< Jeremijas 30 >

1 Šis ir tas vārds, kas notika uz Jeremiju no Tā Kunga sacīdams:
Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, wí pé:
2 Tā runā Tas Kungs, Israēla Dievs, un saka: raksti sev grāmatā visus šos vārdus, ko Es uz tevi esmu runājis.
“Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Ìwọ kọ gbogbo ọ̀rọ̀ tí mo ti bá ọ sọ sínú ìwé kan.
3 Jo redzi, nāks dienas, saka Tas Kungs, ka Es vedīšu atpakaļ Savu Israēla ļaužu un Jūda cietumniekus, saka Tas Kungs; un Es tos vedīšu atpakaļ uz to zemi, ko Es viņu tēviem esmu devis, to iemantot.
Ọjọ́ ń bọ̀ nígbà tí ń ó mú àwọn ènìyàn mi, àwọn ọmọ Israẹli àti Juda kúrò nínú ìgbèkùn, tí n ó sì dá wọn padà sí orí ilẹ̀ tí mo fi fún àwọn baba ńlá wọn láti ní,’ ni Olúwa Ọlọ́run wí.”
4 Un šie ir tie vārdi, ko Tas Kungs runājis par Israēli un par Jūdu.
Ìwọ̀nyí ni àwọn ọ̀rọ̀ Olúwa Ọlọ́run sí Israẹli àti Juda:
5 Jo tā saka Tas Kungs: mēs dzirdam briesmu balsi, tur ir bailes un nemiers.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Igbe ẹ̀rù àti ìwárìrì ni a gbọ́ láìṣe igbe àlàáfíà.
6 Vaicājiet jel un raugāt, vai vīrietis dzemdē? Kāpēc tad es redzu, ka ikkatrs vīrs savas rokas uz ciskām tura, tā kā sieva, kas dzemdē, un visi vaigi palikuši bāli?
Béèrè kí o sì rí. Ǹjẹ́ ọkùnrin le dá ọmọ bí? Èéṣe tí mo fi ń rí àwọn alágbára ọkùnrin tí wọ́n fi ọwọ́ wọn mú inú wọn bí obìnrin tó ń rọbí, tí ojú gbogbo wọ́n sì fàro fún ìrora?
7 Ak vai! Jo tā diena ir tik liela, ka citas tādas nav, un tas ir Jēkaba bēdu laiks; tomēr viņš no tā taps izpestīts.
Ọjọ́ náà yóò ha ti burú tó! Kò sí ọjọ́ tí yóò dàbí rẹ̀, Ọjọ́ náà yóò jẹ́ àkókò ìdààmú fún Jakọbu ṣùgbọ́n yóò rí ìgbàlà kúrò nínú ìdààmú náà.
8 Jo notiks tai dienā, saka Tas Kungs Cebaot, ka Es nolauzīšu viņa jūgu no tava kakla un saraustīšu tavas saites, ka sveši viņu vairs nekalpinās.
“‘Ní ọjọ́ náà,’ Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, ‘Èmi yóò gbé àjàgà kúrò lọ́rùn wọn, Èmi yóò sì tú ìdè wọn sọnù. Àwọn àjèjì kì yóò sì mú ọ sìn wọ́n mọ́.
9 Bet tie kalpos Tam Kungam, savam Dievam, un Dāvidam, savam ķēniņam, ko Es tiem celšu.
Dípò bẹ́ẹ̀ wọn yóò máa sin Olúwa Ọlọ́run wọn àti Dafidi gẹ́gẹ́ bí ọba wọn, ẹni tí èmi yóò gbé dìde fún wọn.
10 Bet tu nebīsties, Mans kalps Jēkab, saka Tas Kungs, un nebaiļojies, Israēl. Jo redzi, Es tevi izpestīšu no tās tālās zemes, un tavu dzimumu no viņa cietuma zemes, un Jēkabs pārnāks un dzīvos mierīgi un droši un neviens viņu netraucēs.
“‘Nítorí náà, má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, má sì ṣe jẹ́ kí ẹ̀rù bà ọ́, ìwọ Israẹli,’ ni Olúwa wí. ‘Èmi yóò gbà ọ́ kúrò láti ọ̀nà jíjìn wá, àní àwọn ìran rẹ láti ilẹ̀ àtìpó wọn. Jakọbu yóò sì tún ní àlàáfíà àti ààbò rẹ̀ padà, kò sì ṣí ẹni tí yóò ṣẹ̀rù bà á mọ́.
11 Jo Es esmu pie tevis, saka Tas Kungs, ka Es tevi izglābju. Jo Es daru galu visiem pagāniem, kurp Es tevi esmu izklīdinājis, bet tev Es nedarīšu galu, bet Es tevi pārmācīšu pēc taisnības, un nepārmācītu tevi nepametīšu.
Èmi wà pẹ̀lú rẹ, n ó sì gbà ọ́,’ ni Olúwa wí. ‘Bí mo tilẹ̀ pa gbogbo orílẹ̀-èdè run, nínú èyí tí mo ti fọ́n ọn yín ká, síbẹ̀ èmi kì yóò pa yín run pátápátá. Èmi yóò bá yín wí pẹ̀lú ìdájọ́ òdodo nìkan; Èmi kò ní fi yín sílẹ̀ láìjìyà.’
12 Jo tā saka Tas Kungs: tava vaina ir nāvīga, tava vāts nav dziedinājama.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Ọgbẹ́ yín kò gbóògùn, bẹ́ẹ̀ ni egbò yín kọjá ìwòsàn.
13 Neviena nav, kas tavu vainu pārrauga un aizsien: dziedinājamas zāles tev nav.
Kò sí ẹnìkan tí yóò bẹ̀bẹ̀ fún àìṣedéédéé yín, kò sí ètùtù fún ọgbẹ́ yín, a kò sì mú yín láradá.
14 Visi tavi mīļotāji tevi aizmirsuši, tie nevaicā pēc tevis; jo Es tevi esmu sitis ar ienaidnieka sitieniem, ar briesmīgu pārmācīšanu tavu daudzo noziegumu dēļ tāpēc ka tavu grēku ļoti daudz.
Gbogbo àwọn olùfẹ́ rẹ ti gbàgbé rẹ, wọn kò sì náání rẹ mọ́ pẹ̀lú. Mo ti nà ọ gẹ́gẹ́ bí ọ̀tá rẹ yóò ti nà ọ, mo sì bá a ọ wí gẹ́gẹ́ bí ìkà, nítorí tí ẹ̀bi rẹ pọ̀ púpọ̀, ẹ̀ṣẹ̀ rẹ kò sì lóǹkà.
15 Ko tu kliedz par savu vainu, un ka tavas sāpes ir nāvīgas? Tavas lielās noziedzības dēļ ka tavu grēku ir ļoti daudz, Es tev to esmu darījis.
Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń kígbe nítorí ọgbẹ́ yín, ìrora yín èyí tí kò ní oògùn? Nítorí ọ̀pọ̀ ẹ̀ṣẹ̀ yín àti ẹ̀bi yín tó ga ni mo fi ṣe àwọn nǹkan wọ̀nyí sí i yín.
16 Tādēļ visi, kas tevi rij, taps aprīti, un visi tavi pretinieki, tie visi ies cietumā, un kas tevi aplaupa, būs paši par laupījumu, un visi, kas tevi posta, tos Es nodošu, ka taps izpostīti.
“‘Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ṣe yín ní ibi ni ibi yóò bá, àní gbogbo àwọn ọ̀tá yín ni a ó sọ di àtìpó ní ilẹ̀ àjèjì; gbogbo àwọn tí wọ́n bà yín jẹ́ ni a ó bàjẹ́.
17 Jo Es atkal aizsiešu tavas vātis un dziedināšu tavas vainas, saka Tas Kungs, tāpēc ka tie tevi nosauc par aizdzītu: „šī ir Ciāna, neviens pēc tās nevaicā“.
Ṣùgbọ́n èmi yóò fi ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ ìlera fún yín, èmi yóò sì wo ọ̀gbẹ́ yín sàn,’ ni Olúwa wí, ‘nítorí tí a pè yín ní alárìnkiri, Sioni tí gbogbo ènìyàn dágunlá sí.’
18 Tā saka Tas Kungs: redzi, Es vedīšu atpakaļ Jēkaba dzīvokļu cietumniekus un apžēlošos par viņa mājas vietām, un tā pilsēta taps uztaisīta uz sava kalna, un tas augstais nams stāvēs savā vecā vietā.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Èmi yóò dá gbogbo ìre àgọ́ Jakọbu padà, èmi yóò sì ṣe àánú fún olùgbé àgọ́ rẹ̀; ìlú náà yóò sì di títúnṣe tí ààfin ìlú náà yóò sì wà ní ipò rẹ̀.
19 Un no tiem izies pateikšana un līksmošanās balss, un Es tiem likšu vairumā iet un ne mazumā, un Es tos pagodināšu, ka vairs nebūs nievājami.
Láti ẹnu wọn ni orin ọpẹ́ àti ìyìn yóò sì ti máa jáde. Èmi yóò sọ wọ́n di púpọ̀, wọn kì yóò sì dínkù ní iye, Èmi yóò fi ọlá fún wọn, wọn kò sì ní di ẹni àbùkù.
20 Un viņa dēli būs kā citkārt, un viņa draudze Manā priekšā pastāvēs, un Es piemeklēšu visus viņa spaidītājus.
Ọmọ ọmọ wọn yóò wà bí i ti ìgbàanì níwájú mi ni wọn yóò sì tẹ àwùjọ wọn dúró sí. Gbogbo ẹni tó bá ni wọ́n lára, ni èmi yóò fì ìyà jẹ.
21 Un viņa cienīgais būs no viņa, un viņa valdnieks nāks no viņa vidus, un Es viņam likšu nākt tuvu, un viņš nāks pie Manis klāt. Jo kas tas tāds, kas iedrošinātos Man tuvoties? saka Tas Kungs.
Ọ̀kan nínú wọn ni yóò jẹ́ olórí wọn, ọba wọn yóò dìde láti àárín wọn. Èmi yóò mú un wá sí ọ̀dọ̀ mi, òun yóò sì súnmọ́ mi, nítorí ta ni ẹni náà tí yóò fi ara rẹ̀ jì láti súnmọ́ mi?’ ni Olúwa wí.
22 Un jūs Man būsiet par ļaudīm, un Es jums būšu par Dievu.
‘Nítorí náà, ẹ̀yin yóò jẹ́ ènìyàn mi, èmi yóò sì jẹ́ Ọlọ́run yín.’”
23 Redzi, vētra no Tā Kunga celsies ar bardzību, briesmīga vētra, tā gāzīsies bezdievīgiem uz galvu.
Wò ó, ìbínú Olúwa yóò tú jáde, ìjì líle yóò sì sọ̀kalẹ̀ sórí àwọn ènìyàn búburú.
24 Tā Kunga bardzības karstums nemitēsies, tiekams Viņš izdarīs un piepildīs Savas sirds domas. Nākamās dienās jūs gan to samanīsiet.
Ìbínú ńlá Olúwa kò ní dẹ̀yìn lẹ́yìn àwọn ìkà títí yóò fi mú èrò ọkàn rẹ̀ ṣẹ. Ní àìpẹ́ ọjọ́, òye rẹ̀ yóò yé e yín.

< Jeremijas 30 >