< Sog̒u 10 >

1 Un pēc Abimeleka, Tolus, Dodus dēla Puūs dēls, vīrs no Īsašara cilts, cēlās, Israēli pestīt, un dzīvoja Zamirā Efraīma kalnos.
Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
2 Un viņš tiesāja Israēli divdesmit un trīs gadus un nomira un Zamirā tapa aprakts.
Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
3 Un pēc viņa cēlās Jaīrs, Gileādietis, un tiesāja Israēli divdesmit un divus gadus.
Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
4 Un tam bija trīsdesmit dēli, tie jāja uz trīsdesmit ēzeļiem, un tiem bija trīsdesmit pilsētas, kuras nosauc (par) Jaīra ciemiem līdz šai dienai; tie ir Gileādas zemē.
Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
5 Un Jaīrs nomira un tapa aprakts Kamonā.
Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
6 Tad Israēla bērni joprojām darīja, kas Tam Kungam nepatika, un kalpoja Baāliem un Astartēm un Sīriešu dieviem un Sidonas dieviem un Moaba dieviem un Amona bērnu dieviem un Fīlistu dieviem un atstāja To Kungu un nekalpoja Viņam.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
7 Tad Tā Kunga dusmība iedegās pret Israēli un Viņš tos pārdeva Fīlistu rokā un Amona bērnu rokā.
ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
8 Un tie satrieca un samina Israēla bērnus no tā gada iesākot astoņpadsmit gadus, visus Israēla bērnus, kas viņpus Jardānes bija, Amoriešu zemē, tas ir Gileādā.
Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
9 Un Amona bērni gāja pār Jardāni un karoja pret Jūdu un pret Benjaminu un pret Efraīma namu, tā ka Israēlim bija ļoti bail.
Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
10 Tad Israēla bērni brēca uz To Kungu un sacīja: mēs pret Tevi esam grēkojuši, jo mēs savu Dievu esam atstājuši un kalpojuši Baāliem.
Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
11 Bet Tas Kungs sacīja uz Israēla bērniem: vai Es jūs neesmu izpestījis no ēģiptiešiem un Amoriešiem un Amona bērniem un Fīlistiem
Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
12 Un Sidoniešiem un Amalekiešiem un Maoniešiem, kad tie jūs spaidīja, un jūs uz Mani brēcāt?
àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
13 Tomēr jūs Mani esat atstājuši un kalpojuši citiem dieviem, tādēļ Es jūs vairs negribu izpestīt.
Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
14 Ejat un brēciet uz saviem dieviem, ko jūs esat izmeklējušies, lai tie jūs izpestī jūsu bēdu laikā.
Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
15 Bet Israēla bērni sacīja uz To Kungu: mēs esam grēkojuši; dari Tu mums, itin kā Tev patīk, izglāb mūs tikai šo reiz'.
Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
16 Un tie meta nost no sevis tos svešos dievus un kalpoja Tam Kungam. Tad Viņam palika žēl par Israēla bēdām.
Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
17 Un Amona bērni tapa sasaukti un apmetās Gileādā un Israēla bērni sapulcējās un apmetās Micpā.
Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
18 Tad tie ļaudis, Gileādas virsnieki, cits uz citu sacīja: kas būs tas vīrs, kas sāks karot pret Amona bērniem. Tam būs galvai būt pār visiem Gileādas iedzīvotājiem.
Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”

< Sog̒u 10 >