< Jāņa Evaņg̒elijs 1 >

1 Iesākumā bija Vārds, un Vārds bija pie Dieva, un Dievs bija Vārds.
Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
2 Tas bija iesākumā pie Dieva.
Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
3 Visas lietas ir darītas caur Viņu, un bez Viņa nekas nav darīts, kas ir darīts.
Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
4 Iekš Viņa bija dzīvība, un tā dzīvība bija cilvēku gaišums.
Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
5 Un tas gaišums spīd tumsībā, un tumsība to nesaņēma.
ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
6 Viens cilvēks bija no Dieva sūtīts, Jānis vārdā.
Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
7 Tas nāca liecības dēļ, ka dotu liecību par To Gaišumu, lai visi caur to ticētu.
Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
8 Viņš pats nebija tas gaišums, bet ka tas liecību dotu par To Gaišumu.
Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
9 Tam patiesam Gaišumam, kas ikvienu cilvēku apgaismo, bija nākt pasaulē.
Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
10 Viņš bija pasaulē, un pasaule ir caur Viņu darīta; bet pasaule Viņu nepazina.
Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
11 Viņš nāca pie tiem savējiem, un šie Viņu neuzņēma.
Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
12 Bet cik Viņu uzņēma, tiem Viņš deva vaļu, palikt par Dieva bērniem, tiem, kas tic uz Viņa Vārdu,
Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
13 Kas ne no asinīm, nedz no miesas gribēšanas, nedz pēc kāda vīra prāta, bet kas no Dieva dzimuši.
Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
14 Un tas Vārds tapa miesa un dzīvoja mūsu starpā, pilns žēlastības un patiesības, un mēs redzējām Viņa godību, tādu godību, kā Tā vienpiedzimušā Dēla no Tā Tēva.
Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
15 Jānis dod liecību par Viņu un sauc sacīdams: “Šis bija Tas, par ko es sacīju: kas nāk pēc manis, Tas ir bijis priekš manis. Viņš bija pirmāk nekā es.”
Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
16 Un no Viņa pilnuma mēs visi esam dabūjuši žēlastību uz žēlastību.
Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
17 Jo bauslība ir dota caur Mozu, žēlastība un patiesība ir notikusi caur Jēzu Kristu.
Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
18 Dievu neviens nekad nav redzējis: tas vienpiedzimušais Dēls, Tēva klēpī būdams, Tas mums to ir stāstījis.
Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
19 Un šī ir Jāņa liecība, kad tie Jūdi no Jeruzālemes priesterus un levitus sūtīja, lai tam jautā: “Kas tu esi?”
Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
20 Un viņš apliecināja un neliedzās, un apliecināja: “Es neesmu Kristus.”
Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
21 Un tie tam jautāja: “Kas tad? Vai tu esi Elija?” Un viņš saka: “Neesmu.” “Vai tu esi tas Pravietis?” Un viņš atbildēja: “Nē”.
Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
22 Tad tie uz viņu sacīja: “Kas tu esi? lai atbildam tiem, kas mūs sūtījuši; ko tu saki par sevi pašu?”
Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
23 Viņš sacīja: “Es esmu saucēja balss tuksnesī: sataisiet Tā Kunga ceļu, kā pravietis Jesaja sacījis.”
Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
24 Un tie izsūtītie bija no tiem farizejiem.
Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
25 Un tie viņam jautāja un uz viņu sacīja: “Kāpēc tad tu kristi, kad tu neesi Tas Kristus, nedz Elija, nedz tas Pravietis?”
bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
26 Jānis tiem atbildēja un sacīja: “Es kristīju ar ūdeni; bet Tas jūsu vidū iestājies, ko jūs nepazīstat;
Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
27 Tas nāk pēc manis, un ir bijis priekš manis, Tam es neesmu cienīgs kurpju siksnas atraisīt.”
Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
28 Tas notika Betanijā viņpus Jardānes upes, kur Jānis kristīja.
Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
29 Otrā dienā Jānis Jēzu ierauga nākam un saka: “Redzi, Tas Dieva Jērs, kas nes pasaules grēkus.
Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
30 Šis ir Tas, par ko es esmu sacījis: pēc manis nāk vīrs, kas bijis priekš manis: jo Viņš bija pirmāk nekā es.
Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
31 Un es Viņu nepazinu: bet lai Viņš Israēlim taptu zināms, tāpēc es esmu nācis, kristīdams ar ūdeni.”
Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
32 Un Jānis deva liecību sacīdams: “Es redzēju to Garu nolaižamies no debess kā balodi un paliekam uz Viņa.
Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
33 Un es Viņu nepazinu, bet kas mani sūtījis kristīt ar ūdeni, Tas uz mani sacīja: uz ko tu redzēsi to Garu nolaižamies un paliekam, šis ir Tas, kas kristī ar Svēto Garu.
Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
34 Un es esmu redzējis un liecību devis, ka šis ir Tas Dieva Dēls.”
Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
35 Otrā dienā Jānis atkal stāvēja un divi no viņa mācekļiem,
Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
36 Un ieraudzījis Jēzu staigājam, viņš saka: “Redzi, Tas Dieva Jērs!”
Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
37 Un tie divi mācekļi viņu dzirdēja runājam un Jēzum gāja pakaļ.
Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
38 Un Jēzus atgriezdamies un tos redzējis pakaļ nākam, uz tiem saka: “Ko jūs meklējat?” Un tie uz Viņu sacīja: “Rabbi, (tas ir tulkots: mācītājs, ) kur Tu mājo?”
Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
39 Viņš uz tiem saka: “Nāciet un redziet.” Tie nāca un redzēja, kur Viņš mājoja, un palika to dienu pie Viņa, un tas bija ap desmito stundu.
Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
40 Andrejs, Sīmaņa Pētera brālis, bija viens no tiem diviem, kas to no Jāņa bija dzirdējuši un Viņam gājuši pakaļ.
Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
41 Šis pirmais atrod savu brāli Sīmani un uz to saka: “Mēs to Mesiju esam atraduši (tas ir tulkots: Kristus).”
Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
42 Un viņš to veda pie Jēzus. Un Jēzus to uzlūkoja un sacīja: “Tu esi Sīmanis, Jonas dēls, tu tapsi saukts Kefas, tas ir tulkots: Pēteris (akmens).”
Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
43 Otrā dienā Jēzus gribēja iziet uz Galileju un atrod Filipu un uz to saka: “Nāc Man pakaļ.”
Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
44 Un Filips bija no Betsaidas, Andreja un Pētera pilsētas.
Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
45 Filips atrod Natanaēli un uz to saka: “Par ko Mozus bauslībā rakstījis un tie pravieši, To mēs esam atraduši, Jēzu no Nacaretes, Jāzepa dēlu.”
Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
46 Un Natanaēls uz to sacīja: “Vai no Nacaretes var būt kāds labums?” Filips uz to saka: “Nāc un redzi!”
Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
47 Jēzus redzēja Natanaēli nākam, un par to saka: “Redzi, patiesi viens Israēlietis, iekš kā viltības nav.”
Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
48 Natanaēls uz Viņu saka: “Kā Tu mani pazīsti?” Jēzus atbildēja un uz to sacīja: “Es tevi redzēju, pirms Filips tevi aicināja, kad tu biji apakš tā vīģes koka.”
Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
49 Natanaēls atbildēja un uz Viņu saka: “Rabbi, Tu esi Dieva Dēls, Tu esi Israēla Ķēniņš.”
Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
50 Jēzus atbildēja un uz to sacīja: “Tādēļ tu tici, ka Es tev esmu sacījis: Es tevi redzēju apakš tā vīģes koka. Tu redzēsi lielākas lietas nekā tās.”
Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
51 Un Viņš uz to saka: “Patiesi, patiesi, Es jums saku: no šī laika jūs redzēsiet debesis atvērtas un Dieva eņģeļus uzkāpjam un nokāpjam uz To Cilvēka Dēlu.”
Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”

< Jāņa Evaņg̒elijs 1 >