< Jozuas 9 >
1 Un kad to dzirdēja visi ķēniņi, kas viņpus Jardānes bija, kalnos un ielejās un gar visu lielās jūras malu, Lībanum pretī, Hetieši un Amorieši, Ferezieši, Hivieši un Jebusieši,
Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
2 Tad tie sapulcējās visi kopā, kauties ar Jozua un ar Israēli.
wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
3 Kad nu Gibeonas iedzīvotāji dzirdēja, ko Jozuas bija darījis ar Jēriku un ar Aju, tad tie arīdzan darīja viltu
Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
4 Un nogāja un likās vēstneši ejoši un ņēma vecus maisus uz saviem ēzeļiem,
wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
5 Un vecus saplīsušus un lāpītus ādas vīna traukus, arī vecas un lāpītas kurpes savās kājās, un tiem bija arī vecas drēbes mugurā, un visa viņu ceļamaize bija sakaltusi un sapelējusi.
Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
6 Un tie gāja pie Jozuas Gilgalas lēģerī un sacīja uz to un uz Israēla vīriem: mēs no tālas zemes esam nākuši; tad dariet nu ar mums derību.
Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
7 Tad Israēla vīri sacīja uz to Hivieti: varbūt, ka tu dzīvo mūsu vidū, kā tad mēs ar tevi varam darīt derību?
Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
8 Tad tie sacīja uz Jozua: mēs esam tavi kalpi. Tad Jozuas uz tiem sacīja: kas jūs esat un no kurienes jūs nākat?
“Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
9 Tie uz viņu sacīja: tavi kalpi nākuši no varen tālas zemes, Tā Kunga, tava Dieva, vārda dēļ; jo mēs esam dzirdējuši Viņa slavu un visu, ko Viņš darījis Ēģiptes zemē.
Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
10 Un visu, ko Viņš darījis tiem diviem Amoriešu ķēniņiem, kas viņpus Jardānes bija, Sihonam, Hešbonas ķēniņam, un Ogam, Basanas ķēniņam, kas Astarotā dzīvoja.
àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
11 Tāpēc mūsu vecaji un visi, kas mūsu zemē dzīvo, uz mums runāja un sacīja: ņemiet savās rokās ceļamaizi un ejat viņiem pretī un sakāt uz tiem: mēs esam jūsu kalpi; un nu dariet ar mums derību.
Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
12 Šo savu maizi mēs jaunu no savām mājām uz ceļu esam paņēmuši līdz, tai dienā, kad mēs izgājām pie jums nākt, bet redzi, nu tā sakaltusi un sapelējusi.
Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
13 Un šie ādas vīna trauki, ko mēs pildījām, bija jauni, bet redzi, tie ir saplīsuši un šīs mūsu drēbes un mūsu kurpes ir vecas palikušas no tā varen tālā ceļa.
Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
14 Tad tie vīri ņēma no viņu ceļamaizes un nevaicāja Tā Kunga muti.
Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
15 Un Jozuas derēja mieru ar tiem un darīja derību ar tiem, tos atstāt dzīvus, un tie draudzes virsnieki tiem zvērēja.
Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
16 Un pēc trim dienām, kad tie derību ar tiem bija darījuši, tad tie dzirdēja, viņus no tuvienes esam un dzīvojam viņu vidū.
Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
17 Jo kad Israēla bērni cēlās, tad tie nāca trešā dienā pie viņu pilsētām. Bet viņu pilsētas bija Gibeona, Kavira un Beērote un Kiriat-Jearima.
Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
18 Un Israēla bērni tos nekāva, tāpēc ka draudzes virsnieki tiem bija zvērējuši pie Tā Kunga, Israēla Dieva; tāpēc visa draudze kurnēja pret tiem virsniekiem.
Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
19 Tad visi tie virsnieki uz visu draudzi sacīja: mēs pie Tā Kunga, Israēla Dieva, tiem esam zvērējuši, tāpēc mēs tos nu nevaram aizskart.
ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
20 Bet mēs tiem darīsim tā: pametīsim tos dzīvus, ka nekāda dusmība pār mums nenāk tā zvēresta dēļ, ko mēs tiem esam zvērējuši.
Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
21 Tad tie virsnieki uz tiem sacīja: lai paliek dzīvi; un tie bija malkas cirtēji un ūdens smēlēji visai draudzei, kā tie virsnieki tiem bija runājuši.
Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
22 Un Jozuas tos aicināja un uz tiem runāja sacīdams: kāpēc jūs mūs esat pievīluši sacīdami, mēs esam ļoti tālu no jums, - un jūs tomēr mūsu vidū dzīvojat?
Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
23 Nu tad esat nolādēti, ka no jums netrūkst kalpu un malkas cirtēju un ūdens smēlēju priekš mūsu Dieva nama.
Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
24 Tie atbildēja Jozuam un sacīja: taviem kalpiem tapa stāstīts, ko Tas Kungs, tavs Dievs, Mozum Savam kalpam, ir pavēlējis, ka Viņš jums visu to zemi grib dot, un visus tos, kas tai zemē dzīvo, no jūsu priekšas izdeldēt, tad mēs savas dzīvības dēļ ļoti bijāmies no jums un tā darījām.
Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
25 Un nu redzi, mēs esam tavā rokā, dari mums, tā kā darīt tavās acīs rādās labi un taisni.
Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
26 Tad viņš tiem tā darīja un tos izglāba no Israēla bērnu rokas, ka tie tos nenokāva.
Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
27 Un Jozuas tai dienā tos nodeva draudzei par malkas cirtējiem un ūdens smēlējiem un priekš Tā Kunga altāra līdz šai dienai tai vietā, ko Viņš izredzētu.
Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.