< Sog̒u 6 >

1 Un Israēla bērni darīja, kas Tam Kungam nepatika. Tad Tas Kungs tos nodeva Midijaniešu rokā septiņus gadus.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú ní ojú Olúwa, Ó sì fi wọ́n lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́ fún ọdún méje.
2 Kad nu Midijaniešu roka palika stipra pret Israēli, tad Israēla bērni sev taisīja alas kalnos un bedres un stipras pilis Midijaniešu dēļ.
Agbára àwọn ará Midiani sì pọ̀ púpọ̀ lórí àwọn Israẹli, wọ́n sì hùwà ipá sí wọn, nítorí ìdí èyí, àwọn Israẹli sálọ sí àwọn orí òkè, wọ́n sì kọ́ àgọ́ fún ara wọn nínú ihò àpáta, àti nínú ọ̀gbun àti ní ibi agbára nínú àpáta.
3 Jo kad Israēls bija sējis, tad nāca Midijanieši un Amalekieši un austruma ļaudis un cēlās pret tiem.
Ní ìgbàkúgbà tí àwọn ọmọ Israẹli bá ti gbin ọ̀gbìn wọn, àwọn ará Midiani, àwọn ará Amaleki àti àwọn ará ìlà-oòrùn mìíràn yóò wá láti bá wọn jà.
4 Un apmetās pret tiem un postīja zemes druvas līdz Gacai; tie neatlicināja pārtikas iekš Israēla, nedz sīku lopu nedz vēršu nedz ēzeļu.
Wọn yóò tẹ̀dó sí orí ilẹ̀ náà, wọn a sì bá irúgbìn wọ̀nyí jẹ́ títí dé Gasa, wọn kì í sì í fi ohun alààyè kankan sílẹ̀ fún àwọn ọmọ Israẹli, kì bá à ṣe àgùntàn, màlúù tàbí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́.
5 Jo tie atnāca ar saviem ganāmiem pulkiem un ar savām teltīm, tie nāca tā kā siseņu pulks, ka tos ar viņu kamieļiem nevarēja skaitīt, un tie nāca, zemi postīt.
Wọn a máa wá pẹ̀lú ohun ọ̀sìn wọn àti àwọn àgọ́ wọn, wọn a sì dàbí eṣú nítorí i púpọ̀ wọn. Ènìyàn kò sì lè ka iye àwọn ènìyàn náà bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìbákasẹ, wọ́n pọ̀ dé bi pé wọn kò ṣe é kà ní iye, wọn a bo ilẹ̀ náà wọn a sì jẹ ẹ́ run.
6 Un Israēls ļoti panīka caur Midijaniešiem. Tad Israēla bērni brēca uz To Kungu.
Àwọn ará Midiani sì pọ́n àwọn ọmọ Israẹli lójú, wọ́n sọ wọ́n di òtòṣì àti aláìní, fún ìdí èyí wọ́n ké pe Olúwa nínú àdúrà fún ìrànlọ́wọ́.
7 Un notikās, kad Israēla bērni Midijana dēļ uz To Kungu brēca,
Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa nítorí àwọn ará Midiani.
8 Tad Tas Kungs sūtīja pravieti pie Israēla bērniem; tas uz viņiem sacīja: tā saka Tas Kungs, Israēla Dievs: Es jūs esmu izvedis no Ēģiptes un jūs izvedis no vergu nama
Olúwa fi etí sí igbe wọn, ó sì rán wòlíì kan sí wọn, ẹni tí ó wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: mo mú yín gòkè ti Ejibiti wá, láti oko ẹrú.
9 Un jūs izglābis no ēģiptiešu rokas un no visu rokas, kas jūs spieda, un Es tos jūsu priekšā izdzinis un jums devis viņu zemi.
Mo gbà yín kúrò nínú agbára Ejibiti àti kúrò ní ọwọ́ gbogbo àwọn aninilára yín. Mo lé wọn kúrò ní iwájú yín, mo sì fi ilẹ̀ wọn fún yín.
10 Un Es uz jums sacīju: Es esmu Tas Kungs, jūsu Dievs, nebīstaties Amoriešu dievus, kuru zemē jūs dzīvojat. Bet jūs neesat klausījuši Manai balsij.
Mo wí fún un yín pé, ‘Èmi ni Olúwa Ọlọ́run yín; ẹ má ṣe sin àwọn òrìṣà àwọn ará Amori, ní ilẹ̀ ẹni tí ẹ̀yin ń gbé.’ Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọ́rọ̀ sí ohun tí mo sọ.”
11 Un Tā Kunga eņģelis nāca un apsēdās apakš tā ozola Ovrā, kas piederēja Joasam, no Abiēzera nama, un viņu dēls Gideons kūla kviešus vīna spaidā, lai tos paslēptu no Midijaniešiem.
Ní ọjọ́ kan angẹli Olúwa wá, ó sì jókòó ní abẹ́ igi óákù Ofira èyí ti ṣe ti Joaṣi ará Abieseri, níbi tí Gideoni ọmọ rẹ̀ ti ń lu ọkà jéró, níbi ìpọntí wáìnì láti fi pamọ́ kúrò níwájú àwọn ará Midiani.
12 Un Tā Kunga eņģelis tam parādījās un uz to sacīja: Tas Kungs ar tevi, tu stiprais varenais vīrs!
Nígbà tí angẹli Olúwa fi ara han Gideoni, ó wí fún un pé, “Olúwa wà pẹ̀lú rẹ, akọni ológun.”
13 Bet Gideons uz viņu sacīja: mans Kungs, kad Tas Kungs ir ar mums, kāpēc tad visas šīs bēdas mums uznākušas? Un kur ir visi viņa brīnumi, ko mums mūsu tēvi teikuši, sacīdami: vai Tas Kungs mūs nav izvedis no Ēģiptes? Bet nu Tas Kungs mūs atstājis un nodevis Midijaniešu rokā.
Gideoni dáhùn pé, “Alàgbà, bí Olúwa bá wà pẹ̀lú wa, kí ló dé tí gbogbo ìwọ̀nyí fi ń ṣẹlẹ̀ sí wa? Níbi gbogbo àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ tí àwọn baba wa ròyìn rẹ̀ fún wa nígbà tí wọ́n wí pé, ‘Olúwa kò ha mú wa gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá?’ Ṣùgbọ́n nísinsin yìí Olúwa ti kọ̀ wá sílẹ̀, ó sì ti fi wá lé àwọn ará Midiani lọ́wọ́.”
14 Tad Tas Kungs uz viņu atgriezās un sacīja: noej šinī savā spēkā, un atpestī Israēli no Midijaniešu rokas; redzi, Es tevi esmu sūtījis.
Olúwa sì yípadà sí i, ó sì wí fún un pé, “Lọ nínú agbára tí o ní yìí, kí o sì gba àwọn ará Israẹli sílẹ̀ kúrò lọ́wọ́ àwọn ará Midiani. Èmi ni ó ń rán ọ lọ.”
15 Un viņš uz to sacīja: mans Kungs, ar ko es Israēli atpestīšu? Redzi, mans radu pulks ir tas mazākais Manasū, un es esmu tas mazākais sava tēva namā.
Gideoni sì dáhùn pé, “Yéè olúwa mi, ọ̀nà wo ni èmi yóò fi gba Israẹli là? Ìdílé mi ni ó jẹ́ aláìlera jù ní Manase, àti pé èmi ni ó sì kéré jù ní ìdílé baba mi.”
16 Un Tas Kungs sacīja uz viņu: tāpēc ka Es būšu ar tevi, tu sitīsi Midijaniešus kā vienu vīru.
Olúwa sì dáhùn pé, “Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, ìwọ yóò sì pa gbogbo àwọn ará Midiani láì ku ẹnìkankan.”
17 Tad tas uz Viņu sacīja: ja es esmu atradis žēlastību Tavās acīs, tad dod man jel zīmi, ka Tu tas esi, kas ar mani runā.
Gideoni sì dáhùn pé, nísinsin yìí tí mo bá bá ojúrere rẹ pàdé, fún mi ní àmì pé ìwọ ni ń bá mi sọ̀rọ̀.
18 Neaizej jel no šejienes, kamēr es pie Tevis nākšu un savu ēdamo upuri atnesīšu un Tev celšu priekšā. Un Viņš sacīja: Es palikšu, kamēr tu atkal nāksi.
Jọ̀wọ́ má ṣe kúrò níbí títí èmi yóò fi mú ọrẹ wá fún ọ kí n sì gbé e sí iwájú rẹ. Olúwa sì wí pé, “Èmi yóò dúró títí ìwọ yóò fi dé.”
19 Un Gideons iegāja un sataisīja kazlēnu un neraudzētas karašas no vienas ēfas miltu; to gaļu viņš lika kurvī un to sulu viņš lēja podā, un to iznesa pie Viņa ārā apakš tā ozola un to nolika zemē.
Gideoni sì yára wọ ilé lọ, ó sì pa ọ̀dọ́ ewúrẹ́ kan, wọ́n sì sè é, ó sì mú ìyẹ̀fun efa kan, ó fi ṣe àkàrà aláìwú. Ó gbé ẹran náà sínú agbọ̀n, ṣùgbọ́n ó fi ọbẹ̀ rẹ̀ sínú ìkòkò, ó gbé wọn jáde tọ angẹli náà wá bí ọrẹ lábẹ́ igi óákù.
20 Un tas Dieva eņģelis sacīja uz viņu: ņem to gaļu un tās neraudzētās karašas un liec to šeitan uz to akmeni un izlej to sulu; un viņš tā darīja.
Angẹli Ọlọ́run náà sì wí fún un pé, “Gbé ẹran náà àti àkàrà àìwú náà, sí orí àpáta yìí, kí o sì da omi ọbẹ̀ rẹ̀ sí orí rẹ̀.” Gideoni sì ṣe bẹ́ẹ̀.
21 Tad Tā Kunga eņģelis izstiepa tā zižļa galu, kas viņam bija rokā, un aizskāra to gaļu un tās neraudzētās maizes. Tad uguns izšāvās no tā akmens un aprija to gaļu un tās neraudzētās karašas; un Tā Kunga eņģelis nozuda no viņa acīm.
Angẹli Olúwa sì fi orí ọ̀pá tí ó wà ní ọwọ́ rẹ̀ kan ẹran àti àkàrà àìwú náà. Iná sì jáde láti inú àpáta, ó sì jó ẹran àti àkàrà náà, kò sì rí angẹli náà mọ́.
22 Kad nu Gideons redzēja, to Tā Kunga eņģeli esam, tad Gideons sacīja: Ak vai! Kungs, Dievs! Jo es Tā Kunga eņģeli vaigu vaigā esmu redzējis!
Nígbà tí Gideoni sì ti mọ̀ dájúdájú pé angẹli Olúwa ni, ó ké wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè! Mo ti rí angẹli Olúwa ní ojúkorojú!”
23 Tad Tas Kungs uz viņu sacīja: miers ar tevi! nebīsties, tu nemirsi!
Ṣùgbọ́n Olúwa wí fún un pé, “Àlàáfíà! Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ kì yóò kùú.”
24 Tad Gideons tur Tam Kungam uzcēla altāri un to nosauca: Tas Kungs ir miers. Tas vēl līdz šodienai ir Abiēzeriešu Ovrā.
Báyìí ni Gideoni mọ pẹpẹ kan fún Olúwa níbẹ̀, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní “Àlàáfíà ni Olúwa.” Ó sì wà ní Ofira ti Abieseri títí di òní.
25 Un tai naktī Tas Kungs uz viņu sacīja: ņem vērsīti no sava tēva lopiem un vēl otru vērsi septiņus gadus vecu, un salauzi Baāla altāri, kas tavam tēvam, un nocērt to elka stabu, kas tur ir klātu.
Ní òru ọjọ́ náà Olúwa wí fún un pé, mú akọ màlúù baba rẹ, àní akọ màlúù kejì ọlọ́dún méje. Wó pẹpẹ Baali baba rẹ lulẹ̀, kí o sì bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ lulẹ̀.
26 Un uztaisi Tam Kungam, savam Dievam, altāri šīs stiprās vietas kalna galā tā kārtīgi, un ņem to otru vērsi un upurē dedzināmo upuri ar to malku no tā elka staba, ko tu nocirtīsi.
Lẹ́yìn èyí kí o wá mọ pẹpẹ èyí tí ó yẹ fún Olúwa Ọlọ́run rẹ lórí òkè yìí. Kí o sì mú akọ màlúù kejì, kí o sì mú igi ère òrìṣà Aṣerah tí ìwọ bẹ́ lulẹ̀ rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
27 Tad Gideons ņēma desmit vīrus no saviem kalpiem un darīja, kā Tas Kungs uz viņu bija runājis; bet viņš bijās no sava tēva nama un tās pilsētas vīriem dienā to darīt, un to darīja naktī.
Gideoni mú mẹ́wàá nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, ó sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún un ṣùgbọ́n, nítorí ó bẹ̀rù àwọn ará ilé baba rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ìlú náà kò ṣe é ní ọ̀sán, òru ni ó ṣe.
28 Kad nu tās pilsētas vīri rītā uzcēlās, redzi, tad Baāla altāris bija salauzīts un tas elka stabs nocirsts, kas tur klātu, un tas otrs vērsis uz tā uztaisīta altāra bija upurēts.
Nígbà tí ilẹ̀ ọjọ́ kejì mọ́, tí àwọn ènìyàn ìlú náà jí, wọ́n rí i pé àti fọ́ pẹpẹ Baali àti pé a ti bẹ́ igi ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, a sì ti fi akọ màlúù kejì rú ẹbọ lórí pẹpẹ tí a ṣẹ̀ṣẹ̀ mọ.
29 Tad tie sacīja cits uz citu: kas to darījis? Un kad tie meklēja un izvaicāja, tad tapa sacīts: Gideons, Joasa dēls, to darījis.
Àwọn ènìyàn ìlú náà bi ara wọn wí pé, “Ta ni ó ṣe èyí?” Lẹ́yìn tí wọn fi ara balẹ̀ ṣe ìwádìí, wọ́n gbọ́ wí pé, “Gideoni ọmọ Joaṣi ni ó ṣe é.”
30 Tad tās pilsētas vīri sacīja uz Joasu: izved savu dēlu, jo tam jāmirst, tāpēc ka viņš nolauzis Baāla altāri un to elka stabu nocirtis, kas tur bija klāt.
Àwọn ọkùnrin ìlú náà sì wí fún Joaṣi wí pé, “Mú ọmọ rẹ jáde wá. Ó ní láti kú nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali lulẹ̀ ó sì ti ké ère òrìṣà Aṣerah tí ó wà ní ẹ̀bá rẹ̀ lulẹ̀.”
31 Un Joas sacīja uz visiem, kas pie viņa stāvēja: vai jūs tiesāsities par Baālu? Vai jūs viņu izpestīsiet? Kas par viņu tiesāsies, tam vēl šodien būs tapt nokautam. Ja viņš ir dievs, tad lai viņš pats par sevi tiesājās, tāpēc ka viņa altāris nolauzīts.
Ṣùgbọ́n Joaṣi bi àwọn èrò tí wọ́n fi ìbínú dúró tì í wí pé, “Ẹ̀yin yóò ha gbìjà Baali bí? Ẹ̀yin yóò ha gbà á sílẹ̀ bí? Ẹnikẹ́ni tí ó bá gbìjà rẹ̀ kíkú ni olúwa rẹ̀ yóò kú ní òwúrọ̀. Bí Baali bá ṣe Ọlọ́run nítòótọ́ yóò jà fún ara rẹ̀ bí ẹnikẹ́ni bá wó pẹpẹ rẹ̀ lulẹ̀.”
32 Un tai dienā viņu nosauca JerubBaālu un sacīja: lai Baāls ar viņu tiesājās, ka tas viņa altāri nolauzījis.
Fún ìdí èyí ní ọjọ́ náà wọ́n pe Gideoni ní “Jerubbaali” wí pé, “Jẹ́ kí Baali bá a jà,” nítorí pé ó ti wó pẹpẹ Baali.
33 Bet visi Midijanieši un Amalekieši un tie austruma ļaudis sapulcējās kopā un pārcēlās un apmetās Jezreēles ielejā.
Láìpẹ́ jọjọ, àwọn ogun àwọn Midiani, ti àwọn Amaleki àti ti àwọn ènìyàn ìhà ìlà-oòrùn yòókù kó ara wọn jọ pọ̀ ní ìṣọ̀kan, wọ́n sì kọjá Jordani wọ́n sì tẹ̀dó sí àfonífojì Jesreeli.
34 Tad Tā Kunga Gars nāca uz Gideonu, un viņš pūta trumetē un sasauca Abiēzeriešus sev pakaļ.
Ẹ̀mí Olúwa sì bà lé Gideoni, ó sì fun fèrè ìpè, láti pe àwọn ará Abieseri láti tẹ̀lé òun.
35 Un viņš sūtīja vēstnešus pa visu Manasu; ir tie tapa sasaukti, viņam pakaļ. Un viņš sūtīja vēstnešus pa Ašeru un pa Zebulonu un pa Naftalu un tie nāca viņiem pretī.
Ó rán àwọn oníṣẹ́ la ilẹ̀ Manase já pé kí wọ́n dira ogun, àti sí Aṣeri, Sebuluni àti Naftali gbogbo pẹ̀lú sì lọ láti pàdé wọn.
36 Un Gideons sacīja uz Dievu: ja Tu Israēli gribi izpestīt caur manu roku, kā Tu esi runājis, -
Gideoni wí fún Ọlọ́run pé, “Bí ìwọ yóò bá gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti ṣe ìlérí—
37 Redzi, es nolikšu aitas cirpumu uz klonu; kad rasa būs uz cirpuma vien un pa visu zemi sausums, tad es zināšu, ka Tu Israēli izpestīsi caur manu roku, kā Tu esi sacījis.
kíyèsi, èmi yóò fi awọ irun àgùntàn lé ilẹ̀ ìpakà ní alẹ́ òní. Bí ìrì bá sẹ̀ sí orí awọ yìí nìkan tí gbogbo ilẹ̀ yòókù sì gbẹ, nígbà náà ni èmi yóò mọ̀ lóòótọ́ pé ìwọ yóò gba Israẹli là nípasẹ̀ mi bí ìwọ ti sọ.”
38 Un tā notika. Jo viņš agri no rīta uzcēlās un izspieda to cirpumu un izgrieza rasu no tā cirpuma, vienu kausu pilnu ar ūdeni.
Èyí ni ó sì ṣẹlẹ̀. Nígbà tí Gideoni jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì fún irun àgùntàn náà, ọpọ́n omi kan sì kún.
39 Un Gideons sacīja uz Dievu: lai Tava bardzība pret mani neiedegās, ka vēl reiz' runāju, - es vēl reiz' raudzīšu ar to cirpumu. Lai jel ir sausums uz tā cirpuma vien, un pa visu zemi lai ir rasa.
Gideoni sì tún wí fún Ọlọ́run pé, “Jọ̀wọ́ má ṣe bínú sí mi, ṣùgbọ́n jẹ́ kí n tún wá ìdánilójú kan sí i, èmi bẹ̀ ọ́ jẹ́ kí n fi awọ irun yìí ṣe ìdánwò kan sí i. Ní àsìkò yìí, jẹ́ kí awọ irun yìí gbẹ kí gbogbo ilẹ̀ sì tutù pẹ̀lú ìrì.”
40 Un Dievs tā darīja tanī naktī; un sausums bija uz tā cirpuma vien, un pa visu zemi bija rasa.
Ní òru náà Ọlọ́run ṣe bẹ́ẹ̀, awọ irun àgùntàn nìkan ni ó gbẹ; gbogbo ilẹ̀ yòókù sì tutù nítorí ìrì.

< Sog̒u 6 >