.”
8 Un tie ļaudis ņēma savu maizi savā rokā un savas trumetes, bet visus citus Israēla vīrus viņš atlaida, ikvienu uz savu dzīvokli, un tos trīs simti vīrus viņš paturēja, un Midijaniešu karaspēks viņam bija ielejas pusē.
Báyìí ni Gideoni ṣe dá àwọn Israẹli tí ó kù padà sí àgọ́ wọn, ṣùgbọ́n ó dá àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin náà dúró. Àwọn wọ̀nyí sì gba gbogbo ohun èlò àti fèrè àwọn tí ó ti padà. Ibùdó ogun àwọn Midiani wà ní àfonífojì ní ìsàlẹ̀. Ibi tí ó wà.
9 Un notika tanī naktī, ka Tas Kungs uz viņu sacīja: celies, noej uz lēģeri, jo Es to esmu devis tavā rokā.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa sọ fún Gideoni pé, “Dìde, dojú ogun kọ ibùdó ogun àwọn ará Midiani nítorí èmi yóò fi lé ọ lọ́wọ́.
10 Bet ja tev ir bail noiet, tad noej uz to lēģeri tu un Purus, tavs puisis,
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀rù àti kọlù wọ́n bá ń bà ọ́, yọ́ wọ ibùdó wọn lọ kí o mú Pura ìránṣẹ́ rẹ lọ́wọ́
11 Tad tu dzirdēsi, ko tie runā, un pēc tam tavas rokas stiprināsies, un tu celsies pret to lēģeri. Tad viņš nogāja ar Puru, savu puisi, pie tiem pirmiem apbruņotiem, kas bija lēģerī.
kí o sì fi ara balẹ̀ gbọ́ ohun tí wọ́n ń sọ nínú ibùdó náà. Lẹ́yìn èyí ọkàn rẹ̀ yóò le láti kọlù ibùdó náà.” Báyìí ni òun àti Pura ìránṣẹ́ rẹ̀ wọ ẹnu-ọ̀nà ibùdó yìí.
12 Un Midijanieši un Amalekieši un visi tie austruma bērni gulēja ielejā kā siseņu pulks, un viņu kamieļu pulku nevarēja skaitīt, kā smiltis jūrmalā.
Àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti gbogbo ènìyàn ìlà-oòrùn tó lọ ní àfonífojì bí eṣú ni wọ́n rí nítorí púpọ̀ wọn. Àwọn ìbákasẹ wọn kò sì lóǹkà, wọ́n sì pọ̀ bí yanrìn inú Òkun.
13 Kad nu Gideons nonāca, redzi, tur viens savam biedram stāstīja sapni un sacīja: redzi, es esmu sapni redzējis, un redzi, cepta miežu maize vēlās Midijaniešu lēģerī un atnāca līdz pat teltij un to sita, ka tā krita, un to pavisam apgāza, un telts gulēja (pie zemes).
Gideoni dé sí àsìkò tí ọkùnrin kan bẹ̀rẹ̀ sí í rọ́ àlá tí ó lá sí ọ̀kan nínú àwọn ọ̀rẹ́ rẹ̀. Ó ní, “Mo lá àlá kan, nínú àlá náà mo rí àkàrà kan tó ṣe róbótó tí a fi barle ṣe ń yí wọ inú ibùdó àwọn ará Midiani, ó sì kọlu àgọ́ pẹ̀lú agbára ńlá dé bi wí pé àgọ́ náà dojúdé, ó sì ṣubú.”
14 Tad viņa biedrs atbildēja un sacīja: tas nav nekas cits, kā Gideona, Joasa dēla, tā Israēlieša, zobens; Dievs Midijaniešus un visu šo lēģeri devis viņa rokā.
Ọ̀rẹ́ rẹ̀ dá a lóhùn pé, “Èyí kò le túmọ̀ sí ohun mìíràn ju idà Gideoni ọmọ Joaṣi ará Israẹli lọ: Ọlọ́run ti fi àwọn ará Midiani àti gbogbo ogun ibùdó lé e lọ́wọ́.”
15 Un kad Gideons dzirdēja šā sapņa stāstīšanu un izskaidrošanu, tad viņš pielūdza Dievu, griezās atpakaļ uz Israēla lēģeri un sacīja: ceļaties, jo Tas Kungs Midijaniešu karaspēku devis jūsu rokās.
Nígbà tí Gideoni gbọ́ àlá náà àti ìtumọ̀ rẹ̀, ó wólẹ̀ sin Ọlọ́run: lẹ́yìn náà ni ó padà sí ibùdó àwọn ọmọ Israẹli ó sì pè wọ́n pé, “Ẹ dìde! Nítorí pé Olúwa yóò lò yín láti ṣẹ́gun gbogbo ogun Midiani.”
16 Un viņš dalīja tos trīs simtI vīrus trijos pulkos, un deva visiem trumetes un tukšas krūzes rokā un lāpas krūzēs.
Nígbà tí ó ti pín àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì sí ọ̀nà mẹ́ta, ó fi fèrè, pẹ̀lú àwọn òfìfo ìkòkò lé ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn lọ́wọ́, iná sì wà nínú àwọn ìkòkò náà.
17 Un viņš uz tiem sacīja: skatāties uz mani un tā dariet; un redzi, kad es nākšu pie lēģera malas, tad dariet jūs tā, kā es daru.
Ó sọ fún wọn pé, “Ẹ máa wò mí, kí ẹ sì máa ṣe ohun tí mo bá ṣe. Nígbà tí mo bá dé igun ibùdó wọn ẹ ṣe ohun tí mo bá ṣe.
18 Kad es trumetēšu, es un visi, kas pie manis, tad jums arīdzan būs trumetēt ap visu lēģeri un saukt: Tā Kunga un Gideona (zobens)!
Nígbà tí èmi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú mi bá fun fèrè wa, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin náà ni gbogbo igun ibùdó tí ẹ̀ bá wà kí ẹ fun àwọn fèrè yín kí ẹ sì hó pé, ‘Fún Olúwa àti fún Gideoni.’”
19 Tad Gideons un tie simts vīri ar viņu nāca pie lēģera malas ap nakts vidu, kad nule sargi bija mainīti, un tie pūta trumetēs un sadauzīja tās krūzes savās rokās.
Gideoni àti àwọn ọgọ́rùn-ún ọkùnrin tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ dé òpin ibùdó àwọn ará Midiani ní nǹkan bí agogo méjìlá padà. Wọ́n fun fèrè wọn, wọ́n sì tún fọ́ àwọn ìkòkò tí ó wà ní ọwọ́ mọ́lẹ̀.
20 Tā tie trīs pulki pūta trumetēs un sadauzīja tās krūzes un turēja ar kreiso roku tās lāpas un savā labajā rokā tās trumetes un pūta un kliedza: Tā Kunga un Gideona zobens.
Àwọn ẹgbẹ́ mẹ́tẹ̀ẹ̀ta fun fèrè wọn, wọ́n tún fọ́ àwọn ìkòkò wọn mọ́lẹ̀. Wọ́n mú àwọn fìtílà iná wọn ní ọwọ́ òsì wọn àti fèrè tí wọ́n ń fun ní ọwọ́ ọ̀tún wọn. Wọ́n pariwo hé è pé, “Idà kan fún Olúwa àti fún Gideoni!”
21 Un tie stāvēja ikviens savā vietā ap to lēģeri. Tad viss karaspēks sāka skriet un tie brēca un bēga.
Nígbà tí ọkùnrin kọ̀ọ̀kan dúró ní ipò rẹ̀ yí ibùdó àwọn Midiani ká, gbogbo àwọn ọmọ-ogun Midiani ń sá káàkiri, wọ́n ń pariwo bí wọ́n ṣe ń sálọ.
22 Jo kad tie trīs simti vīri trumetēs pūta, tad Tas Kungs grieza viena zobenu pret otru visā lēģerī, un tas karaspēks bēga līdz BetZitai uz Careratas pusi, līdz AbelMeolas robežai pie Tābatas.
Nígbà tí àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin wọ̀n-ọn-nì fun fèrè wọn, Olúwa sì yí ojú idà ọkùnrin kọ̀ọ̀kan padà sí ẹnìkejì rẹ̀ àti sí gbogbo ogun wọn. Àwọn ọmọ-ogun sì sá títí dé Beti-Sitta ní ọ̀nà Serera títí lọ dé ìpínlẹ̀ Abeli-Mehola ní ẹ̀bá Tabbati.
23 Tad Israēla vīri tapa sasaukti no Naftalus un no Ašera un no visa Manasus, un tie dzinās pakaļ Midijanam.
Gbogbo àwọn ọmọ-ogun Israẹli láti ẹ̀yà Naftali, Aṣeri àti gbogbo Manase ni Gideoni ránṣẹ́ si, wọ́n wá wọ́n sì lé àwọn ará Midiani.
24 Un Gideons sūtīja vēstnešus uz visiem Efraīma kalniem un sacīja: nonāciet pretī Midijaniešiem un aizstājiet tiem to ūdeni līdz Betbarai un Jardāni. Tā visi Efraīma vīri tika sasaukti un aizstāja to ūdeni līdz Betbarai un Jardāni.
Gideoni tún ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ìlú tí ó wà ní orí òkè Efraimu wí pé, “Ẹ jáde wá bá àwọn ará Midiani jà, kí ẹ tètè gba àwọn omi Jordani títí dé Beti-Bara kí wọ́n tó dé bẹ̀.” Báyìí ni a ṣe pe gbogbo ọkùnrin ológun Efraimu jáde tí wọ́n sì gba gbogbo àwọn à bá wọ odò Jordani títí dé Beti-Bara.
25 Un tie gūstīja divus Midijaniešu valdniekus, Orebu un Zeēbu, un nokāva Orebu pie Oreb akmens, un Zeēbu tie nokāva pie Zeēba spaida un dzinās pakaļ Midijanam un nonesa Oreba un Zeēba galvas pie Gideona viņpus Jardānes.
Wọ́n mú méjì nínú àwọn olórí àwọn ará Midiani, àwọn náà ni Orebu àti Seebu. Wọ́n pa Horebu nínú àpáta Orebu, wọ́n sì pa Seebu níbi tí àwọn ènìyàn ti mọ̀ fún wáìnì tí a ń pè ní ìfúntí Seebu. Wọ́n lé àwọn ará Midiani, nígbà tí wọ́n gbé orí Orebu àti Seebu tọ Gideoni wá ẹni tí ó wà ní apá kejì Jordani.

< Sog̒u 7 >