< Jeremijas 24 >

1 Tas Kungs man rādīja un redzi, tur bija nolikti divi vīģu kurvji Tā Kunga nama priekšā, kad Nebukadnecars, Bābeles ķēniņš, bija aizvedis Jekoniju, Jojaķima dēlu, Jūda ķēniņu līdz ar Jūda lielkungiem, un amatniekus un kalējus, un tos bija novedis no Jeruzālemes uz Bābeli.
Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
2 Vienā kurvī bija ļoti labas vīģes, kā agrejās vīģes, bet otrā kurvī bija ļoti nelāga vīģes, ko nevarēja ēst aiz viņu nelāguma.
Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
3 Un Tas Kungs sacīja uz mani: ko tu redzi, Jeremija? Un es sacīju: vīģes. Tās labās vīģes ir ļoti labas un tās nelāga vīģes ir ļoti nelabas, ka nevar ēst aiz nelāguma.
Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
4 Tad Tā Kunga vārds uz mani notika sacīdams:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
5 Tā saka Tas Kungs, Israēla Dievs: tā kā šās vīģes labas, tā Es atzīšu par labiem tos, kas no Jūda aizvesti, ko no šās vietas esmu aizsūtījis uz Kaldeju zemi.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
6 Un Es Savu aci uz tiem metīšu par labu, un tos atvedīšu atpakaļ uz šo zemi, un tos uztaisīšu un nenolauzīšu, Es tos dēstīšu un neizraušu.
Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
7 Un Es tiem došu sirdi, Mani atzīt, ka Es esmu Tas Kungs, un tie Man būs par ļaudīm, un Es tiem būšu par Dievu; jo tie pie Manis atgriezīsies no visas savas sirds.
Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
8 Bet kādas tās nelāga vīģes ir, ko nevar ēst aiz nelāguma, tā saka Tas Kungs, par tādiem Es darīšu Cedeķiju, Jūda ķēniņu, un viņa lielkungus un Jeruzālemes atlikušos, kas atlikuši šai zemē un kas dzīvo Ēģiptes zemē.
“‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
9 Un Es tos nodošu uz vārdzināšanu, uz nelaimi visās pasaules valstīs, uz nievāšanu un uz lamāšanu, uz mēdīšanu un lādēšanu visās vietās, kurp tos būšu aizdzinis.
Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
10 Un Es tiem sūtīšu zobenu, badu un mēri, tiekams tie būs izdeldēti no tās zemes, ko Es tiem un viņu tēviem esmu devis.
Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”

< Jeremijas 24 >