< Jeremijas 42 >

1 Tad visi kara virsnieki, Jehohanans, Kareūs dēls, un Jaazanija, Ozajas dēls, un visi ļaudis, mazi un lieli, piegāja
Nígbà náà ní gbogbo àwọn olórí ogun àti Johanani ọmọkùnrin Karea àti Jesaniah ọmọkùnrin Hoṣaiah àti kékeré títí dé orí ẹni ńlá wá.
2 Un sacīja uz pravieti Jeremiju: lai jel mūsu sirsnīgā lūgšana tev ir pieņēmīga, un lūdz mūsu dēļ To Kungu, savu Dievu, par šiem atlikušiem, jo no daudziem mēs mazums esam atlikušies, kā tavas acis mūs redz,
Sí ọ̀dọ̀ Jeremiah wòlíì náà, wọ́n sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wa, kí o sì gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ fún gbogbo ìyókù yìí. Nítorí gẹ́gẹ́ bi ìwọ ṣe rí i nísinsin yìí pé a pọ̀ níye nígbà kan rí; ṣùgbọ́n báyìí àwa díẹ̀ la ṣẹ́kù.
3 Ka Tas Kungs, tavs Dievs, mums darītu zināmu to ceļu, pa ko mums jāstaigā un to vārdu, pēc kā mums jādara!
Gbàdúrà pé kí Olúwa Ọlọ́run rẹ sọ ibi tí àwa yóò lọ fún wa àti ohun tí àwa yóò ṣe.”
4 Un pravietis Jeremija uz tiem sacīja: es paklausīšu, redzi, es pielūgšu To Kungu, jūsu Dievu, pēc jūsu vārdiem, un visu, ko Tas Kungs atbildēs, to es jums sacīšu un nekā neslēpšu.
Wòlíì Jeremiah sì dáhùn wí pé, “Mo ti gbọ́. Èmi yóò gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run yín gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin ṣe béèrè. Èmi yóò sọ gbogbo ohun tí Olúwa bá sọ fún un yín, ń kò sì ní fi ohunkóhun pamọ́ fún un yín.”
5 Tad tie sacīja uz Jeremiju: lai Tas Kungs pret mums ir patiesīgs un taisns liecinieks, ja mēs nedarīsim pēc ikkatra vārda, ko Tas Kungs, tavs Dievs, mums pavēlēs.
Nígbà náà ni wọ́n sọ fún Jeremiah wí pé, “Kí Olúwa ṣe ẹlẹ́rìí òtítọ́ àti òdodo láàrín wa, bí àwa kò bá ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo ohun tí Olúwa Ọlọ́run rẹ bá rán ọ láti sọ fún wa.
6 Lai būtu labs, lai ļauns, mēs klausīsim Tā Kunga, sava Dieva balsij, pie kā mēs tevi sūtam; lai mums labi klājās, kad mēs Tā Kunga, sava Dieva, balsij klausīsim.
Ìbá à ṣe rere, ìbá à ṣe búburú, àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, èyí tí àwa ń rán ọ sí, kí ó ba à lè dára fún wa. Nítorí pé àwa yóò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa.”
7 Un pēc desmit dienām Tā Kunga vārds notika uz Jeremiju.
Lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́wàá, ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá,
8 Tad viņš aicināja Jehohananu, Kareūs dēlu, un visus kara virsniekus, kas bija pie viņa, un visus ļaudis, mazus un lielus.
O sì pe Johanani ọmọkùnrin Karea àti gbogbo àwọn olórí ogun tí wọ́n wà pẹ̀lú rẹ̀; àti gbogbo àwọn ènìyàn láti orí ẹni tí ó kéré dé orí ẹni ńlá.
9 Un viņš uz tiem sacīja: tā saka Tas Kungs, Israēla Dievs, pie kā jūs mani esat sūtījuši, jūsu lūgšanu nest priekš Viņa vaiga.
Ó sì wí fún wọn pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli wí: ‘Èyí ni ẹni tí ẹ̀yin ti rán láti gbé ẹ̀bẹ̀ yín lọ síwájú mi.
10 Ja jūs paliksiet dzīvot šai zemē, tad Es jūs gribu uztaisīt un nenolauzīt, Es jūs gribu dēstīt un neizraut, jo Man jau ir žēl tā ļaunuma, ko Es jums esmu darījis.
Bí ẹ̀yin bá gbé ní ilẹ̀ yìí, èmi yóò gbé e yín ró, n kò sí ní fà yín lulẹ̀, èmi yóò gbìn yín, n kì yóò fà yín tu nítorí wí pé èmi yí ọkàn padà ní ti ibi tí mo ti ṣe sí i yín.
11 Nebīstaties no Bābeles ķēniņa, no kā vaiga jūs bīstaties; nebīstaties no viņa, saka Tas Kungs; jo Es esmu ar jums, jūs atpestīt un jūs izglābt no viņa rokas.
Ẹ má ṣe bẹ̀rù ọba Babeli tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù, báyìí ẹ má ṣe bẹ̀rù rẹ̀ ni Olúwa wí; nítorí tí èmi wà pẹ̀lú yín láti pa yín mọ́ àti láti gbà yín ní ọwọ́ rẹ̀.
12 Un Es jums došu žēlastību, ka viņš par jums apžēlojās un jūs atkal atlaiž uz jūsu zemi.
Èmi yóò fi àánú hàn sí i yín, kí ó lè ṣàánú fún un yín, kí ó sì mú un yín padà sí ilẹ̀ yín.’
13 Bet ja jūs sacīsiet: mēs šai zemē negribam palikt, un neklausīsiet Tā Kunga, sava Dieva, balsij,
“Ṣùgbọ́n sá, bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Àwa kò ní gbé ilẹ̀ yìí,’ ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn sí Olúwa Ọlọ́run yín.
14 Un sacīsiet: Nē, bet mēs iesim uz Ēģiptes zemi, kur neredzēsim karu un nedzirdēsim trumetes balsi, nedz būsim izsalkuši pēc maizes, un tur mēs gribam dzīvot,
Àti pé bí ẹ̀yin bá wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́, àwa yóò lọ gbé ní Ejibiti; níbi tí àwa kì yóò rí ìró ogunkógun, tí a kì yóò sì gbọ́ ìró fèrè, tí ebi oúnjẹ kì yóò sì pa wá, níbẹ̀ ni àwa ó sì máa gbé,’
15 Nu tad klausiet Tā Kunga vārdu, jūs atlikušie no Jūda! Tā saka Tas Kungs Cebaot, Israēla Dievs: ja jūs savu vaigu griezīsiet, iet uz Ēģipti un iesiet tur piemājot, -
nítorí náà, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ìyókù Juda èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: ‘Bí ẹ̀yin bá pinnu láti lọ sí Ejibiti láti lọ ṣe àtìpó níbẹ̀.
16 Tad tas zobens, no kā jūs bīstaties, jūs panāks Ēģiptes zemē, un tas bads, par ko jūs bēdājaties, jums tur noies pakaļ, un jūs tur nomirsiet.
Yóò sì ṣe, idà tí ẹ̀yin bẹ̀rù yóò sì lé e yín bá níbẹ̀; àti ìyanu náà tí ẹ̀yin ń bẹ̀rù yóò sì tẹ̀lé yín lọ sí Ejibiti àti pé ibẹ̀ ni ẹ̀yin yóò kú sí.
17 Tā visiem vīriem, kas savu vaigu griež, iet uz Ēģipti, tur piemājot, būs mirt caur zobenu un caur badu un caur mēri, un no tiem neviens neatliks un neizbēgs no tā ļaunuma, ko Es pār tiem vedīšu.
Nítorí náà, gbogbo àwọn tí ó ti pinnu láti ṣe àtìpó ní Ejibiti ni yóò ti ipa idà kú, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn kò sì ní jẹ́ kí ẹnikẹ́ni nínú wọn yè tàbí sá àsálà nínú ibi tí èmi yóò mú wá sórí wọn.’
18 Jo tā saka Tas Kungs Cebaot, Israēla Dievs: tā kā Mana dusmība un Mana bardzība ir izgāzta pār Jeruzālemes iedzīvotājiem, tā Mana bardzība pār jums izgāzīsies, kad jūs iesiet uz Ēģipti, un jūs būsiet par lāstu un briesmām un par apsmieklu un kaunu, un vairs neredzēsiet šo vietu.
Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí èmi ti da ìbínú àti ìrunú síta sórí àwọn tí ó ń gbé ní Jerusalẹmu, bẹ́ẹ̀ ni ìrunú mi yóò dà síta sórí yín, nígbà tí ẹ̀yin bá lọ sí Ejibiti. Ẹ̀yin ó sì di ẹni ègún àti ẹni ẹ̀gàn àti ẹ̀sín, ẹ̀yin kì yóò sì rí ibí yìí mọ́.’
19 Tas Kungs pret jums runājis, jūs atlikušie no Jūda: neejat uz Ēģipti. Ziniet zinādami, ka es šodien pret jums esmu liecību devis.
“Ẹ̀yin yòókù Juda, Olúwa ti sọ fún un yín pé, ‘Kí ẹ má ṣe lọ sí Ejibiti.’ Ẹ mọ èyí dájú, èmi kìlọ̀ fún un yín lónìí,
20 Jo jūs pieviļat savas dvēseles: Jūs mani esat sūtījuši pie Tā Kunga, sava Dieva, un sacījuši: lūdz par mums To Kungu, mūsu Dievu, un tā kā Tas Kungs, mūsu Dievs, sacīs, tā mums to dari zināmu, un mēs to gribam darīt.
pé àṣìṣe ńlá gbá à ni ẹ̀yin ṣe nígbà tí ẹ̀yin rán mi sí Olúwa Ọlọ́run yín pé, ‘Gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa; sọ fún wa gbogbo ohun tí ó bá sọ, àwa yóò sì ṣe é.’
21 Nu es jums to esmu sacījis, bet jūs neklausāt Tā Kunga, sava Dieva, balsij, nedz tam, ar ko Viņš mani pie jums sūtījis.
Mo ti sọ fún un yín lónìí, ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹ̀yin kò tí ì gbọ́ ohùn Olúwa Ọlọ́run yín, àti gbogbo ohun tí ó rán mi láti sọ fún un yín.
22 Tad ziniet nu, ka jūs caur zobenu, caur badu un caur mēri mirsiet tai vietā, kurp gribat iet, tur piemājot.
Ǹjẹ́ nísinsin yìí ẹ mọ èyí dájú pé, ẹ̀yin yóò kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn níbikíbi tí ẹ̀yin bá fẹ́ lọ láti ṣe àtìpó.”

< Jeremijas 42 >