< Jonas 3 >

1 Un Tā Kunga vārds notika otru reizi uz Jonu sacīdams:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé:
2 Celies, ej uz Ninivi, to lielo pilsētu, un sludini pret viņu to sludināšanu, ko Es tev sacīšu.
“Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”
3 Tad Jona cēlās un gāja uz Ninivi pēc Tā Kunga vārda. Bet Ninive bija liela Dieva pilsēta treju dienu gājumu.
Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta.
4 Un Jona sāka pilsētā iet vienas dienas gājumu un sludināja un sacīja: vēl četrdesmit dienas, tad Ninive taps apgāzta.
Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.”
5 Tad Ninives ļaudis ticēja uz Dievu un izsauca gavēni un apģērbās ar maisiem, gan lieli, gan mazi.
Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.
6 Un kad tas vārds Ninives ķēniņa priekšā nāca, tad viņš cēlās no sava goda krēsla un nolika savas ķēniņa drēbes no sevis un apvilka maisu un apsēdās pelnos.
Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú.
7 Un viņš lika izsaukt un sludināt Ninivē ķēniņa un viņa lielkungu pavēli: lai ne cilvēks, ne lops, ne vērsis, ne avs nekā nebauda, lai neiet ganos un nedzer ūdeni.
Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé, “Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé: “Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò, má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi.
8 Bet cilvēki un lopi lai sedzās ar maisiem un Dievu gauži piesauc, un lai tie atgriežas ikviens no sava ļaunā ceļa un no tā varas darba, kas viņu rokās.
Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn.
9 Varbūt ka Dievs atgriezīsies, un Viņam būs žēl un atkāpsies no Savas dusmības karstuma, ka mēs neejam bojā.
Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”
10 Un Dievs redzēja viņu darbus, ka tie atgriezās no sava niknā ceļa, un Dievam palika žēl viss tas ļaunums, ko Viņš bija runājis, tiem darīt, un to nedarīja.
Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn, Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.

< Jonas 3 >