< Jeremijas 4 >

1 Ja tu atgriezīsies, Israēl, saka Tas Kungs, pie Manis atgriezīsies, un ja tu savas negantības Manā priekšā atstāsi un neskraidīsi apkārt,
“Tí ìwọ yóò bá yí padà, ìwọ Israẹli, padà tọ̀ mí wá,” ni Olúwa wí. “Tí ìwọ yóò bá sì mú ìríra rẹ kúrò níwájú mi, ìwọ kí ó sì rìn kiri.
2 Un ja tu zvērēsi: „tik tiešām kā Tas Kungs dzīvo!“Ar patiesību, ar tiesu un ar taisnību, tad tautas iekš viņa svētīsies un ar viņu lielīsies.
Tí ó bá jẹ́ lóòtítọ́ àti òdodo ni ìwọ búra. Nítòótọ́ bí Olúwa ti wà láààyè, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò di alábùkún fún nípasẹ̀ rẹ, àti nínú rẹ̀ ni wọn yóò ṣògo.”
3 Jo tā saka Tas Kungs uz Jūda un Jeruzālemes vīriem: ariet sev jaunu zemi un nesējat ērkšķos.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí fún àwọn ènìyàn Juda àti Jerusalẹmu: “Hú gbogbo ilẹ̀ tí ẹ kò lò rí, kí o má sì ṣe gbìn sáàrín ẹ̀gún.
4 Apgraizaties Tam Kungam un atņemat nost savas sirds priekšādu, Jūda vīri un Jeruzālemes iedzīvotāji, ka Mana bardzība neizšaujās kā uguns un nedeg, ka neviens nevar dzēst, jūsu nedarbu dēļ.
Kọ ara rẹ ní ilà sí Olúwa, kọ ọkàn rẹ ní ilà, ẹ̀yin ènìyàn Juda àti gbogbo ènìyàn Jerusalẹmu, bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ìbínú mi yóò ru jáde yóò sì jó bí iná, nítorí ibi tí o ti ṣe kì yóò sí ẹni tí yóò pa á.
5 Sludinājiet Jūdā un Jeruzālemē, liekat to dzirdēt un stāstiet, bazūnējat ar bazūni tai zemē, sauciet ar pilnu muti un sakāt: sapulcinājaties un iesim stiprās pilsētās.
“Kéde ní Juda, kí o sì polongo ní Jerusalẹmu, kí o sì wí pé: ‘Fun fèrè káàkiri gbogbo ilẹ̀!’ Kí o sì kígbe: ‘Kó ara jọ pọ̀! Jẹ́ kí a sálọ sí ìlú olódi.’
6 Paceļat karogu uz Ciānu, bēgat, nestāvat. Jo Es atvedu nelaimi no ziemeļa puses un lielu postu.
Fi àmì láti sálọ sí Sioni hàn, sálọ fún ààbò láìsí ìdádúró. Nítorí èmi ó mú àjálù láti àríwá wá, àní ìparun tí ó burú jọjọ.”
7 Lauva ceļas no sava biezuma, un tautu maitātājs nāk; viņš ir izgājis no savas vietas, tavu zemi darīt tukšu, lai tavas pilsētas top izpostītas, ka neviens tur vairs nedzīvo.
Kìnnìún ti sá jáde láti inú ibùgbé rẹ̀, apanirun orílẹ̀-èdè sì ti jáde. Ó ti fi ààyè rẹ̀ sílẹ̀ láti ba ilẹ̀ rẹ̀ jẹ́. Ìlú rẹ yóò di ahoro láìsí olùgbé.
8 Tādēļ apjoziet maisus, žēlojaties un kauciet, jo Tā Kunga bardzības karstums no mums neatstājās.
Nítorí náà, gbé aṣọ ọ̀fọ̀ wọ̀ káàánú kí o sì pohùnréré ẹkún, nítorí ìbínú ńlá Olúwa kò tí ì kúrò lórí wa.
9 Tai dienā, saka Tas Kungs, iznīks ķēniņa sirds drošība un lielo kungu sirds drošība, un priesteri izbīsies, un pravieši iztrūcināsies.
“Ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa wí pé, “Àwọn ọba àti ìjòyè yóò pàdánù ẹ̀mí wọn, àwọn àlùfáà yóò wárìrì, àwọn wòlíì yóò sì fòyà.”
10 Tad es sacīju: ak Kungs, Dievs! Patiesi, šiem ļaudīm un Jeruzālemei Tu esi ļāvis kļūt lielā viltū, ka sacīja: jums būs miers! Kur tomēr zobens sniedzās līdz pat dvēselei.
Nígbà náà ni mo sì wí pé, “Háà! Olúwa Olódùmarè, báwo ni ìwọ ti ṣe tan àwọn ènìyàn wọ̀nyí àti Jerusalẹmu jẹ nípa sísọ wí pé, ‘Ìwọ yóò wà ní àlàáfíà,’ nígbà tí o jẹ́ wí pé idà wà ní ọ̀fun wa.”
11 Tanī laikā sacīs uz šiem ļaudīm un uz Jeruzālemi: sauss vējš nāk no augstiem tuksneša kalniem pret Manu tautu, ne vētīšanas, ne tīrīšanas pēc.
Nígbà náà ni a ó sọ fún Jerusalẹmu àti àwọn ènìyàn pé, “Ẹ̀fúùfù líle láti aṣálẹ̀ fẹ́ lu àwọn ènìyàn mi, kì í ṣe láti sọ di mímọ́.
12 Vējš Man nāks, kas stiprāks būs nekā viņi, tad arī Es nesīšu tiesu pret viņiem.
Ẹ̀fúùfù líle tí ó wá láti ọ̀dọ̀ mi. Báyìí mo kéde ìdájọ́ mi lórí wọn.”
13 Redzi, viņš cēlās kā debesis, un viņa rati ir kā viesulis, viņa zirgi ir čaklāki nekā ērgļi, - ak vai, mums, jo mēs esam postā!
Wò ó! O ń bọ̀ bí ìkùùkuu kẹ̀kẹ́ ogun rẹ̀ sì wá bí ìjì líle ẹṣin rẹ̀ sì yára ju idì lọ. Ègbé ni fún wa àwa parun.
14 Mazgā savu sirdi no ļaunuma, Jeruzāleme, ka topi izglābta; cik ilgi tu savas nelietības domas glabāsi savā sirdī?
Ìwọ Jerusalẹmu, mú búburú kúrò lọ́kàn rẹ kí o sì yè. Yóò ti pẹ́ tó tí ìwọ yóò mú èrò búburú wà ní ọkàn rẹ?
15 Jo balss sludina no Dana un ziņo bēdas no Efraīma kalniem.
Ohùn kan sì ń kéde ní Dani o ń kókìkí ìparun láti orí òkè Efraimu wá.
16 Dariet pagāniem zināmu, redzi, sludinājiet par Jeruzālemi: sargi nāk no tālas zemes, un tie paceļ savu balsi pret Jūda pilsētām.
“Sọ èyí fún àwọn orílẹ̀-èdè, kéde rẹ̀ fún Jerusalẹmu pé: ‘Ọmọ-ogun ọ̀tá ń bọ̀ láti ilẹ̀ jíjìn wá wọ́n sì ń kígbe ogun láti dojúkọ ìlú Juda.
17 Kā sargi ap tīrumu, tā tie būs visapkārt pret viņu, tādēļ ka tā pret Mani cēlusies, saka Tas Kungs.
Wọ́n yí i ká bí ìgbà tí àwọn ọkùnrin bá ń ṣọ́ pápá, nítorí pé ó ti dìtẹ̀ sí mi,’” ni Olúwa wí.
18 Tavs ceļš un tavi nedarbi tev to padara; tā ir tava blēdība, kas tik rūgta, ka tā sniedzās līdz pat tavai sirdij.
“Ìwà rẹ àti ìṣe rẹ ló fa èyí bá ọ ìjìyà rẹ sì nìyìí. Báwo ló ti ṣe korò tó! Báwo ló ti ṣe gún ọkàn rẹ sí!”
19 Ak manas iekšas, manas iekšas! Kā bērnu sāpes man spiežas caur manu sirdi, mana sirds lec iekš manis, es nevaru klusu ciest, jo mana dvēsele dzird bazūnes skaņu un kara troksni.
Háà! Ìrora mi, ìrora mi! Mo yí nínú ìrora. Háà, ìrora ọkàn mi! Ọkàn mi lù kìkì nínú mi, n kò le è dákẹ́. Nítorí mo ti gbọ́ ohùn ìpè, mo sì ti gbọ́ igbe ogun.
20 Posts pār postu tiek daudzināts. Jo visa zeme ir postīta, piepeši ir postīti mani dzīvokļi, acumirklī manas teltis.
Ìparun ń gorí ìparun; gbogbo ilẹ̀ náà sì ṣubú sínú ìparun lọ́gán ni a wó àwọn àgọ́ mi, tí ó jẹ́ ohun ààbò mi níṣẹ́jú kan.
21 Cik ilgi jel man būs redzēt karogu, dzirdēt bazūnes skaņu?
Yóò ti pẹ́ tó, tí èmi yóò rí ogun tí èmi yóò sì gbọ́ ìró fèrè?
22 Tiešām, mani ļaudis ir traki un mani nepazīst; tie ir ģeķīgi bērni un neprātīgi. Tie gan ir gudri, ļaunu darīt, bet labu darīt tie nemāk.
“Aṣiwèrè ni àwọn ènìyàn mi; wọn kò mọ̀ mí. Wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n ọmọ; wọ́n sì jẹ́ aláìlóye. Wọ́n mọ ibi ni ṣíṣe; wọn kò mọ bí a ti í ṣe rere.”
23 Es uzlūkoju zemi, un redzi, tā ir tumša un tukša, - un debesi, un viņai nav sava gaišuma.
Mo bojú wo ayé, ó sì wà ní júujùu, ó sì ṣófo àti ní ọ̀run, ìmọ́lẹ̀ wọn kò sì ṣí.
24 Es uzlūkoju kalnus, un redzi, tie dreb, un visi kalni trīc.
Mo wo àwọn òkè ńlá, wọ́n wárìrì; gbogbo òkè kéékèèké mì jẹ̀jẹ̀.
25 Es lūkoju, un redzi, neviena cilvēka nav, un visi putni apakš debess ir aizskrējuši.
Mo wò yíká n kò rí ẹnìkan; gbogbo ẹyẹ ojú ọ̀run ló ti fò lọ.
26 Es lūkoju, un redzi, auglīgais lauks ir tuksnesis, un visas viņa pilsētas ir salauztas priekš Tā Kunga un priekš Viņa bardzības karstuma.
Mo bojú wò, ilẹ̀ eléso, ó sì di aṣálẹ̀ gbogbo àwọn ìlú inú rẹ̀ sì ṣubú sínú ìparun níwájú Olúwa àti níwájú ríru ìbínú rẹ̀.
27 Jo tā saka Tas Kungs: visa tā zeme būs postā, tomēr Es to neizpostīšu pavisam.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Gbogbo ìlú náà yóò sì di ahoro, síbẹ̀ èmi kì yóò pa á run pátápátá.
28 Tādēļ zeme bēdāsies, un debess augšām aptumšosies, jo Es to esmu runājis un apņēmies, un tas Man nebūs žēl, un no tā Es neatkāpšos.
Nítorí náà, ayé yóò pohùnréré ẹkún àwọn ọ̀run lókè yóò ṣú òòkùn nítorí mo ti sọ, mo sì ti pète rẹ̀ mo ti pinnu, n kì yóò sì yí i padà.”
29 Visas pilsētas bēgs no jātnieku un strēlnieku trokšņa, tie ies biezos mežos un kāps uz klints kalniem, visas pilsētas taps atstātas, un neviena nebūs, kas tur dzīvos.
Nípa ariwo àwọn ẹlẹ́ṣin àti àwọn tafàtafà gbogbo ìlú yóò sálọ. Ọ̀pọ̀ sálọ sínú igbó; ọ̀pọ̀ yóò sì gun orí àpáta lọ. Gbogbo ìlú náà sì di ahoro; kò sì ṣí ẹnìkan nínú rẹ̀.
30 Ko tu tad darīsi, tu postītā? Jebšu tu apģērbsies ar purpuru, jebšu tu izgreznosies ar zelta glītumu, jebšu tu savas acis darīsi jaukas, tad tu tomēr velti izgreznosies. Tie drauģeļi tevi apsmies, tie meklēs tavu dvēseli.
Kí ni ò ń ṣe, ìwọ tí o ti di ìjẹ tán? Ìwọ ìbá wọ ara rẹ ní aṣọ òdodo kí o sì fi wúrà ṣe ara rẹ lọ́ṣọ̀ọ́. Àwọn olólùfẹ́ rẹ kẹ́gàn rẹ; wọ́n sì ń lépa ẹ̀mí rẹ.
31 Jo Es dzirdu kā dzemdētājas balsi, vaidēšanu, kā no tās, kas cieš pirmās bērnu sāpes, Ciānas meitas balsi; tā vaid un izpleš savas rokas: ak vai, man! Jo manu dvēseli nomāc slepkavas.
Mo gbọ́ ìró kan bí i igbe obìnrin tó ń rọbí, tí ó ń rọbí, ìrora bí i abiyamọ ọmọbìnrin Sioni tí ń pohùnréré ẹkún ara rẹ̀. Tí ó na ọwọ́ rẹ̀ tí ó sì wí pé, “Kíyèsi i mo gbé, nítorí a ti fi ẹ̀mí mi lé àwọn apani lọ́wọ́.”

< Jeremijas 4 >