< Jesajas 37 >

1 Kad nu ķēniņš Hizkija to dzirdēja, tad viņš saplēsa savas drēbes un apsedzās ar maisu un gāja Tā Kunga namā,
Nígbà tí ọba Hesekiah gbọ́ èyí, ó fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì fi aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara rẹ̀, ó sì wọ inú tẹmpili Olúwa lọ.
2 Un sūtīja nama uzraugu Elijaķimu un skrīveri Šebnu un tos priesteru vecajus, maisos ģērbušos, pie pravieša Jesajas, Amoca dēla.
Òun sì rán Eliakimu alákòóso ààfin, Ṣebna akọ̀wé, àti aṣíwájú àwọn àlùfáà, gbogbo wọn nínú aṣọ ọ̀fọ̀ lọ sí ọ̀dọ̀ wòlíì Isaiah ọmọ Amosi.
3 Un tie uz viņu sacīja: Tā saka Hizkija: Šī diena ir bēdu- un sodības- un kauna- diena; jo bērni nākuši uz dzimšanu, un spēka nav dzemdēt.
Wọ́n sọ fún un pé, “Báyìí ni Hesekiah wí, ọjọ́ òní jẹ́ ọjọ́ ìbànújẹ́, ìbáwí àti ẹ̀gàn gẹ́gẹ́ bí ìgbà ìbí àwọn ọmọdé tí kò sì ṣí agbára láti bí wọn.
4 Kaut Tas Kungs, tavs Dievs, dzirdētu Rabzakus vārdus, ko viņa kungs, Asīrijas ķēniņš, ir sūtījis, zaimot to dzīvo Dievu, un pārmācītu par tiem vārdiem, ko Viņš ir dzirdējis, Tas Kungs, tavs Dievs! Celies tad un lūdz par tiem atlikušiem, kas vēl atrodas.
Ó lè jẹ́ pé Olúwa Ọlọ́run rẹ yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ọ̀gágun ẹni tí ọ̀gá rẹ̀ ọba Asiria ti rán láti fi Ọlọ́run alààyè ṣe ẹlẹ́yà, àti pé òun ni yóò bá a wí nítorí àwọn ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti gbọ́. Nítorí náà gbàdúrà fún àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n sì wà láààyè.”
5 Un ķēniņa Hizkijas kalpi nāca pie Jesajas.
Nígbà tí àwọn ìjòyè ọba Hesekiah dé ọ̀dọ̀ Isaiah,
6 Un Jesaja uz tiem sacīja: tā jums būs sacīt savam kungam: tā saka Tas Kungs: nebīsties par tiem vārdiem, ko tu esi dzirdējis, ar ko Asīrijas ķēniņa sulaiņi Mani zaimojuši.
Isaiah sọ fún wọn pé, “Ẹ sọ fún ọ̀gá yín pé, ‘Ohun tí Olúwa sọ nìyìí. Má ṣe bẹ̀rù ohun tí ẹ ti gbọ́ gbogbo ọ̀rọ̀ tí ọba Asiria tí ó wà nínú ìdè ti fi sọ̀rọ̀-òdì sí mi.
7 Redzi, Es tam došu tādu garu, ka tas dzirdēs baumas un ies atpakaļ uz savu zemi, un Es viņam likšu krist caur zobenu viņa zemē.
Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò fi ẹ̀mí kan sínú rẹ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi jẹ́ pé bí o bá ti gbọ́ ìròyìn kan, òun yóò padà sí orílẹ̀-èdè rẹ̀, níbẹ̀ ni n ó sì ti jẹ́ kí wọn ké e lulẹ̀ pẹ̀lú idà.’”
8 Tad Rabzakus gāja atpakaļ un atrada Asīrijas ķēniņu pret Libnu karojam, jo viņš bija dzirdējis, ka tas no Laķisa jau bija aizgājis.
Nígbà tí ọ̀gágun gbọ́ pé ọba Asiria ti fi Lakiṣi sílẹ̀, ó padà sẹ́yìn, ó sì bá ọba tí ń bá Libina jà.
9 Un viņš par Tiraku, Moru ķēniņu, dzirdēja sakām: viņš ir izgājis, ar tevi karot.
Ní àkókò yìí Sennakeribu gbọ́ ìròyìn kan pé Tirakah ará Kuṣi ọba Ejibiti ń jáde bọ̀ wá bá òun jà. Nígbà tí ó gbọ́ èyí, ó rán oníṣẹ́ sí Hesekiah pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọ̀nyí,
10 Kad viņš to dzirdēja, tad viņš atkal sūtīja vēstnešus pie Hizkijas un sacīja: tā runājiet uz Hizkiju, Jūda ķēniņu, un sakāt: lai tevi nepieviļ tavs Dievs, uz ko tu paļaujies sacīdams: Jeruzāleme netaps dota Asīrijas ķēniņa rokā.
“Ẹ sọ fún Hesekiah ọba Juda pé: Má ṣe jẹ́ kí òrìṣà tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé tàn ọ́ jẹ nígbà tí ó sọ pé, ‘A kì yóò jọ̀wọ́ Jerusalẹmu fún ọba Asiria.’
11 Redzi, tu esi dzirdējis, ko Asīrijas ķēniņi darījuši visām zemēm, tās izdeldēdami; un tu domā izglābties?
Dájúdájú, ìwọ ti gbọ́ ohun tí ọba Asiria ti ṣe sí àwọn orílẹ̀-èdè, tí ó pa wọ́n run pátápátá. Ǹjẹ́ a ó ha dá ọ nídè bí?
12 Vai pagānu dievi tos glābuši, ko mani tēvi postījuši, Gozanu un Haranu un Recevu un Edeņa bērnus, kas bija Telasarā.
Ǹjẹ́ àwọn òrìṣà àwọn orílẹ̀-èdè tí àwọn baba ńlá mi parun ha gbà wọ́n sílẹ̀ bí àwọn òrìṣà Gosani, Harani, Reṣefu àti àwọn ènìyàn Edeni tí wọ́n wà ní Teli-Assari?
13 Kur ir Hamatas ķēniņš un Arpadas ķēniņš un Sefarvaimas pilsētas, Enas un Ivas ķēniņš?
Níbo ni ọba Hamati wà, ọba Arpadi, ọba ìlú Sefarfaimi tàbí Hena tàbí Iffa?”
14 Kad nu Hizkija bija dabūjis tās grāmatas no vēstneša rokas un tās izlasījis, tad viņš gāja Tā Kunga namā, un Hizkija tās atpleta Tā Kunga priekšā.
Hesekiah gba ìwé náà lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ó sì kà á. Lẹ́yìn náà ni ó gòkè lọ sí tẹmpili Olúwa ó sì tẹ́ ìwé náà sílẹ̀ níwájú Olúwa.
15 Un Hizkija pielūdza Tā Kunga priekšā un sacīja:
Hesekiah sì gbàdúrà sí Olúwa:
16 Ak Kungs Cebaot, Tu Israēla Dievs, kas sēž pār ķerubiem, Tu viens pats esi Dievs pār visām zemes valstīm, Tu esi radījis debesis un zemi.
Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli, tí ó gúnwà láàrín àwọn kérúbù, ìwọ nìkan ni Ọlọ́run lórí i gbogbo ìjọba orílẹ̀ ayé. Ìwọ ti dá ọ̀run àti ayé.
17 Atgriez, ak Kungs, Savas ausis un klausies, atveri, ak Kungs, Savas acis un redzi, un dzirdi visus Sanheriba vārdus, ko viņš sūtījis, zaimot to dzīvo Dievu.
Tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ Olúwa, kí o gbọ́, ya ojú rẹ, Ìwọ Olúwa, kí o rí i; tẹ́tí sí gbogbo ọ̀rọ̀ tí Sennakeribu rán láti fi àbùkù kan Ọlọ́run alààyè.
18 Patiesi, Kungs, Asīrijas ķēniņi ir postījuši visas zemes malas ar visām viņu valstīm,
“Òtítọ́ ni Olúwa pé àwọn ọba Asiria ti sọ àwọn ènìyàn àti ilẹ̀ wọn di asán.
19 Un viņu dievus metuši ugunī, jo tie nebija dievi, bet cilvēku roku darbs, koks un akmens, tāpēc tie tos ir postījuši.
Wọ́n ti da àwọn òrìṣà wọn sínú iná wọ́n sì ti pa wọ́n run, nítorí àwọn wọ̀nyí kì í ṣe ọlọ́run bí kò ṣe igi àti òkúta lásán, tí a ti ọwọ́ ènìyàn ṣe.
20 Nu tad, ak Kungs, mūsu Dievs, izglāb mūs jel no viņa rokas, lai visas valstis virs zemes atzīst, ka Tu vien esi Tas Kungs.
Nísinsin yìí, ìwọ Olúwa, Ọlọ́run wa, gbà wá lọ́wọ́ rẹ̀, tí ó fi jẹ́ pé gbogbo ìjọba ilẹ̀ ayé yóò fi mọ̀ pé Ìwọ, Ìwọ nìkan, Olúwa ni Ọlọ́run.”
21 Tad Jesaja, Amoca dēls, sūtīja pie Hizkijas un lika sacīt: Tā saka Tas Kungs, Israēla Dievs: par ko tu Mani esi pielūdzis pret Sanheribu, Asīrijas ķēniņu, -
Lẹ́yìn náà Isaiah ọmọ Amosi rán iṣẹ́ kan sí Hesekiah: “Èyí ni ohun tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli sọ pé, nítorí pé ìwọ ti gbàdúrà sí mi nípa Sennakeribu ọba Asiria,
22 Šis ir tas vārds, ko Tas Kungs pret viņu runājis: tevi nievā, tevi apsmej jaunava Ciānas meita, aiz tevis galvu krata Jeruzālemes meita.
èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa rẹ̀: “Wúńdíá ọmọbìnrin Sioni ti kẹ́gàn rẹ, ó sì ti fi ọ ṣe ẹlẹ́yà. Ọmọbìnrin Jerusalẹmu ti mi orí rẹ̀ bí ó ti ń sálọ.
23 Ko tu esi apsmējis un zaimojis, un pret ko tu esi pacēlis balsi un augsti uzcēlis savas acis? Pret To Svēto iekš Israēla.
Ta ni ìwọ ti bú tí ìwọ sì ti sọ̀rọ̀-òdì sí? Sí ta ní ìwọ ti gbé ohùn rẹ sókè tí o sì gbé ojú rẹ sókè ní ìgbéraga? Sí Ẹni Mímọ́ Israẹli!
24 Caur saviem kalpiem tu To Kungu esi apmēdījis un sacījis: ar savu ratu pulku es uzkāpju kalnu galos, Lībanus virsgalā, un izcērtu viņa augstos ciedru kokus un izlasītās priedes, un tieku līdz pat viņa galam, viņa kuplākam mežam.
Nípa àwọn ìránṣẹ́ rẹ, ìwọ ti sọ̀rọ̀ búburú sí Olúwa. Tì wọ sì wí pé, ‘Pẹ̀lú ọ̀pọ̀ kẹ̀kẹ́ mi ni èmi sì fi dé orí àwọn òkè ńlá, sí ibi gíga jùlọ Lebanoni. Èmi a sì ké igi kedari gíga rẹ̀ lulẹ̀, àti ààyò igi firi rẹ̀. Èmi ti dé ibi rẹ̀ tí ó ga jùlọ, igbó rẹ̀ tí ó dára jùlọ.
25 Es roku un dzeru ūdeni un no manu kāju pēdām paliek sausas visas Ēģiptes upes.
Èmi ti gbẹ́ kànga ní ilẹ̀ àjèjì mo sì mu omi ní ibẹ̀, pẹ̀lú àtẹ́lẹsẹ̀ mi Èmi ti gbẹ́ gbogbo omi àwọn odò Ejibiti.’
26 Vai tu neesi dzirdējis, ka Es jau sen iepriekš to esmu sataisījis, jau vecos laikos to esmu apņēmies. Un tagad Es tam esmu licis notikt, ka tu izposti stipras pilsētas un dari par akmeņu kopām.
“Ṣé o kò tí ì gbọ́? Tipẹ́tipẹ́ ni mo ti fìdí rẹ̀ mulẹ̀. Láti ìgbà pípẹ́ ni mo ti ṣètò rẹ̀; ní àkókò yìí ni mo mú wá sí ìmúṣẹ, pé o ti sọ àwọn ìlú olódi di àkójọpọ̀ àwọn òkúta.
27 Tāpēc viņu iedzīvotājiem nogura rokas, un tie iztrūcinājās un tapa kaunā, un tie bija ka zāle laukā un kā uzzēlis zaļums, tā kā zāle uz jumtiem, kā rūsaina labība, pirms nāk stiebros.
Àwọn ènìyàn, tí agbára ti wọ̀ lẹ́wù, ni wọ́n banújẹ́ tí a sì dójútì. Wọ́n dàbí ohun ọ̀gbìn nínú pápá, gẹ́gẹ́ bí ọ̀jẹ̀lẹ̀ èhíhù tuntun, gẹ́gẹ́ bí i koríko tí ó ń hù lórí òrùlé, tí ó jóná kí ó tó dàgbàsókè.
28 Bet Es zinu tavu sēdēšanu un tavu iziešanu un tavu ieiešanu un tavu trakošanu pret Mani.
“Ṣùgbọ́n mo mọ ibi tí o wà àti ìgbà tí o wá tí o sì lọ àti bí inú rẹ ṣe ru sí mi.
29 Tavas trakošanas dēļ pret Mani un tavas pārgalvības pēc, kas nākusi Manās ausīs, Es Savu kāsi likšu tavās nāsīs un Savus laužņus tavā mutē, un Es tev likšu griezties atpakaļ pa to ceļu, kur tu esi nācis.
Nítorí pé inú rẹ ru sí mi àti nítorí pé orí kunkun rẹ ti dé etí ìgbọ́ mi, Èmi yóò fi ìwọ̀ mi sí ọ ní imú, àti ìjẹ mi sí ọ lẹ́nu, èmi yóò sì jẹ́ kí o padà láti ọ̀nà tí o gbà wá.
30 Un tas tev būs par zīmi: šai gadā ēdīs papuvē augušu un otrā gadā ataugu, bet trešā gadā sējat un pļaujat un stādāt vīna dārzus un ēdat viņu augļus.
“Èyí ni yóò ṣe àmì fún ọ, ìwọ Hesekiah: “Ní ọdún yìí, ìwọ yóò jẹ ohun tí ó hù fúnra rẹ̀, àti ní ọdún kejì ohun tí ó jáde láti ara rẹ. Ṣùgbọ́n ní ọdún kẹta, ẹ gbìn kí ẹ sì kórè, ẹ gbin ọgbà àjàrà kí ẹ sì jẹ èso wọn.
31 Un kas no Jūda nama ir izglābts un atlicis, sakņos atkal zemjup un nesīs augļus augšup.
Lẹ́ẹ̀kan sí i, àṣẹ́kù láti ilé Juda yóò ta gbòǹgbò nísàlẹ̀ yóò sì ṣo èso lókè.
32 Jo no Jeruzālemes izies atlikuši un atpestīti no Ciānas kalna. To darīs Tā Kunga Cebaot karstums.
Nítorí láti Jerusalẹmu ni àwọn àṣẹ́kù yóò ti wá, àti láti òkè Sioni ni ikọ̀ àwọn tí ó sálà. Ìtara Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni yóò mú èyí ṣẹ.
33 Tādēļ tā saka Tas Kungs par Asīrijas ķēniņu: viņš šai pilsētā nenāks un tanī neiešaus nevienu bultu un nepacels pret to priekšturamās bruņas un neuzmetīs pret to valni.
“Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa wí nípa ọba Asiria, “Òun kì yóò wọ ìlú yìí wá tàbí ta ẹyọ ọfà kan níhìn-ín Òun kì yóò wá síwájú rẹ pẹ̀lú asà tàbí kí ó kó dágunró sílẹ̀ fún un.
34 Pa to pašu ceļu, kur viņš nācis, viņam būs griezties atpakaļ, bet šai pilsētā viņš nenāks, saka Tas Kungs.
Nípa ọ̀nà tí ó gbà wá náà ni yóò padà lọ; òun kì yóò wọ inú ìlú yìí,” ni Olúwa wí.
35 Jo Es šo pilsētu paglabāšu un izpestīšu, Sevis labad un Sava kalpa Dāvida labad.
“Èmi yóò dáàbò bo ìlú yìí èmi ó sì gbà á là, nítorí mi àti nítorí Dafidi ìránṣẹ́ mi!”
36 Tad Tā Kunga eņģelis izgāja un nokāva Asiriešu lēģerī simts astoņdesmit piecus tūkstošus. Un kad no rīta agri cēlās, redzi, tad tur viss bija pilns miroņu.
Lẹ́yìn náà ni angẹli Olúwa jáde lọ ó sì pa ọ̀kẹ́ mẹ́sàn-án ó lé ẹgbẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n ènìyàn ní i ibùdó àwọn Asiria. Nígbà tí àwọn ènìyàn yìí jí ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì gbogbo wọn ti dòkú!
37 Tā Sanheribs, Asīrijas ķēniņš, aizgāja un gāja projām un griezās atpakaļ un palika Ninivē.
Nítorí náà Sennakeribu ọba Asiria fọ́ bùdó ó sì pẹsẹ̀dà. Òun sì padà sí Ninefe, ó sì dúró síbẹ̀.
38 Un kad viņš pielūdza Nizroka, sava dieva, namā, tad Adrameleķs un Sarecers, viņa dēli, to nokāva ar zobenu un aizbēga uz Ararat zemi. Un viņa dēls Asaradons palika par ķēniņu viņa vietā.
Ní ọjọ́ kan, bí ó ti ń jọ́sìn nínú tẹmpili Nisroki òrìṣà rẹ̀, àwọn ọmọ rẹ̀ Adrameleki àti Ṣareseri gé e lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n sì sálọ sí ilẹ̀ Ararati. Bẹ́ẹ̀ ni Esarhadoni ọmọ rẹ̀ sì gba ipò rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọba.

< Jesajas 37 >