< Jesajas 60 >

1 Celies, topi apgaismota, jo tava gaisma nāk, un Tā Kunga godība uzlec pār tevi.
“Dìde, tànmọ́lẹ̀, nítorí ìmọ́lẹ̀ rẹ ti dé, ògo Olúwa sì ràdàbò ọ́.
2 Jo redzi, tumsība apklāj zemi un krēslība ļaudis, bet pār tevi uzlēks Tas Kungs, un Viņa godība pār tevi rādīsies.
Kíyèsi i, òkùnkùn bo ilẹ̀ ayé òkùnkùn biribiri sì wà lórí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n Olúwa ràn bò ọ́ ògo rẹ̀ sì farahàn lórí i rẹ.
3 Un pagāni staigās tavā gaismā un ķēniņi tai spožumā, kas pār tevi uzlēcis.
Àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá sí ìmọ́lẹ̀ rẹ, àti àwọn ọba sí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀ rẹ.
4 Pacel savas acis visapkārt un skaties: visi tie ir sapulcināti un nāk pie tevis. Tavi dēli nāk no tālienes, un tavas meitas uz rokām top atnestas.
“Gbé ojú rẹ sókè, kí o sì wò. Gbogbo wọn ṣa ara jọ pọ̀, wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ; àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin yóò wá láti ọ̀nà jíjìn, àwọn ọmọ rẹ obìnrin ni a ó tọ́jú ní ẹ̀gbẹ́ rẹ.
5 Tad tu redzēsi un izplūdīsi kā upe, un tava sirds brīnīsies un izpletīsies, jo jūras draudze pie tevis atgriezīsies un pagānu spēks nāks pie tevis.
Nígbà náà ni ìwọ yóò wò tí ojú rẹ yóò máa dán, ọkàn rẹ yó fò, yó sì kún fún ayọ̀; ọrọ̀ inú Òkun ni a ó kò wá sọ́dọ̀ rẹ, sí ọ̀dọ̀ rẹ ni ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè yóò wá.
6 Tevi apklās kamieļu pulks, čaklie kamieļi no Midijanas un Epas, visi tie nāks no Sabas, zeltu un vīraku tie atnesīs un teiks Tā Kunga slavu.
Ọ̀wọ́ ìbákasẹ yóò bo gbogbo ilẹ̀ rẹ, àwọn ọ̀dọ́ ìbákasẹ Midiani àti Efani. Àti gbogbo wọn láti Ṣeba yóò wá, wọn yóò mú wúrà àti tùràrí lọ́wọ́ tí wọn yóò sì máa kéde ìyìn Olúwa.
7 Visas avis no Ķedara sapulcēsies pie tevis, tie auni no Nebajota tev kalpos, tie nāks par labprātību uz Manu altāri, un Es pagodināšu Savas godības namu.
Gbogbo agbo ẹran ìlú Kedari ni a ó kójọ sọ́dọ̀ rẹ, àwọn àgbò ti Nebaioti yóò sìn ọ́; wọn yóò jẹ́ ọrẹ ìtẹ́wọ́gbà lórí i pẹpẹ mi, bẹ́ẹ̀ ni n ó sì ṣe tẹmpili ògo mi lọ́ṣọ̀ọ́.
8 Kas ir tie, kas skriedami nāk kā padebeši, un kā baloži pie saviem logiem?
“Ta ni àwọn wọ̀nyí tí ń fò lọ bí i kurukuru, gẹ́gẹ́ bí àwọn àdàbà sí ìtẹ́ wọn?
9 Jo salas gaida uz Mani un Taršiša kuģi iet papriekš, tavus bērnus atvest no tālienes, un viņu zeltu un sudrabu līdz ar tiem, Tā Kunga, tava Dieva vārdam un tam Svētajam iekš Israēla; jo Viņš tevi pagodinājis.
Lóòtítọ́ àwọn erékùṣù bojú wò mí; ní ìṣíwájú ni àwọn ọkọ̀ ojú omi Tarṣiṣi; mú àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ wá láti ọ̀nà jíjìn, pẹ̀lú fàdákà àti wúrà wọn, fún ti ọlá Olúwa Ọlọ́run rẹ, Ẹni Mímọ́ Israẹli, nítorí òun ti fi ohun dídára ṣe ó lọ́ṣọ̀ọ́.
10 Un sveši uzcels tavus mūrus, un viņu ķēniņi tev kalpos; jo Savā dusmībā Es tevi esmu sitis, bet Savā žēlastībā Es par tevi esmu apžēlojies.
“Àwọn àjèjì yóò tún ògiri rẹ mọ àwọn ọba wọn yóò sì sìn ọ́. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ní ìbínú ni mo lù ọ́, ní àánú èmi yóò ṣe inú rere sí ọ.
11 Un tavi vārti stāvēs vienmēr vaļā un netaps aizslēgti ne dienu ne nakti, ka pie tevis var atvest pagānu spēku un viņu ķēniņus ar pavadīšanu.
Gbogbo ẹnu-bodè rẹ ni yóò wà ní ṣíṣí sílẹ̀, a kì yóò tì wọ́n ní ọ̀sán àti ní òru, tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ọkùnrin yóò le è kó ọrọ̀ àwọn orílẹ̀-èdè wá tí àwọn ọba wọn yóò ṣáájú ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ ìṣẹ́gun.
12 Jo tās tautas un valstis, kas tev negrib kalpot, ies bojā, un šīs tautas pavisam taps izdeldētas.
Nítorí pé orílẹ̀-èdè tàbí ilẹ̀ ọba tí kì yóò sìn ọ́ ni yóò parun; pátápátá ni yóò sì dahoro.
13 Lībanus godība nāks pie tevis, priede, kļava un bukses koks, tie visi, un pušķos Mana svētuma vietu, un Es pagodināšu to vietu, kur Manas kājas dus.
“Ògo Lebanoni yóò wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, igi junifa, firi àti sípírẹ́ṣì papọ̀, láti bu ọlá fún ilé ìsìn mi; àti pé èmi yóò sì ṣe ibi ẹsẹ̀ mi lógo.
14 Un pazemīgi nāks pie tevis tavu spaidītāju bērni, un visi, kas tevi zaimojuši, klanīsies līdz tavām pēdām un tevi nosauks par Tā Kunga pilsētu, par Ciānu, kur tas Israēla Svētais.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin àwọn apọ́nilójú rẹ yóò wá foríbalẹ̀ fún ọ; gbogbo àwọn tí ó ti kẹ́gàn rẹ ni wọn yóò tẹríba níwájú rẹ wọn yóò sì pè ọ́ ní ìlú Olúwa, Sioni ti Ẹni Mímọ́ Israẹli.
15 Par to, ka tu esi bijusi atstāta un ienīdēta un neapmeklēta, Es tevi iecelšu par mūžīgu greznumu, par prieku līdz cilšu ciltīm.
“Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a ti kórìíra rẹ, a sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀, láìsí ẹnìkan tí ó ń gba ọ̀dọ̀ rẹ kọjá, Èmi yóò ṣe ọ́ ní ìṣògo ayérayé àti ayọ̀ àtìrandíran.
16 Un tu zīdīsi pagānu pienu, un ķēniņu krūtis tu zīdīsi. Un tu atzīsi, ka Es, Tas Kungs, esmu tavs Pestītājs un tavs izglābējs, tas varenais iekš Jēkaba.
Ìwọ yóò mu wàrà gbogbo orílẹ̀-èdè a ó sì fun ọ́ ni ọmú àwọn ọba. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára ti Jakọbu.
17 Vara vietā Es atnesīšu zeltu, un dzelzs vietā Es atnesīšu sudrabu un koku vietā varu un akmeņu vietā dzelzi, un darīšu mieru par tavu valdītāju un taisnību par tavu uzraugu.
Dípò idẹ, èmi ó mú wúrà wá fún ọ, dípò fàdákà èmi ó mú irin wá. Dípò igi yóò mú idẹ wá fún ọ, àti irin dípò òkúta. Èmi yóò fi àlàáfíà ṣe àwọn ìjòyè rẹ àti òdodo gẹ́gẹ́ bí alákòóso rẹ.
18 Varas darbs tavā zemē vairs netaps dzirdēts, un ne posts ne pazušana tavās robežās, bet tu nosauksi pestīšanu par saviem mūriem un slavu par saviem vārtiem.
A kì yóò gbọ́ nípa rògbòdìyàn ní ilẹ̀ rẹ mọ́, tàbí ìdahoro àti ìparun nínú agbègbè rẹ, ṣùgbọ́n ìwọ yóò pe ògiri rẹ ní ìgbàlà àti àwọn ẹnu-bodè rẹ ní ìyìn.
19 Saule tev vairs nebūs par gaismu dienā, nedz mēnesis tev spīdēs par spīdekli, bet Tas Kungs tev būs par mūžīgu gaismu, un tavs Dievs par tavu greznumu.
Òòrùn kì yóò sì jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ní ọ̀sán mọ́, tàbí kí ìtànṣán òṣùpá tún ràn sí ọ mọ́, nítorí Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ rẹ ayérayé, àti Ọlọ́run rẹ yóò jẹ́ ògo rẹ.
20 Tava saule vairs nenoies un tavs mēnesis vairs nemainīsies; jo Tas Kungs tev būs par mūžīgu gaismu, un tavām skumju dienām būs gals.
Òòrùn rẹ kì yóò sì wọ̀ mọ́, àti òṣùpá rẹ kì yóò sì wọ òòkùn mọ́; Olúwa ni yóò jẹ́ ìmọ́lẹ̀ ayérayé rẹ, àti àwọn ọjọ́ arò rẹ yóò sì dópin.
21 Un tavi ļaudis būs visnotaļ taisni, tie turēs to zemi par īpašumu mūžam, tie būs Manis dēstīts zars un Manu roku darbs, Man par godu.
Lẹ́yìn náà ni gbogbo àwọn ènìyàn rẹ yóò di òdodo àwọn ni yóò sì jogún ilẹ̀ náà títí ayé. Àwọn ni irúgbìn tí mo ti gbìn, iṣẹ́ ọwọ́ mi, láti fi ọláńlá mi hàn.
22 Tas mazākais paliks par tūkstoti un tas sīkākais par varenu tautu. Es Tas Kungs to pasteigšu (izpildīt) savā laikā.
Èyí tí ó kéré jù nínú yín yóò di ẹgbẹ̀rún kan, èyí tí ó kéré yóò di orílẹ̀-èdè ńlá. Èmi ni Olúwa; ní àkókò rẹ̀, Èmi yóò ṣe èyí kánkán.”

< Jesajas 60 >